< Deuteronomy 25 >

1 Nígbà tí àwọn ènìyàn méjì bá ń jà, kí wọn kó ẹjọ́ lọ sí ilé ìdájọ́, kí àwọn onídàájọ́ dá ẹjọ́ náà, kí wọn dá àre fún aláre àti ẹ̀bi fún ẹlẹ́bi.
Hangĩgĩa ngarari gatagatĩ ka andũ eerĩ, nĩmatware ciira ũcio igooti-inĩ, nao atuithania a ciira mamatuithanie, marekererie mũndũ ũrĩa ũtarĩ na mahĩtia, nake ũrĩa ũrĩ na mahĩtia mamũtuĩre itua.
2 Bí ó bá tọ́ láti na ẹlẹ́bi, kí onídàájọ́ dá a dọ̀bálẹ̀ kí a sì nà án ní ojú u rẹ̀ ní iye pàṣán tí ó tọ́ sí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀.
Kũngĩoneka atĩ ũrĩa ũrĩ na mahĩtia nĩagĩrĩire kũhũũrwo, mũtuithania wa ciira nĩagaathana akome ahũũrwo iboko iringaine na mahĩtia make, mũciiri ũcio akĩonaga,
3 Ṣùgbọ́n kò gbọdọ̀ fún un ju ogójì pàṣán lọ. Bí ó bá nà án ju bẹ́ẹ̀ lọ, arákùnrin rẹ̀ yóò di ẹni ìrẹ̀sílẹ̀ ní ojú rẹ̀.
no rĩrĩ, ndakamũhũũrithie iboko makĩria ya mĩrongo ĩna. Angĩhũũrwo makĩria ya iboko icio, mũrũ wa thoguo aahota kuoneka arĩ mũmene maitho-inĩ maku.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹ́nu.
Ndũkanoohe ndegwa kanua hĩndĩ ĩrĩa ĩkũranga ngano ĩkĩmĩhũũra.
5 Bí àwọn arákùnrin bá ń gbé pọ̀, tí ọ̀kan nínú wọn bá sì kú, tí kò sí ní ọmọkùnrin, kí aya òkú má ṣe ní àlejò ará òde ní ọkọ rẹ̀. Arákùnrin ọkọ rẹ̀ ni kí ó wọlé tọ̀ ọ́, kí ó fi ṣe aya, kí ó sì ṣe iṣẹ́ arákùnrin ọkọ fún un.
Mũndũ na mũrũ wa nyina mangĩkorwo matũũranagia hamwe, na ũmwe wao akue atarĩ na mwana wa kahĩĩ, mũtumia ũcio wake ndakanahike nja ya nyũmba ĩyo. Mũrũ ũcio wa nyina na mũthuuriwe nĩakamuoya amũhikie, na amũhingĩrie bata wake o ta mũrũ wa nyina na mũthuuriwe.
6 Ọmọkùnrin tí ó bá kọ́ bí ni yóò máa jẹ́ orúkọ arákùnrin rẹ̀ tí ó kú náà, kí orúkọ rẹ̀ má ba á parẹ́ ní Israẹli.
Mwana wa mbere wa kahĩĩ ũrĩa agaaciara nĩwe ũgaatũũria rĩĩtwa rĩa ũcio ũkuĩte, nĩgeetha rĩĩtwa rĩake rĩtikanathario rĩehere Isiraeli.
7 Ṣùgbọ́n bí ọkùnrin náà kò bá fẹ́ fi aya arákùnrin rẹ̀ ṣe aya rẹ̀, obìnrin náà yóò lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú láti sọ pé, “Arákùnrin ọkọ ọ̀ mi kọ̀ láti gbé orúkọ arákùnrin rẹ̀ ró ní Israẹli. Kò ní ṣe ojúṣe rẹ̀ bí arákùnrin ọkọ mi sí mi.”
No rĩrĩ, mũndũ angĩkorwo ndekwenda kũhikia mũtumia wa mũrũ wa nyina, mũtumia ũcio nĩagathiĩ kũrĩ athuuri hau kĩhingo-inĩ gĩa itũũra, ameere atĩrĩ, “Mũrũ wa nyina na mũthuuri wakwa nĩaregete gũtũũria rĩĩtwa rĩa mũrũ wa nyina gũkũ Isiraeli. Nĩaregete kũhingia bata ũrĩa mũrũ wa nyina na mũthuuri wa mũtumia agĩrĩirwo nĩ kũhingia.”
