< Deuteronomy 20 >

1 Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
Lorsque tu sortiras pour combattre tes ennemis, et que tu verras des chevaux, des chars et un peuple plus nombreux que toi, tu ne les craindras pas, car l'Éternel, ton Dieu, qui t'a fait monter du pays d'Égypte, est avec toi.
2 Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
Lorsque vous approcherez de la bataille, le prêtre s'approchera et parlera au peuple,
3 yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
et il lui dira: « Écoute, Israël, tu t'approches aujourd'hui de la bataille contre tes ennemis. Que ton cœur ne s'affaiblisse pas! N'aie pas peur, ne tremble pas et n'aie pas peur d'eux;
4 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
car Yahvé ton Dieu est celui qui marche avec toi, pour combattre pour toi contre tes ennemis, pour te sauver. »
5 Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
Les officiers parleront au peuple, en disant: « Quel est l'homme qui a construit une maison neuve et qui ne l'a pas consacrée? Qu'il aille et retourne dans sa maison, de peur qu'il ne meure dans la bataille et qu'un autre ne la dédie.
6 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
Quel est l'homme qui a planté une vigne, et qui n'en a pas utilisé le fruit? Qu'il s'en aille et retourne dans sa maison, de peur qu'il ne meure dans la bataille, et qu'un autre n'en utilise le fruit.
7 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
Quel est l'homme qui s'est engagé à épouser une femme, et qui ne l'a pas prise? Qu'il aille et retourne dans sa maison, de peur qu'il ne meure dans la bataille et qu'un autre homme ne la prenne. »
8 Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
Les officiers parleront encore au peuple, et ils diront: « Quel est l'homme qui a peur et qui est pusillanime? Qu'il s'en aille et retourne dans sa maison, de peur que le cœur de son frère ne se fonde comme son cœur. »
9 Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
Lorsque les officiers auront fini de parler au peuple, ils nommeront des chefs d'armée à la tête du peuple.
10 Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
Lorsque vous vous approchez d'une ville pour la combattre, annoncez-lui la paix.
11 Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
Si elle te donne une réponse de paix et s'ouvre à toi, tous les habitants qui s'y trouvent deviendront tes travailleurs forcés et te serviront.
12 Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
S'il ne veut pas faire la paix avec toi, mais te faire la guerre, tu l'assiégeras.
13 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
Lorsque Yahvé, ton Dieu, la livrera entre tes mains, tu en frapperas tous les mâles du tranchant de l'épée.
14 Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
Mais tu prendras pour toi les femmes, les petits enfants, le bétail, tout ce qui se trouve dans la ville et tout son butin. Tu pourras utiliser le butin de tes ennemis, que Yahvé ton Dieu t'a donné.
15 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
Tu feras ainsi à toutes les villes qui sont très éloignées de toi et qui ne font pas partie des villes de ces peuples.
16 Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
Mais parmi les villes de ces peuples que l'Éternel, ton Dieu, te donne en héritage, tu ne sauveras rien de ce qui respire,
17 Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
mais tu les dévoueras par interdit, le Héthien, l'Amoréen, le Cananéen, le Phérézien, le Hévien et le Jébusien, comme l'Éternel, ton Dieu, te l'a ordonné,
18 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
afin qu'ils ne t'apprennent pas à suivre toutes leurs abominations, qu'ils ont faites pour leurs dieux, et que tu ne pèches pas contre l'Éternel, ton Dieu.
19 Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
Lorsque tu assiégeras une ville pendant une longue période, en lui faisant la guerre pour la prendre, tu ne détruiras pas ses arbres en maniant la hache contre eux, car tu pourras en manger. Tu ne les couperas pas, car l'arbre des champs est-il un homme, pour que tu l'assailles?
20 Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.
Seuls les arbres dont tu sais qu'ils ne sont pas destinés à la nourriture, tu les détruiras et tu les couperas. Tu construiras des remparts contre la ville qui te fait la guerre, jusqu'à ce qu'elle tombe.

< Deuteronomy 20 >