< Deuteronomy 24 >
1 Bí ọkùnrin kan bá fẹ́ obìnrin kan, tí ó sì gbe ní ìyàwó, yóò sì ṣe, bí obìnrin náà kò bá rí ojúrere ní ojú ọkùnrin náà, nítorí ó rí ohun àìtọ́ kan lára rẹ̀, ǹjẹ́ kí ó kọ ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún obìnrin náà, kí ó sì fi lé e lọ́wọ́, kí ó sì ran jáde kúrò nínú ilé rẹ̀,
Naar en Mand tager en Hustru og ægter hende, og hun ikke finder Naade for hans Øjne, fordi han fandt ublu Handel hos hende, og han da skriver hende et Skilsmissebrev og giver det i hendes Haand og lader hende fare bort fra sit Hus,
2 tí ó bá di ìyàwó ọkùnrin mìíràn lẹ́yìn ìgbà tí ó kúrò nílé rẹ,
og hun da gaar ud af hans Hus og gaar bort og bliver en anden Mands,
3 àti tí ọkọ rẹ̀ kejì kò bá fẹ́ràn rẹ̀ tí ó sì kọ ìwé-ẹ̀rí ìkọ̀sílẹ̀ sí i, kí ó fi fún un kí ó sì lé e kúrò nílé e rẹ̀, tàbí tí ọkọ rẹ̀ kejì bá kú,
og den samme anden Mand faar Had til hende og skriver hende et Skilsmissebrev og giver i hendes Haand og lader hende fare bort fra sit Hus; eller om den anden Mand dør, som tog hende til Hustru:
4 nígbà náà ni ọkọ, tí ó ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, kò gbọdọ̀ fẹ́ ẹ mọ́ lẹ́yìn tí ó ti di àìmọ́. Nítorí èyí ni ìríra níwájú Olúwa. Má ṣe mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sórí ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ bí ogún.
Da maa ikke hendes første Mand, som lod hende fare, atter tage hende til sin Hustru, siden hun er bleven uren, thi det er en Vederstyggelighed for Herrens Ansigt; og du skal ikke gøre det Land syndigt, som Herren din Gud giver dig til Arv.
5 Bí ọkùnrin kan bá ṣẹ̀ṣẹ̀ gbéyàwó, o kò gbọdọ̀ ran lọ sí ogun tàbí kí ó ní iṣẹ́ kan láti ṣe. Ó ní láti ní òmìnira fún ọdún kan kí ó dúró sílé kí ó sì mú inú dídùn bá ìyàwó rẹ̀ tí ó fẹ́.
Naar en Mand nylig har taget en Hustru, skal han ikke drage ud i Striden, og man skal ingen Tynge lægge paa ham; han skal være fri i sit Hus eet Aar og være glad med sin Hustru, som han har taget.
6 Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ gba ìyá ọlọ tàbí ọmọ ọlọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìdúró fún gbèsè, nítorí pé ẹ̀mí ènìyàn ni ó gbà ní pàṣípàrọ̀ n nì.
Man skal ikke tage begge Møllestene eller den øverste Møllesten til Pant; thi saa tager man Livet til Pant.
7 Bí a bá mú ọkùnrin kan tí ó jí ọ̀kan nínú arákùnrin rẹ̀ ní Israẹli gbé àti tí ó jí ọ̀kan nínú ẹrú tàbí kí ó tà á, ẹni tí ó jí ènìyàn gbé ní láti kú. Ẹ ní láti wẹ búburú kúrò láàrín yín.
Om nogen findes, som stjæler en Person af sine Brødre af Israels Børn og driver Handel med ham eller sælger ham, da skal samme Tyv dø, og du skal borttage den onde fra dig.
8 Ní ti ààrùn ẹ̀tẹ̀ kíyèsára láti máa ṣe gẹ́gẹ́ bí àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi ti pàṣẹ fún ọ. O ní láti máa fi ìṣọ́ra tẹ̀lé ohun tí mo ti pàṣẹ fún wọn.
Tag dig i Vare for Spedalskheds Plage, saa at du tager vel Vare paa og gør efter alt det, som Præsterne, Leviterne skulle lære eder; eftersom jeg har budet dem, skulle I tage Vare paa at gøre.
9 Rántí ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ṣe sí Miriamu lójú ọ̀nà lẹ́yìn ìgbà tí o jáde kúrò ní Ejibiti.
Kom i Hu, hvad Herren, din Gud gjorde ved Maria paa Vejen, der I droge ud af Ægypten.
