< Deuteronomy 21 >

1 Tí a bá rí ọkùnrin tí a pa, ní ìdùbúlẹ̀ ní pápá nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ láti jogún, tí a kò sì mọ ẹni tí ó pa á,
Naar man i det Land, HERREN din Gud vil give dig i Eje, finder en liggende dræbt paa Marken, uden at det vides, hvem der har slaaet ham ihjel,
2 àwọn àgbàgbà yín yóò jáde lọ láti wọn jíjìnnà ibi òkú sí ìlú tí ó wà nítòsí.
da skal dine Ældste og Dommere gaa ud og maale Afstanden til de Byer, som ligger rundt om den dræbte.
3 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí òkú yóò mú ẹgbọrọ abo màlúù tí kò ì ṣiṣẹ́ rí àti tí kò sì fà nínú àjàgà rí,
Derpaa skal de Ældste i den By, der ligger nærmest ved den dræbte, tage en Kvie, som ikke har været brugt til Arbejde eller baaret Aag,
4 kí àwọn àgbàgbà ìlú náà kí wọn mú ẹgbọrọ abo màlúù náà sọ̀kalẹ̀ wá sí àfonífojì tí ó ní omi ṣíṣàn kan, tí a kò ro, tí a kò sì gbìn, kí wọn kí ó sì ṣẹ́ ọrùn ẹgbọrọ màlúù náà níbẹ̀ ní àfonífojì náà.
og Byens Ældste skal trække Kvien ned i en Dal med stedserindende Vand, som ikke dyrkes og besaaes, og der i Dalen skal de sønderbryde Nakken paa Kvien.
5 Àwọn àlùfáà, ọmọ Lefi yóò wá síwájú, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún un àti láti bùkún ní orúkọ Olúwa àti láti parí gbogbo ẹjọ́ àríyànjiyàn àti ọ̀rọ̀ ìlú.
Saa skal Præsterne, Levis Sønner, træde til — thi dem har HERREN din Gud udvalgt til sin Tjeneste og til at velsigne i HERRENS Navn, og efter deres Ord skal al Trætte og enhver Sag, der vedrører Legemsskade, afgøres —
6 Nígbà náà ni gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí yóò wẹ ọwọ́ wọn lórí ẹgbọrọ abo màlúù tí a ti kan ọrùn rẹ̀ ní àfonífojì,
og alle de Ældste i den By, der ligger nærmest ved den dræbte, skal tvætte deres hænder over Kvien, hvis Nakke blev sønderbrudt i Dalen,
7 wọn yóò sì sọ pé, “Ọwọ́ wa kò ta ẹ̀jẹ̀ yìí sílẹ̀, tàbí kí ojú wa rí i ní títa sílẹ̀.”
og bekende: »Vore Hænder har ikke udgydt dette Blod, og vore Øjne har ikke set det!
8 Dáríjì, Olúwa, àwọn ènìyàn rẹ ni Israẹli, tí ìwọ ti dá sílẹ̀, àti kí ìwọ má ṣe gba ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ ní àárín àwọn ènìyàn rẹ ní Israẹli. Ṣùgbọ́n kí a dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yìí jì.
Tilgiv, HERRE, dit Folk Israel, som du udløste, og lad ikke dit Folk Israel undgælde for det uskyldige Blod!« Saa skal der skaffes dem Soning for Blodskylden.
9 Nígbà náà ni ìwọ wẹ̀ kúrò láàrín rẹ ẹ̀bi títa ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí o ti ṣe èyí tí ó tọ́ níwájú Olúwa.
Du skal skaffe det uskyldige Blod bort fra dig. Det skal gaa dig vel, naar du gør, hvad der er ret i HERRENS Øjne.
10 Nígbà tí o bá lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá rẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ tí o sì mú àwọn ìgbèkùn,
Naar du drager i Krig mod dine Fjender, og HERREN din Gud giver dem i din Haand, og du tager Fanger iblandt dem
11 tí o sì rí obìnrin tí ó dára lára àwọn ìgbèkùn, tí o sì ní ìfẹ́ sí i, o lè mu u gẹ́gẹ́ bí aya à rẹ.
og blandt Fangerne faar Øje paa en Kvinde, som ser godt ud, og faar Kærlighed til hende og ønsker at tage hende til Ægte,
12 Mú u wá sí ilé e rẹ kí o sì jẹ́ kí ó fá irun orí rẹ̀, gé èékánná an rẹ̀,
da skal du føre hende ind i dit Hus, og hun skal klippe sit Haar af, skære sine Negle,
13 kí o sì mú aṣọ tí ó wọ̀ nígbà tí ó di ìgbèkùn sí ẹ̀gbẹ́ kan. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ń gbé ilé rẹ tí ó sì ti ṣọ̀fọ̀ baba àti ìyá rẹ̀ fún odidi oṣù kan, nígbà náà ni o lè tọ̀ ọ́ lọ kí o sì ṣe ọkọ rẹ̀ kí ó jẹ́ aya rẹ.
aflægge sin Fangedragt og opholde sig en Maanedstid i dit Hus og græde over sin Fader og Moder. Saa kan du gaa ind til hende og ægte hende, saa hun bliver din Hustru.
