< Deuteronomy 23 >

1 Kí ẹnikẹ́ni tí a fọ́ ní kóró ẹpọ̀n nípa rírùn tàbí gígé má ṣe wọ inú ìjọ Olúwa wá.
Nowa dunu da ea gulusu danai o ea ewa damuni fasi da Hina Gode Ea fi ilima gilisimu da sema bagade.
2 Kí ọmọ àlè má ṣe wọ ìpéjọ Olúwa, pàápàá títí dé ìran kẹwàá.
Fa mano da Hina Gode Ea Fi ilima hame gilisimu. Amola amo fa mano ea mano da Gode Ea Fi ilima hame gilisimu.
3 Kí ọmọ Ammoni tàbí ọmọ Moabu, kì yóò wọ ìjọ Olúwa, àní títí dé ìran kẹwàá, ènìyàn wọn kan kì yóò wọ inú ìjọ ènìyàn Olúwa láéláé.
A: monaide dunu, Moua: be dunu amola ilia mano amola iligaga fi huluane da Gode Ea Fi ilima afafai dagoi.
4 Nítorí wọn kò fi àkàrà àti omi pàdé e yín lójú ọ̀nà nígbà tí ò ń bọ̀ láti Ejibiti àti nítorí wọ́n gba ẹ̀yà iṣẹ́ láti fi ọ́ gégùn ún Balaamu ọmọ Beori ará a Petori ti Aramu-Naharaimu.
Dilia da Idibidi soge fisili, logoga ahoanoba, ilia da dilima hano amola ha: i manu hame i. Amola dilima gagabusu aligima: ne, ilia da Bio ea mano Ba: ila: me (ea moilai bai bagade da Bedo moilai Mesoubouda: imia soge ganodini diala) amo bidiga lai dagoi.
5 Síbẹ̀síbẹ̀, Olúwa Ọlọ́run rẹ kò ní fetí sí Balaamu ṣùgbọ́n ó yí ègún sí ìbùkún fún ọ, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ fẹ́ràn rẹ.
Be dilia Hina Gode da Ba: ilame ea sia: hame nabi. Be E da amo gagabusu afadenene bu hahawane dogolegele fidisu dilima i. Bai E da dilima asigisa.
6 Ìwọ kò gbọdọ̀ wá àlàáfíà, tàbí ire wọn níwọ̀n ìgbà tí o sì wà láààyè.
Dilia da fi esalea, amo dunu fi mae fidima amola ilima mae asigima.
7 Ìwọ kò gbọdọ̀ kórìíra ará Edomu kan nítorí arákùnrin rẹ ni. Ìwọ kò gbọdọ̀ kórìíra ará Ejibiti, nítorí o gbé gẹ́gẹ́ bí àjèjì ní ilẹ̀ rẹ̀.
Idome dunu amo mae higama. Ilia da dilia fi dunu. Amola Idibidi dunu mae higama. Musa: dili da ilia soge ganodini esalu.
8 Ìran kẹta àwọn ọmọ tí a bí fún wọn lè wọ ìpéjọ Olúwa.
Sosogo fifi masunu udiana agoane asili, Idibidi dunu iligaga fi dunu ilia da Hina Gode Ea Fi amoma gilisimu da defea.
9 Nígbà tí o bá dó ti àwọn ọ̀tá rẹ, pa gbogbo ohun àìmọ́ kúrò.
Dilia gegesea, dilia ha wa: i fisisu ganodini esalea, ledo liligi huluane mae digili ba: ma.
10 Bí ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin rẹ bá jẹ́ aláìmọ́ nítorí ìtújáde tí ó ní, o ní láti jáde kúrò nínú àgọ́, kí o má ṣe wọ inú àgọ́.
Dunu da gasia ea da: i amoga ami udigili ahoabeba: le, e da ledo agoane ba: sea, e da ha wa: i fisisu amoga gadili masunu amola amo gasi ganodini bu hame misa: mu.
11 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá di ìrọ̀lẹ́ o ní láti wẹ ara rẹ, àti ní àṣálẹ́ kí o padà sínú àgọ́.
Aya daeya agoane e da dodofelalu, eso dasea bu ha wa: i fisisu amo golili misunu da defea.
12 Sàmì sí ibìkan lóde àgọ́, níbi tí o lè máa lọ láti dẹ ara rẹ lára.
Dilia fonobahadi diasu amoga masa: ne, sogebi amo ha wa: i fisisu gadili ilegema.
13 Kí ìwọ kí ó sì mú ìwalẹ̀ kan pẹ̀lú ohun ìjà rẹ; yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ yóò bá gbọnṣẹ̀ lẹ́yìn ibùdó, kí ìwọ kí ó mú ìwalẹ̀, kí ìwọ kí ó sì yípadà, kí o sì bo ohun tí ó jáde láara rẹ.
Dilia liligi amo ganodini, ifa daba: gaguli masa. Amoga dilia da iga gia ahoasea uli dogone, iga amo dedeboma.
