< Deuteronomy 24 >

1 Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, tí ó sì gbe ní ìyàwó, yóò sì ṣe, bí obìnrin náà kò bá rí ojúrere ní ojú ọkùnrin náà, nítorí ó rí ohun àìtọ́ kan lára rẹ̀, ǹjẹ́ kí ó kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún obìnrin náà, kí ó sì fi lé e lọ́wọ́, kí ó sì ran jáde kúrò nínú ilé rẹ̀,
Кынд чинева ышь ва луа о невастэ ши се ва ынсура ку еа ши с-ар ынтымпла ка еа сэ ну май айбэ тречере ынаинтя луй, пентру кэ а дескоперит чева рушинос ын еа, сэ-й скрие о карте де деспэрцире ши, дупэ че-й ва да-о ын мынэ, сэ-й дя друмул дин каса луй.
2 tí ó bá di ìyàwó ọkùnrin mìíràn lẹ́yìn ìgbà tí ó kúrò nílé rẹ,
Еа сэ ясэ де ла ел, сэ плече ши ва путя сэ се мэрите дупэ ун алт бэрбат.
3 àti tí ọkọ rẹ̀ kejì kò bá fẹ́ràn rẹ̀ tí ó sì kọ ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ sí i, kí ó fi fún un kí ó sì lé e kúrò nílé e rẹ̀, tàbí tí ọkọ rẹ̀ kejì bá kú,
Дакэ ши ачеста дин урмэ ынчепе с-о ураскэ, ый скрие о карте де деспэрцире ши, дупэ че й-о дэ ын мынэ, ый дэ друмул дин каса луй сау дакэ ачест бэрбат дин урмэ каре а луат-о де невастэ моаре,
4 nígbà náà ni ọkọ, tí ó ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, kò gbọdọ̀ fẹ́ ẹ mọ́ lẹ́yìn tí ó ti di àìmọ́. Nítorí èyí ni ìríra níwájú Olúwa. Má ṣe mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sórí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún.
атунч бэрбатул динтый, каре ый дэдусе друмул, ну ва путя с-о я ярэшь де невастэ, дупэ че с-а пынгэрит еа, кэч лукрул ачеста есте о урычуне ынаинтя Домнулуй, ши сэ ну фачь виноватэ де пэкат цара пе каре ць-о дэ де моштенире Домнул Думнезеул тэу.
5 Bí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, o kò gbọdọ̀ ran lọ sí ogun tàbí kí ó ní iṣẹ́ kan láti ṣe. Ó ní láti ní òmìnira fún ọdún kan kí ó dúró sílé kí ó sì mú inú dídùn bá ìyàwó rẹ̀ tí ó fẹ́.
Дакэ ун ом ва фи ынсурат де курынд, сэ ну се дукэ ла оасте ши сэ ну се пунэ ничо сарчинэ песте ел; сэ фие скутит дин причина фамилией тимп де ун ан ши сэ веселяскэ астфел пе неваста пе каре шь-а луат-о.
6 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ gba ìyá ọlọ tàbí ọmọ ọlọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìdúró fún gbèsè, nítorí pé ẹ̀mí ènìyàn ni ó gbà ní pàṣípàrọ̀ n nì.
Сэ ну ей зэлог челе доуэ петре де рышницэ, нич кяр пятра де рышницэ де дясупра, кэч ар ынсемна кэ ей зэлог ынсэшь вяца куйва.
7 Bí a bá mú ọkùnrin kan tí ó jí ọ̀kan nínú arákùnrin rẹ̀ ní Israẹli gbé àti tí ó jí ọ̀kan nínú ẹrú tàbí kí ó tà á, ẹni tí ó jí ènìyàn gbé ní láti kú. Ẹ ní láti wẹ búburú kúrò láàrín yín.
Дакэ се ва гэси чинева каре сэ фи фурат пе вреунул дин фраций луй, пе вреунул дин копиий луй Исраел, ши сэ-л фи фэкут роб сау сэ-л фи вындут, хоцул ачела сэ фие педепсит ку моартя. Сэ курэцешть астфел рэул дин мижлокул тэу.
8 Ní ti ààrùn ẹ̀tẹ̀ kíyèsára láti máa ṣe gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ti pàṣẹ fún ọ. O ní láti máa fi ìṣọ́ra tẹ̀lé ohun tí mo ti pàṣẹ fún wọn.
Я сяма бине ши пэзеште-те де рана лепрей ши сэ фачець тот че вэ вор ынвэца преоций динтре левиць, сэ авець грижэ сэ лукраць дупэ порунчиле пе каре ли ле-ам дат.
9 Rántí ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe sí Miriamu lójú ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí o jáde kúrò ní Ejibiti.
Аду-ць аминте че а фэкут Домнул Думнезеул тэу Марией пе друм, ла еширя воастрэ дин Еӂипт.
