< Deuteronomy 20 >
1 Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
Rĩrĩa mũgaathiĩ kũrũa na thũ cianyu na muone irĩ na mbarathi na ngaari cia ita na mbũtũ cia ita nyingĩ gũkĩra cianyu, mũtikanaciĩtigĩre, nĩ ũndũ Jehova Ngai wanyu, ũrĩa wamũrutire bũrũri wa Misiri, agaakorwo hamwe na inyuĩ.
2 Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
Rĩrĩa mũgaakorwo mũkuhĩrĩirie gũthiĩ mbaara, mũthĩnjĩri-Ngai nĩagakuhĩrĩria mbũtũ cia ita na aciarĩrie.
3 yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
Aciĩre atĩrĩ, “Thikĩrĩria wee Isiraeli, ũmũthĩ nĩ ũgũthiĩ mbaara-inĩ ũkarũe na thũ ciaku. Ndũgakue ngoro kana wĩtigĩre na ndũkamake kana ũinaine ũrĩ mbere yacio.
4 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
Nĩgũkorwo Jehova Ngai waku nĩwe ũgũtwarana nawe nĩguo akũrũĩrĩre kũrĩ thũ ciaku, akũhootanĩre.”
5 Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
Anene nao nĩmakooria mbũtũ ya ita atĩrĩ: “Nĩ harĩ mũndũ wakĩte nyũmba njerũ na ndamĩrugũrĩtie? Nĩarekwo acooke mũciĩ, ndagakuĩre mbaara-inĩ, nake mũndũ ũngĩ atuĩke wa kũmĩrugũria.
6 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
Nĩ harĩ mũndũ ũhaandĩte mũgũnda wa mĩthabibũ na ndambĩrĩirie gũkenera matunda maguo? Nĩarekwo ainũke ndagakuĩre mbaara-inĩ nake mũndũ ũngĩ atuĩke wa gũkenera matunda macio.
7 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
Nĩ harĩ mũndũ marĩkanĩire na mũndũ-wa-nja atĩ nĩekũmũhikia na ndamũhikĩtie? O nake nĩ ainũke ndagakuĩre mbaara-inĩ nake mũndũ-wa-nja ũcio ahikio nĩ mũndũ ũngĩ.”
8 Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
Ningĩ anene nĩmagacooka morie atĩrĩ, “Nĩ harĩ mũndũ ũretigĩra kana agakua ngoro? Ũcio nĩarekwo ainũke nĩgeetha ariũ a ithe o nao matigakue ngoro.”
9 Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
Rĩrĩa anene makaarĩkia kwarĩria mbũtũ cia ita-rĩ, nĩmagathuura anene a ita a gũtongoria mbũtũ icio.
10 Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
Rĩrĩa mũkaambata mũkahũũre itũũra inene, mũkaamba kũũria andũ a rĩo metĩkĩre kũgĩe thayũ.
11 Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
Mangĩgetĩkĩra na mahingũre ihingo ciao-rĩ, andũ a itũũra rĩu othe magaatuĩka a kũrutithio wĩra na hinya, mamũrutagĩre wĩra.
12 Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
Mangĩkaarega kũgĩe thayũ na mambĩrĩrie kũrũa na inyuĩ, mũgaathiũrũrũkĩria itũũra rĩu.
13 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
Rĩrĩa Jehova Ngai wanyu akaarĩneana moko-inĩ manyu-rĩ, mũkooraga arũme othe arĩa marĩ thĩinĩ warĩo.
14 Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
No ha ũhoro wa andũ-a-nja, na ciana, na mahiũ, o na kĩndũ kĩrĩa kĩngĩ gĩothe kĩrĩ thĩinĩ wa itũũra rĩu, no mũcitahe ituĩke cianyu. Na rĩrĩ, no mũhũthĩre indo icio Jehova Ngai wanyu amũheete kuuma kũrĩ thũ cianyu.
15 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
Ũguo nĩguo mũgeeka matũũra manene mothe marĩa marĩ kũraya na kũrĩa mũrĩ no ti ma ndũrĩrĩ iria irĩ gũkuhĩ na inyuĩ.
16 Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
No rĩrĩ, thĩinĩ wa matũũra manene ma ndũrĩrĩ marĩa Jehova Ngai wanyu ekũmũhe matuĩke igai rĩanyu, mũtikanatigie kĩndũ o nakĩ, kĩhihagia kana kĩrĩ muoyo.
17 Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
Mũkaamaniina biũ; andũ a Ahiti, na Aamori, na Akaanani, na Aperizi, na Ahivi, na Ajebusi o ta ũrĩa Jehova Ngai wanyu aamwathĩte.
18 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Kwaga ũguo nĩmakamũruta kũrũmĩrĩra maũndũ mothe marĩ magigi marĩa mekaga makĩhooya ngai ciao, na inyuĩ nĩmũkehĩria Jehova Ngai wanyu.
19 Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
Mũngĩgaakorwo mũthiũrũrũkĩirie itũũra ihinda iraaya, mũkĩrĩhũũra nĩguo mũrĩtahe, mũtikanathũkangie mĩtĩ yarĩo na kũmĩtemanga na ithanwa, nĩ ũndũ no mũrĩe matunda mayo. Mũtikanamĩteme. Mĩtĩ ya gĩthaka ĩkĩrĩ andũ, atĩ nĩguo mũmĩthiũrũrũkĩrie?
20 Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.
No rĩrĩ, no mũteme mĩtĩ ĩrĩa mũkũmenya atĩ ti ya matunda, na mũmĩtũmĩre gwĩthondekera mwĩgitio wa rũirigo nginya itũũra rĩu rĩrarũa na inyuĩ rĩgwe.