< Deuteronomy 22 >

1 Bí o bá rí màlúù tàbí àgùntàn arákùnrin rẹ tí ó ń sọnù, má ṣe ṣé àìkíyèsí i rẹ̀ ṣùgbọ́n rí i dájú pé o mú padà wá fún un.
Tu ne verras pas le bœuf ou la brebis de ton frère s'égarer et tu ne t'en cacheras pas. Tu les ramèneras sûrement à ton frère.
2 Bí ọkùnrin náà kì í bá gbé ní tòsí rẹ tàbí bí o kò bá mọ ẹni náà, mú un lọ ilé pẹ̀lú rẹ kí o sì fi pamọ́ títí yóò fi wá a wá. Nígbà náà ni kí o fi fún un.
Si ton frère n'est pas près de toi ou si tu ne le connais pas, tu le ramèneras dans ta maison et il restera avec toi jusqu'à ce que ton frère vienne le chercher, et tu le lui rendras.
3 Ṣe bákan náà tí o bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ arákùnrin rẹ tàbí aṣọ ìlekè tàbí ohunkóhun rẹ̀ tí ó sọnù. Má ṣe ṣe àìkíyèsí i rẹ̀.
Tu feras de même avec son âne. Tu feras de même pour son vêtement. Tu feras de même pour tout objet perdu de ton frère, qu'il a perdu et que tu as retrouvé. Tu ne pourras pas te cacher.
4 Bí o bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí màlúù arákùnrin rẹ tí o dùbúlẹ̀ sójú ọ̀nà, má ṣe ṣàìfiyèsí i rẹ̀, ràn án lọ́wọ́ láti dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀.
Tu ne verras pas l'âne ou le bœuf de ton frère tombé sur le chemin et tu ne t'en cacheras pas. Tu l'aideras à les relever.
5 Obìnrin kò gbọdọ̀ wọ aṣọ ọkùnrin, tàbí kí ọkùnrin wọ aṣọ obìnrin, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó ṣe èyí.
La femme ne portera pas de vêtements d'homme, et l'homme ne mettra pas de vêtements de femme, car quiconque fait cela est en abomination à Yahvé ton Dieu.
6 Bí ìwọ bá ṣe alábòápàdé ìtẹ́ ẹyẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà, bóyá lára igi tàbí lórí ilẹ̀, tí ìyá wọn sì jókòó lórí àwọn ọmọ, tàbí lórí àwọn ẹyin, má ṣe gbé ìyá pẹ̀lú àwọn ọmọ.
Si tu rencontres en chemin un nid d'oiseau, dans un arbre ou sur le sol, avec des petits ou des œufs, et que la poule soit assise sur les petits ou sur les œufs, tu ne prendras pas la poule avec les petits.
7 Ìwọ lè gbé ọmọ, ṣùgbọ́n rí i dájú pé o jọ̀wọ́ ìyá lọ́wọ́ lọ, kí ó ba à lè dára fún ọ àti kí o lè ní ẹ̀mí gígùn.
Tu laisseras aller la poule, mais tu prendras les petits pour toi, afin que tu sois heureux et que tu prolonges tes jours.
8 Nígbà tí o bá kọ́ ilé tuntun, mọ odi yí òrùlé rẹ̀ ká nítorí kí o má ba à mú ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ wá sórí ilẹ̀ rẹ bí ẹnikẹ́ni bá ṣubú láti òrùlé.
Lorsque tu construiras une nouvelle maison, tu feras une balustrade autour de ton toit, afin de ne pas faire couler le sang sur ta maison si quelqu'un en tombe.
9 Má ṣe gbin oríṣìí èso méjì sínú ọgbà àjàrà rẹ; bí o bá ṣe bẹ́ẹ̀, kì í ṣe èso oko tí o gbìn nìkan ṣùgbọ́n èso ọgbà àjàrà pẹ̀lú yóò bàjẹ́.
Tu ne sèmeras pas ta vigne avec deux sortes de semences, de peur que tout le fruit ne soit souillé, la semence que tu as semée et le produit de la vigne.
10 Ìwọ kò gbọdọ̀ fi akọ màlúù àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tulẹ̀ pọ̀.