14 Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń rìn láàrín àgọ́ láti dáàbò bò ọ́ àti láti fi àwọn ọ̀tá à rẹ lé ọ lọ́wọ́. Àgọ́ rẹ ní láti jẹ́ mímọ́, nítorí kí ó má ba à rí ohun àìtọ́ láàrín yín kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ yín.
Dilia ha wa: i fisisu sogebi da ledo hame ba: ma: mu. Bai dilia Hina Gode da dili fidima: ne amola dili gaga: ma: ne, dilia fi amo ganodini esala. Amaiba: le, Hina Gode da ledo o wadela: i hou ba: sea, dili fisisa: besa: le, ledo liligi ba: mu da sema bagade.
15 Bí ẹrú kan bá ti gba ààbò lọ́dọ̀ rẹ, má ṣe fi lé ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
Udigili hawa: hamosu dunu da ea ouligisu yolesili dima gaga: musa: hobeasea, e buhagima: ne mae asunasima.
16 Jẹ́ kí ó máa gbé láàrín rẹ níbikíbi tí ó bá fẹ́ àti èyíkéyìí ìlú tí ó bá mú. Má ṣe ni í lára.
Be e da ea hanai moilai amo ganodini fimu da defea. Amola ema ougili mae hamoma.
17 Kí ọkùnrin tàbí obìnrin Israẹli má ṣe padà di alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
Isala: ili dunu o uda da ogogosu debolo diasu ganodini aheda: le wadela: i uda lasu hou hamomu da sema bagade.
18 Ìwọ kò gbọdọ̀ mú owó iṣẹ́ panṣágà obìnrin tàbí ọkùnrin wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ láti fi san ẹ̀jẹ́ kankan; nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ kórìíra àwọn méjèèjì.
Amola muni amo aheda: i hawa: hamosu hamoiba: le lai da Gode Ea diasu ganodini, dilia Godema imunu ilegele sia: iba: le amo Godema imunu da sema bagade. Bai Gode da udigili wadela: i debolo uda lasu dunu amola aheda: i uda bagade higasa.
19 Ìwọ kò gbọdọ̀ ka èlé sí arákùnrin rẹ lọ́rùn, bóyá lórí owó tàbí oúnjẹ tàbí ohunkóhun mìíràn tí ó lè mú èlé wá.
Dilia da dilia na: iyado Isala: ili dunu ilima muni bu fa: no lama: ne iasea, eno muni (interest) amola gilisili mae lama.
20 Ìwọ lè ka èlé sí àlejò lọ́rùn, ṣùgbọ́n kì í ṣe arákùnrin ọmọ Israẹli, nítorí kí Olúwa Ọlọ́run rẹ lè bùkún ọ nínú ohun gbogbo tí o bá dáwọ́lé ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
Dilia da ga fi dunuma muni bu ima: ne iasea, gilisili dabe amolawane lamu da defea, be dilia na: iyado Isala: ili dunu ilima hamomu da sema gala. Dilia amo sema nabawane hamosea, dilia Hina Gode da soge dilia da gesowale fimu amo ganodini dilia hou huluane hahawane dogolegelewane fidimu.
21 Bí o bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ, má ṣe lọ́ra láti san án, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò béèrè rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ, o sì máa jẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀.
Dilia Hina Godema hou hamomu ilegele sia: sea, defea, dilia sia: i liligi hedolowane hamoma. Hina Gode da dilia sia: i liligi nabi amola dilia da Ema ogogomu higasa. Hame hamosea, amo da dima wadela: i hou.
22 Ṣùgbọ́n tí o bá fàsẹ́yìn láti jẹ́ ẹ̀jẹ́, o kò ní jẹ̀bi.
Dilia da Godema hou hamomu hame ilegele sia: sea, amo da wadela: i hame.
23 Rí i dájú pé o ṣe ohunkóhun tí o bá ti ètè rẹ jáde, nítorí pé ìwọ fi tinútinú rẹ jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pẹ̀lú ẹnu ara rẹ.
Be ilegele sia: sea, dawa: ma! Dilia sia: i liligi noga: le hamoma.
24 Bí ìwọ bá wọ inú ọgbà àjàrà aládùúgbò rẹ, o lè jẹ gbogbo èso àjàrà tí o bá fẹ́, ṣùgbọ́n má ṣe fi nǹkan kan sínú agbọ̀n rẹ.
Di da dunu eno ea waini sagai ganodini logoga ahoasea, dia hanai defele waini fage faili manu da defea. Be waini fage amo faili, dia esa ganodini gaguli masunu da sema bagade.
25 Bí ìwọ bá wọ inú oko ọkà aládùúgbò rẹ, o lè fi ọwọ́ rẹ ya síírí rẹ̀, ṣùgbọ́n o kò gbọdọ̀ ki dòjé bọ ọkà tí ó dúró.
Di da dunu eno ea gagoma bugi soge amo ganodini logoga ahoasea, dia loboga gagoma faili manu da defea. Be gagoma gobihei amoga damusia da sema bagade.

< Deuteronomy 23 >