< Deuteronomy 20 >

1 Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
Gdy wyruszysz na wojnę przeciw swoim wrogom i zobaczysz konie, rydwany i lud liczniejszy od ciebie, nie bój się ich, gdyż [jest] z tobą PAN, twój Bóg, który cię wyprowadził z ziemi Egiptu.
2 Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
A gdy będziecie się zbliżać do walki, kapłan wystąpi i przemówi do ludu;
3 yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
I powie do niego: Słuchaj, Izraelu! Dziś staczacie bitwę ze swymi wrogami. Niech wasze serce nie słabnie, nie bójcie się, nie trwóżcie ani nie lękajcie się ich;
4 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
Gdyż PAN, wasz Bóg, idzie z wami, aby za was walczyć z waszymi wrogami i was wybawić.
5 Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
Dowódcy również przemówią do ludu i powiedzą: Jeśli jest ktoś, kto zbudował nowy dom, a jeszcze go nie poświęcił, niech idzie i wraca do swego domu, aby nie zginął w bitwie i aby ktoś inny go nie poświęcił.
6 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
Albo jeśli jest ktoś, kto zasadził winnicę i jeszcze nie spożywał z niej owocu, niech idzie i wraca do swego domu, by nie zginął w bitwie i aby ktoś inny z niej nie spożywał.
7 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
Albo jeśli jest ktoś, kto poślubił żonę, a jeszcze jej nie pojął, niech idzie i wraca do swego domu, by nie zginął w bitwie i aby inny jej nie pojął.
8 Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
Dowódcy jeszcze przemówią do ludu i powiedzą: Jeśli ktoś jest bojaźliwy i lękliwego serca, niech idzie i wraca do swego domu, aby serce jego braci nie było słabe jak jego serce [jest słabe].
9 Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
A gdy dowódcy przestaną mówić do ludu, wtedy wyznaczą dowódców wojsk na czele ludu.
10 Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
Gdy podejdziesz do [jakiegoś] miasta, aby je zdobyć, zaoferujesz mu pokój.
11 Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
A jeśli odpowie ci z pokojem i otworzy ci [bramy], wtedy cały lud znajdujący się w nim stanie się twoim hołdownikiem i będzie ci służył.
12 Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
Jeśli jednak nie zawrze z tobą pokoju, lecz wznieci przeciw tobie wojnę, oblegniesz je.
13 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
A gdy PAN, twój Bóg, wyda je w twoje ręce, zabijesz w nim każdego mężczyznę ostrzem miecza.
14 Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
Tylko kobiety, dzieci, bydło oraz wszystko, co będzie w mieście, cały łup z niego, weźmiesz sobie jako zdobycz; i będziesz jadł z łupu swoich wrogów, których daje ci PAN, twój Bóg.
15 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
Tak postąpisz ze wszystkimi miastami bardzo oddalonymi od ciebie, które nie należą do miast tych narodów.
16 Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
Ale z miast tych narodów, które PAN, twój Bóg, daje ci w dziedzictwo, żadnej duszy nie zostawisz przy życiu.
17 Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
Lecz doszczętnie je wytępisz: Chetytów, Amorytów, Kananejczyków, Peryzzytów, Chiwwitów i Jebusytów, jak ci nakazał PAN, twój Bóg;
18 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Aby nie uczyli was czynić według wszystkich swoich obrzydliwości, jakie czynili swym bogom, i abyście nie zgrzeszyli przeciw PANU, swojemu Bogu.
19 Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
Gdy przez wiele dni będziesz oblegał jakieś miasto, walcząc przeciwko niemu, aby je zdobyć, nie niszcz jego drzew, wycinając je siekierą. Będziesz bowiem z nich jeść, więc nie wycinaj ich (bo drzewa polne są dla [życia] człowieka), aby ich użyć do oblężenia.
20 Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.
Tylko te drzewa, o których wiesz, że nie rodzą owoców, zniszczysz i wytniesz; i zbudujesz narzędzia przeciwko temu miastu, które z tobą walczy, aż je opanujesz.

< Deuteronomy 20 >