< Deuteronomy 24 >

1 Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, tí ó sì gbe ní ìyàwó, yóò sì ṣe, bí obìnrin náà kò bá rí ojúrere ní ojú ọkùnrin náà, nítorí ó rí ohun àìtọ́ kan lára rẹ̀, ǹjẹ́ kí ó kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún obìnrin náà, kí ó sì fi lé e lọ́wọ́, kí ó sì ran jáde kúrò nínú ilé rẹ̀,
Kadar si moški vzame ženo in jo poroči in se pripeti, da ona ne najde naklonjenosti v njegovih očeh, ker je v njej našel nekaj nečistega, potem naj ji napiše ločitveni list in ji ga da v roko in jo pošlje ven iz svoje hiše.
2 tí ó bá di ìyàwó ọkùnrin mìíràn lẹ́yìn ìgbà tí ó kúrò nílé rẹ,
Ko je odšla iz njegove hiše, lahko gre in postane žena drugega moškega.
3 àti tí ọkọ rẹ̀ kejì kò bá fẹ́ràn rẹ̀ tí ó sì kọ ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ sí i, kí ó fi fún un kí ó sì lé e kúrò nílé e rẹ̀, tàbí tí ọkọ rẹ̀ kejì bá kú,
Če jo zadnji mož sovraži in ji napiše ločitveni list in ji ga da v roko in jo pošlje ven iz svoje hiše, ali če zadnji soprog, ki jo je vzel, da bi bila njegova žena, umre,
4 nígbà náà ni ọkọ, tí ó ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, kò gbọdọ̀ fẹ́ ẹ mọ́ lẹ́yìn tí ó ti di àìmọ́. Nítorí èyí ni ìríra níwájú Olúwa. Má ṣe mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sórí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún.
je njen prejšnji soprog, ki jo je poslal proč, ne sme ponovno vzeti, da bi bila njegova žena, potem ko je omadeževana, kajti to je ogabnost pred Gospodom in ti deželi, ki ti jo daje Gospod, tvoj Bog, za dediščino, ne boš povzročil, da greši.
5 Bí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, o kò gbọdọ̀ ran lọ sí ogun tàbí kí ó ní iṣẹ́ kan láti ṣe. Ó ní láti ní òmìnira fún ọdún kan kí ó dúró sílé kí ó sì mú inú dídùn bá ìyàwó rẹ̀ tí ó fẹ́.
Ko si je mož vzel novo ženo, ne bo šel ven na vojno niti ne bo obremenjen s kakršnimkoli poslom, temveč bo eno leto doma svoboden in bo razveseljeval svojo ženo, ki jo je vzel.
6 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ gba ìyá ọlọ tàbí ọmọ ọlọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìdúró fún gbèsè, nítorí pé ẹ̀mí ènìyàn ni ó gbà ní pàṣípàrọ̀ n nì.
Noben človek ne bo za jamstvo vzel spodnji ali zgornji mlinski kamen, kajti za jamstvo jemlje človeško življenje.
7 Bí a bá mú ọkùnrin kan tí ó jí ọ̀kan nínú arákùnrin rẹ̀ ní Israẹli gbé àti tí ó jí ọ̀kan nínú ẹrú tàbí kí ó tà á, ẹni tí ó jí ènìyàn gbé ní láti kú. Ẹ ní láti wẹ búburú kúrò láàrín yín.
Če je mož najden, da krade kateregakoli izmed svojih bratov, Izraelovih otrok in iz njega dela trgovsko blago ali ga proda, potem bo ta tat umrl, in ti boš izmed vas iztrebil zlo.
8 Ní ti ààrùn ẹ̀tẹ̀ kíyèsára láti máa ṣe gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ti pàṣẹ fún ọ. O ní láti máa fi ìṣọ́ra tẹ̀lé ohun tí mo ti pàṣẹ fún wọn.
Pazi na nadlogo gobavosti, da marljivo obeležuješ in delaš glede na vse, kar te bodo Lévijevci učili. Kakor sem jim zapovedal tako boste vi obeleževali, da delate.
9 Rántí ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe sí Miriamu lójú ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí o jáde kúrò ní Ejibiti.
Spominjaj se, kaj je Gospod, tvoj Bog, storil Mirjam na poti potem, ko ste izšli iz Egipta.
