< Deuteronomy 22 >

1 Bí o bá rí màlúù tàbí àgùntàn arákùnrin rẹ tí ó ń sọnù, má ṣe ṣé àìkíyèsí i rẹ̀ ṣùgbọ́n rí i dájú pé o mú padà wá fún un.
Jeźlibyś ujrzał wołu brata twego, albo owcę jego obłąkaną, nie mijajże ich, ale je koniecznie odprowadź do brata twego.
2 Bí ọkùnrin náà kì í bá gbé ní tòsí rẹ tàbí bí o kò bá mọ ẹni náà, mú un lọ ilé pẹ̀lú rẹ kí o sì fi pamọ́ títí yóò fi wá a wá. Nígbà náà ni kí o fi fún un.
Choćciby nie był blisko brat twój, anibyś go znał, przecię zapędzisz je do domu swego, i będzie przy tobie, ażby tego szukał brat twój, i wrócisz mu je.
3 Ṣe bákan náà tí o bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ arákùnrin rẹ tàbí aṣọ ìlekè tàbí ohunkóhun rẹ̀ tí ó sọnù. Má ṣe ṣe àìkíyèsí i rẹ̀.
Toż uczynisz osłowi jego; toż też uczynisz szacie jego; toż też uczynisz wszelakiej rzeczy zgubionej brata twego, która by mu zginęła, jeźlibyś ją znalazł, nie mijajże jej.
4 Bí o bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí màlúù arákùnrin rẹ tí o dùbúlẹ̀ sójú ọ̀nà, má ṣe ṣàìfiyèsí i rẹ̀, ràn án lọ́wọ́ láti dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀.
Jeźlibyś ujrzał osła brata twego, albo wołu jego, że upadł na drodze, nie mijajże ich, ale go zaraz z nim podnieś.
5 Obìnrin kò gbọdọ̀ wọ aṣọ ọkùnrin, tàbí kí ọkùnrin wọ aṣọ obìnrin, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó ṣe èyí.
Niech nie bierze niewiasta na się szat męskich, ani niech się nie obłóczy mąż w szatę niewieścią; albowiem jest obrzydliwością Panu, Bogu twemu, kto by to czynił.
6 Bí ìwọ bá ṣe alábòápàdé ìtẹ́ ẹyẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà, bóyá lára igi tàbí lórí ilẹ̀, tí ìyá wọn sì jókòó lórí àwọn ọmọ, tàbí lórí àwọn ẹyin, má ṣe gbé ìyá pẹ̀lú àwọn ọmọ.
Gdybyś trafił gniazdo ptasze przed sobą w drodze, na jakiemkolwiek drzewie, albo na ziemi, a w niem ptaszęta albo jajka, a matka by siedziała na ptaszętach albo na jajkach, nie bierzże macierzy z dziećmi;
7 Ìwọ lè gbé ọmọ, ṣùgbọ́n rí i dájú pé o jọ̀wọ́ ìyá lọ́wọ́ lọ, kí ó ba à lè dára fún ọ àti kí o lè ní ẹ̀mí gígùn.
Ale wolno puściwszy matkę, dzieci weźmiesz sobie, abyć się dobrze działo, i żebyś przedłużył dni twoich
8 Nígbà tí o bá kọ́ ilé tuntun, mọ odi yí òrùlé rẹ̀ ká nítorí kí o má ba à mú ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ wá sórí ilẹ̀ rẹ bí ẹnikẹ́ni bá ṣubú láti òrùlé.
Gdy też zbudujesz dom nowy, tedy uczynisz blanki po kraju dachu twego, abyś nie przywiódł krwi na dom twój, gdyby kto spadł z niego.
9 Má ṣe gbin oríṣìí èso méjì sínú ọgbà àjàrà rẹ; bí o bá ṣe bẹ́ẹ̀, kì í ṣe èso oko tí o gbìn nìkan ṣùgbọ́n èso ọgbà àjàrà pẹ̀lú yóò bàjẹ́.
Nie posiewaj winnicy twojej, różnem nasieniem, byś snać nie splugawił pożytku nasienia, któreś siał, i urodzaju winnicy.
10 Ìwọ kò gbọdọ̀ fi akọ màlúù àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tulẹ̀ pọ̀.