10 Nígbà tí o bá wín arákùnrin rẹ ní ohunkóhun, má ṣe lọ sí ilé rẹ̀ láti gba ohun tí ó bá mú wá bí ẹ̀rí.
Дакэ ай врео даторие ла апроапеле тэу, сэ ну интри ын каса луй ка сэ-й ей лукрул пус зэлог,
11 Dúró síta gbangba kí o sì jẹ́ kí ọkùnrin tí o wín mú ògo rẹ jáde wá fún ọ.
чи сэ стай афарэ, ши чел пе каре л-ай ымпрумутат сэ-ць адукэ афарэ лукрул пус зэлог.
12 Bí ọkùnrin náà bá jẹ́ tálákà má ṣe lọ sùn ti ìwọ ti ògo rẹ.
Дакэ омул ачела есте сэрак, сэ ну те кулчь ку лукрул луат зэлог де ла ел ла тине;
13 Dá aṣọ ìlekè rẹ padà ní àṣálẹ́ kí ó bá à le sùn lórí i rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, ó sì máa jásí ìwà òdodo níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
сэ и-л дай ынапой ла апусул соарелуй, ка сэ се кулче ын хайна луй ши сэ те бинекувынтезе, ши лукрул ачеста ци се ва сокоти ка ун лукру бун ынаинтя Домнулуй Думнезеулуй тэу.
14 Má ṣe ni alágbàṣe kan lára tí ó jẹ́ tálákà àti aláìní, bóyá ó jẹ́ arákùnrin Israẹli tàbí àlejò tí ó ń gbé ní ọ̀kan nínú àwọn ìlú rẹ.
Сэ ну недрептэцешть пе симбриашул сэрак ши невояш, фие кэ есте унул дин фраций тэй, фие кэ есте унул дин стрэиний каре локуеск ын цара та, ын четэциле тале.
15 San owó iṣẹ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà kí ó tó di àṣálẹ́, nítorí ó jẹ́ tálákà, ó sì gbẹ́kẹ̀lé e bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ó lè ké pe Olúwa sí ọ, o sì máa gba ìdálẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀.
Сэ-й дай плата пентру зиуа луй ынаинте де апусул соарелуй, кэч е сэрак ши о дореште мулт. Алтфел, ар стрига кэтре Домнул ымпотрива та, ши те-ай фаче виноват де ун пэкат.
16 Baba kò gbọdọ̀ kú fún àwọn ọmọ wọn tàbí kí àwọn ọmọ kú fún baba wọ́n; olúkúlùkù ní láti kú fún ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
Сэ ну оморь пе пэринць пентру копий ши сэ ну оморь пе копий пентру пэринць; фиекаре сэ фие оморыт пентру пэкатул луй.
17 Má ṣe yí ìdájọ́ po fún àlejò tàbí aláìní baba, tàbí gba aṣọ ìlekè opó bí ẹ̀rí.
Сэ ну те атинӂь де дрептул стрэинулуй ши ал орфанулуй ши сэ ну ей зэлог хайна вэдувей.
18 Rántí pé o jẹ́ ẹrú ní Ejibiti tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì gbà ọ́ níbẹ̀. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Сэ-ць адучь аминте кэ ай фост роб ын Еӂипт ши кэ Домнул Думнезеул тэу те-а рэскумпэрат де аколо, де ачея ыць дау ачесте порунчь, ка сэ ле ымплинешть.
19 Nígbà tí o bá ń kórè oko rẹ tí o sì fojú fo ìtí kan, má ṣe padà lọ mú u. Fi í kalẹ̀ fún àwọn àlejò, aláìní baba àti opó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún fún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ.
Кынд ыць вей сечера огорул ши вей уйта ун сноп пе кымп, сэ ну те ынторчь сэ-л ей – сэ фие ал стрэинулуй, ал орфанулуй ши ал вэдувей, пентру ка Домнул Думнезеул тэу сэ те бинекувынтезе ын тот лукрул мынилор тале.
20 Nígbà tí o bá ń gun igi olifi lára àwọn igi i rẹ, má ṣe padà lọ sí ẹ̀ka náà ní ìgbà kejì. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Кынд ыць вей скутура мэслиний, сэ ну кулеӂь а доуа оарэ роаделе рэмасе пе рамурь – еле сэ фие але стрэинулуй, але орфанулуй ши але вэдувей.
21 Nígbà tí ìwọ bá kórè èso àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ, má ṣe lọ sí ọgbà náà mọ́. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Кынд ыць вей кулеӂе вия, сэ ну кулеӂь а доуа оарэ чоркинеле каре рэмын пе урма та – еле сэ фие але стрэинулуй, але орфанулуй ши але вэдувей.
22 Rántí pé ìwọ ti jẹ́ àlejò ní Ejibiti. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Аду-ць аминте кэ ай фост роб ын цара Еӂиптулуй, де ачея ыць дау порунчиле ачестя, ка сэ ле ымплинешть.

< Deuteronomy 24 >