< Deuteronomy 20 >

1 Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
If thou goist out to batel ayens thin enemyes, and seest multitude of knyytis, and charis, and grettere multitude of the aduersarie oost than thou hast, thou schalt not drede hem; for thi Lord God is with thee, that ledde thee out of the lond of Egipt.
2 Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
Sotheli whanne the batel neiyeth now, the preest schal stonde bifor the scheltrun, and thus he schal speke to the puple,
3 yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
Thou, Israel, here to dai, ye han batel ayens youre enemyes; youre herte drede not, `nyle ye drede; nyle ye yyue stede, drede ye not hem;
4 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
for youre Lord God is in the myddis of you, and he schal fiyte for you ayens aduersaries, that he delyuere you fro perel.
5 Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
`Also the duykis schulen crie bi alle cumpanyes, `while the oost schal here, Who is a man that bildide a newe hows, and halewide not it? go he and turne ayen into his hows, lest perauenture he die in batel, and another man halewe it.
6 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
Who is a man that plauntide a vyner, and not yit made it to be comyn, and of which it is leeueful to alle men to ete? go he, and turne ayen in to his hows, lest perauenture he die in batel, and anothir man be set in his office.
7 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
Who is a man that spowside a wijf, and `took not hir `bi fleischli knowyng? go he, and turne ayen in to his hows, lest perauenture he die in batel, and anothir man take hir.
8 Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
Whanne these thingis ben seid, thei schulen adde othere thingis, and schulen speke to the peple, Who is a ferdful man, and of gastful herte? go he, and turne ayen in to his hows, lest he make `the hertis of his britheren for to drede, as he is agast bi drede.
9 Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
And whanne the duykis of the oost ben stille, and han maad ende of speking, ech `of the princis and cheuenteyns of the oost schal make redie his cumpeneyes to batel.
10 Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
If ony tyme thou schalt go to a citee to ouercome it, first thou schalt profire pees to it.
11 Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
If the citee resseyueth, and openeth to thee the yatis, al the puple that is ther ynne schal be saued, and schal serue thee vndur tribut.
12 Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
Sotheli if they nylen make boond of pees, and bigynnen batel ayens thee, thou schalt fiyte ayens it.
13 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
And whanne thi Lord God hath bitake it in thin hond, thou schalt smyte bi the scharpnesse of swerd al thing of male kynde which is ther ynne,
14 Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
with out wymmen, and yonge children, beestis and othere thingis that ben in the citee. Thou schalt departe al the prey to the oost, and thou schalt ete of the spuylis of thin enemyes, whiche spuylis thi Lord God yaf to thee.
15 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
Thus thou schalt do to alle the citees, that ben ful fer fro thee, and ben not of these citees which thou schalt take in to possessioun.
16 Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
Sotheli of these citees that schulen be youun to thee, thou schalt not suffre eny to lyue,
17 Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
but thou schalt sle bi the scharpnesse of swerd; that is to seie, Ethei, and Ammorrey, and Cananei, Ferezei, Euey, and Jebusei, as `thi Lord God comaundide to thee;
18 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
lest perauenture thei techen you to do alle abhomynaciouns, whiche thei wrouyten to her goddis, and ye doon synne ayens youre Lord God.
19 Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
Whanne thou hast bisegid a citee `in myche tyme, and hast cumpassid with strengthingis that thou ouercome it, thou schalt not kitte doun trees, of whiche `me may ete, nether thou schalt waste the cuntrey `bi cumpas with axis; for it is `a tree, and not man, nether it may encresse the noumbre of fiyteris ayens thee.
20 Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.
Forsothe if onye ben not appil trees, but `of the feeld, and ben able in to othere vsis, kitte doun, and make thou engynes, til thou take the citee that fiytith ayens thee.

< Deuteronomy 20 >