< Deuteronomy 24 >

1 Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, tí ó sì gbe ní ìyàwó, yóò sì ṣe, bí obìnrin náà kò bá rí ojúrere ní ojú ọkùnrin náà, nítorí ó rí ohun àìtọ́ kan lára rẹ̀, ǹjẹ́ kí ó kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún obìnrin náà, kí ó sì fi lé e lọ́wọ́, kí ó sì ran jáde kúrò nínú ilé rẹ̀,
If a man takith a wijf, and hath hir, and sche fyndith not grace bifor hise iyen for sum vilite, he schal write a `libel, ethir litil book, of forsakyng, and he schal yyue in `the hond of hir, and he schal delyuere hir fro his hows.
2 tí ó bá di ìyàwó ọkùnrin mìíràn lẹ́yìn ìgbà tí ó kúrò nílé rẹ,
And whanne sche goith out, and weddith anothir hosebonde,
3 àti tí ọkọ rẹ̀ kejì kò bá fẹ́ràn rẹ̀ tí ó sì kọ ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ sí i, kí ó fi fún un kí ó sì lé e kúrò nílé e rẹ̀, tàbí tí ọkọ rẹ̀ kejì bá kú,
and he also hatith hir, and yyueth to hir a `litil booke of forsakyng, and delyuereth hir fro his hows, ethir certis he is deed,
4 nígbà náà ni ọkọ, tí ó ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, kò gbọdọ̀ fẹ́ ẹ mọ́ lẹ́yìn tí ó ti di àìmọ́. Nítorí èyí ni ìríra níwájú Olúwa. Má ṣe mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sórí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún.
the formere hosebonde schal not mow resseyue hir in to wijf, for sche is defoulid, and maad abhomynable bifore the Lord; lest thou make thi lond to do synne, which lond thi Lord God yaf to thee to welde.
5 Bí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, o kò gbọdọ̀ ran lọ sí ogun tàbí kí ó ní iṣẹ́ kan láti ṣe. Ó ní láti ní òmìnira fún ọdún kan kí ó dúró sílé kí ó sì mú inú dídùn bá ìyàwó rẹ̀ tí ó fẹ́.
Whanne a man hath take late a wijf, he schal not go forth to batel, nethir ony thing of comyn nede schal be enioyned to hym, but he schal yyue tent with out blame to his hows, that he be glad in o yeer with his wijf.
6 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ gba ìyá ọlọ tàbí ọmọ ọlọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìdúró fún gbèsè, nítorí pé ẹ̀mí ènìyàn ni ó gbà ní pàṣípàrọ̀ n nì.
Thou schalt not take in the stide of wed the lowere and the hiyere queerne stoon of thi brothir, for he puttide his lijf to thee.
7 Bí a bá mú ọkùnrin kan tí ó jí ọ̀kan nínú arákùnrin rẹ̀ ní Israẹli gbé àti tí ó jí ọ̀kan nínú ẹrú tàbí kí ó tà á, ẹni tí ó jí ènìyàn gbé ní láti kú. Ẹ ní láti wẹ búburú kúrò láàrín yín.
If a man is takun, `that is, conuyct in doom, bisili aspiynge to stele his brothir of the sones of Israel, and whanne he hath seeld hym, takith priys, he schal be slayn; and thou schalt do awey yuel fro the myddis of thee.
8 Ní ti ààrùn ẹ̀tẹ̀ kíyèsára láti máa ṣe gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ti pàṣẹ fún ọ. O ní láti máa fi ìṣọ́ra tẹ̀lé ohun tí mo ti pàṣẹ fún wọn.
Kepe thou diligentli, lest thou renne in to the sijknesse of lepre, but thou schalt do what euer thingis the preestis of the kyn of Leuy techen thee, bi that that Y comaundide to hem, and `fille thou diligentli.
9 Rántí ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe sí Miriamu lójú ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí o jáde kúrò ní Ejibiti.
Haue ye mynde what thingis youre Lord God dide to Marie, in the weie, whanne ye yede `out of Egipt.
