< Deuteronomy 20 >

1 Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
Ha kivonulsz háborúba ellenségeid ellen és látsz lovat és szekeret, számosabb népet nálad, ne félj tőlük, mert az Örökkévaló, a te Istened veled van, aki fölhozott téged Egyiptom országából.
2 Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
és lesz, midőn közeledtek a csatához, akkor lépjen oda a pap és szóljon a néphez,
3 yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
és mondja nekik: Halljad Izrael! ti közeledtek ma a csatához ellenségeitek ellen, ne csüggedjen szívetek, ne féljetek, ne ijedjetek meg és ne rettegjetek tőlük.
4 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
Mert az Örökkévaló, a ti Istenetek az; aki veletek megy, hogy harcoljon értetek ellenségetekkel, hogy segítsen benneteket.
5 Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
És szóljanak a felügyelők a néphez, mondván: Ki az a férfiú, aki új házat épített és nem avatta föl? Menjen és térjen vissza házába, hogy meg ne haljon a háborúban és más férfiú avassa azt föl.
6 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
És ki az a férfiú, ki szőlőt ültetett és nem vette hasznát? Menjen és térjen vissza házába, hogy meg ne haljon a háborúban és más férfiú vegye hasznát.
7 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
És ki az a férfiú, ki eljegyzett nőt és nem vette őt el? Menjen és térjen vissza házába, hogy meg ne haljon a háborúban és más férfiú vegye el.
8 Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
Továbbá szóljanak még a felügyelők a néphez és mondják: Ki az a férfiú, aki fél és csüggedtszívű? Menjen és térjen vissza házába, hogy el ne csüggedjen testvéreinek szíve, mint az ő szíve.
9 Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
És lesz, midőn végeztek a felügyelők azzal, hogy szóljanak a néphez, akkor rendeljenek csapattiszteket a nép elé.
10 Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
Ha közeledsz egy városhoz, hogy harcolj ellene, szólítsd föl azt békére.
11 Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
És lesz, ha békével felel neked és kaput nyit neked, akkor legyen mind a nép, mely találtatik benne – legyenek neked adófizetővé és szolgáljanak neked.
12 Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
De ha nem köt békét veled, hanem háborút visel veled, akkor ostromold azt.
13 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
És midőn kezedbe adja azt az Örökkévaló, a te Istened, akkor verd le minden férfiszemélyét a kard élével.
14 Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
Csak a nőket, a gyermekeket, a barmot és mindent, ami a városban lesz, minden zsákmányát prédáld magadnak és élvezd ellenségeid zsákmányát, melyet az Örökkévaló, a te Istened neked ad.
15 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
Így tégy mind a városokkal, melyek igen távol vannak tőled, melyek nem eme népek városai közül valók.
16 Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
De eme népek városaiból, melyeket az Örökkévaló, a te Istened neked ad birtokul, ne hagyj életben egy lelket se;
17 Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
hanem pusztítsd el azokat, a Chittit, az Emórit, a Kanaánit, a Perizzit, a Chivvit és a Jevúszit, amint parancsolta neked az Örökkévaló, a te Istened.
18 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Hogy ne tanítsanak benneteket cselekedni mind az ő utálataik szerint, amit tettek ők isteneiknek és vétkeznétek az Örökkévaló, a ti Istenetek ellen.
19 Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
Ha ostromolsz egy várost hosszú időn át, harcolván ellene, hogy bevedd azt, ne pusztítsd el fáját, fejszét emelvén rá, mert ehetsz róla, de ki ne vágd azt, mert ember-e a mező fája, hogy ostrom alá jusson előtted?
20 Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.
Csak azt a fát, melyről tudod, hogy nem gyümölcsfa, azt megronthatod és kivághatod, hogy építs ostromot a város ellen, amely háborút visel veled, amíg el nem esik.

< Deuteronomy 20 >