< Deuteronomy 23 >
1 Kí ẹnikẹ́ni tí a fọ́ ní kóró ẹpọ̀n nípa rírùn tàbí gígé má ṣe wọ inú ìjọ Olúwa wá.
“Loba ngubani olimele amaphambili, kungaba ngokuthenwa kumbe ukugxotshwa kavunyelwa ukungena ebandleni likaThixo.
2 Kí ọmọ àlè má ṣe wọ ìpéjọ Olúwa, pàápàá títí dé ìran kẹwàá.
Loba ngubani ozelwe ngobufebe loba izizukulwane zakhe kuze kube ngesetshumi, kavunyelwa ukungena ebandleni likaThixo.
3 Kí ọmọ Ammoni tàbí ọmọ Moabu, kì yóò wọ ìjọ Olúwa, àní títí dé ìran kẹwàá, ènìyàn wọn kan kì yóò wọ inú ìjọ ènìyàn Olúwa láéláé.
Kakho umʼAmoni loba owaseMowabi loba isizukulwane sakhe kuze kufike esizukulwaneni setshumi ozavunyelwa ukungena embuthanweni kaThixo.
4 Nítorí wọn kò fi àkàrà àti omi pàdé e yín lójú ọ̀nà nígbà tí ò ń bọ̀ láti Ejibiti àti nítorí wọ́n gba ẹ̀yà iṣẹ́ láti fi ọ́ gégùn ún Balaamu ọmọ Beori ará a Petori ti Aramu-Naharaimu.
Kungenxa yokuthi abalihlangabezanga beliphathele isinkwa kanye lamanzi endleleni yenu ekuphumeni kwenu eGibhithe, bona basuka baqhatsha uBhalamu indodana kaBheyori owePhethori e-Aramu Naharayimu ukuba ehlisele isiqalekiso phezu kwenu.
5 Síbẹ̀síbẹ̀, Olúwa Ọlọ́run rẹ kò ní fetí sí Balaamu ṣùgbọ́n ó yí ègún sí ìbùkún fún ọ, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ fẹ́ràn rẹ.
Kodwa-ke, uThixo uNkulunkulu wenu kazangalalele uBhalamu kodwa waphendula isiqalekiso saba yisibusiso kini, ngenxa yokuthi uThixo uNkulunkulu wenu uyalithanda.
6 Ìwọ kò gbọdọ̀ wá àlàáfíà, tàbí ire wọn níwọ̀n ìgbà tí o sì wà láààyè.
Lingadingi ukwakha ubungane labo ekuphileni kwenu konke.
7 Ìwọ kò gbọdọ̀ kórìíra ará Edomu kan nítorí arákùnrin rẹ ni. Ìwọ kò gbọdọ̀ kórìíra ará Ejibiti, nítorí o gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì ní ilẹ̀ rẹ̀.
Lingamenyanyi owase-Edomi, ngoba ungumfowenu. Lingamenyanyi umGibhithe, ngoba laphila njengabezizweni elizweni lakhe.
8 Ìran kẹta àwọn ọmọ tí a bí fún wọn lè wọ ìpéjọ Olúwa.
Isizukulwane sesithathu sabantwana abazalwa lapho bangangena ebandleni likaThixo.”
9 Nígbà tí o bá dó ti àwọn ọ̀tá rẹ, pa gbogbo ohun àìmọ́ kúrò.
“Nxa lithobelene lezitha zenu ekuhlaseleni, xekani lakho konke okungahlanzekanga.
10 Bí ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin rẹ bá jẹ́ aláìmọ́ nítorí ìtújáde tí ó ní, o ní láti jáde kúrò nínú àgọ́, kí o má ṣe wọ inú àgọ́.
Nxa kukhona indoda phakathi kwenu ezichithele ngobudoda ebusuku, kumele iphumele ngaphandle kwezihonqo ihle iyehlala khonale.
11 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá di ìrọ̀lẹ́ o ní láti wẹ ara rẹ, àti ní àṣálẹ́ kí o padà sínú àgọ́.
Kodwa-ke akuthi ilanga selithambeka igeze, kuthi-ke ngokutshona kwelanga ibuyele ezihonqweni.
12 Sàmì sí ibìkan lóde àgọ́, níbi tí o lè máa lọ láti dẹ ara rẹ lára.
Khethani indawo ngaphandle kwezihonqo lapho elizayela ngaphandle khona.
13 Kí ìwọ kí ó sì mú ìwalẹ̀ kan pẹ̀lú ohun ìjà rẹ; yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ yóò bá gbọnṣẹ̀ lẹ́yìn ibùdó, kí ìwọ kí ó mú ìwalẹ̀, kí ìwọ kí ó sì yípadà, kí o sì bo ohun tí ó jáde láara rẹ.
Wobani lesikhali sokugebha kuthi lingaya ngaphandle, ligebhe igodi ligqibele leyongcekeza.
