< Deuteronomy 22 >

1 Bí o bá rí màlúù tàbí àgùntàn arákùnrin rẹ tí ó ń sọnù, má ṣe ṣé àìkíyèsí i rẹ̀ ṣùgbọ́n rí i dájú pé o mú padà wá fún un.
Not you will see [the] ox of countryman your or sheep his going astray and you will hide yourself from them certainly you will return them to countryman your.
2 Bí ọkùnrin náà kì í bá gbé ní tòsí rẹ tàbí bí o kò bá mọ ẹni náà, mú un lọ ilé pẹ̀lú rẹ kí o sì fi pamọ́ títí yóò fi wá a wá. Nígbà náà ni kí o fi fún un.
And if not [is] near countryman your to you and not you know him and you will gather it into [the] middle of house your and it will be with you until seeks countryman your it and you will return it to him.
3 Ṣe bákan náà tí o bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ arákùnrin rẹ tàbí aṣọ ìlekè tàbí ohunkóhun rẹ̀ tí ó sọnù. Má ṣe ṣe àìkíyèsí i rẹ̀.
And thus you will do for donkey his and thus you will do for clothing his and thus you will do for every thing lost of countryman your which it will be lost from him and you will find it not you will be able to hide yourself.
4 Bí o bá rí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tàbí màlúù arákùnrin rẹ tí o dùbúlẹ̀ sójú ọ̀nà, má ṣe ṣàìfiyèsí i rẹ̀, ràn án lọ́wọ́ láti dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀.
Not you will see [the] donkey of countryman your or ox his falling by the way and you will hide yourself from them certainly you will raise [it] up with him.
5 Obìnrin kò gbọdọ̀ wọ aṣọ ọkùnrin, tàbí kí ọkùnrin wọ aṣọ obìnrin, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ kórìíra ẹnikẹ́ni tí ó ṣe èyí.
Not it will be [the] garment[s] of a man on a woman and not he will wear a man [the] clothing of a woman for [is] [the] abomination of Yahweh God your every [one who] does these [things].
6 Bí ìwọ bá ṣe alábòápàdé ìtẹ́ ẹyẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀nà, bóyá lára igi tàbí lórí ilẹ̀, tí ìyá wọn sì jókòó lórí àwọn ọmọ, tàbí lórí àwọn ẹyin, má ṣe gbé ìyá pẹ̀lú àwọn ọmọ.
If it will be met a nest of a bird - before you by the way in any tree - or on the ground young ones or eggs and the mother [is] lying on the young ones or on the eggs not you will take the mother with the young ones.
7 Ìwọ lè gbé ọmọ, ṣùgbọ́n rí i dájú pé o jọ̀wọ́ ìyá lọ́wọ́ lọ, kí ó ba à lè dára fún ọ àti kí o lè ní ẹ̀mí gígùn.
Certainly you will let go the mother and the young ones you will take for yourself so that it may go well for you and you will prolong days.
8 Nígbà tí o bá kọ́ ilé tuntun, mọ odi yí òrùlé rẹ̀ ká nítorí kí o má ba à mú ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ wá sórí ilẹ̀ rẹ bí ẹnikẹ́ni bá ṣubú láti òrùlé.
If you will build a house new and you will make a parapet for roof your and not you will put blood on house your if he will fall [one who] falls from it.
9 Má ṣe gbin oríṣìí èso méjì sínú ọgbà àjàrà rẹ; bí o bá ṣe bẹ́ẹ̀, kì í ṣe èso oko tí o gbìn nìkan ṣùgbọ́n èso ọgbà àjàrà pẹ̀lú yóò bàjẹ́.
Not you will sow vineyard your two kinds lest it should be set apart the full produce the seed which you will sow and [the] produce of the vineyard.
10 Ìwọ kò gbọdọ̀ fi akọ màlúù àti akọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tulẹ̀ pọ̀.
Not you will plow with an ox and with a donkey together.
