< Deuteronomy 25 >
1 Nígbà tí àwọn ènìyàn méjì bá ń jà, kí wọn kó ẹjọ́ lọ sí ilé ìdájọ́, kí àwọn onídàájọ́ dá ẹjọ́ náà, kí wọn dá àre fún aláre àti ẹ̀bi fún ẹlẹ́bi.
S'il s'élève un différend entre des hommes, ils se présenteront au Tribunal, pour qu'on les juge, et que l'on déclare innocent l'innocent, et coupable le coupable.
2 Bí ó bá tọ́ láti na ẹlẹ́bi, kí onídàájọ́ dá a dọ̀bálẹ̀ kí a sì nà án ní ojú u rẹ̀ ní iye pàṣán tí ó tọ́ sí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀.
Et si le coupable mérite des coups, le Juge le fera étendre par terre et battre sous ses yeux d'un nombre de coups suffisant en raison de sa culpabilité.
3 Ṣùgbọ́n kò gbọdọ̀ fún un ju ogójì pàṣán lọ. Bí ó bá nà án ju bẹ́ẹ̀ lọ, arákùnrin rẹ̀ yóò di ẹni ìrẹ̀sílẹ̀ ní ojú rẹ̀.
Il lui fera donner quarante coups, pas plus, de peur que s'il y fait ajouter des coups en grand nombre, ton frère ne soit avili devant toi.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹ́nu.
Tu n'emmusèleras pas le bœuf, quand il foule le grain.
5 Bí àwọn arákùnrin bá ń gbé pọ̀, tí ọ̀kan nínú wọn bá sì kú, tí kò sí ní ọmọkùnrin, kí aya òkú má ṣe ní àlejò ará òde ní ọkọ rẹ̀. Arákùnrin ọkọ rẹ̀ ni kí ó wọlé tọ̀ ọ́, kí ó fi ṣe aya, kí ó sì ṣe iṣẹ́ arákùnrin ọkọ fún un.
Si des frères demeurent dans un même lieu, ou que l'un d'eux meure sans laisser de fils, la femme du frère mort ne se mariera point au dehors à un étranger; son beau-frère s'approchera d'elle, et la prendra pour sa femme, et remplira envers elle le devoir du beau-frère.
6 Ọmọkùnrin tí ó bá kọ́ bí ni yóò máa jẹ́ orúkọ arákùnrin rẹ̀ tí ó kú náà, kí orúkọ rẹ̀ má ba á parẹ́ ní Israẹli.
Et ce cas échéant, le premier-né qu'elle enfantera, succédera au nom du frère défunt, afin que son nom ne disparaisse pas d'Israël.
7 Ṣùgbọ́n bí ọkùnrin náà kò bá fẹ́ fi aya arákùnrin rẹ̀ ṣe aya rẹ̀, obìnrin náà yóò lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú láti sọ pé, “Arákùnrin ọkọ ọ̀ mi kọ̀ láti gbé orúkọ arákùnrin rẹ̀ ró ní Israẹli. Kò ní ṣe ojúṣe rẹ̀ bí arákùnrin ọkọ mi sí mi.”
Mais si l'homme ne se soucie pas d'épouser sa belle-sœur, sa belle-sœur se présentera, à la Porte devant les Anciens et dira: Mon beau-frère se refuse à faire revivre le nom de son frère en Israël; il ne veut pas remplir envers moi le devoir du Lévirat.
8 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀ yóò pè é, wọn yóò sì bá sọ̀rọ̀. Bí ó bá sì kọ̀ jálẹ̀ tí ó bá sọ pé, “Èmi kò fẹ́ láti fẹ́ ẹ,”
Alors les Anciens de sa ville le citeront, et ils lui parleront;
9 opó arákùnrin rẹ̀ yìí yóò lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ní ojú àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀, yóò yọ bàtà ẹsẹ̀ rẹ̀ kan, yóò sì tu itọ́ sí ọkùnrin náà lójú, yóò sì wí pé, “Èyí ni ohun tí a ṣe sí ọkùnrin tí kò jẹ́ kí ìdílé arákùnrin rẹ̀ wà títí ayé.”
et s'il persiste et dit: Je ne me soucie pas de l'épouser; sa belle-sœur s'avancera, vers lui, devant les yeux des Anciens, et lui détachera sa sandale du pied, et crachera en face de lui; puis prenant la parole elle dira: Ainsi soit fait à l'homme qui n'édifie pas la maison de son frère.
