< Deuteronomy 21 >

1 Tí a bá rí ọkùnrin tí a pa, ní ìdùbúlẹ̀ ní pápá nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ láti jogún, tí a kò sì mọ ẹni tí ó pa á,
Ако в земята, която Господ твоят Бог ти дава да притежаваш, се намери някой убит, паднал на полето, и не се знае, кой го е убил,
2 àwọn àgbàgbà yín yóò jáde lọ láti wọn jíjìnnà ibi òkú sí ìlú tí ó wà nítòsí.
тогава старейшините ти и съдиите ти да излязат и измерят разстоянието до градовете, които са около убития;
3 Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí òkú yóò mú ẹgbọrọ abo màlúù tí kò ì ṣiṣẹ́ rí àti tí kò sì fà nínú àjàgà rí,
и старейшините на града, който е най-близо до убития, да вземат юница, с която не е работено и която не е теглила ярем;
4 kí àwọn àgbàgbà ìlú náà kí wọn mú ẹgbọrọ abo màlúù náà sọ̀kalẹ̀ wá sí àfonífojì tí ó ní omi ṣíṣàn kan, tí a kò ro, tí a kò sì gbìn, kí wọn kí ó sì ṣẹ́ ọrùn ẹgbọrọ màlúù náà níbẹ̀ ní àfonífojì náà.
и старейшините на оня град да докарат юницата в някоя долина, гдето има текуща вода, долина която не е орана нито е сеяна, и там в долината да пресекат врата на юницата.
5 Àwọn àlùfáà, ọmọ Lefi yóò wá síwájú, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún un àti láti bùkún ní orúkọ Olúwa àti láti parí gbogbo ẹjọ́ àríyànjiyàn àti ọ̀rọ̀ ìlú.
Тогава да пристъпят свещениците, Ливиевите потомци, (понеже тях избра Господ твоят Бог да Му служат, и да благославят в Господното Име, и по тяхното обяснение да се съди всеки спор и всеки побой),
6 Nígbà náà ni gbogbo àwọn àgbàgbà ìlú tí ó wà nítòsí yóò wẹ ọwọ́ wọn lórí ẹgbọrọ abo màlúù tí a ti kan ọrùn rẹ̀ ní àfonífojì,
и всичките старейшини от оня град, който е най-близо до убития, да умият ръцете си над закланата в долината юница,
7 wọn yóò sì sọ pé, “Ọwọ́ wa kò ta ẹ̀jẹ̀ yìí sílẹ̀, tàbí kí ojú wa rí i ní títa sílẹ̀.”
и да проговорят, казвайки: Нашите ръце не са пролели тая кръв, нито са видели проливането нашите очи;
8 Dáríjì, Olúwa, àwọn ènìyàn rẹ ni Israẹli, tí ìwọ ti dá sílẹ̀, àti kí ìwọ má ṣe gba ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ ní àárín àwọn ènìyàn rẹ ní Israẹli. Ṣùgbọ́n kí a dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yìí jì.
бъди милостив, Господи, на людете си Израиля, които си изкупил и не вменявай, на людете си Израиля кръв проляна без тяхна вина И кръвта ще им се прости.
9 Nígbà náà ni ìwọ wẹ̀ kúrò láàrín rẹ ẹ̀bi títa ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí o ti ṣe èyí tí ó tọ́ níwájú Olúwa.
Така да заличиш изсред себе си проляната без твоя вина кръв, когато сториш това, което е право пред Господните очи.
10 Nígbà tí o bá lọ sí ogun sí àwọn ọ̀tá rẹ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́ tí o sì mú àwọn ìgbèkùn,
Когато излезеш да воюваш против неприятелите си, и Господ твоят Бог ги предаде в ръцете ти, и вземеш от тях пленници,
11 tí o sì rí obìnrin tí ó dára lára àwọn ìgbèkùn, tí o sì ní ìfẹ́ sí i, o lè mu u gẹ́gẹ́ bí aya à rẹ.
ако видиш между пленниците красива жена, и като я залюбиш пожелаеш да я вземеш за своя жена,
12 Mú u wá sí ilé e rẹ kí o sì jẹ́ kí ó fá irun orí rẹ̀, gé èékánná an rẹ̀,
тогава да я заведеш у дома си; и тя да обръсне главата си, да изреже ноктите си
13 kí o sì mú aṣọ tí ó wọ̀ nígbà tí ó di ìgbèkùn sí ẹ̀gbẹ́ kan. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ń gbé ilé rẹ tí ó sì ti ṣọ̀fọ̀ baba àti ìyá rẹ̀ fún odidi oṣù kan, nígbà náà ni o lè tọ̀ ọ́ lọ kí o sì ṣe ọkọ rẹ̀ kí ó jẹ́ aya rẹ.