Nie będziesz orał wołem i osłem pospołu.
11 Ìwọ kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun àgùntàn àti aṣọ funfun papọ̀.
Nie obleczesz szaty utkanej z wełny i ze lnu pospołu.
12 Kí o ṣe wajawaja sí etí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin aṣọ ìlekè rẹ.
Poczynisz sobie sznurki na czterech rogach szaty twojej, którą się odziewać będziesz.
13 Bí ọkùnrin kan bá mú ìyàwó àti, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti dùbúlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, kórìíra rẹ̀,
Gdyby kto pojął żonę, a wszedłszy do niej, miałby ją w nienawiści;
14 tí ó ṣì sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sì i, tí o sì fún un ní orúkọ búburú, wí pé, “Mo fẹ́ obìnrin yìí, ṣùgbọ́n nígbà tí mo súnmọ́ ọn. Èmi kò rí àmì ìbálé rẹ̀.”
A dałby przyczynę, aby mówiono o niej, i wprowadziłby na nię złą sławę, mówiąc; Pojąłem tę żonę, a wszedłszy do niej, nie znalazłem jej panną:
15 Nígbà náà ni baba ọmọbìnrin náà àti ìyá rẹ̀ yóò mú ẹ̀rí pé, ó ti wà ní ìbálé tẹ́lẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ìlú ní ẹnu-bodè.
Tedy weźmie ojciec dzieweczki, i matka jej, i przyniosą znaki panieństwa dzieweczki onej do starszych miasta onego do bramy;
16 Baba obìnrin náà yóò wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Mo fi ọmọbìnrin mi fún ọkùnrin yìí láti fẹ́ níyàwó, ṣùgbọ́n ó kórìíra rẹ̀.
I rzecze ojciec onej dzieweczki do starszych: Córkę swoję dałem mężowi temu za żonę; a on ją ma w nienawiści;
17 Ní ìsinsin yìí ó ti sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí i ó sì wí pé, ‘Èmi kò rí ọmọbìnrin rẹ kí ó wà ní wúńdíá.’ Ṣùgbọ́n níhìn-ín yìí ni ẹ̀rí ìbálé ọmọbìnrin mi.” Nígbà náà ni àwọn òbí rẹ̀ yóò fi aṣọ hàn níwájú àwọn àgbàgbà ìlú,
A oto sam dał przyczynę, aby mówiono o niej, powiadając: Nie znalazłem przy córce twojej panieństwa: ale oto są znaki panieństwa córki mojej. Tedy rozwiną ono prześcieradło przed starszymi miasta onego.
18 àwọn àgbàgbà yóò sì mú ọkùnrin náà, wọn yóò sì jẹ ní yà.
A wziąwszy starsi miasta onego męża skarzą go.
19 Wọn yóò sì gba ìtánràn ọgọ́rùn-ún ṣékélì owó fàdákà fún baba ọmọbìnrin náà, nítorí ọkùnrin yìí ti fi orúkọ búburú fún wúńdíá Israẹli. Yóò sì máa ṣe ìyàwó rẹ̀; kò gbọdọ̀ kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ní gbogbo ayé e rẹ̀.
I wezmą z niego winę sto srebrników, które oddadzą ojcu onej dzieweczki, przeto, że puścił złą sławę o pannie Izraelskiej, i będzie ją miał za żonę, i nie będzie jej mógł opuścić po wszystkie dni swoje.
20 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀sùn náà bá jẹ́ òtítọ́ tí a kò sí rí ẹ̀rí ìbálé obìnrin náà,
Ale byłoliby prawdziwe to obwinienie jej, a nie znalazłyby się znaki panieństwa przy onej dzieweczce;
21 wọn yóò mú wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé baba rẹ̀ níbẹ̀ sì ni àwọn ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò ti sọ ọ́ ní òkúta pa. Ó ti ṣe ohun ìtìjú ní Israẹli nípa ṣíṣe àgbèrè nígbà tí ó wà nílé baba rẹ̀. Ẹ ní láti pa ohun búburú kúrò láàrín yín.
Tedy wywiodą onę dzieweczkę przed drzwi domu ojca jej, i ukamionują ją ludzie miasta onego, i umrze: bo uczyniła hańbę w Izraelu, popełniwszy nierząd w domu ojca swego; tak odejmiesz złe z pośród siebie.