10 Nígbà tí o bá wín arákùnrin rẹ ní ohunkóhun, má ṣe lọ sí ilé rẹ̀ láti gba ohun tí ó bá mú wá bí ẹ̀rí.
Kadar karkoli posodiš svojemu bratu, ne boš šel v njegovo hišo, da bi dobil svoje jamstvo.
11 Dúró síta gbangba kí o sì jẹ́ kí ọkùnrin tí o wín mú ògo rẹ jáde wá fún ọ.
Stal boš zunaj in mož, ki si mu posodil, bo jamstvo prinesel ven k tebi.
12 Bí ọkùnrin náà bá jẹ́ tálákà má ṣe lọ sùn ti ìwọ ti ògo rẹ.
Če je mož reven, ne boš spal z njegovim jamstvom.
13 Dá aṣọ ìlekè rẹ padà ní àṣálẹ́ kí ó bá à le sùn lórí i rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, ó sì máa jásí ìwà òdodo níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
V vsakem primeru mu boš ponovno izročil jamstvo, ko sonce zaide, da bo lahko spal v svojem lastnem oblačilu in te blagoslovil in to ti bo pravičnost pred Gospodom, tvojim Bogom.
14 Má ṣe ni alágbàṣe kan lára tí ó jẹ́ tálákà àti aláìní, bóyá ó jẹ́ arákùnrin Israẹli tàbí àlejò tí ó ń gbé ní ọ̀kan nínú àwọn ìlú rẹ.
Ne boš zatiral najetega služabnika, ki je reven in pomoči potreben, bodisi je od tvojih bratov ali od tvojih tujcev, ki so v tvoji deželi, znotraj tvojih velikih vrat.
15 San owó iṣẹ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà kí ó tó di àṣálẹ́, nítorí ó jẹ́ tálákà, ó sì gbẹ́kẹ̀lé e bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ó lè ké pe Olúwa sí ọ, o sì máa gba ìdálẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀.
Na njegov dan mu boš dal njegovo najemnino niti ne bo sonce zašlo nad le-to, kajti on je reven in nanjo naravnava svoje srce, da ne bi zoper tebe klical h Gospodu in bi bil tebi to greh.
16 Baba kò gbọdọ̀ kú fún àwọn ọmọ wọn tàbí kí àwọn ọmọ kú fún baba wọ́n; olúkúlùkù ní láti kú fún ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
Očetje ne bodo usmrčeni zaradi otrok niti ne bodo otroci usmrčeni zaradi očetov. Vsak mož bo usmrčen za svoj greh.
17 Má ṣe yí ìdájọ́ po fún àlejò tàbí aláìní baba, tàbí gba aṣọ ìlekè opó bí ẹ̀rí.
Ne boš izkrivljal sodbe tujcu niti siroti niti za jamstvo ne jemlji vdovinega oblačila,
18 Rántí pé o jẹ́ ẹrú ní Ejibiti tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì gbà ọ́ níbẹ̀. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
temveč se boš spominjal, da si bil suženj v Egiptu in Gospod, tvoj Bog, te je odkupil od tam. Zato ti zapovedujem, da to stvar storiš.
19 Nígbà tí o bá ń kórè oko rẹ tí o sì fojú fo ìtí kan, má ṣe padà lọ mú u. Fi í kalẹ̀ fún àwọn àlejò, aláìní baba àti opó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún fún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ.
Ko na svojem polju požanješ svojo žetev in si snop pozabil na polju, ne boš ponovno šel, da ga vzameš. Ta bo za tujca, siroto in vdovo, da te Gospod, tvoj Bog, lahko blagoslovi pri vsem delu tvojih rok.
20 Nígbà tí o bá ń gun igi olifi lára àwọn igi i rẹ, má ṣe padà lọ sí ẹ̀ka náà ní ìgbà kejì. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Kadar klatiš svojo oljko, ne boš ponovno šel preko vej. To bo za tujca, siroto in vdovo.
21 Nígbà tí ìwọ bá kórè èso àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ, má ṣe lọ sí ọgbà náà mọ́. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Kadar nabiraš grozdje iz svojega vinograda, ne boš kasneje paberkoval. To bo za tujca, siroto in vdovo.
22 Rántí pé ìwọ ti jẹ́ àlejò ní Ejibiti. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Spominjal se boš, da si bil suženj v egiptovski deželi, zato ti zapovedujem, da to stvar storiš.

< Deuteronomy 24 >