11 Ìwọ kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun àgùntàn àti aṣọ funfun papọ̀.
Not you will wear mixed stuff wool and linen together.
12 Kí o ṣe wajawaja sí etí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin aṣọ ìlekè rẹ.
Tassels you will make for yourself on [the] four [the] corners of covering your which you will cover with it.
13 Bí ọkùnrin kan bá mú ìyàwó àti, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti dùbúlẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, kórìíra rẹ̀,
If he will take a man a wife and he will go into her and he will hate her.
14 tí ó ṣì sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sì i, tí o sì fún un ní orúkọ búburú, wí pé, “Mo fẹ́ obìnrin yìí, ṣùgbọ́n nígbà tí mo súnmọ́ ọn. Èmi kò rí àmì ìbálé rẹ̀.”
And he will make to her deeds of words and he will send forth on her a name bad and he will say the woman this I took and I drew near to her and not I found to her virginiti.
15 Nígbà náà ni baba ọmọbìnrin náà àti ìyá rẹ̀ yóò mú ẹ̀rí pé, ó ti wà ní ìbálé tẹ́lẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ àwọn àgbàgbà ìlú ní ẹnu-bodè.
And he will take [the] father of (the young woman *Q(k)*) and mother her and they will bring forth [the] virginiti of (the young woman *Q(k)*) to [the] elders of the city the gate towards.
16 Baba obìnrin náà yóò wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Mo fi ọmọbìnrin mi fún ọkùnrin yìí láti fẹ́ níyàwó, ṣùgbọ́n ó kórìíra rẹ̀.
And he will say [the] father of (the young woman *Q(k)*) to the elders daughter my I gave to the man this to a wife and he hated her.
17 Ní ìsinsin yìí ó ti sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí i ó sì wí pé, ‘Èmi kò rí ọmọbìnrin rẹ kí ó wà ní wúńdíá.’ Ṣùgbọ́n níhìn-ín yìí ni ẹ̀rí ìbálé ọmọbìnrin mi.” Nígbà náà ni àwọn òbí rẹ̀ yóò fi aṣọ hàn níwájú àwọn àgbàgbà ìlú,
And there! he he has made deeds of words saying not I found to daughter your virginiti and these [are] [the] virginiti of daughter my and they will spread out the garment before [the] elders of the city.
18 àwọn àgbàgbà yóò sì mú ọkùnrin náà, wọn yóò sì jẹ ní yà.
And they will take [the] elders of the city that the man and they will punish him.
19 Wọn yóò sì gba ìtánràn ọgọ́rùn-ún ṣékélì owó fàdákà fún baba ọmọbìnrin náà, nítorí ọkùnrin yìí ti fi orúkọ búburú fún wúńdíá Israẹli. Yóò sì máa ṣe ìyàwó rẹ̀; kò gbọdọ̀ kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ní gbogbo ayé e rẹ̀.
And they will fine him a hundred silver and they will give [them] to [the] father of the young woman for he has sent forth a name bad on [the] virgin of Israel and of him she will become a wife not he will be able (to send away her *L(abh)*) all days his.
20 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀sùn náà bá jẹ́ òtítọ́ tí a kò sí rí ẹ̀rí ìbálé obìnrin náà,
And if truth it was the word this not they were found virginiti (for the young woman. *Q(k)*)
21 wọn yóò mú wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé baba rẹ̀ níbẹ̀ sì ni àwọn ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò ti sọ ọ́ ní òkúta pa. Ó ti ṣe ohun ìtìjú ní Israẹli nípa ṣíṣe àgbèrè nígbà tí ó wà nílé baba rẹ̀. Ẹ ní láti pa ohun búburú kúrò láàrín yín.
And they will bring out (the young woman *Q(k)*) to [the] entrance of [the] house of father her and they will stone her [the] men of city her with stones and she will die for she has done folly in Israel by acting as a prostitute [the] house of father her and you will remove the evil from midst your.
