< Deuteronomy 23 >

1 Kí ẹnikẹ́ni tí a fọ́ ní kóró ẹpọ̀n nípa rírùn tàbí gígé má ṣe wọ inú ìjọ Olúwa wá.
Celui qui est eunuque pour avoir été écrasé, ou pour avoir été taillé, n'entrera point dans l'assemblée de l'Éternel.
2 Kí ọmọ àlè má ṣe wọ ìpéjọ Olúwa, pàápàá títí dé ìran kẹwàá.
Le bâtard n'entrera point dans l'assemblée de l'Éternel; même sa dixième génération n'entrera point dans l'assemblée de l'Éternel.
3 Kí ọmọ Ammoni tàbí ọmọ Moabu, kì yóò wọ ìjọ Olúwa, àní títí dé ìran kẹwàá, ènìyàn wọn kan kì yóò wọ inú ìjọ ènìyàn Olúwa láéláé.
L'Ammonite et le Moabite n'entreront point dans l'assemblée de l'Éternel; même leur dixième génération n'entrera point dans l'assemblée de l'Éternel, à jamais;
4 Nítorí wọn kò fi àkàrà àti omi pàdé e yín lójú ọ̀nà nígbà tí ò ń bọ̀ láti Ejibiti àti nítorí wọ́n gba ẹ̀yà iṣẹ́ láti fi ọ́ gégùn ún Balaamu ọmọ Beori ará a Petori ti Aramu-Naharaimu.
Parce qu'ils ne sont point venus au-devant de vous avec le pain et l'eau, dans le chemin, quand vous sortiez d'Égypte, et parce qu'ils firent venir, à prix d'argent, contre toi Balaam, fils de Béor, de Pethor en Mésopotamie, pour te maudire.
5 Síbẹ̀síbẹ̀, Olúwa Ọlọ́run rẹ kò ní fetí sí Balaamu ṣùgbọ́n ó yí ègún sí ìbùkún fún ọ, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ fẹ́ràn rẹ.
Mais l'Éternel ton Dieu ne voulut point écouter Balaam; et l'Éternel ton Dieu changea pour toi la malédiction en bénédiction, parce que l'Éternel ton Dieu t'aime.
6 Ìwọ kò gbọdọ̀ wá àlàáfíà, tàbí ire wọn níwọ̀n ìgbà tí o sì wà láààyè.
Tu ne chercheras jamais, tant que tu vivras, leur paix ni leur bien.
7 Ìwọ kò gbọdọ̀ kórìíra ará Edomu kan nítorí arákùnrin rẹ ni. Ìwọ kò gbọdọ̀ kórìíra ará Ejibiti, nítorí o gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì ní ilẹ̀ rẹ̀.
Tu n'auras point en abomination l'Iduméen; car il est ton frère. Tu n'auras point en abomination l'Égyptien; car tu as été étranger dans son pays;
8 Ìran kẹta àwọn ọmọ tí a bí fún wọn lè wọ ìpéjọ Olúwa.
Les enfants qui leur naîtront à la troisième génération, pourront entrer dans l'assemblée de l'Éternel.
9 Nígbà tí o bá dó ti àwọn ọ̀tá rẹ, pa gbogbo ohun àìmọ́ kúrò.
Quand tu marcheras en armes contre tes ennemis, garde-toi de toute chose mauvaise.
10 Bí ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin rẹ bá jẹ́ aláìmọ́ nítorí ìtújáde tí ó ní, o ní láti jáde kúrò nínú àgọ́, kí o má ṣe wọ inú àgọ́.
S'il y a quelqu'un d'entre vous qui ne soit point pur, par suite d'un accident arrivé de nuit, il sortira hors du camp, il n'entrera point dans le camp;
11 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá di ìrọ̀lẹ́ o ní láti wẹ ara rẹ, àti ní àṣálẹ́ kí o padà sínú àgọ́.
Et sur le soir il se lavera dans l'eau, et dès que le soleil sera couché, il rentrera dans le camp.
12 Sàmì sí ibìkan lóde àgọ́, níbi tí o lè máa lọ láti dẹ ara rẹ lára.
Tu auras un endroit, hors du camp, où tu sortiras; et tu auras un pieu avec ton bagage;
13 Kí ìwọ kí ó sì mú ìwalẹ̀ kan pẹ̀lú ohun ìjà rẹ; yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ yóò bá gbọnṣẹ̀ lẹ́yìn ibùdó, kí ìwọ kí ó mú ìwalẹ̀, kí ìwọ kí ó sì yípadà, kí o sì bo ohun tí ó jáde láara rẹ.
Et quand tu voudras t'asseoir dehors, tu creuseras avec ce pieu, et tu recouvriras ce qui sera sorti de toi.