14 Bí inú rẹ̀ kò bá sì dùn sí i, jẹ́ kí ó lọ sí ibikíbi tí ó bá fẹ́. O kò gbọdọ̀ tà á tàbí lò ó bí ẹrú, lẹ́yìn ìgbà tí o ti dójútì í.
Men hvis du ikke mere synes om hende, skal du give hende fri, du maa ikke sælge hende for Penge; du maa ikke være hensynsløs imod hende, eftersom du har krænket hende.
15 Bí ọkùnrin kan bá ní ìyàwó méjì, tí ó sì fẹ́ ọ̀kan ṣùgbọ́n tí kò fẹ́ èkejì, tí àwọn méjèèjì sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un ṣùgbọ́n tí àkọ́bí jẹ́ ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn.
Naar en Mand har to Hustruer, en han elsker, og en han tilsidesætter, og de føder ham Sønner, baade Yndlingshustruen og den tilsidesatte, og den førstefødte er den tilsidesattes Søn,
16 Nígbà tí ó bá ń pín ohun ìní rẹ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, kò gbọdọ̀ fi ẹ̀tọ́ àkọ́bí fún ọmọ ìyàwó tí kò fẹ́ràn.
saa maa Manden, naar han skifter sin Ejendom mellem Sønnerne, ikke give Yndlingshustruens Søn Førstefødselsretten til Skade for den førstefødte, den tilsidesattes Søn.
17 Ó ní láti fi ipò ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn fun un gẹ́gẹ́ bí àkọ́bí i rẹ̀ nípa fífún un ní ìlọ́po ìpín gbogbo ohun tí ó ní. Ọmọ yẹn ni àmì àkọ́kọ́ agbára baba rẹ̀. Ẹ̀tọ́ àkọ́bí jẹ́ tirẹ̀.
Men han skal anerkende den førstefødte, den tilsidesattes Søn, som førstefødt, og give ham dobbelt Del af alt, hvad han ejer; thi han er Førstegrøden af hans Manddomskraft, og hans er Førstefødselsretten.
18 Bí ọkùnrin kan bá ní aláìgbọ́ràn tàbí ọlọ̀tẹ̀ ọmọ tí kò gbọ́rọ̀ sí baba àti ìyá rẹ̀ tí kò sì ní í gbà tí wọ́n bá ń bá a wí,
Naar nogen har en vanartet og genstridig Søn, der ikke vil adlyde sine Forældres Røst og, selv naar de trygler ham, ikke adlyder dem,
19 baba àti ìyá rẹ̀ yóò gbá a mú, wọn yóò mu wá fún àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú u rẹ̀.
saa skal hans Forældre tage ham med Magt og føre ham ud til de Ældste i hans By og til Porten der
20 Wọn yóò sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ọmọ wa yìí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀. Kò ní gbọ́rọ̀ sí wa lẹ́nu. Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtípara ni.”
og sige til Byens Ældste: »Vor Søn her er vanartet og genstridig; han vil ikke adlyde os, men er en Ødeland og Drukkenbolt.«
21 Nígbà náà ni gbogbo ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò sọ ọ́ ní òkúta pa. Ìwọ yóò sì mú ìwà ibi kúrò láàrín yín, gbogbo Israẹli yóò gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n.
Derpaa skal alle Mændene i hans By stene ham til Døde. Saaledes skal du udrydde det onde af din Midte, og hele Israel skal høre det og gribes af Frygt.
22 Bí ọkùnrin kan tí ó jẹ̀bi ẹ̀sùn bá ní láti kú tí ó sì kú, tí a sì gbé òkú rẹ̀ kọ́ sára igi,
Naar en Mand har gjort sig skyldig i en Synd, der straffes med Døden, og aflives, og du hænger ham op i et Træ,
23 o kò gbọdọ̀ fi òkú rẹ̀ sílẹ̀ sára igi ní gbogbo òru. Gbìyànjú láti sin ín ní ọjọ́ náà gan an, nítorí ẹni tí a bá gbé kọ́ sórí igi wà lábẹ́ ègún Ọlọ́run. Ìwọ kò gbọdọ̀ ba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún jẹ́.
saa maa hans Lig ikke blive hængende Natten over i Træet; men du skal begrave ham samme Dag; thi en hængt er en Guds Forbandelse, og du maa ikke gøre dit Land urent, som HERREN din Gud vil give dig i Eje.

< Deuteronomy 21 >