< Deuteronomy 24 >
1 Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, tí ó sì gbe ní ìyàwó, yóò sì ṣe, bí obìnrin náà kò bá rí ojúrere ní ojú ọkùnrin náà, nítorí ó rí ohun àìtọ́ kan lára rẹ̀, ǹjẹ́ kí ó kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún obìnrin náà, kí ó sì fi lé e lọ́wọ́, kí ó sì ran jáde kúrò nínú ilé rẹ̀,
Ha valaki feleséget vesz magának és férjévé lesz, akkor lesz, ha nem talál az kegyet szemeiben, mert talált rajta valami szemérmetlen dolgot és ír neki válólevelet, kezébe adja és elküldi házából –
2 tí ó bá di ìyàwó ọkùnrin mìíràn lẹ́yìn ìgbà tí ó kúrò nílé rẹ,
az elmegy házából és megy és más férfiúé lesz,
3 àti tí ọkọ rẹ̀ kejì kò bá fẹ́ràn rẹ̀ tí ó sì kọ ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ sí i, kí ó fi fún un kí ó sì lé e kúrò nílé e rẹ̀, tàbí tí ọkọ rẹ̀ kejì bá kú,
de meggyűlöli őt az utóbbi férfi és ír neki válólevelet, kezébe adja és elküldi házából vagy ha meghal az utóbbi férfi, aki elvette feleségül:
4 nígbà náà ni ọkọ, tí ó ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, kò gbọdọ̀ fẹ́ ẹ mọ́ lẹ́yìn tí ó ti di àìmọ́. Nítorí èyí ni ìríra níwájú Olúwa. Má ṣe mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sórí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún.
nem szabad az első férjének, aki elküldte, visszavennie, hogy felesége legyen neki, miután megfertőztetett, mert utálat az az Örökkévaló színe előtt; és ne vidd vétekre az országot, melyet az Örökkévaló, a te Istened ad neked örökségül.
5 Bí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, o kò gbọdọ̀ ran lọ sí ogun tàbí kí ó ní iṣẹ́ kan láti ṣe. Ó ní láti ní òmìnira fún ọdún kan kí ó dúró sílé kí ó sì mú inú dídùn bá ìyàwó rẹ̀ tí ó fẹ́.
Ha valaki vesz új feleséget, ne vonuljon ki a sereggel és ne jusson rá semmi teher; szabad legyen háza számára egy évig, hogy örvendeztesse feleségét, akit elvett.
6 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ gba ìyá ọlọ tàbí ọmọ ọlọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìdúró fún gbèsè, nítorí pé ẹ̀mí ènìyàn ni ó gbà ní pàṣípàrọ̀ n nì.
Ne vegyen senki zálogul malmot és felső malomkövet, mert életet venne zálogba.
7 Bí a bá mú ọkùnrin kan tí ó jí ọ̀kan nínú arákùnrin rẹ̀ ní Israẹli gbé àti tí ó jí ọ̀kan nínú ẹrú tàbí kí ó tà á, ẹni tí ó jí ènìyàn gbé ní láti kú. Ẹ ní láti wẹ búburú kúrò láàrín yín.
Ha rajtaérnek valakit, aki embert lop testvérei közül, Izrael fiai közül, hatalmaskodik fölötte és eladja őt, akkor haljon meg az a tolvaj, Így irtsd ki a gonoszt közepedből.
8 Ní ti ààrùn ẹ̀tẹ̀ kíyèsára láti máa ṣe gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ti pàṣẹ fún ọ. O ní láti máa fi ìṣọ́ra tẹ̀lé ohun tí mo ti pàṣẹ fún wọn.
Őrizkedjél a poklosság sérelménél, hogy őrizkedjél nagyon és cselekedjél mind aszerint, amint tanítanak benneteket a levita papok, amint parancsoltam nekik, úgy őrizzétek meg, hogy megtegyétek.
9 Rántí ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe sí Miriamu lójú ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí o jáde kúrò ní Ejibiti.
Emlékezzél meg arról, amit tett az Örökkévaló, a te Istened Mirjámmal az úton, mikor kivonultatok Egyiptomból.