10 A ó sì mọ ìdílé arákùnrin yìí ní Israẹli gẹ́gẹ́ bí “Ìdílé tí a yọ bàtà rẹ̀.”
Et en Israël on le désignera de ce nom: Maison du déchaussé.
11 Bí ọkùnrin méjì bá ń jà, tí ìyàwó ọ̀kan nínú wọn bá sì wá láti gbèjà ọkọ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin tí ń lù ú, tí ó sì nawọ́ di nǹkan ọkùnrin abẹ́ ẹ rẹ̀ mú.
Si des hommes ont entre eux une rixe, l'un avec l'autre, et que la femme de l'un accoure pour tirer son mari des mains de celui qui le bat, et qu'étendant la main elle saisisse celui-ci par les parties honteuses,
12 Ìwọ yóò gé ọwọ́ rẹ̀ náà kúrò. Má ṣe ṣàánú fún un.
coupe-lui la main, et cela sans pitié.
13 Má ṣe ní oríṣìí ìtẹ̀wọ̀n méjì tó yàtọ̀ sí ara wọn nínú àpò rẹ, ọ̀kan wúwo àti ọ̀kan fífúyẹ́.
Tu n'auras pas dans ta bourse double pierre à peser, une grosse et une petite.
14 Má ṣe ní oríṣìí ìwọ̀n méjì tí ó yàtọ̀ sí ara wọn ní ilé è rẹ: ọ̀kan fífẹ̀, ọ̀kan kékeré.
Tu n'auras pas dans ta maison double épha, un grand et un petit.
15 O gbọdọ̀ ní ìtẹ̀wọ̀n àti òsùwọ̀n pípé àti ti òtítọ́ nítorí náà kí ìwọ kí ó lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ.
Aie des pierres d'un poids complet et juste, et un épha d'une capacité complète et juste, afin que tes jours se prolongent dans le pays que l'Éternel, ton Dieu, te donne.
16 Nítorí Olúwa Ọlọ́run kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí, àní ẹnikẹ́ni tí ń ṣe àìṣòdodo.
Car quiconque le fait, quiconque fraude, est l'abomination de l'Éternel.
17 Rántí ohun tí àwọn ará Amaleki ṣe sí i yín ní ọ̀nà nígbà tí ẹ̀ ń jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Rappelle-toi ce que t'a fait Amalek pendant le trajet lors de votre sortie d'Egypte,
18 Nígbà tí àárẹ̀ mú un yín tí agara sì dá a yín, wọ́n pàdé e yín ní ọ̀nà àjò o yín, wọ́n gé àwọn tí ó rẹ̀yìn kúrò, wọn kò ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
comment il t'a attaqué sur la route, est tombé sur ton arrière-garde, sur toute la troupe débile qui se traînait après toi, toi-même étant épuisé et las, et comment il n'eut aucune crainte de Dieu.
19 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá fún un yín ní ìsinmi lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá yín tí ó yí i yín ká ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run ń fi fún yín láti ni ní ìní, ẹ̀yin yóò sì pa ìrántí Amaleki rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Má ṣe gbàgbé.
Et lorsque l'Éternel, ton Dieu, t'aura donné le repos et t'aura débarrassé de tous les ennemis de tes alentours dans le pays que l'Éternel, ton Dieu, te donne en propriété pour le conquérir, tu mettras fin à la mémoire d'Amalek sous les Cieux. Ne l'oublie pas.