Tu ne laboureras pas avec un bœuf et un âne ensemble.
11 Ìwọ kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun àgùntàn àti aṣọ funfun papọ̀.
Tu ne porteras pas de vêtements de laine et de lin tissés ensemble.
12 Kí o ṣe wajawaja sí etí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin aṣọ ìlekè rẹ.
Vous vous ferez des franges aux quatre coins du manteau dont vous vous couvrirez.
13 Bí ọkùnrin kan bá mú ìyàwó àti, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti dùbúlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, kórìíra rẹ̀,
Si un homme prend une femme, s'approche d'elle, la déteste,
14 tí ó ṣì sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sì i, tí o sì fún un ní orúkọ búburú, wí pé, “Mo fẹ́ obìnrin yìí, ṣùgbọ́n nígbà tí mo súnmọ́ ọn. Èmi kò rí àmì ìbálé rẹ̀.”
l'accuse de choses honteuses, lui donne un mauvais nom, et dit: « J'ai pris cette femme, et quand je me suis approché d'elle, je n'ai pas trouvé en elle les marques de la virginité »,
15 Nígbà náà ni baba ọmọbìnrin náà àti ìyá rẹ̀ yóò mú ẹ̀rí pé, ó ti wà ní ìbálé tẹ́lẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ìlú ní ẹnu-bodè.
le père et la mère de la jeune fille prendront les marques de la virginité de la jeune fille et les apporteront aux anciens de la ville, à la porte.
16 Baba obìnrin náà yóò wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Mo fi ọmọbìnrin mi fún ọkùnrin yìí láti fẹ́ níyàwó, ṣùgbọ́n ó kórìíra rẹ̀.
Le père de la jeune fille dira aux anciens: « J'ai donné ma fille pour femme à cet homme, et il la déteste.
17 Ní ìsinsin yìí ó ti sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí i ó sì wí pé, ‘Èmi kò rí ọmọbìnrin rẹ kí ó wà ní wúńdíá.’ Ṣùgbọ́n níhìn-ín yìí ni ẹ̀rí ìbálé ọmọbìnrin mi.” Nígbà náà ni àwọn òbí rẹ̀ yóò fi aṣọ hàn níwájú àwọn àgbàgbà ìlú,
Voici qu'il l'a accusée de choses honteuses, en disant: « Je n'ai pas trouvé dans ta fille les signes de la virginité »; or, voici les signes de la virginité de ma fille. » Ils étendront le linge devant les anciens de la ville.
18 àwọn àgbàgbà yóò sì mú ọkùnrin náà, wọn yóò sì jẹ ní yà.
Les anciens de cette ville prendront l'homme et le châtieront.
19 Wọn yóò sì gba ìtánràn ọgọ́rùn-ún ṣékélì owó fàdákà fún baba ọmọbìnrin náà, nítorí ọkùnrin yìí ti fi orúkọ búburú fún wúńdíá Israẹli. Yóò sì máa ṣe ìyàwó rẹ̀; kò gbọdọ̀ kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ní gbogbo ayé e rẹ̀.
Ils lui infligeront une amende de cent sicles d'argent qu'ils remettront au père de la jeune fille, car il a donné un mauvais nom à une vierge d'Israël. Elle sera sa femme. Il ne pourra pas la répudier toute sa vie.
20 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀sùn náà bá jẹ́ òtítọ́ tí a kò sí rí ẹ̀rí ìbálé obìnrin náà,
Mais si cela est vrai, c'est-à-dire si les signes de virginité n'ont pas été trouvés chez la jeune fille,
21 wọn yóò mú wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé baba rẹ̀ níbẹ̀ sì ni àwọn ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò ti sọ ọ́ ní òkúta pa. Ó ti ṣe ohun ìtìjú ní Israẹli nípa ṣíṣe àgbèrè nígbà tí ó wà nílé baba rẹ̀. Ẹ ní láti pa ohun búburú kúrò láàrín yín.
on fera sortir la jeune fille à l'entrée de la maison de son père, et les gens de sa ville la lapideront, parce qu'elle a commis une folie en Israël, en se prostituant dans la maison de son père. Ainsi vous éloignerez le mal du milieu de vous.
