< Deuteronomy 20 >

1 Nígbà tí o bá lọ sí ogun pẹ̀lú ọ̀tá rẹ, tí o sì rí ẹṣin àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun àti ológun tí ó jù ọ́ lọ, má ṣe bẹ̀rù u wọn, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ń mú ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti, yóò wà pẹ̀lú rẹ.
Når du drager i Krig mod din Fjende og får Øje på Heste, Vogne og Krigsfolk, der er talrigere end du selv skal du ikke blive bange for dem; thi HERREN din Gud er med dig, han, som førte dig op fra Ægypten
2 Nígbà tí o bá fẹ́ lọ jagun, àlùfáà yóò wá síwájú, yóò sì bá ọmọ-ogun sọ̀rọ̀,
Når I rykker ud til Kamp, skal Præsten træde frem og tale til Folket,
3 yóò sì wí pé, “Gbọ́, ìwọ Israẹli, lónìí ò ń jáde lọ sójú ogun sí ọ̀tá rẹ. Ẹ má ṣe jẹ́ kí ọkàn yín ṣojo tàbí bẹ̀rù; ẹ má ṣe jáyà tàbí kí ẹ fi ààyè fún ìjayà níwájú u wọn.
og han skal sige til dem: "Hør, Israel! I rykker i Dag ud til Kamp mod eders Fjender, lad ikke eders Hjerte være forsagt, frygt ikke, forfærdes ikke og vær ikke bange for dem!
4 Nítorí Olúwa Ọlọ́run yín ní bá yín lọ, láti bá àwọn ọ̀tá yín jà fún yín, láti gbà yín là.”
Thi HERREN eders Gud drager med eder for at stride for eder mod eders Fjender og give eder Sejr."
5 Àwọn olórí ogun yóò sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó kọ́ ilé tuntun tí kò sì tì ì yà á sọ́tọ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí ó lè kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbà á.
Og Tilsynsmændene skal tale således til Folket: "Er der nogen, som har bygget et nyt Hus og endnu ikke indviet det, må han have Lov at vende hjem til sit Hus, for at ikke en anden skal indvie det, om han falder i Slaget.
6 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó gbin ọgbà àjàrà kan tí kò sì tí ì bẹ̀rẹ̀ sí ń gbádùn rẹ̀? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì gbádùn rẹ̀.
Og er der nogen, som har plantet en Vingård og ikke taget den i Brug, må han have Lov at vende hjem til sit Hus, for at ikke en anden skal tage den i Brug, om han falder i Slaget.
7 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni tí ó wá ògo obìnrin kan tí kò ì tí ì fẹ́ ẹ? Jẹ́ kí ó lọ ilé, tàbí kí ó kú sójú ogun kí ẹlòmíràn sì fẹ́ ẹ.”
Og er der nogen, som har trolovet sig med en kvinde, men endnu ikke taget hende til Hustru, må han have Lov at vende hjem til sit Hus, for at ikke en anden skal tage hende til Hustru, om han falder i Slaget."
8 Nígbà náà ni olórí yóò tún fi kún un pé, “Ǹjẹ́ ọkùnrin kankan ń bẹ̀rù tàbí páyà? Jẹ́ kí ó lọ ilé nítorí kí arákùnrin rẹ̀ má ba à wá tún dáyà fò ó.”
Og Tilsynsmændene skal fremdeles tale til Folket og sige: "Er der nogen, som er bange og forsagt, må han have Lov at vende hjem til sit Hus, for at ikke hans Brødre skal blive forsagte, som han selv er det!"
9 Nígbà tí olórí ogun bá ti dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ sí àwọn ènìyàn, wọn yóò yan olórí ogun lórí i rẹ̀.
Når så Tilsynsmandene er færdige med at tale til Folket, skal der sættes Høvedsmænd i Spidsen for Folket.
10 Nígbà tí ó bá súnmọ́ iwájú láti dojúkọ ìlú kan láti bá a jà, nígbà náà ni kí ó fi àlàáfíà lọ̀ ọ́.
Når du rykker frem til Angreb på en By, skal du først tilbyde den Fred.
