< Deuteronomy 20 >

1 Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
Când ieşi la bătălie împotriva duşmanilor tăi şi vezi cai şi care şi un popor mai mare la număr decât tine, să nu te temi de ei, pentru că DOMNUL Dumnezeul tău, care te-a scos din ţara Egiptului, este cu tine.
2 Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
Şi va fi astfel, când vă veţi fi apropiat de bătălie, preotul să se apropie şi să vorbească poporului.
3 yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
Şi să le spună: Ascultă, Israele! Astăzi vă apropiaţi de bătălia împotriva duşmanilor voştri, să nu vă slăbească inimile; nu vă temeţi şi nu tremuraţi, nici nu vă înspăimântaţi din cauza lor.
4 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
Pentru că DOMNUL Dumnezeul vostru este cel care merge cu voi, ca să lupte pentru voi împotriva duşmanilor voştri să vă salveze.
5 Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
Şi administratorii să vorbească poporului, spunând: Cine este bărbatul care şi-a zidit o casă nouă şi nu a dedicat-o? Să plece şi să se întoarcă acasă, ca nu cumva să moară în bătălie şi să o dedice altul.
6 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
Şi cine este bărbatul care a sădit o vie şi nu a mâncat din ea? Să plece şi să se întoarcă acasă, ca nu cumva să moară în bătălie şi să mănânce altul din ea.
7 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
Şi cine este bărbatul care s-a logodit cu o femeie şi nu a luat-o? Să plece şi să se întoarcă acasă, ca nu cumva să moară în bătălie şi să o ia altul.
8 Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
Şi administratorii să mai vorbească poporului şi să spună: Cine este bărbatul care este fricos şi are inima slabă? Să plece şi să se întoarcă acasă, ca nu cumva să slăbească şi inima fraţilor săi, ca inima lui.
9 Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
Şi va fi astfel, după ce administratorii vor termina de vorbit poporului, că vor pune căpetenii ai armatelor să conducă poporul.
10 Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
Când te apropii de o cetate ca să lupţi împotriva ei, să îi oferi pace.
11 Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
Şi va fi astfel, dacă îţi va da răspuns de pace şi îţi va deschide, atunci să fie astfel, tot poporul care se află în ea să îţi fie tributar şi să îţi servească.
12 Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
Şi dacă nu va face pace cu tine, ci se va război împotriva ta, atunci să o asediezi.
13 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
Şi după ce DOMNUL Dumnezeul tău o va fi dat în mâinile tale, să loveşti fiecare parte bărbătească din ea prin ascuţişul sabiei,
14 Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
Dar pe femei şi pe micuţi şi pe vite şi tot ce este în cetate, toată prada ei, să le iei pentru tine; şi să mănânci prada duşmanilor tăi, pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău.
15 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
Astfel să faci tuturor cetăţilor, care sunt foarte departe de tine, care nu sunt dintre cetăţile acestor naţiuni.
16 Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
Dar din cetăţile acestor popoare, pe care ţi le dă DOMNUL Dumnezeul tău ca moştenire, să nu laşi viu nimic ce respiră,
17 Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
Ci să îi nimiceşti în întregime: pe hitiţi şi pe amoriţi şi pe canaaniţi şi pe periziţi, pe hiviţi şi pe iebusiţi, precum ţi-a poruncit DOMNUL Dumnezeul tău,
18 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Ca să nu vă înveţe să faceţi după toate urâciunile lor, pe care le-au făcut dumnezeilor lor, şi să păcătuiţi împotriva DOMNULUI Dumnezeul vostru.
19 Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
Când vei asedia o cetate mult timp, făcând război împotriva ei ca să o iei, să nu îi distrugi pomii dând cu securea în ei, pentru că poţi să mănânci din ei şi să nu îi retezi (pentru că pomul câmpului este viaţa omului) pentru a-i folosi în asediu,
20 Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.
Numai pomii, pe care îi cunoşti că nu sunt pomi pentru hrană, să îi distrugi şi să îi retezi; şi să ridici întărituri împotriva cetăţii care face război cu tine, până când este cucerită.

< Deuteronomy 20 >