8 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀ yóò pè é, wọn yóò sì bá sọ̀rọ̀. Bí ó bá sì kọ̀ jálẹ̀ tí ó bá sọ pé, “Èmi kò fẹ́ láti fẹ́ ẹ,”
Hĩndĩ ĩyo athuuri acio a itũũra rĩake nĩmageta mũndũ ũcio mamwarĩrie. Mũndũ ũcio angĩgwatĩria kuuga atĩrĩ, “Ndirenda kũmũhikia,”
9 opó arákùnrin rẹ̀ yìí yóò lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ní ojú àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀, yóò yọ bàtà ẹsẹ̀ rẹ̀ kan, yóò sì tu itọ́ sí ọkùnrin náà lójú, yóò sì wí pé, “Èyí ni ohun tí a ṣe sí ọkùnrin tí kò jẹ́ kí ìdílé arákùnrin rẹ̀ wà títí ayé.”
mũtumia ũcio wa mũrũ wa nyina nĩakambata athiĩ harĩ we o hau harĩ athuuri acio, amũrute kĩraatũ kĩmwe gĩake, acooke amũtuĩre mata ũthiũ, amwĩre atĩrĩ, “Ũũ nĩguo mũndũ ũrĩa warega gwaka nyũmba ya mũrũ wa nyina ekagwo.”
10 A ó sì mọ ìdílé arákùnrin yìí ní Israẹli gẹ́gẹ́ bí “Ìdílé tí a yọ bàtà rẹ̀.”
Rũciaro rwa mũndũ ũcio kũu Isiraeli rũgeetagwo Nyũmba ya Mũndũ Ũrutĩtwo Kĩraatũ.
11 Bí ọkùnrin méjì bá ń jà, tí ìyàwó ọ̀kan nínú wọn bá sì wá láti gbèjà ọkọ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin tí ń lù ú, tí ó sì nawọ́ di nǹkan ọkùnrin abẹ́ ẹ rẹ̀ mú.
Andũ eerĩ mangĩkorwo makĩrũa, nake mũtumia wa ũmwe wao oke gũteithũra mũthuuri wake kuuma kũrĩ ũcio maraarũa nake, nake amũnyiite kĩĩga gĩake gĩa ũciari,
12 Ìwọ yóò gé ọwọ́ rẹ̀ náà kúrò. Má ṣe ṣàánú fún un.
nĩagatinio guoko kũu gwake. Ndakanaiguĩrwo tha.
13 Má ṣe ní oríṣìí ìtẹ̀wọ̀n méjì tó yàtọ̀ sí ara wọn nínú àpò rẹ, ọ̀kan wúwo àti ọ̀kan fífúyẹ́.
Mũtigaakoragwo na mahiga ma gũthima meerĩ mataiganainie ũritũ mondo-inĩ cianyu, rĩmwe iritũ na rĩngĩ ihũthũ.
14 Má ṣe ní oríṣìí ìwọ̀n méjì tí ó yàtọ̀ sí ara wọn ní ilé è rẹ: ọ̀kan fífẹ̀, ọ̀kan kékeré.
Mũtigakoragwo na igeri igĩrĩ itaiganaine nyũmba-inĩ cianyu, kĩmwe kĩnene na kĩmwe kĩnini.
15 O gbọdọ̀ ní ìtẹ̀wọ̀n àti òsùwọ̀n pípé àti ti òtítọ́ nítorí náà kí ìwọ kí ó lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ.
No nginya mũkoragwo na ithimi na igeri iria ciagĩrĩire na cia kwĩhokwo, nĩgeetha matukũ manyu maingĩhe ma gũtũũra bũrũri ũrĩa Jehova Ngai wanyu ekũmũhe.
16 Nítorí Olúwa Ọlọ́run kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí, àní ẹnikẹ́ni tí ń ṣe àìṣòdodo.
Nĩgũkorwo Jehova Ngai wanyu nĩathũire mũndũ o wothe wĩkaga maũndũ macio, mũndũ o wothe wĩkaga maũndũ matarĩ ma wĩhokeku.
17 Rántí ohun tí àwọn ará Amaleki ṣe sí i yín ní ọ̀nà nígbà tí ẹ̀ ń jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Ririkanaga ũrĩa Aamaleki maamwĩkire mũrĩ njĩra-inĩ rĩrĩa mwoimire bũrũri wa Misiri.
18 Nígbà tí àárẹ̀ mú un yín tí agara sì dá a yín, wọ́n pàdé e yín ní ọ̀nà àjò o yín, wọ́n gé àwọn tí ó rẹ̀yìn kúrò, wọn kò ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
Hĩndĩ ĩrĩa mwarĩ anogu na mũgathirwo nĩ hinya, nĩmacemanirie na inyuĩ rĩrĩa mwarĩ rũgendo-inĩ na makĩũraga andũ othe arĩa maarigĩtie na thuutha; makĩaga gwĩtigĩra Ngai.
19 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá fún un yín ní ìsinmi lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá yín tí ó yí i yín ká ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run ń fi fún yín láti ni ní ìní, ẹ̀yin yóò sì pa ìrántí Amaleki rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Má ṣe gbàgbé.
Hĩndĩ ĩrĩa Jehova Ngai wanyu akaamũhe ũhurũko kuuma kũrĩ thũ iria ciothe imũrigiicĩirie bũrũri-inĩ ũrĩa ekũmũhe mũwĩgwatĩre ũtuĩke igai rĩanyu-rĩ, mũkaaniina kĩndũ o gĩothe kĩngĩtũma Aamaleki maririkanwo gũkũ thĩ guothe. Mũtikanariganĩrwo nĩ ũndũ ũcio.

< Deuteronomy 25 >