< Deuteronomy 24 >

1 Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, tí ó sì gbe ní ìyàwó, yóò sì ṣe, bí obìnrin náà kò bá rí ojúrere ní ojú ọkùnrin náà, nítorí ó rí ohun àìtọ́ kan lára rẹ̀, ǹjẹ́ kí ó kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún obìnrin náà, kí ó sì fi lé e lọ́wọ́, kí ó sì ran jáde kúrò nínú ilé rẹ̀,
Uba indoda ithatha umfazi, imgane, kuzakuthi nxa engatholi umusa emehlweni ayo, ngoba ifice kuye into elihlazo, kayimbhalele incwadi yesehlukaniso, ifake esandleni sakhe, imkhuphe endlini yayo.
2 tí ó bá di ìyàwó ọkùnrin mìíràn lẹ́yìn ìgbà tí ó kúrò nílé rẹ,
Nxa esephumile endlini yayo, angahamba, ayekuba ngowenye indoda.
3 àti tí ọkọ rẹ̀ kejì kò bá fẹ́ràn rẹ̀ tí ó sì kọ ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ sí i, kí ó fi fún un kí ó sì lé e kúrò nílé e rẹ̀, tàbí tí ọkọ rẹ̀ kejì bá kú,
Uba lindoda elandelayo imzonda, imbhalele incwadi yesehlukaniso, iyifake esandleni sakhe, imkhiphe endlini yayo; loba lindoda elandelayo isifa ebimthethe waba ngumkayo,
4 nígbà náà ni ọkọ, tí ó ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, kò gbọdọ̀ fẹ́ ẹ mọ́ lẹ́yìn tí ó ti di àìmọ́. Nítorí èyí ni ìríra níwájú Olúwa. Má ṣe mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sórí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún.
indoda yakhe yokuqala eyamkhiphayo ingemthathe futhi abe ngumkayo, emva kokuba esengcolisiwe; ngoba kuyisinengiso phambi kweNkosi. Ngakho kawuyikwenza ilizwe lone iNkosi uNkulunkulu wakho ekunika lona ukuba yilifa.
5 Bí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, o kò gbọdọ̀ ran lọ sí ogun tàbí kí ó ní iṣẹ́ kan láti ṣe. Ó ní láti ní òmìnira fún ọdún kan kí ó dúró sílé kí ó sì mú inú dídùn bá ìyàwó rẹ̀ tí ó fẹ́.
Nxa indoda ithethe umfazi omutsha kayiyikuphuma impi, futhi kayiyikuphathiswa laloba yiwuphi umsebenzi; izakuba sekhaya ikhululekile umnyaka owodwa ukuze ithokozise umkayo emthetheyo.
6 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ gba ìyá ọlọ tàbí ọmọ ọlọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìdúró fún gbèsè, nítorí pé ẹ̀mí ènìyàn ni ó gbà ní pàṣípàrọ̀ n nì.
Kakungabi khona ozathatha ilitshe lokucholela loba imbokodo ukuze kube yisibambiso; ngoba uthatha impilo ibe yisibambiso.
7 Bí a bá mú ọkùnrin kan tí ó jí ọ̀kan nínú arákùnrin rẹ̀ ní Israẹli gbé àti tí ó jí ọ̀kan nínú ẹrú tàbí kí ó tà á, ẹni tí ó jí ènìyàn gbé ní láti kú. Ẹ ní láti wẹ búburú kúrò láàrín yín.
Uba umuntu eficwa eseba umuntu kubafowabo ebantwaneni bakoIsrayeli, amphathe njengesigqili kumbe amthengise, lelosela lizakufa. Ngalokhu uzakhupha ububi phakathi kwakho.
8 Ní ti ààrùn ẹ̀tẹ̀ kíyèsára láti máa ṣe gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ti pàṣẹ fún ọ. O ní láti máa fi ìṣọ́ra tẹ̀lé ohun tí mo ti pàṣẹ fún wọn.
Qaphela esifeni sobulephero, ukunanzelelisisa wenze njengakho konke abapristi abangamaLevi abakufundisa khona; njengalokhu ngabalaya, nanzelelani ukukwenza.
9 Rántí ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe sí Miriamu lójú ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí o jáde kúrò ní Ejibiti.
Khumbula lokho iNkosi uNkulunkulu wakho eyakwenza kuMiriyamu endleleni ekuphumeni kwenu eGibhithe.
