< Deuteronomy 21 >

1 Tí a bá rí ọkùnrin tí a pa, ní ìdùbúlẹ̀ ní pápá nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ láti jogún, tí a kò sì mọ ẹni tí ó pa á,
Na Angraeng Sithaw mah qawk ah toep han nangcae khae paek ih prae thung ih ahmuen maeto ah angsong sut kami qok to oh, toe anih loe mi mah maw hum, tito panoek o ai nahaeloe,
2 àwọn àgbàgbà yín yóò jáde lọ láti wọn jíjìnnà ibi òkú sí ìlú tí ó wà nítòsí.
kacoehtanawk hoi lokcaekkungnawk to caeh o ueloe, qok ohhaih ahmuen hoiah kazoi koek vangpuinawk loe nasetto maw angthla, tito tah oh.
3 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí òkú yóò mú ẹgbọrọ abo màlúù tí kò ì ṣiṣẹ́ rí àti tí kò sì fà nínú àjàgà rí,
To pacoengah qok hoi anghnai koek vangpui ih kacoehtanawk mah, toksah vai ai laikok atokhaih thing ruet vai ai maitaw tala to la o ueloe,
4 kí àwọn àgbàgbà ìlú náà kí wọn mú ẹgbọrọ abo màlúù náà sọ̀kalẹ̀ wá sí àfonífojì tí ó ní omi ṣíṣàn kan, tí a kò ro, tí a kò sì gbìn, kí wọn kí ó sì ṣẹ́ ọrùn ẹgbọrọ màlúù náà níbẹ̀ ní àfonífojì náà.
lawk sak han vat vai ai, aanmu doeh patii vai ai azawn ah maitaw tala to caeh haih pacoengah, to ahmuen ah maitaw tala ih tahnong to aat o tih;
5 Àwọn àlùfáà, ọmọ Lefi yóò wá síwájú, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún un àti láti bùkún ní orúkọ Olúwa àti láti parí gbogbo ẹjọ́ àríyànjiyàn àti ọ̀rọ̀ ìlú.
na Angraeng Sithaw ih tok kasah, Angraeng ih ahmin hoiah tahamhoihaih paek hanah qoih ih, Levi acaeng qaimanawk angzo o ueloe, lokpunghaih hoi humhaih nuiah lok to takroek o tih:
6 Nígbà náà ni gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí yóò wẹ ọwọ́ wọn lórí ẹgbọrọ abo màlúù tí a ti kan ọrùn rẹ̀ ní àfonífojì,
qok ohhaih ahmuen hoi anghnai koek vangpui thung ih kacoehtanawk loe, to azawn ih vacong ah tahnong aah o ih maitaw tala nuiah ban to amsae o tih,
7 wọn yóò sì sọ pé, “Ọwọ́ wa kò ta ẹ̀jẹ̀ yìí sílẹ̀, tàbí kí ojú wa rí i ní títa sílẹ̀.”
hae athii loe kaicae ih ban hoiah long ai; mik hoiah doeh ka hnu o ai.
8 Dáríjì, Olúwa, àwọn ènìyàn rẹ ni Israẹli, tí ìwọ ti dá sílẹ̀, àti kí ìwọ má ṣe gba ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ ní àárín àwọn ènìyàn rẹ ní Israẹli. Ṣùgbọ́n kí a dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yìí jì.
Aw Angraeng, na krang ih Israel kaminawk hae tahmen ah; zaehaih tawn ai kami ih athii tho lu lakhaih loe nangmah ih Israel kaminawk nuiah krahsak hmah, tiah thui o tih. To tiah sah nahaeloe kami athii palonghaih to tahmen tih.
9 Nígbà náà ni ìwọ wẹ̀ kúrò láàrín rẹ ẹ̀bi títa ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí o ti ṣe èyí tí ó tọ́ níwájú Olúwa.
Angraeng mikhnuk ah kamsoem hmuen to na sak o pongah, zaehaih tawn ai kami ih athii palonghaih hoiah na ciim o tih.
10 Nígbà tí o bá lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá rẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ tí o sì mú àwọn ìgbèkùn,
Misatuk han na caeh naah, na Angraeng mah nangcae ban ah misanawk to ang paek, nihcae to tamna ah na naeh,
11 tí o sì rí obìnrin tí ó dára lára àwọn ìgbèkùn, tí o sì ní ìfẹ́ sí i, o lè mu u gẹ́gẹ́ bí aya à rẹ.
misong ah na naeh ih nongpatanawk thungah kranghoih parai nongpata maeto oh, anih to na khit parai nahaeloe, zu ah na lak thaih;
12 Mú u wá sí ilé e rẹ kí o sì jẹ́ kí ó fá irun orí rẹ̀, gé èékánná an rẹ̀,
to nongpata to na im ah caeh haih ah loe a sam to aat paeh, a banpacinnawk doeh aat paeh loe,
13 kí o sì mú aṣọ tí ó wọ̀ nígbà tí ó di ìgbèkùn sí ẹ̀gbẹ́ kan. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ń gbé ilé rẹ tí ó sì ti ṣọ̀fọ̀ baba àti ìyá rẹ̀ fún odidi oṣù kan, nígbà náà ni o lè tọ̀ ọ́ lọ kí o sì ṣe ọkọ rẹ̀ kí ó jẹ́ aya rẹ.
misong ah na naeh nathuem ih khukbuennawk to khring pae boih ah, na im ah omsak ah loe, khrahto thung amno hoi ampa dawnhaih palungsae dip pacoengah, a taengah caeh ah; nang loe anih ih sava ah om ah, anih doeh na zu ah om tih.