10 Nígbà tí o bá wín arákùnrin rẹ ní ohunkóhun, má ṣe lọ sí ilé rẹ̀ láti gba ohun tí ó bá mú wá bí ẹ̀rí.
Dersom du udlaaner til din Næste noget Laan, da skal du ikke gaa ind i hans Hus og tage hans Pant.
11 Dúró síta gbangba kí o sì jẹ́ kí ọkùnrin tí o wín mú ògo rẹ jáde wá fún ọ.
Du skal staa udenfor, og den Mand, hvem du har laant noget, skal bære Pantet ud til dig udenfor.
12 Bí ọkùnrin náà bá jẹ́ tálákà má ṣe lọ sùn ti ìwọ ti ògo rẹ.
Men dersom han er en nødlidende Mand, da skal du ikke lægge dig til Hvile med hans Pant.
13 Dá aṣọ ìlekè rẹ padà ní àṣálẹ́ kí ó bá à le sùn lórí i rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, ó sì máa jásí ìwà òdodo níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Men du skal give ham Pantet tilbage, naar Solen gaar ned, at han kan lægge sig i sit Klædebon og velsigne dig; og det skal være dig en Retfærdighed for Herren din Guds Ansigt.
14 Má ṣe ni alágbàṣe kan lára tí ó jẹ́ tálákà àti aláìní, bóyá ó jẹ́ arákùnrin Israẹli tàbí àlejò tí ó ń gbé ní ọ̀kan nínú àwọn ìlú rẹ.
Du skal ikke gøre en nødlidende og en fattig Daglønner Uret, være sig af dine Brødre eller af dine fremmede, som ere i dit Land inden dine Porte.
15 San owó iṣẹ́ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà kí ó tó di àṣálẹ́, nítorí ó jẹ́ tálákà, ó sì gbẹ́kẹ̀lé e bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ ó lè ké pe Olúwa sí ọ, o sì máa gba ìdálẹ́bi ẹ̀ṣẹ̀.
Du skal give ham hans Løn paa hans Dag, og Solen skal ikke gaa ned derover; thi han er nødlidende, og til den sætter han sin Hu; at han ikke skal raabe over dig til Herren, og det skal være dig til Synd.
16 Baba kò gbọdọ̀ kú fún àwọn ọmọ wọn tàbí kí àwọn ọmọ kú fún baba wọ́n; olúkúlùkù ní láti kú fún ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀.
Forældre skulle ikke dødes for Børn, og Børn skulle ikke dødes for Forældrene; de skulle dødes hver for sin Synd.
17 Má ṣe yí ìdájọ́ po fún àlejò tàbí aláìní baba, tàbí gba aṣọ ìlekè opó bí ẹ̀rí.
Du skal ikke bøje Retten for den fremmede, den faderløse, og ej tage en Enkes Klædebon til Pant.
18 Rántí pé o jẹ́ ẹrú ní Ejibiti tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì gbà ọ́ níbẹ̀. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Og du skal komme i Hu, at du var en Træl i Ægypten, og Herren din Gud udløste dig derfra; derfor byder jeg dig at gøre denne Gerning.
19 Nígbà tí o bá ń kórè oko rẹ tí o sì fojú fo ìtí kan, má ṣe padà lọ mú u. Fi í kalẹ̀ fún àwọn àlejò, aláìní baba àti opó, kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún fún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ.
Naar du høster din Høst paa din Ager og har glemt et Neg paa Ageren, da skal du ikke vende tilbage at tage det; det skal høre den fremmede, den faderløse og Enken til, paa det at Herren din Gud maa velsigne dig i al dine Hænders Gerning.
20 Nígbà tí o bá ń gun igi olifi lára àwọn igi i rẹ, má ṣe padà lọ sí ẹ̀ka náà ní ìgbà kejì. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Naar du ryster dit Olietræ, da skal du ikke siden efter gennemsøge Grenene; det skal høre den fremmede, den faderløse og Enken til.
21 Nígbà tí ìwọ bá kórè èso àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ, má ṣe lọ sí ọgbà náà mọ́. Fi èyí tí ó kù fún àlejò, aláìní baba àti opó.
Naar du plukker din Vingaard, da skal du ikke siden eftersanke; det skal høre den fremmede, den faderløse og Enken til.
22 Rántí pé ìwọ ti jẹ́ àlejò ní Ejibiti. Ìdí nìyí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ṣe èyí.
Og du skal komme i Hu, at du var en Træl i Ægyptens Land, derfor byder jeg dig at gøre denne Gerning.