< Deuteronomy 20 >

1 Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
Gdy się ruszysz na wojnę przeciw nieprzyjaciołom twoim, a obaczysz konie, i wozy, i lud większy nad cię, nie bój się ich; bo Pan, Bóg twój, z tobą jest, który cię wywiódł z ziemi Egipskiej.
2 Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
A gdy się przybliżać będziecie ku potykaniu, wystąpi kapłan, i przemówi do ludu.
3 yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
A rzecze do nich: Słuchaj Izraelu, wy dziś staczacie bitwę z nieprzyjacioły waszymi; niechajże nie słabieje serce wasze, nie bójcie się i nie trwożcie sobą, ani się ich lękajcie;
4 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
Albowiem Pan, Bóg wasz, idzie z wami, aby walczył za was z nieprzyjacioły waszymi, a iżby was wybawił.
5 Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
Także mówić będą hetmani do ludu, i rzeką: Jeźliż kto jest, co zbudował dom nowy, a w nim nie począł mieszkać, niech idzie, a wróci się do domu swego, by snać nie zginął w bitwie, a kto inny począłby w nim mieszkać.
6 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
Albo jeźli kto jest, co nasadził winnicę, a nie używał owocu z niej, niech idzie, a wróci się do domu swego, by snać nie zginął w bitwie, a kto inny używałby z niej.
7 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
Albo jeźli kto jest, co ma poślubioną żonę, a jeszcze jej nie pojął, niech idzie, a wróci się do domu swego, by snać nie zginął w bitwie, a kto inny nie pojął jej.
8 Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
Nadto hetmani mówić będą do ludu, i rzeką: Jeźli kto jest bojaźliwy, a lękliwego serca, niech idzie, a wróci się do domu swego, aby nie psował serca braci swej, jako jest zepsowane serce jego.
9 Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
A gdy przestaną hetmani mówić do ludu, tedy postawią rotmistrze wojsk przed ludem.
10 Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
Gdy przyciągniesz do jakiego miasta, abyś go dobywał, poczęstujesz je pokojem.
11 Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
A jeźliże pokój ofiarowany przyjmie, i otworzyć bramy, tedy wszystek lud znaleziony w niem będzie hołdował i służył.
12 Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
Ale jeźli nie uczyni pokoju z tobą, lecz podniesie przeciw tobie wojnę, oblężesz je.
13 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
A gdy je da Pan, Bóg twój, w rękę twoję, tedy zabijesz w niem każdego mężczyznę ostrzem miecza.
14 Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
Tylko niewiasty, i dziatki, i bydła, i wszystko, co będzie w mieście, wszystek łup jego obrócisz sobie w korzyść, i będziesz jadł łupy nieprzyjaciół twoich, które da Pan, Bóg twój, tobie.
15 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
Tak uczynisz wszystkim miastom, daleko odległym od ciebie, które nie są z miast tych narodów.
16 Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
Ale z miast narodów tych, które Pan, Bóg twój, podawa tobie w dziedzictwo, żadnej duszy żywić nie będziesz.
17 Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
Lecz do szczętu wytracisz je, Hetejczyka, Amorejczyka, Chananejczyka, i Ferezejczyka, Hewejczyka, i Jebuzejczyka, jakoć rozkazał Pan, Bóg twój;
18 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Przeto żeby nie uczyli was czynić według wszystkich obrzydliwości swoich, które czynili bogom swym, i zgrzeszylibyście przeciw Panu, Bogu waszemu.
19 Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
Gdy oblężesz jakie miasto, a przez wiele dni dobywać go będziesz, abyś je wziął, nie psuj drzewa jego, wycinając je siekierą, bo z niego jeść będziesz; przetoż go nie wycinaj, (bo azaż są ludźmi drzewa polne?) abyś ich używał do oblężenia.
20 Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.
Tylko drzewa, które obaczysz, że owocu nie rodzą, te psować będziesz i wycinać: i budować będziesz baszty przeciwko onemu miastu, które z tobą walczy, póki go nie opanujesz.

< Deuteronomy 20 >