10 Nígbà tí o bá wín arákùnrin rẹ ní ohunkóhun, má ṣe lọ sí ilé rẹ̀ láti gba ohun tí ó bá mú wá bí ẹ̀rí.
Nxa useboleka umakhelwane wakho ulutho, ungangeni endlini yakhe ukuthi uthathe isibambiso sakhe.
11 Dúró síta gbangba kí o sì jẹ́ kí ọkùnrin tí o wín mú ògo rẹ jáde wá fún ọ.
Uzakuma phandle, lomuntu omebolekayo akukhuphele isibambiso phandle.
12 Bí ọkùnrin náà bá jẹ́ tálákà má ṣe lọ sùn ti ìwọ ti ògo rẹ.
Njalo uba umuntu engumyanga, ungalali lesibambiso sakhe;
13 Dá aṣọ ìlekè rẹ padà ní àṣálẹ́ kí ó bá à le sùn lórí i rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, ó sì máa jásí ìwà òdodo níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
uzabuyisela lokubuyisela isibambiso kuye lapho ilanga litshona, ukuze alale ngesembatho sakhe, akubusise; lalokho kuzakuba yikulunga kuwe phambi kweNkosi uNkulunkulu wakho.
14 Má ṣe ni alágbàṣe kan lára tí ó jẹ́ tálákà àti aláìní, bóyá ó jẹ́ arákùnrin Israẹli tàbí àlejò tí ó ń gbé ní ọ̀kan nínú àwọn ìlú rẹ.
Ungacindezeli inceku eqhatshiweyo engumyanga leswelayo, ingowabafowenu loba ingowezizweni oselizweni lakini phakathi kwamasango akho.
15 San owó iṣẹ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà kí ó tó di àṣálẹ́, nítorí ó jẹ́ tálákà, ó sì gbẹ́kẹ̀lé e bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ó lè ké pe Olúwa sí ọ, o sì máa gba ìdálẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀.
Uzanika iholo layo ngosuku lwayo, lelanga kalingatshoni phezu kwalo, ngoba ingumyanga, ibeke inhliziyo yayo kulo; ukuze ingakhali eNkosini ngawe, njalo kube yisono kuwe.
16 Baba kò gbọdọ̀ kú fún àwọn ọmọ wọn tàbí kí àwọn ọmọ kú fún baba wọ́n; olúkúlùkù ní láti kú fún ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
Oyise kabayikubulawa ngenxa yabantwana, labantwana kabayikubulawa ngenxa yaboyise; ngulowo lalowo uzabulawa ngenxa yesakhe isono.
17 Má ṣe yí ìdájọ́ po fún àlejò tàbí aláìní baba, tàbí gba aṣọ ìlekè opó bí ẹ̀rí.
Ungaphambuli isahlulelo sowemzini lentandane; ungathathi isembatho somfelokazi sibe yisibambiso;
18 Rántí pé o jẹ́ ẹrú ní Ejibiti tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì gbà ọ́ níbẹ̀. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
kodwa ukhumbule ukuthi wawuyisigqili eGibhithe, leNkosi uNkulunkulu wakho yakuhlenga khona; ngakho ngiyakulaya ukuthi wenze lolulutho.
19 Nígbà tí o bá ń kórè oko rẹ tí o sì fojú fo ìtí kan, má ṣe padà lọ mú u. Fi í kalẹ̀ fún àwọn àlejò, aláìní baba àti opó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún fún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ.
Nxa uvuna isivuno sakho ensimini yakho, ukhohlwe isithungo ensimini, ungabuyeli ukusithatha; sizakuba ngesowemzini, esentandane lesomfelokazi; ukuze iNkosi uNkulunkulu wakho ikubusise emsebenzini wonke wezandla zakho.
20 Nígbà tí o bá ń gun igi olifi lára àwọn igi i rẹ, má ṣe padà lọ sí ẹ̀ka náà ní ìgbà kejì. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Nxa uvuthuza isihlahla sakho somhlwathi, ungayihlola izingatsha emva kwakho; kuzakuba ngokowemzini lokwentandane lokomfelokazi.
21 Nígbà tí ìwọ bá kórè èso àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ, má ṣe lọ sí ọgbà náà mọ́. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Nxa usuvunile izithelo zesivini sakho, ungakhothozi emva kwakho; kuzakuba ngokowemzini lokwentandane lokomfelokazi.
22 Rántí pé ìwọ ti jẹ́ àlejò ní Ejibiti. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Uzakhumbula ukuthi wawuyisigqili elizweni leGibhithe; ngakho ngiyakulaya ukwenza lolulutho.

< Deuteronomy 24 >