14 Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń rìn láàrín àgọ́ láti dáàbò bò ọ́ àti láti fi àwọn ọ̀tá à rẹ lé ọ lọ́wọ́. Àgọ́ rẹ ní láti jẹ́ mímọ́, nítorí kí ó má ba à rí ohun àìtọ́ láàrín yín kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ yín.
Ngenxa yokuthi uThixo uNkulunkulu wenu uyahambahamba phakathi kwezihonqo zenu ukuze alivikele ezitheni zenu. Izihonqo zenu kumele zibengcwele, ukuze angaboni lutho olungalunganga phakathi kwenu okuzakwenza alifulathele.”
15 Bí ẹrú kan bá ti gba ààbò lọ́dọ̀ rẹ, má ṣe fi lé ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
“Nxa isigqili sidinga ukuphephela kini lingasibuyiseli kumnikazi waso.
16 Jẹ́ kí ó máa gbé láàrín rẹ níbikíbi tí ó bá fẹ́ àti èyíkéyìí ìlú tí ó bá mú. Má ṣe ni í lára.
Siyekeleni sizihlalele lapho esifuna ukuhlala khona njalo sizihlalele kulelodolobho esifuna ukuhlala kulo. Lingasincindezeli.
17 Kí ọkùnrin tàbí obìnrin Israẹli má ṣe padà di alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
Akungabi lowesilisa wako-Israyeli loba owesifazane ozakuba yisifebe sethempelini.
18 Ìwọ kò gbọdọ̀ mú owó iṣẹ́ panṣágà obìnrin tàbí ọkùnrin wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ láti fi san ẹ̀jẹ́ kankan; nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ kórìíra àwọn méjèèjì.
Lingaboletha inzuzo yowesifazane ofebayo loba owesilisa ofebayo endlini kaThixo uNkulunkulu wenu ezobhadala loba yisiphi isithembiso, ngoba uThixo uNkulunkulu wenu uyanengeka ngabo bonke.
19 Ìwọ kò gbọdọ̀ ka èlé sí arákùnrin rẹ lọ́rùn, bóyá lórí owó tàbí oúnjẹ tàbí ohunkóhun mìíràn tí ó lè mú èlé wá.
Umfowenu ungamhlawulisi inzuzo, loba ngeyemali loba ngeyokudla loba yini engamlethela inzuzo.
20 Ìwọ lè ka èlé sí àlejò lọ́rùn, ṣùgbọ́n kì í ṣe arákùnrin ọmọ Israẹli, nítorí kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún ọ nínú ohun gbogbo tí o bá dáwọ́lé ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
Owezizweni lingamhlawulisa inzuzo, kodwa hatshi umfowenu wako-Israyeli, ukuze uThixo uNkulunkulu wenu alibusise kukho konke elikwenza ngezandla zenu elizweni elizangena kulo ukuba libe ngelenu.
21 Bí o bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, má ṣe lọ́ra láti san án, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, o sì máa jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀.
Nxa lingenza isifungo kuThixo uNkulunkulu wenu, lingaphuzi ukusibhadala, ngoba uThixo uNkulunkulu wenu uzakufuna kini loba sekutheni njalo lizakuba lomlandu wesono.
22 Ṣùgbọ́n tí o bá fàsẹ́yìn láti jẹ́ ẹ̀jẹ́, o kò ní jẹ̀bi.
Kodwa nxa lingayekela ukwenza isifungo kaliyikuba lomlandu.
23 Rí i dájú pé o ṣe ohunkóhun tí o bá ti ètè rẹ jáde, nítorí pé ìwọ fi tinútinú rẹ jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú ẹnu ara rẹ.
Konke lokho okuphuma endebeni zenu kumele libe leqiniso ukukwenza, ngoba lenze lesosifungo ngokukhululeka lithembisa kuThixo uNkulunkulu wenu ngemilomo yenu.
24 Bí ìwọ bá wọ inú ọgbà àjàrà aládùúgbò rẹ, o lè jẹ gbogbo èso àjàrà tí o bá fẹ́, ṣùgbọ́n má ṣe fi nǹkan kan sínú agbọ̀n rẹ.
Nxa lingangena esivinini sikamakhelwane wenu, lingadla wonke amagrebisi elifisa ukuwadla, kodwa lingafaki lelilodwa esitsheni senu.
25 Bí ìwọ bá wọ inú oko ọkà aládùúgbò rẹ, o lè fi ọwọ́ rẹ ya síírí rẹ̀, ṣùgbọ́n o kò gbọdọ̀ ki dòjé bọ ọkà tí ó dúró.
Nxa lingena ensimini kamakhelwane eyamabele, lilakho ukudobha okuwileyo ngezandla, kodwa limukani lingasebenzisi isikela emabeleni alokhu emi ngamahlanga.”