22 Bí o bá rí ọkùnrin kan tí ó bá ìyàwó ọkùnrin mìíràn lòpọ̀, àwọn méjèèjì ní láti kú. Ẹ ní láti pa ohun búburú kúrò láàrín Israẹli.
Jeźliby kto znalezion był, obcujący z niewiastą, mającą męża, tedy niech umrą oboje, mąż, który obcował z cudzą żoną, i ona niewiasta; tak odejmiesz złe z Izraela.
23 Bí ó bá ṣẹlẹ̀ wí pé ọkùnrin kan pàdé wúńdíá tí a ti fi fún ni láti fẹ́ láàrín ìlú tí ó sì lòpọ̀ pẹ̀lú u rẹ̀,
Byłaliby dzieweczka panna poślubiona mężowi, a trafiłby ją kto w mieście, i obcowałby z nią;
24 ìwọ yóò mú àwọn méjèèjì lọ sí ẹnu ibodè ìlú náà kí o sì sọ wọ́n ní òkúta pa nítorí ọmọbìnrin náà wà ní ìlú kò sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́, àti ọkùnrin náà nítorí ó ba ìyàwó ọkùnrin mìíràn jẹ́. O ní láti wẹ búburú kúrò láàrín rẹ.
Tedy wywiódłszy ono oboje przed bramę miasta, ukamionujecie je, i umrą; dzieweczkę przeto, iż nie wołała w mieście, a męża przeto, iż zelżył żonę bliźniego swego: tak odejmiesz złe z pośrodku siebie.
25 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe ìgbẹ́ ní ó ti ṣẹlẹ̀ pé ọkùnrin kan ti pàdé ọmọbìnrin tí a ti fẹ́ ṣọ́nà tí o sì fi tagbára tagbára bá a ṣe, ọkùnrin náà nìkan tí ó ṣe èyí ni yóò kú.
A jeźliby na polu trafił mąż dzieweczkę poślubioną a porwawszy ją, zgwałciłby ją, tedy umrze mąż, który obcował z nią, sam tylko.
26 Má ṣe fi ohunkóhun ṣe ọmọbìnrin náà; kò ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó tọ́ sí ikú. Ẹjọ́ yìí rí bí i ti ẹnìkan tí a gbámú tí ó pa aládùúgbò rẹ̀.
Ale dzieweczce nic nie uczynisz; dzieweczka nie jest winna śmierci; bo jako gdyby kto powstawszy przeciwko bliźniemu swemu, zamordował go, taka to sprawa.
27 Nítorí ọkùnrin náà rí ọmọbìnrin náà ní ìta ibodè, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọmọbìnrin àfẹ́sọ́nà kígbe, kò sí ẹnìkankan níbẹ̀ láti gbà á kalẹ̀.
Ponieważ ją na polu trafił, a gdy wołała dzieweczka poślubiona, nie był, kto by ją ratował.
28 Bí ó bá ṣẹlẹ̀ pé ọkùnrin pàdé wúńdíá tí kò ì tí ì ní àfẹ́sọ́nà tí ó sì fi tipátipá bá a ṣe tí a gbá wọn mú.
Gdyby też kto, trafiwszy dzieweczkę pannę, która nie jest za mąż zmówioną, porwał ją, i leżałby z nią, a zastano by je:
29 Ó ní láti san àádọ́ta fàdákà fún baba obìnrin náà, nítorí tí ó ti bà á jẹ́. Kò lè kọ̀ ọ́ sílẹ̀ níwọ̀n ìgbà tí ó sì wà láààyè.
Tedy da on mąż, który obcował z nią, ojcu dzieweczki pięćdziesiąt srebrników, i będzie mu za żonę, przeto że ją zelżył, ani jej będzie mógł opuścić po wszystkie dni swoje.
30 Ọkùnrin kò gbọdọ̀ fẹ́ ìyàwó baba rẹ̀; kò gbọdọ̀ sọ ìtẹ́ baba rẹ̀ di àìlọ́wọ̀.
Nie pojmie nikt żony ojca swego, i nie odkryje podołka ojca swego.

< Deuteronomy 22 >