14 Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń rìn láàrín àgọ́ láti dáàbò bò ọ́ àti láti fi àwọn ọ̀tá à rẹ lé ọ lọ́wọ́. Àgọ́ rẹ ní láti jẹ́ mímọ́, nítorí kí ó má ba à rí ohun àìtọ́ láàrín yín kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ yín.
Car l'Éternel ton Dieu marche au milieu de ton camp pour te délivrer, et pour livrer tes ennemis devant toi. Que ton camp soit donc saint, de peur qu'il ne voie chez toi quelque chose d'impur, et qu'il ne se détourne de toi.
15 Bí ẹrú kan bá ti gba ààbò lọ́dọ̀ rẹ, má ṣe fi lé ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
Tu ne livreras point à son maître l'esclave qui se sera sauvé chez toi d'avec son maître;
16 Jẹ́ kí ó máa gbé láàrín rẹ níbikíbi tí ó bá fẹ́ àti èyíkéyìí ìlú tí ó bá mú. Má ṣe ni í lára.
Il demeurera avec toi, au milieu de toi, dans le lieu qu'il choisira dans l'une de tes villes, où il lui plaira; tu ne le molesteras point.
17 Kí ọkùnrin tàbí obìnrin Israẹli má ṣe padà di alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
Qu'il n'y ait point de prostituée entre les filles d'Israël, et qu'aucun des fils d'Israël ne se prostitue à l'infamie.
18 Ìwọ kò gbọdọ̀ mú owó iṣẹ́ panṣágà obìnrin tàbí ọkùnrin wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ láti fi san ẹ̀jẹ́ kankan; nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ kórìíra àwọn méjèèjì.
Tu n'apporteras point dans la maison de l'Éternel ton Dieu le salaire d'une prostituée, ni le prix d'un chien, pour quelque vœu que ce soit; car tous les deux sont en abomination à l'Éternel ton Dieu.
19 Ìwọ kò gbọdọ̀ ka èlé sí arákùnrin rẹ lọ́rùn, bóyá lórí owó tàbí oúnjẹ tàbí ohunkóhun mìíràn tí ó lè mú èlé wá.
Tu ne prêteras point à intérêt à ton frère, ni de l'argent, ni des vivres, ni quoi que ce soit qu'on prête à intérêt.
20 Ìwọ lè ka èlé sí àlejò lọ́rùn, ṣùgbọ́n kì í ṣe arákùnrin ọmọ Israẹli, nítorí kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún ọ nínú ohun gbogbo tí o bá dáwọ́lé ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
Tu pourras prêter à intérêt à l'étranger, mais tu ne prêteras point à intérêt à ton frère; afin que l'Éternel ton Dieu te bénisse en toute chose à laquelle tu mettras la main, dans le pays où tu vas entrer pour le posséder.
21 Bí o bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, má ṣe lọ́ra láti san án, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, o sì máa jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀.
Quand tu auras fait un vœu à l'Éternel ton Dieu, tu ne différeras point de l'accomplir; car l'Éternel ton Dieu ne manquerait pas de te le redemander; et il y aurait du péché en toi.
22 Ṣùgbọ́n tí o bá fàsẹ́yìn láti jẹ́ ẹ̀jẹ́, o kò ní jẹ̀bi.
Mais quand tu t'abstiendras de faire des vœux, il n'y aura point de péché en toi.
23 Rí i dájú pé o ṣe ohunkóhun tí o bá ti ètè rẹ jáde, nítorí pé ìwọ fi tinútinú rẹ jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú ẹnu ara rẹ.
Tu prendras garde de faire ce qui sera sorti de tes lèvres, lorsque tu auras fait à l'Éternel ton Dieu un vœu volontaire, que tu auras prononcé de ta bouche.
24 Bí ìwọ bá wọ inú ọgbà àjàrà aládùúgbò rẹ, o lè jẹ gbogbo èso àjàrà tí o bá fẹ́, ṣùgbọ́n má ṣe fi nǹkan kan sínú agbọ̀n rẹ.
Quand tu entreras dans la vigne de ton prochain, tu pourras manger des raisins selon ton appétit, pour te rassasier, mais tu n'en mettras point dans ton panier.
25 Bí ìwọ bá wọ inú oko ọkà aládùúgbò rẹ, o lè fi ọwọ́ rẹ ya síírí rẹ̀, ṣùgbọ́n o kò gbọdọ̀ ki dòjé bọ ọkà tí ó dúró.
Quand tu entreras dans les blés de ton prochain, tu pourras arracher des épis avec ta main; mais tu ne mettras point la faucille dans les blés de ton prochain.

< Deuteronomy 23 >