10 Nígbà tí o bá wín arákùnrin rẹ ní ohunkóhun, má ṣe lọ sí ilé rẹ̀ láti gba ohun tí ó bá mú wá bí ẹ̀rí.
Whanne thou schalt axe of thi neiyebore ony thing which he owith to thee, thou schalt not entre in to his hows, that thou take awei a wed;
11 Dúró síta gbangba kí o sì jẹ́ kí ọkùnrin tí o wín mú ògo rẹ jáde wá fún ọ.
but thou schalt stonde with out forth, and he schal brynge forth that that he hath.
12 Bí ọkùnrin náà bá jẹ́ tálákà má ṣe lọ sùn ti ìwọ ti ògo rẹ.
Sotheli if he is pore, the wed schal not dwelle bi nyyt at thee,
13 Dá aṣọ ìlekè rẹ padà ní àṣálẹ́ kí ó bá à le sùn lórí i rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, ó sì máa jásí ìwà òdodo níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
but anoon thou schalt yelde to hym bifor the goyng doun of the sunne, that he slepe in his cloth, and blesse thee, and thou haue riytfulnesse bifor thi Lord God.
14 Má ṣe ni alágbàṣe kan lára tí ó jẹ́ tálákà àti aláìní, bóyá ó jẹ́ arákùnrin Israẹli tàbí àlejò tí ó ń gbé ní ọ̀kan nínú àwọn ìlú rẹ.
Thou schalt not denye the hire of thi brother nedi and pore, ethir of the comelyng that dwellith with thee in thi lond, and is with ynne thi yatis;
15 San owó iṣẹ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà kí ó tó di àṣálẹ́, nítorí ó jẹ́ tálákà, ó sì gbẹ́kẹ̀lé e bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ó lè ké pe Olúwa sí ọ, o sì máa gba ìdálẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀.
but in the same dai thou schalt yelde to hym the prijs of his trauel, bifor the goyng doun of the sunne, for he is pore, and susteyneth therof his lijf; lest he crye ayens thee to the Lord, and it be arettid to thee into synne.
16 Baba kò gbọdọ̀ kú fún àwọn ọmọ wọn tàbí kí àwọn ọmọ kú fún baba wọ́n; olúkúlùkù ní láti kú fún ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
The fadris schulen not be slayn for the sones, nether the sones for the fadris, but ech man schal die for hys owne synne.
17 Má ṣe yí ìdájọ́ po fún àlejò tàbí aláìní baba, tàbí gba aṣọ ìlekè opó bí ẹ̀rí.
Thou schalt not `peruerte, ethir waiwardli turne, the doom of the comelyng, and of fadirles ethir modirles; nethir thou schalt take awei in the stide of wed the cloth of a widewe.
18 Rántí pé o jẹ́ ẹrú ní Ejibiti tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì gbà ọ́ níbẹ̀. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Haue thou mynde, that thou seruedist in Egipt, and thi Lord God delyuerede thee fro thennus; therfor Y comaunde to thee that thou do this thing.
19 Nígbà tí o bá ń kórè oko rẹ tí o sì fojú fo ìtí kan, má ṣe padà lọ mú u. Fi í kalẹ̀ fún àwọn àlejò, aláìní baba àti opó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún fún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ.
Whanne thou repist corn in the feeld, and foryetist, and leeuest a repe, thou schalt not turne ayen to take it, but thou schalt suffre that a comelyng, and fadirles, ethir modirles, and a widewe take awei, that thi Lord God blesse thee in al the werk of thin hondis.
20 Nígbà tí o bá ń gun igi olifi lára àwọn igi i rẹ, má ṣe padà lọ sí ẹ̀ka náà ní ìgbà kejì. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
If thou gaderist fruytis of olyues, what euer thing leeueth in trees, thou schalt not turne ayen to gadere, but thou schalt leeue to a comelyng, fadirles, ether modirles, and to a widewe.
21 Nígbà tí ìwọ bá kórè èso àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ, má ṣe lọ sí ọgbà náà mọ́. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
If thou gaderist grapis of the vyner, thou schalt not gadere raisyns that leeuen, but tho schulen falle in to the vsis of the comelyng, of the fadirles, ethir modirles, and of the wydewe.
22 Rántí pé ìwọ ti jẹ́ àlejò ní Ejibiti. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Haue thou mynde that also thou seruedist in Egipt, and therfor Y comaunde to thee, that thou do this thing.

< Deuteronomy 24 >