< Deuteronomy 25 >

1 Nígbà tí àwọn ènìyàn méjì bá ń jà, kí wọn kó ẹjọ́ lọ sí ilé ìdájọ́, kí àwọn onídàájọ́ dá ẹjọ́ náà, kí wọn dá àre fún aláre àti ẹ̀bi fún ẹlẹ́bi.
Kong adunay paglalis sa taliwala sa mga tawo, ug mangadto sila sa paghukom, ug mga maghuhukom magahukom kanila, pagabuhian nila ang matarung, ug pagahukman nila sa silot ang dautan.
2 Bí ó bá tọ́ láti na ẹlẹ́bi, kí onídàájọ́ dá a dọ̀bálẹ̀ kí a sì nà án ní ojú u rẹ̀ ní iye pàṣán tí ó tọ́ sí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀.
Ug mahitabo nga kong ang dautang tawo angay nga pagahampakon, nga ang maghuhukom magapaubo kaniya ug iyang ipahampak siya sa iyang atubangan, sumala sa iyang pagkadautan, sa pila ka isip.
3 Ṣùgbọ́n kò gbọdọ̀ fún un ju ogójì pàṣán lọ. Bí ó bá nà án ju bẹ́ẹ̀ lọ, arákùnrin rẹ̀ yóò di ẹni ìrẹ̀sílẹ̀ ní ojú rẹ̀.
Iyang pagalatuson siya ug kap-atan ka hampak, dili siya magapalabaw niini; tingali kong siya magahampak nga kapin niini, unya ang imong igsoon madautan nga pagatan-awon sa atubangan mo.
4 Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹ́nu.
Dili mo pagbutangan ug busal ang baba sa vaca kong magagiuk kini sa trigo.
5 Bí àwọn arákùnrin bá ń gbé pọ̀, tí ọ̀kan nínú wọn bá sì kú, tí kò sí ní ọmọkùnrin, kí aya òkú má ṣe ní àlejò ará òde ní ọkọ rẹ̀. Arákùnrin ọkọ rẹ̀ ni kí ó wọlé tọ̀ ọ́, kí ó fi ṣe aya, kí ó sì ṣe iṣẹ́ arákùnrin ọkọ fún un.
Kong ang mga managsoon magatingub sa pagpuyo, ug mamatay ang usa kanila, ug walay anak, ang asawa sa namatay dili makapamana sa gawas sa lalake nga dumuloong: ang igsoon sa iyang bana moadto kaniya ug mangasawa kaniya, ug magabuhat siya sa katungdanan ingon nga igsoon sa bana niya.
6 Ọmọkùnrin tí ó bá kọ́ bí ni yóò máa jẹ́ orúkọ arákùnrin rẹ̀ tí ó kú náà, kí orúkọ rẹ̀ má ba á parẹ́ ní Israẹli.
Ug mahitabo nga ang panganay nga lalake nga igapanganak niya, magabangon sa ngalan sa iyang igsoon nga namatay, aron ang ngalan niini dili mapala sa Israel.
7 Ṣùgbọ́n bí ọkùnrin náà kò bá fẹ́ fi aya arákùnrin rẹ̀ ṣe aya rẹ̀, obìnrin náà yóò lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú láti sọ pé, “Arákùnrin ọkọ ọ̀ mi kọ̀ láti gbé orúkọ arákùnrin rẹ̀ ró ní Israẹli. Kò ní ṣe ojúṣe rẹ̀ bí arákùnrin ọkọ mi sí mi.”
Ug kong ang tawo dili buot magadawat sa asawa sa iyang igsoon, unya moadto ang asawa sa iyang igsoon sa pultahan ngadto sa mga anciano, ug magaingon siya: Ang igsoon nga lalake sa akong bana dili buot magabangon pag-usab alang sa iyang igsoon ug ngalan sa Israel; siya dili buot magpakigkaubanan kanako.
8 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀ yóò pè é, wọn yóò sì bá sọ̀rọ̀. Bí ó bá sì kọ̀ jálẹ̀ tí ó bá sọ pé, “Èmi kò fẹ́ láti fẹ́ ẹ,”
Unya ang mga anciano sa iyang lungsod magapaanha kaniya, ug magapakigsulti kaniya: ug kong siya motingog ug moingon: Ako dili buot magadawat kaniya.
9 opó arákùnrin rẹ̀ yìí yóò lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ní ojú àwọn àgbàgbà ìlú rẹ̀, yóò yọ bàtà ẹsẹ̀ rẹ̀ kan, yóò sì tu itọ́ sí ọkùnrin náà lójú, yóò sì wí pé, “Èyí ni ohun tí a ṣe sí ọkùnrin tí kò jẹ́ kí ìdílé arákùnrin rẹ̀ wà títí ayé.”
