< Deuteronomy 24 >

1 Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, tí ó sì gbe ní ìyàwó, yóò sì ṣe, bí obìnrin náà kò bá rí ojúrere ní ojú ọkùnrin náà, nítorí ó rí ohun àìtọ́ kan lára rẹ̀, ǹjẹ́ kí ó kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún obìnrin náà, kí ó sì fi lé e lọ́wọ́, kí ó sì ran jáde kúrò nínú ilé rẹ̀,
Om en man har tagit sig en hustru och äktat henne, men hon sedan icke längre finner nåd för hans ögon, därför att han hos henne har funnit något som väcker hans leda, och om han fördenskull har skrivit skiljebrev åt henne och givit henne det i handen och skickat bort henne från sitt hus,
2 tí ó bá di ìyàwó ọkùnrin mìíràn lẹ́yìn ìgbà tí ó kúrò nílé rẹ,
och kvinnan sedan, när hon har lämnat hans hus, går åstad och bliver en annans hustru,
3 àti tí ọkọ rẹ̀ kejì kò bá fẹ́ràn rẹ̀ tí ó sì kọ ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ sí i, kí ó fi fún un kí ó sì lé e kúrò nílé e rẹ̀, tàbí tí ọkọ rẹ̀ kejì bá kú,
och nu också denne andre man får motvilja mot henne och skriver skiljebrev åt henne och giver henne det i handen och skickar henne bort ifrån sitt hus, eller om denne andre man som har tagit henne till sin hustru dör,
4 nígbà náà ni ọkọ, tí ó ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, kò gbọdọ̀ fẹ́ ẹ mọ́ lẹ́yìn tí ó ti di àìmọ́. Nítorí èyí ni ìríra níwájú Olúwa. Má ṣe mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sórí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún.
då får icke hennes förste man, som skickade bort henne, åter taga henne till sin hustru, sedan hon har låtit orena sig, ty detta vore en styggelse inför HERREN; du skall icke draga synd över det land som HERREN, din Gud, vill giva dig till arvedel.
5 Bí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, o kò gbọdọ̀ ran lọ sí ogun tàbí kí ó ní iṣẹ́ kan láti ṣe. Ó ní láti ní òmìnira fún ọdún kan kí ó dúró sílé kí ó sì mú inú dídùn bá ìyàwó rẹ̀ tí ó fẹ́.
Om en man nyligen har tagit sig hustru, behöver han icke gå i krigstjänst, ej heller må någon annan tjänstgöring åläggas honom. Han skall vara fri ett år för att stanna hemma och glädja den hustru han har tagit.
6 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ gba ìyá ọlọ tàbí ọmọ ọlọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìdúró fún gbèsè, nítorí pé ẹ̀mí ènìyàn ni ó gbà ní pàṣípàrọ̀ n nì.
Man skall icke taga handkvarnen eller ens kvarnens översten i pant, ty den så gör tager livet i pant.
7 Bí a bá mú ọkùnrin kan tí ó jí ọ̀kan nínú arákùnrin rẹ̀ ní Israẹli gbé àti tí ó jí ọ̀kan nínú ẹrú tàbí kí ó tà á, ẹni tí ó jí ènìyàn gbé ní láti kú. Ẹ ní láti wẹ búburú kúrò láàrín yín.
Om en man befinnes hava stulit någon av sina bröder, Israels barn, och han behandlar denne såsom träl eller säljer honom, så skall tjuven dö: du skall skaffa bort ifrån dig vad ont är.
8 Ní ti ààrùn ẹ̀tẹ̀ kíyèsára láti máa ṣe gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ti pàṣẹ fún ọ. O ní láti máa fi ìṣọ́ra tẹ̀lé ohun tí mo ti pàṣẹ fún wọn.
Tag dig till vara, så att du, när någon bliver angripen av spetälska, noga håller och gör allt som de levitiska prästerna lära eder. Vad jag har bjudit dem skolen I hålla och göra.
9 Rántí ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe sí Miriamu lójú ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí o jáde kúrò ní Ejibiti.
Kom ihåg vad HERREN, din Gud, gjorde med Mirjam på vägen, när I drogen ut ur Egypten.