10 Nígbà tí o bá wín arákùnrin rẹ ní ohunkóhun, má ṣe lọ sí ilé rẹ̀ láti gba ohun tí ó bá mú wá bí ẹ̀rí.
Ha kölcsönzöl felebarátodnak bármely kölcsönt, ne menj be házába, hogy elvedd zálogát,
11 Dúró síta gbangba kí o sì jẹ́ kí ọkùnrin tí o wín mú ògo rẹ jáde wá fún ọ.
kinn állj meg és az az ember, akinek kölcsönöztél, hozza ki neked a zálogot az utcára.
12 Bí ọkùnrin náà bá jẹ́ tálákà má ṣe lọ sùn ti ìwọ ti ògo rẹ.
Ha pedig szegény ember az, ne feküdjél le zálogával;
13 Dá aṣọ ìlekè rẹ padà ní àṣálẹ́ kí ó bá à le sùn lórí i rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, ó sì máa jásí ìwà òdodo níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
add vissza neki a zálogot, mikor lemegy a nap, hogy lefeküdhessék az ő ruhájában és áldjon téged; neked pedig igazságul lesz az az Örökkévaló a te Istened színe előtt.
14 Má ṣe ni alágbàṣe kan lára tí ó jẹ́ tálákà àti aláìní, bóyá ó jẹ́ arákùnrin Israẹli tàbí àlejò tí ó ń gbé ní ọ̀kan nínú àwọn ìlú rẹ.
Ne nyomorgasd a bérmunkást, a szegényt és szűkölködőt testvéreid közül vagy idegened közül, aki országodban, kapuidban van.
15 San owó iṣẹ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà kí ó tó di àṣálẹ́, nítorí ó jẹ́ tálákà, ó sì gbẹ́kẹ̀lé e bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ó lè ké pe Olúwa sí ọ, o sì máa gba ìdálẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀.
Aznap add meg bérét és ne menjen le fölötte a nap, mert szegény ő és azután vágyódik lelke, hogy ne kiáltson ellened az Örökkévalóhoz és vétek legyen rajtad.
16 Baba kò gbọdọ̀ kú fún àwọn ọmọ wọn tàbí kí àwọn ọmọ kú fún baba wọ́n; olúkúlùkù ní láti kú fún ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
Ne ölessenek meg atyák a gyermekek miatt és gyermekek ne ölessenek meg az atyák miatt; mindenki a maga vétkéért ölessék meg.
17 Má ṣe yí ìdájọ́ po fún àlejò tàbí aláìní baba, tàbí gba aṣọ ìlekè opó bí ẹ̀rí.
Ne hajlítsd el az idegennek és az árvának a jogát, és ne vedd el zálogba az özvegy ruháját.
18 Rántí pé o jẹ́ ẹrú ní Ejibiti tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì gbà ọ́ níbẹ̀. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Emlékezzél meg arról, hogy rabszolga voltál Egyiptomban és megváltott téged az Örökkévaló, a te Istened onnan; azért parancsolom neked, hogy tedd ezt a dolgot.
19 Nígbà tí o bá ń kórè oko rẹ tí o sì fojú fo ìtí kan, má ṣe padà lọ mú u. Fi í kalẹ̀ fún àwọn àlejò, aláìní baba àti opó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún fún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ.
Mikor learatod aratni valódat meződön, és elfelejtesz kévét a mezőn, ne térj vissza, hogy azt elvedd; az idegené, az árváé és az özvegyé legyen, hogy megáldjon téged az Örökkévaló, a te Istened kezed minden munkájában.
20 Nígbà tí o bá ń gun igi olifi lára àwọn igi i rẹ, má ṣe padà lọ sí ẹ̀ka náà ní ìgbà kejì. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Mikor lerázod olajfádat, ne szedd le (a bogyókat) magad után; az idegené, az árváé és az özvegyé legyen.
21 Nígbà tí ìwọ bá kórè èso àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ, má ṣe lọ sí ọgbà náà mọ́. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Ha leszüreteled szőlődet, ne böngéssz magad után; az idegené, az árváé és az özvegyé legyen.
22 Rántí pé ìwọ ti jẹ́ àlejò ní Ejibiti. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Emlékezzél meg arról, hogy rabszolga voltál Egyiptom országában, azért parancsolom meg neked, hogy tedd ezt a dolgot.