< Deuteronomy 23 >

1 Kí ẹnikẹ́ni tí a fọ́ ní kóró ẹpọ̀n nípa rírùn tàbí gígé má ṣe wọ inú ìjọ Olúwa wá.
Nie wnijdzie wypukły, ani trzebieniec do zgromadzenia Pańskiego.
2 Kí ọmọ àlè má ṣe wọ ìpéjọ Olúwa, pàápàá títí dé ìran kẹwàá.
Ani wnijdzie niepoczciwego łoża syn do zgromadzenia Pańskiego, i dziesiąte pokolenie jego nie wnijdzie do zgromadzenia Pańskiego.
3 Kí ọmọ Ammoni tàbí ọmọ Moabu, kì yóò wọ ìjọ Olúwa, àní títí dé ìran kẹwàá, ènìyàn wọn kan kì yóò wọ inú ìjọ ènìyàn Olúwa láéláé.
Nie wnijdzie też Ammonita, i Moabczyk do zgromadzenia Pańskiego, ani dziesiąte pokolenie ich nie wnijdzie do zgromadzenia Pańskiego, aż na wieki;
4 Nítorí wọn kò fi àkàrà àti omi pàdé e yín lójú ọ̀nà nígbà tí ò ń bọ̀ láti Ejibiti àti nítorí wọ́n gba ẹ̀yà iṣẹ́ láti fi ọ́ gégùn ún Balaamu ọmọ Beori ará a Petori ti Aramu-Naharaimu.
Dla tego, że wam nie zabieżeli z chlebem, ani z wodą w drodze, gdyście szli z Egiptu, a że najęli za zapłatę przeciw tobie Balaama, syna Beorowego, z Pethor Mesopotamii Syryjskiej, aby cię przeklinał.
5 Síbẹ̀síbẹ̀, Olúwa Ọlọ́run rẹ kò ní fetí sí Balaamu ṣùgbọ́n ó yí ègún sí ìbùkún fún ọ, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ fẹ́ràn rẹ.
Acz nie chciał Pan, Bóg twój, wysłuchać Balaama, ale obrócił Pan, Bóg twój, tobie jego przeklęstwo w błogosławieństwo; bo cię umiłował Pan, Bóg twój.
6 Ìwọ kò gbọdọ̀ wá àlàáfíà, tàbí ire wọn níwọ̀n ìgbà tí o sì wà láààyè.
Nie szukaj pokoju ich, ani dobrego ich, po wszystkie dni twoje na wieki.
7 Ìwọ kò gbọdọ̀ kórìíra ará Edomu kan nítorí arákùnrin rẹ ni. Ìwọ kò gbọdọ̀ kórìíra ará Ejibiti, nítorí o gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì ní ilẹ̀ rẹ̀.
Nie będziesz się brzydził Idumejczykiem, bo bratem twoim jest; nie będziesz się brzydził Egipczykiem, boś był przychodniem w ziemi jego.
8 Ìran kẹta àwọn ọmọ tí a bí fún wọn lè wọ ìpéjọ Olúwa.
Synowie, którzy się im zrodzą w trzeciem pokoleniu, wnijdą do zgromadzenia Pańskiego.
9 Nígbà tí o bá dó ti àwọn ọ̀tá rẹ, pa gbogbo ohun àìmọ́ kúrò.
Gdy się ruszysz z wojskiem naprzeciwko nieprzyjaciołom twoim, strzeż się od wszelkiej złej rzeczy.
10 Bí ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin rẹ bá jẹ́ aláìmọ́ nítorí ìtújáde tí ó ní, o ní láti jáde kúrò nínú àgọ́, kí o má ṣe wọ inú àgọ́.
Jeźliby był między wami kto, coby był nieczystym z przygody nocnej, wynijdzie za obóz, a nie wróci się do niego.
11 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá di ìrọ̀lẹ́ o ní láti wẹ ara rẹ, àti ní àṣálẹ́ kí o padà sínú àgọ́.
A ku wieczorowi omyje się wodą, a po zajściu słońca wnijdzie do obozu.
12 Sàmì sí ibìkan lóde àgọ́, níbi tí o lè máa lọ láti dẹ ara rẹ lára.
Będziecie też mieli miejsce za obozem, gdzie będziecie wychodzili na potrzebę przyrodzoną;
13 Kí ìwọ kí ó sì mú ìwalẹ̀ kan pẹ̀lú ohun ìjà rẹ; yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ yóò bá gbọnṣẹ̀ lẹ́yìn ibùdó, kí ìwọ kí ó mú ìwalẹ̀, kí ìwọ kí ó sì yípadà, kí o sì bo ohun tí ó jáde láara rẹ.