10 Nígbà tí o bá wín arákùnrin rẹ ní ohunkóhun, má ṣe lọ sí ilé rẹ̀ láti gba ohun tí ó bá mú wá bí ẹ̀rí.
Om du giver något lån åt din nästa, så skall du icke gå in i hans hus och taga pant av honom.
11 Dúró síta gbangba kí o sì jẹ́ kí ọkùnrin tí o wín mú ògo rẹ jáde wá fún ọ.
Du skall stanna utanför, och mannen som du har lånat åt skall bära ut panten till dig.
12 Bí ọkùnrin náà bá jẹ́ tálákà má ṣe lọ sùn ti ìwọ ti ògo rẹ.
Och om det är en fattig man, så skall du icke hava hans pant till täcke, när du ligger och sover.
13 Dá aṣọ ìlekè rẹ padà ní àṣálẹ́ kí ó bá à le sùn lórí i rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, ó sì máa jásí ìwà òdodo níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Du skall giva honom panten tillbaka, när solen går ned, så att han kan hava sin mantel på sig när han ligger och sover, och så välsigna dig; och detta skall lända dig till rättfärdighet inför HERREN, din Gud.
14 Má ṣe ni alágbàṣe kan lára tí ó jẹ́ tálákà àti aláìní, bóyá ó jẹ́ arákùnrin Israẹli tàbí àlejò tí ó ń gbé ní ọ̀kan nínú àwọn ìlú rẹ.
Du skall icke göra en arm och fattig daglönare orätt, evad han är en dina bröder, eller han är en av främlingarna som äro hos dig i ditt land, inom dina portar.
15 San owó iṣẹ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà kí ó tó di àṣálẹ́, nítorí ó jẹ́ tálákà, ó sì gbẹ́kẹ̀lé e bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ó lè ké pe Olúwa sí ọ, o sì máa gba ìdálẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀.
Samma dag han har gjort sitt arbete skall du giva honom hans lön och icke låta solen gå ned däröver, eftersom han är arm och längtar efter sin lön; han kan eljest ropa över dig till HERREN, och så kommer synd att vila på dig.
16 Baba kò gbọdọ̀ kú fún àwọn ọmọ wọn tàbí kí àwọn ọmọ kú fún baba wọ́n; olúkúlùkù ní láti kú fún ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
Föräldrarna skola icke dödas för sina barns skull och barnen skola icke dödas för sina föräldrars skull; var och en skall lida döden genom sin egen synd.
17 Má ṣe yí ìdájọ́ po fún àlejò tàbí aláìní baba, tàbí gba aṣọ ìlekè opó bí ẹ̀rí.
Du skall icke vränga rätten för främlingen eller den faderlöse, och en änkas kläder skall du icke taga i pant;
18 Rántí pé o jẹ́ ẹrú ní Ejibiti tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì gbà ọ́ níbẹ̀. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
du skall komma ihåg att du själv har varit en träl i Egypten, och att HERREN, din Gud, har förlossat dig därifrån; därför bjuder jag dig att iakttaga detta.
19 Nígbà tí o bá ń kórè oko rẹ tí o sì fojú fo ìtí kan, má ṣe padà lọ mú u. Fi í kalẹ̀ fún àwọn àlejò, aláìní baba àti opó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún fún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ.
Om du, när du inbärgar skörden på din åker, glömmer en kärve kvar på åkern, skall du icke gå tillbaka för att hämta den, ty den skall tillhöra främlingen, den faderlöse och änkan. Detta skall du iakttaga, för att HERREN, din Gud, må välsigna dig i alla dina händers verk.
20 Nígbà tí o bá ń gun igi olifi lára àwọn igi i rẹ, má ṣe padà lọ sí ẹ̀ka náà ní ìgbà kejì. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
När du har slagit ned dina oliver, skall du icke sedan genomsöka grenarna; vad där finnes kvar skall tillhöra främlingen den faderlöse och änkan.
21 Nígbà tí ìwọ bá kórè èso àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ, má ṣe lọ sí ọgbà náà mọ́. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
När du har avbärgat din vingård, skall du sedan icke göra någon efterskörd; vad där finnes kvar skall tillhöra främlingen, den faderlöse och änkan.
22 Rántí pé ìwọ ti jẹ́ àlejò ní Ejibiti. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Du skall komma ihåg att du själv har varit en träl i Egyptens land; därför bjuder jag dig att iakttaga detta.

< Deuteronomy 24 >