и, като съблече дрехите, в които е била пленена, да седи у дома ти да оплаква баща си и майка си цял месец; и подир това да влезеш при нея и да й бъдеш мъж, и тя да ти бъде жена.
14 Bí inú rẹ̀ kò bá sì dùn sí i, jẹ́ kí ó lọ sí ibikíbi tí ó bá fẹ́. O kò gbọdọ̀ tà á tàbí lò ó bí ẹrú, lẹ́yìn ìgbà tí o ti dójútì í.
Но ако не останеш доволен от нея, тогава да я изпратиш свободна; но да не я продаваш за пари, нито да я правиш робиня, защото си я обезчестил.
15 Bí ọkùnrin kan bá ní ìyàwó méjì, tí ó sì fẹ́ ọ̀kan ṣùgbọ́n tí kò fẹ́ èkejì, tí àwọn méjèèjì sì bí àwọn ọmọkùnrin fún un ṣùgbọ́n tí àkọ́bí jẹ́ ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn.
Ако има някой две жени, едната любима, а другата нелюбима, и му народят деца - любимата и нелюбимата, и ако първородният син е на нелюбимата,
16 Nígbà tí ó bá ń pín ohun ìní rẹ̀ fún àwọn ọmọ rẹ̀, kò gbọdọ̀ fi ẹ̀tọ́ àkọ́bí fún ọmọ ìyàwó tí kò fẹ́ràn.
тогава в деня, когато дели между синовете си имота си, не бива да направи първороден сина на любимата наместо сина на нелюбимата, който е истинският първороден;
17 Ó ní láti fi ipò ọmọ ìyàwó rẹ̀ tí kò fẹ́ràn fun un gẹ́gẹ́ bí àkọ́bí i rẹ̀ nípa fífún un ní ìlọ́po ìpín gbogbo ohun tí ó ní. Ọmọ yẹn ni àmì àkọ́kọ́ agbára baba rẹ̀. Ẹ̀tọ́ àkọ́bí jẹ́ tirẹ̀.
но да признае за първороден сина на нелюбимата и да му даде двоен дял от всичкия си имот; защото той е пръв плод на първородството.
18 Bí ọkùnrin kan bá ní aláìgbọ́ràn tàbí ọlọ̀tẹ̀ ọmọ tí kò gbọ́rọ̀ sí baba àti ìyá rẹ̀ tí kò sì ní í gbà tí wọ́n bá ń bá a wí,
Ако има някой упорит и непокорен син, който не слуша думите на баща си или думите на майка си, и при все, че те го наказват, пак той ще да ги слуша,
19 baba àti ìyá rẹ̀ yóò gbá a mú, wọn yóò mu wá fún àwọn àgbàgbà ní ẹnu-bodè ìlú u rẹ̀.
тогава баща му и майка му да го хванат и да го заведат пи старейшините на града му и при портата на местожителството му,
20 Wọn yóò sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ọmọ wa yìí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀. Kò ní gbọ́rọ̀ sí wa lẹ́nu. Ọ̀jẹun àti ọ̀mùtípara ni.”
и да кажат на старейшините на града му: Тоя наш син е упорит и непокорен; не слуша думите ни, разблуден е и пияница.
21 Nígbà náà ni gbogbo ọkùnrin ìlú rẹ̀ yóò sọ ọ́ ní òkúta pa. Ìwọ yóò sì mú ìwà ibi kúrò láàrín yín, gbogbo Israẹli yóò gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n.
Тогава всичките мъже от града му да го убият с камъни, та да умре; така да отмахнеш злото отсред себе си; и целият Израил ще чуе и ще се убои.
22 Bí ọkùnrin kan tí ó jẹ̀bi ẹ̀sùn bá ní láti kú tí ó sì kú, tí a sì gbé òkú rẹ̀ kọ́ sára igi,
Ако някой извърши престъпление, което заслужава смърт, и бъде умъртвен като го обесиш на дърво,
23 o kò gbọdọ̀ fi òkú rẹ̀ sílẹ̀ sára igi ní gbogbo òru. Gbìyànjú láti sin ín ní ọjọ́ náà gan an, nítorí ẹni tí a bá gbé kọ́ sórí igi wà lábẹ́ ègún Ọlọ́run. Ìwọ kò gbọdọ̀ ba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún jẹ́.
да не остане тялото му през цялата нощ на дървото, но непременно да го погребеш в същия ден; защото обесеният е проклет от Бога; така да не оскверниш земята, която Господ твоят Бог ти дава в наследство.

< Deuteronomy 21 >