22 Bí o bá rí ọkùnrin kan tí ó bá ìyàwó ọkùnrin mìíràn lòpọ̀, àwọn méjèèjì ní láti kú. Ẹ ní láti pa ohun búburú kúrò láàrín Israẹli.
If he will be found a man lying - with a woman married of a husband and they will die also both of them the man who lay with the woman and the woman and you will remove the evil from Israel.
23 Bí ó bá ṣẹlẹ̀ wí pé ọkùnrin kan pàdé wúńdíá tí a ti fi fún ni láti fẹ́ láàrín ìlú tí ó sì lòpọ̀ pẹ̀lú u rẹ̀,
If he will be (a young woman *Q(k)*) a virgin betrothed to a man and he will find her a man in the city and he will lie with her.
24 ìwọ yóò mú àwọn méjèèjì lọ sí ẹnu ibodè ìlú náà kí o sì sọ wọ́n ní òkúta pa nítorí ọmọbìnrin náà wà ní ìlú kò sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́, àti ọkùnrin náà nítorí ó ba ìyàwó ọkùnrin mìíràn jẹ́. O ní láti wẹ búburú kúrò láàrín rẹ.
And you will bring out both of them to [the] gate of - the city that and you will stone them with stones and they will die (the young woman *Q(k)*) on [the] thing that not she cried for help in the city and the man on [the] thing that he has humiliated [the] wife of neighbor his and you will remove the evil from midst your.
25 Ṣùgbọ́n bí ó bá ṣe ìgbẹ́ ní ó ti ṣẹlẹ̀ pé ọkùnrin kan ti pàdé ọmọbìnrin tí a ti fẹ́ ṣọ́nà tí o sì fi tagbára tagbára bá a ṣe, ọkùnrin náà nìkan tí ó ṣe èyí ni yóò kú.
And if in the open country he will find the man (the young woman *Q(k)*) betrothed and he will take hold on her the man and he will lie with her and he will die the man who lay with her to only him.
26 Má ṣe fi ohunkóhun ṣe ọmọbìnrin náà; kò ṣẹ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó tọ́ sí ikú. Ẹjọ́ yìí rí bí i ti ẹnìkan tí a gbámú tí ó pa aládùúgbò rẹ̀.
(And to the young woman *Q(k)*) not you will do anything not ([belongs] to the young woman *Q(k)*) sin of death for just as he will arise someone on neighbor his and he will kill him life so the matter this.
27 Nítorí ọkùnrin náà rí ọmọbìnrin náà ní ìta ibodè, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọmọbìnrin àfẹ́sọ́nà kígbe, kò sí ẹnìkankan níbẹ̀ láti gbà á kalẹ̀.
That in the open country he found her she cried for help (the young woman *Q(k)*) betrothed and not a deliverer [belonged] to her.
28 Bí ó bá ṣẹlẹ̀ pé ọkùnrin pàdé wúńdíá tí kò ì tí ì ní àfẹ́sọ́nà tí ó sì fi tipátipá bá a ṣe tí a gbá wọn mú.
If he will find a man (a young woman *Q(k)*) a virgin who not she is betrothed and he will seize her and he will lie with her and they will be found.
29 Ó ní láti san àádọ́ta fàdákà fún baba obìnrin náà, nítorí tí ó ti bà á jẹ́. Kò lè kọ̀ ọ́ sílẹ̀ níwọ̀n ìgbà tí ó sì wà láààyè.
And he will give the man who lay with her to [the] father of (the young woman *Q(k)*) fifty silver and of him she will become a wife because that he has humiliated her not he will be able (to send away her *L(abh)*) all days his.
30 Ọkùnrin kò gbọdọ̀ fẹ́ ìyàwó baba rẹ̀; kò gbọdọ̀ sọ ìtẹ́ baba rẹ̀ di àìlọ́wọ̀.
Not he will take a man [the] wife of father his and not he will uncover [the] skirt of father his.

< Deuteronomy 22 >