I będziesz miał rydlik między naczyniem swojem; a gdybyś chciał usiąść dla potrzeby, wykopiesz nim dołek, a obróciwszy się, zagrzebiesz plugastwo twoje.
14 Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń rìn láàrín àgọ́ láti dáàbò bò ọ́ àti láti fi àwọn ọ̀tá à rẹ lé ọ lọ́wọ́. Àgọ́ rẹ ní láti jẹ́ mímọ́, nítorí kí ó má ba à rí ohun àìtọ́ láàrín yín kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ yín.
Albowiem Pan, Bóg twój, chodzi w pośrodku obozu twego, aby cię wyrwał, i podał ci nieprzyjacioły twoje; przetoż niech będzie obóz twój święty, aby nie widział przy tobie sprosności jakiej, dla której by się odwrócił od ciebie.
15 Bí ẹrú kan bá ti gba ààbò lọ́dọ̀ rẹ, má ṣe fi lé ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
Nie wydasz sługi panu jego, któryby się uciekł do ciebie od pana swego.
16 Jẹ́ kí ó máa gbé láàrín rẹ níbikíbi tí ó bá fẹ́ àti èyíkéyìí ìlú tí ó bá mú. Má ṣe ni í lára.
Z tobą będzie mieszkał w pośrodku ciebie, na miejscu, które sobie obierze w jednem z miast twoich, gdzieby mu się podobało; nie uczynisz mu gwałtu.
17 Kí ọkùnrin tàbí obìnrin Israẹli má ṣe padà di alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
Nie będzie nierządnica z córek Izraelskich, ani będzie nierządnik z synów Izraelskich.
18 Ìwọ kò gbọdọ̀ mú owó iṣẹ́ panṣágà obìnrin tàbí ọkùnrin wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ láti fi san ẹ̀jẹ́ kankan; nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ kórìíra àwọn méjèèjì.
Nie wnoś zapłaty nierządnicy, ani zapłaty psa w dom Pana, Boga twego, za jakikolwiek ślub; bo obrzydliwością u Pana, Boga twego, jest to oboje.
19 Ìwọ kò gbọdọ̀ ka èlé sí arákùnrin rẹ lọ́rùn, bóyá lórí owó tàbí oúnjẹ tàbí ohunkóhun mìíràn tí ó lè mú èlé wá.
Nie dasz na lichwę bratu twemu, ani pieniędzy, ani żywności, ani jakiejkolwiek rzeczy, którą dawają na lichwę.
20 Ìwọ lè ka èlé sí àlejò lọ́rùn, ṣùgbọ́n kì í ṣe arákùnrin ọmọ Israẹli, nítorí kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún ọ nínú ohun gbogbo tí o bá dáwọ́lé ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
Cudzoziemcowi na lichwę dawać możesz; ale bratu twemu na lichwę nie dasz, abyć błogosławił Pan, Bóg twój, w każdej sprawie, do której ściągniesz rękę twoję w ziemi, do której wnijdziesz, abyś ją posiadł.
21 Bí o bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, má ṣe lọ́ra láti san án, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, o sì máa jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀.
Jeźlibyś ślubował ślub Panu, Bogu twemu, nie omieszkiwajże oddawać go; bo koniecznie upomni się go Pan, Bóg twój, od ciebie, a będzie na tobie grzech.
22 Ṣùgbọ́n tí o bá fàsẹ́yìn láti jẹ́ ẹ̀jẹ́, o kò ní jẹ̀bi.
A jeźli nie będziesz ślubował, nie będzie na tobie grzechu.
23 Rí i dájú pé o ṣe ohunkóhun tí o bá ti ètè rẹ jáde, nítorí pé ìwọ fi tinútinú rẹ jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú ẹnu ara rẹ.
To co wynijdzie z ust twoich, wypełnisz, i uczynisz, jakoś ślubował Panu, Bogu twemu, dobrowolnie, coś wymówił usty twemi.
24 Bí ìwọ bá wọ inú ọgbà àjàrà aládùúgbò rẹ, o lè jẹ gbogbo èso àjàrà tí o bá fẹ́, ṣùgbọ́n má ṣe fi nǹkan kan sínú agbọ̀n rẹ.
Gdy wnijdziesz do winnicy bliźniego twego, jedz jagody, ileć się podoba, aż do sytości; ale do naczynia twego nie bierz.
25 Bí ìwọ bá wọ inú oko ọkà aládùúgbò rẹ, o lè fi ọwọ́ rẹ ya síírí rẹ̀, ṣùgbọ́n o kò gbọdọ̀ ki dòjé bọ ọkà tí ó dúró.
Także gdy wnijdziesz między zboże bliźniego twego, tedy narwiesz kłosów ręką twą; ale sierpa nie zapuszczaj w zboże bliźniego twego.

< Deuteronomy 23 >