< Deuteronomy 21 >

1 Tí a bá rí ọkùnrin tí a pa, ní ìdùbúlẹ̀ ní pápá nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ láti jogún, tí a kò sì mọ ẹni tí ó pa á,
Jeźliby znaleziony był zabity w ziemi, którą Pan, Bóg twój, dawa tobie, abyś ją posiadł, leżący na polu, a nie wiedziano by, kto go zabił:
2 àwọn àgbàgbà yín yóò jáde lọ láti wọn jíjìnnà ibi òkú sí ìlú tí ó wà nítòsí.
Tedy wynijdą starsi twoi, i sędziowie twoi, i rozmierzą ziemię aż do miast, które są w około onego zabitego.
3 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí òkú yóò mú ẹgbọrọ abo màlúù tí kò ì ṣiṣẹ́ rí àti tí kò sì fà nínú àjàgà rí,
A które by miasto bliższe było onego zabitego, tedy wezmą starsi miasta onego jałowicę z stada, którą jeszcze nie robiono, a która nie ciągnęła w jarzmie;
4 kí àwọn àgbàgbà ìlú náà kí wọn mú ẹgbọrọ abo màlúù náà sọ̀kalẹ̀ wá sí àfonífojì tí ó ní omi ṣíṣàn kan, tí a kò ro, tí a kò sì gbìn, kí wọn kí ó sì ṣẹ́ ọrùn ẹgbọrọ màlúù náà níbẹ̀ ní àfonífojì náà.
I zawiodą starsi tego miasta onę jałowicę w dolinę kamienistą, gdzie nigdy nie orano, ani siano, i utną tam szyję jałowicy w onej dolinie.
5 Àwọn àlùfáà, ọmọ Lefi yóò wá síwájú, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún un àti láti bùkún ní orúkọ Olúwa àti láti parí gbogbo ẹjọ́ àríyànjiyàn àti ọ̀rọ̀ ìlú.
Zatem przyjdą kapłani, synowie Lewiego; bo je obrał Pan, Bóg twój, aby mu służyli, i żeby błogosławili w imieniu Pańskiem, a według uznania ich kończyć się ma każdy spór, i każda rana.
6 Nígbà náà ni gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí yóò wẹ ọwọ́ wọn lórí ẹgbọrọ abo màlúù tí a ti kan ọrùn rẹ̀ ní àfonífojì,
Także wszyscy starsi miasta onego, które jest najbliższe zabitego, umyją ręce swoje nad jałowicą ściętą w dolinie;
7 wọn yóò sì sọ pé, “Ọwọ́ wa kò ta ẹ̀jẹ̀ yìí sílẹ̀, tàbí kí ojú wa rí i ní títa sílẹ̀.”
I oświadczą się, mówiąc: Ręce nasze nie wylały tej krwi, ani oczy nasze na to patrzały.
8 Dáríjì, Olúwa, àwọn ènìyàn rẹ ni Israẹli, tí ìwọ ti dá sílẹ̀, àti kí ìwọ má ṣe gba ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ ní àárín àwọn ènìyàn rẹ ní Israẹli. Ṣùgbọ́n kí a dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yìí jì.
Oczyść lud twój Izraelski, któryś odkupił, Panie, a nie poczytaj krwi niewinnej w pośrodku ludu twego Izraelskiego. Tedy oczyszczeni będą od onej krwi,
9 Nígbà náà ni ìwọ wẹ̀ kúrò láàrín rẹ ẹ̀bi títa ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí o ti ṣe èyí tí ó tọ́ níwájú Olúwa.
A ty odejmiesz krew niewinną z pośrodku siebie, gdy uczynisz, co prawego jest przed oczyma Pańskiemi.
10 Nígbà tí o bá lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá rẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ tí o sì mú àwọn ìgbèkùn,
Gdy też wynijdziesz na wojnę przeciw nieprzyjaciołom twoim, a podać je Pan, Bóg twój, w ręce twoje, i nabierzesz z nich więźniów;
11 tí o sì rí obìnrin tí ó dára lára àwọn ìgbèkùn, tí o sì ní ìfẹ́ sí i, o lè mu u gẹ́gẹ́ bí aya à rẹ.
A obaczysz między więźniami niewiastę nadobną, której rozmiłowawszy się, wziąłbyś ją sobie za żonę:
12 Mú u wá sí ilé e rẹ kí o sì jẹ́ kí ó fá irun orí rẹ̀, gé èékánná an rẹ̀,
Tedy ją wprowadzisz do domu swego; i ogoli głowę swoję, i obrzeże paznogcie swoje;
13 kí o sì mú aṣọ tí ó wọ̀ nígbà tí ó di ìgbèkùn sí ẹ̀gbẹ́ kan. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ń gbé ilé rẹ tí ó sì ti ṣọ̀fọ̀ baba àti ìyá rẹ̀ fún odidi oṣù kan, nígbà náà ni o lè tọ̀ ọ́ lọ kí o sì ṣe ọkọ rẹ̀ kí ó jẹ́ aya rẹ.