11 Tí wọ́n bá dá ọ lóhùn àlàáfíà, tí wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn, gbogbo àwọn tó wà níbẹ̀ yóò máa jẹ́ olùsìn fún ọ, wọn ó sì máa sìn ọ́.
Hvis den da tager mod Fredstilbudet og åbner sine Porte for dig, skal alle Folk, som findes i den, være dine livegne og trælle for dig
12 Tí wọ́n bá kọ̀ láti bá ọ ṣe àlàáfíà ṣùgbọ́n tí wọ́n bá gbóguntì ọ́, nígbà náà ni kí ìwọ gbà á.
Vil den derimod ikke slutte Fred, men kæmpe med dig, da skal du belejre den,
13 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá fi lé ọ lọ́wọ́, kí ẹ̀yin kí ó fi ojú idà pa gbogbo àwọn ọkùnrin tí ó wà níbẹ̀.
og når HERREN din Gud giver den i din Hånd, skal du hugge alle af Mandkøn ned med Sværdet.
14 Ní ti obìnrin, àwọn ọmọdé, ohun ọ̀sìn àti gbogbo ohun tí ó kù nínú ìlú náà, o lè mú ìwọ̀nyí gẹ́gẹ́ bí ìkógun fún ara rẹ. O sì lè lo ìkógun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá rẹ.
Men Kvinderne, Børnene, Kvæget og alt, hvad der er i Byen, alt, hvad der røves i den, må du tage som Bytte, og du må gøre dig til gode med det, som røves fra dine Fjender, hvad HERREN din Gud giver dig.
15 Báyìí ni ìwọ yóò ṣe sí gbogbo ìlú tí wọ́n wà ní ọ̀nà jíjìn sí ọ tí wọn kò sì tara àwọn orílẹ̀-èdè tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ẹ̀ rẹ.
Således skal du bære dig ad med alle de Byer, som ligger langt fra dig og ikke hører til disse Folkeslags Byer her;
16 Ṣùgbọ́n, nínú àwọn ìlú ti àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, má ṣe dá ohun ẹlẹ́mìí kankan sí.
men i disse Folks Byer, som HERREN din Gud giver dig i Eje, må du ikke lade en eneste Sjæl i Live.
17 Pa wọ́n run pátápátá, àwọn ọmọ Hiti, ọmọ Amori, ọmọ Kenaani, ọmọ Peresi, ọmọ Hifi, ọmọ Jebusi gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pa á láṣẹ fún ọ.
På dem skal du lægge Band, på Hetiterne, Amoriterne, Kanånæerne, Periiterne, Hiiterne og Jebusiteme, som HERREN din Gud har pålagt dig,
18 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kọ́ ọ láti tẹ̀lé gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ń ṣe nínú sí sin àwọn ọlọ́run wọn, ìwọ yóò sì ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
for at de ikke skal lære eder at efterligne alle deres Vederstyggeligheder, som de øver til Ære for deres Guder, så I forsynder eder mod HERREN eders Gud.
19 Nígbà tí o bá dó ti ìlú kan láti ọjọ́ pípẹ́, ẹ bá wọn jà láti gbà á, má ṣe pa àwọn igi ibẹ̀ run nípa gbígbé àáké lé wọn, nítorí o lè jẹ èso wọn. Má ṣe gé wọn lulẹ̀. Nítorí igi igbó ha á ṣe ènìyàn bí, tí ìwọ ó máa dó tì rẹ̀.
Når du ved Belejringen af en By må holde den indesluttet i lang Tid for at indtage den, må du ikke ødelægge de Træer, der hører til den, ved at svinge Øksen imod dem; fra dem får du Føde; dem må du ikke hugge om; thi mon Markens Træer er Mennesker, at de også skulde rammes af Belejringen?
20 Ṣùgbọ́n ìwọ lè gé àwọn igi tí o mọ̀ pé wọn kì í ṣe igi eléso lulẹ̀ kí o sì lò wọ́n láti kọ́ ìṣọ́ sí ìlú tí ó ń bá ọ jagun, títí tí yóò fi ṣubú.
Kun Træer, du ved, ikke bærer spiselig Frugt, må du ødelægge og fælde for at bygge Belejringsværker mod den By, som er i Krig med dig, til den falder.

< Deuteronomy 20 >