< Deuteronomy 20 >
1 Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
"Jos lähdet sotaan vihollistasi vastaan ja näet hevosia ja sotavaunuja ja sotajoukon, joka on sinua suurempi, niin älä pelkää heitä, sillä Herra, sinun Jumalasi, on sinun kanssasi, hän, joka johdatti sinut Egyptin maasta.
2 Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
Kun olette ryhtymässä taisteluun, astukoon pappi esiin puhumaan kansalle
3 yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
ja sanokoon heille: 'Kuule, Israel! Te ryhdytte nyt taisteluun vihollisianne vastaan. Älkää arkailko, älkää peljätkö älkääkä hätääntykö, älkää säikähtykö heitä;
4 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
sillä Herra, teidän Jumalanne, käy teidän kanssanne, sotii teidän puolestanne vihollisianne vastaan ja antaa teille voiton.'
5 Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
Ja päällysmiehet puhukoot kansalle ja sanokoot: 'Joka on rakentanut uuden talon, mutta ei vielä ole sitä vihkinyt, menköön ja palatkoon kotiinsa, ettei hän kaatuisi taistelussa ja joku toinen vihkisi sitä.
6 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
Joka on istuttanut viinitarhan, mutta ei vielä ole korjannut sen ensi hedelmää, menköön ja palatkoon kotiinsa, ettei hän kaatuisi taistelussa ja joku toinen korjaisi sen ensi hedelmää.
7 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
Joka on kihlannut naisen, mutta ei vielä ole ottanut häntä vaimoksensa, menköön ja palatkoon kotiinsa, ettei hän kaatuisi taistelussa ja joku toinen ottaisi hänen morsiantaan vaimoksensa.'
8 Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
Vielä puhukoot päällysmiehet kansalle ja sanokoot: 'Joka pelkää ja arkailee, menköön ja palatkoon kotiinsa, etteivät hänen veljensäkin menettäisi rohkeuttaan niinkuin hän'.
9 Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
Ja kun päällysmiehet ovat tämän kaiken kansalle puhuneet, asettakoot he osastopäälliköt väen johtoon.
10 Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
Kun lähestyt jotakin kaupunkia sotiaksesi sitä vastaan, tarjoa sille ensin rauhaa.
11 Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
Ja jos se suostuu tarjoamaasi rauhaan ja avaa sinulle porttinsa, suorittakoon kaikki siellä oleva kansa sinulle työveroa ja palvelkoon sinua.
12 Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
Mutta jos se ei tee rauhaa sinun kanssasi, vaan valmistautuu taistelemaan sinua vastaan, niin piiritä sitä.
13 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
Ja jos Herra, sinun Jumalasi, antaa sen sinun käsiisi, niin surmaa kaikki sen miesväki miekan terällä.
14 Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
Mutta naiset, lapset ja karja ja kaikki, mitä kaupungissa on, kaikki, mitä sieltä on saatavana saalista, ryöstä itsellesi, ja nauti vihollisiltasi saatu saalis, minkä Herra, sinun Jumalasi, sinulle antaa.
15 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
Tee näin kaikille niille kaupungeille, jotka ovat sinusta hyvin kaukana, jotka eivät ole näiden kansojen kaupunkeja.
16 Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
Mutta näiden kansojen kaupungeissa, jotka Herra, sinun Jumalasi, antaa sinulle perintöosaksi, älä jätä ainoatakaan henkeä eloon,
17 Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
vaan vihi ne tuhon omiksi: heettiläiset ja amorilaiset, kanaanilaiset ja perissiläiset, hivviläiset ja jebusilaiset, niinkuin Herra, sinun Jumalasi, on sinua käskenyt,
18 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
etteivät he opettaisi teitä tekemään kaikkia niitä kauhistavia tekoja, joita he ovat tehneet palvellessaan jumaliansa, ja ettette te rikkoisi Herraa, teidän Jumalaanne, vastaan.
19 Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
Jos joudut kauan piirittämään kaupunkia ja sotimaan sitä vastaan valloittaaksesi sen, niin älä hävitä sen puita äläkä heiluta kirvestäsi niitä vastaan. Niiden hedelmiä saat nauttia, mutta älä hakkaa niitä maahan, sillä eivät kedon puut ole ihmisiä joutuakseen sinun piiritettäviksesi.
20 Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.
Ainoastaan ne puut, joista tiedät, että niissä ei ole mitään syötävää, saat hävittää ja hakata maahan, rakentaaksesi niistä varustuksia sinun kanssasi sotivaa kaupunkia vastaan, kunnes se kukistuu."