A złożywszy z siebie szatę, w której jest pojmana, zostanie w domu twym, a płakać będzie ojca swego, i matki swojej przez cały miesiąc: a potem wnijdziesz do niej, i będziesz mężem jej, a ona będzie tobie za żonę.
14 Bí inú rẹ̀ kò bá sì dùn sí i, jẹ́ kí ó lọ sí ibikíbi tí ó bá fẹ́. O kò gbọdọ̀ tà á tàbí lò ó bí ẹrú, lẹ́yìn ìgbà tí o ti dójútì í.
A jeźlibyć się potem nie podobała, tedy ją wolno puścisz, a żadną miarą nie sprzedasz jej za pieniądze, ani nią kupczyć będziesz, ponieważeś ją zelżył.
15 Bí ọkùnrin kan bá ní ìyàwó méjì, tí ó sì fẹ́ ọ̀kan ṣùgbọ́n tí kò fẹ́ èkejì, tí àwọn méjèèjì sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un ṣùgbọ́n tí àkọ́bí jẹ́ ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn.
Gdyby też kto miał dwie żony, jednę miłą, a drugą omierzłą, i narodziłyby mu synów, miła i omierzła, a byłby syn pierworodny omierzłej;
16 Nígbà tí ó bá ń pín ohun ìní rẹ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, kò gbọdọ̀ fi ẹ̀tọ́ àkọ́bí fún ọmọ ìyàwó tí kò fẹ́ràn.
Tedy gdy stanowić będzie za dziedzice syny swoje, dóbr swoich: nie będzie mógł dać pierworodztwa synowi miłej przed synem pierworodnym onej omierzłej;
17 Ó ní láti fi ipò ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn fun un gẹ́gẹ́ bí àkọ́bí i rẹ̀ nípa fífún un ní ìlọ́po ìpín gbogbo ohun tí ó ní. Ọmọ yẹn ni àmì àkọ́kọ́ agbára baba rẹ̀. Ẹ̀tọ́ àkọ́bí jẹ́ tirẹ̀.
Ale pirworodztwo synowi omierzłej przyzna, dawszy mu dwojaką część wszystkiego, co ma; ponieważ on jest początkiem siły jego, jego jest prawo pierworodztwa.
18 Bí ọkùnrin kan bá ní aláìgbọ́ràn tàbí ọlọ̀tẹ̀ ọmọ tí kò gbọ́rọ̀ sí baba àti ìyá rẹ̀ tí kò sì ní í gbà tí wọ́n bá ń bá a wí,
Jeźliby kto miał syna swawolnego, i krnąbrnego, któryby nie słuchał głosu ojca swego, i głosu matki swojej, a będąc strofowany, nie usłuchałby ich:
19 baba àti ìyá rẹ̀ yóò gbá a mú, wọn yóò mu wá fún àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú u rẹ̀.
Tedy go wezmą ojciec jego i matka jego, i przywiodą go do starszych miasta swego, i do bramy sądowej miejsca onego,
20 Wọn yóò sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ọmọ wa yìí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀. Kò ní gbọ́rọ̀ sí wa lẹ́nu. Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtípara ni.”
I rzeką do starszych miasta onego: Ten nasz syn jest swawolny i krnąbrny, nieposłuszny głosu naszemu, żarłok jest i pijanica;
21 Nígbà náà ni gbogbo ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò sọ ọ́ ní òkúta pa. Ìwọ yóò sì mú ìwà ibi kúrò láàrín yín, gbogbo Israẹli yóò gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n.
Tedy ukamionują go wszyscy ludzie miasta onego, i umrze; a tak odejmiesz złe z pośrodku siebie, co gdy wszystek Izrael usłyszy, bać się będą.
22 Bí ọkùnrin kan tí ó jẹ̀bi ẹ̀sùn bá ní láti kú tí ó sì kú, tí a sì gbé òkú rẹ̀ kọ́ sára igi,
A gdyby kto popełnił grzech godny śmierci, a byłby skazany na śmierć, a obwiesiłbyś go na drzewie,
23 o kò gbọdọ̀ fi òkú rẹ̀ sílẹ̀ sára igi ní gbogbo òru. Gbìyànjú láti sin ín ní ọjọ́ náà gan an, nítorí ẹni tí a bá gbé kọ́ sórí igi wà lábẹ́ ègún Ọlọ́run. Ìwọ kò gbọdọ̀ ba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún jẹ́.
Nie zostanie przez noc trup jego na drzewie, ale koniecznie pochowasz go tegoż dnia; bo przeklęstwem Bożem jest ten, co wisi. Przetoż nie będziesz plugawił ziemi twojej, którą Pan, Bóg twój, dawa tobie w dziedzictwo.

< Deuteronomy 21 >