14 Bí inú rẹ̀ kò bá sì dùn sí i, jẹ́ kí ó lọ sí ibikíbi tí ó bá fẹ́. O kò gbọdọ̀ tà á tàbí lò ó bí ẹrú, lẹ́yìn ìgbà tí o ti dójútì í.
To pacoengah anih to na koeh ai nahaeloe, angmah koeh ah caehsak ah; toe anih to azat na paek boeh pongah, phoisa hoi zaw hmah loe, misong baktiah doeh suem hmah.
15 Bí ọkùnrin kan bá ní ìyàwó méjì, tí ó sì fẹ́ ọ̀kan ṣùgbọ́n tí kò fẹ́ èkejì, tí àwọn méjèèjì sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un ṣùgbọ́n tí àkọ́bí jẹ́ ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn.
Kami maeto mah zu hnetto tawnh; zu maeto loe palung moe, kalah maeto loe a hnukma; a palung ih zu doeh a hnukma ih zu doeh caa sak hoi hmaek; a hnukma ih zu mah anih hanah capa to sah pae hmaloe nahaeloe,
16 Nígbà tí ó bá ń pín ohun ìní rẹ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, kò gbọdọ̀ fi ẹ̀tọ́ àkọ́bí fún ọmọ ìyàwó tí kò fẹ́ràn.
to kami mah a tawnh ih qawk to a caa hnik khaeah pazet naah, a hnukma ih zu mah sak pae ih calu han paek koi qawk to, a palung kue ih zu mah sak pae ih capa hanah paek lat mak ai;
17 Ó ní láti fi ipò ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn fun un gẹ́gẹ́ bí àkọ́bí i rẹ̀ nípa fífún un ní ìlọ́po ìpín gbogbo ohun tí ó ní. Ọmọ yẹn ni àmì àkọ́kọ́ agbára baba rẹ̀. Ẹ̀tọ́ àkọ́bí jẹ́ tirẹ̀.
a hnukma ih zu mah sak ih capa loe calu ni, tiah panoek moe, a tawnh ih hmuennawk boih thung hoiah anih to alet hnetto paek han oh; to capa loe ampa thacak tangsuekhaih ah oh pongah, calu angdoethaih ahmuen loe anih ih qawk ah oh.
18 Bí ọkùnrin kan bá ní aláìgbọ́ràn tàbí ọlọ̀tẹ̀ ọmọ tí kò gbọ́rọ̀ sí baba àti ìyá rẹ̀ tí kò sì ní í gbà tí wọ́n bá ń bá a wí,
Kami maeto loe amno hoi ampa lok tahngai ai, lokaek thaih capa maeto tawnh; amno hoi ampa mah a capa thuitaek naah, lok tahngai ai nahaeloe,
19 baba àti ìyá rẹ̀ yóò gbá a mú, wọn yóò mu wá fún àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú u rẹ̀.
amno hoi ampa mah anih to naeh ueloe, kacoehtanawk ohhaih vangpui thungah caeh hoi haih tih;
20 Wọn yóò sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ọmọ wa yìí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀. Kò ní gbọ́rọ̀ sí wa lẹ́nu. Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtípara ni.”
vangpui thungah kaom kacoehtanawk khaeah, Hae ka capa loe palungthah parai moe, lok tahngai ai; ka thuih hoi ih lok doeh tahngai ai; anih loe caak amoeh moe, mu paquih thaih kami ah oh, tiah thui pae hoi tih.
21 Nígbà náà ni gbogbo ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò sọ ọ́ ní òkúta pa. Ìwọ yóò sì mú ìwà ibi kúrò láàrín yín, gbogbo Israẹli yóò gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n.
To naah to vangpui thungah kaom kaminawk boih mah anih to duek khoek to thlung hoiah va o tih; to tiah kasae hmuen to nangcae salak hoiah takhoe oh; to tiah ni Israel kaminawk boih mah thaih o naah, zii o tih.
22 Bí ọkùnrin kan tí ó jẹ̀bi ẹ̀sùn bá ní láti kú tí ó sì kú, tí a sì gbé òkú rẹ̀ kọ́ sára igi,
Kami maeto loe duek han krah zaehaih to a sak, anih loe hum han oh boeh pongah, thing nuiah bang hoiah hum nahaeloe,
23 o kò gbọdọ̀ fi òkú rẹ̀ sílẹ̀ sára igi ní gbogbo òru. Gbìyànjú láti sin ín ní ọjọ́ náà gan an, nítorí ẹni tí a bá gbé kọ́ sórí igi wà lábẹ́ ègún Ọlọ́run. Ìwọ kò gbọdọ̀ ba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún jẹ́.
kadueh qok to aqum puek thing nuiah suek han om ai, duekhaih niah aphum roep han oh; (mi kawbaktih doeh thing pongah angbang kami loe, Sithaw tangoenghaih tongh kami ah oh); na Angraeng Sithaw mah qawk ah paek ih prae to, nam hnong o sak han ai ah to tiah sak han oh.

< Deuteronomy 21 >