Nan moduol kaniya ang asawa sa iyang igsoon sa atubangan sa mga anciano, ug magabadbad sa iyang sapin sa iyang tiil, ug magaluwa sa iyang nawong ug mosulti ug magaingon: Mao kini ang pagabuhaton sa tawo nga dili magatukod sa balay sa iyang igsoon nga lalake.
10 A ó sì mọ ìdílé arákùnrin yìí ní Israẹli gẹ́gẹ́ bí “Ìdílé tí a yọ bàtà rẹ̀.”
Ug ang iyang ngalan pagahinganlan sa Israel: Ang balay sa binadbaran sa sapin.
11 Bí ọkùnrin méjì bá ń jà, tí ìyàwó ọ̀kan nínú wọn bá sì wá láti gbèjà ọkọ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin tí ń lù ú, tí ó sì nawọ́ di nǹkan ọkùnrin abẹ́ ẹ rẹ̀ mú.
Sa diha nga manag-away ang mga tawo sa usa ug usa, ug moabut ang asawa sa usa aron sa pagluwas sa iyang bana gikan sa kamot sa magasamad kaniya, ug igakuot niya ang iyang kamot, ug iyang pagakuhaon siya pinaagi sa mga butang tinago;
12 Ìwọ yóò gé ọwọ́ rẹ̀ náà kúrò. Má ṣe ṣàánú fún un.
Unya pagaputlon mo ang iyang kamot: ang imong mata dili magakalooy kaniya.
13 Má ṣe ní oríṣìí ìtẹ̀wọ̀n méjì tó yàtọ̀ sí ara wọn nínú àpò rẹ, ọ̀kan wúwo àti ọ̀kan fífúyẹ́.
Dili ka magbaton diha sa imong puntil sa nagakalainlain nga timbang, dagku ug gagmay.
14 Má ṣe ní oríṣìí ìwọ̀n méjì tí ó yàtọ̀ sí ara wọn ní ilé è rẹ: ọ̀kan fífẹ̀, ọ̀kan kékeré.
Dili ka magbaton diha sa imong balay sa taksanan nga nagkalainlain, dagku ug gagmay.
15 O gbọdọ̀ ní ìtẹ̀wọ̀n àti òsùwọ̀n pípé àti ti òtítọ́ nítorí náà kí ìwọ kí ó lè pẹ́ ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ.
Magabaton ka ug timbangan nga hingpit ug matarung: magabaton ka ug taksanan nga hingpit ug matarung: aron pahalugwayan ang imong mga adlaw sa yuta nga ginahatag kanimo ni Jehova nga imong Dios.
16 Nítorí Olúwa Ọlọ́run kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí, àní ẹnikẹ́ni tí ń ṣe àìṣòdodo.
Kadtong tanan nga magabuhat nianang mga butanga, bisan kinsa nga magabuhat ug dili matarung, maoy usa ka dulumtanan alang kang Jehova nga imong Dios.
17 Rántí ohun tí àwọn ará Amaleki ṣe sí i yín ní ọ̀nà nígbà tí ẹ̀ ń jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá.
Hinumduman mo ang gibuhat ni Amalec kanimo sa dalan, sa paggikan ninyo sa Egipto:
18 Nígbà tí àárẹ̀ mú un yín tí agara sì dá a yín, wọ́n pàdé e yín ní ọ̀nà àjò o yín, wọ́n gé àwọn tí ó rẹ̀yìn kúrò, wọn kò ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
Nga siya misugat kanimo sa dalan, ug naglaglag sa ulahi nga panon sa mga sundalo, sa tanan nga mga mahuyang sa ulahi nimo, sa diha nga gikapuyan ka ug gibudlay; ug wala siya mahadlok sa Dios.
19 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run yín bá fún un yín ní ìsinmi lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá yín tí ó yí i yín ká ní ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run ń fi fún yín láti ni ní ìní, ẹ̀yin yóò sì pa ìrántí Amaleki rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Má ṣe gbàgbé.
Busa mahitabo, sa diha nga si Jehova nga imong Dios makahatag na kanimo sa kapahulayan gikan sa imong mga kaaway nga nagalibut, sa yuta nga gihatag kanimo ni Jehova nga imong Dios sa pagkapanulondon aron magapanag-iya niini, nga pagapalaon mo ang handumanan ni Amalec gikan sa ilalum sa langit: dili ka mahikalimot.

< Deuteronomy 25 >