22 Bí o bá rí ọkùnrin kan tí ó bá ìyàwó ọkùnrin mìíràn lòpọ̀, àwọn méjèèjì ní láti kú. Ẹ ní láti pa ohun búburú kúrò láàrín Israẹli.
Si un homme est trouvé couché avec une femme mariée, ils mourront tous deux, l'homme qui a couché avec la femme et la femme. Tu feras ainsi disparaître le mal d'Israël.
23 Bí ó bá ṣẹlẹ̀ wí pé ọkùnrin kan pàdé wúńdíá tí a ti fi fún ni láti fẹ́ láàrín ìlú tí ó sì lòpọ̀ pẹ̀lú u rẹ̀,
S'il y a une jeune fille vierge promise à un mari, et qu'un homme la trouve dans la ville et couche avec elle,
24 ìwọ yóò mú àwọn méjèèjì lọ sí ẹnu ibodè ìlú náà kí o sì sọ wọ́n ní òkúta pa nítorí ọmọbìnrin náà wà ní ìlú kò sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́, àti ọkùnrin náà nítorí ó ba ìyàwó ọkùnrin mìíràn jẹ́. O ní láti wẹ búburú kúrò láàrín rẹ.
vous les amènerez tous deux à la porte de cette ville, et vous les lapiderez à mort: la jeune fille, parce qu'elle n'a pas pleuré, étant dans la ville, et l'homme, parce qu'il a humilié la femme de son prochain. Ainsi vous éloignerez le mal du milieu de vous.
25 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe ìgbẹ́ ní ó ti ṣẹlẹ̀ pé ọkùnrin kan ti pàdé ọmọbìnrin tí a ti fẹ́ ṣọ́nà tí o sì fi tagbára tagbára bá a ṣe, ọkùnrin náà nìkan tí ó ṣe èyí ni yóò kú.
Mais si l'homme trouve dans les champs la femme promise au mariage, qu'il la force et couche avec elle, l'homme qui a couché avec elle mourra seul;
26 Má ṣe fi ohunkóhun ṣe ọmọbìnrin náà; kò ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó tọ́ sí ikú. Ẹjọ́ yìí rí bí i ti ẹnìkan tí a gbámú tí ó pa aládùúgbò rẹ̀.
mais vous ne ferez rien à la femme. Il n'y a dans cette dame aucun péché qui mérite la mort; car il en est de même lorsqu'un homme se lève contre son prochain et le tue;
27 Nítorí ọkùnrin náà rí ọmọbìnrin náà ní ìta ibodè, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọmọbìnrin àfẹ́sọ́nà kígbe, kò sí ẹnìkankan níbẹ̀ láti gbà á kalẹ̀.
car il l'a trouvée dans les champs, la jeune fille promise au mariage a crié, et il n'y avait personne pour la sauver.
28 Bí ó bá ṣẹlẹ̀ pé ọkùnrin pàdé wúńdíá tí kò ì tí ì ní àfẹ́sọ́nà tí ó sì fi tipátipá bá a ṣe tí a gbá wọn mú.
Si un homme trouve une jeune fille vierge, qui n'est pas fiancée, qu'il la saisisse et couche avec elle, et qu'ils soient trouvés,
29 Ó ní láti san àádọ́ta fàdákà fún baba obìnrin náà, nítorí tí ó ti bà á jẹ́. Kò lè kọ̀ ọ́ sílẹ̀ níwọ̀n ìgbà tí ó sì wà láààyè.
l'homme qui a couché avec elle donnera au père de la jeune fille cinquante sicles d'argent. Elle sera sa femme, car il l'a humiliée. Il ne pourra pas la répudier toute sa vie.
30 Ọkùnrin kò gbọdọ̀ fẹ́ ìyàwó baba rẹ̀; kò gbọdọ̀ sọ ìtẹ́ baba rẹ̀ di àìlọ́wọ̀.
Un homme ne prendra pas la femme de son père, et ne découvrira pas le pan de son père.

< Deuteronomy 22 >