< Deuteronomy 2 >

1 Nígbà náà ni a yípadà, tí a sì mú ọ̀nà wa pọ̀n lọ sí aginjù, a gba ọ̀nà Òkun Pupa, bí Olúwa ti darí mi. Ìgbà pípẹ́ ni a fi ń rìn kiri yíká agbègbè àwọn ìlú olókè Seiri.
Потом се вратисмо, и идосмо у пустињу к Црвеном Мору, као што ми заповеди Господ, и обилазисмо гору Сир дуго времена.
2 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé,
И рече ми Господ:
3 “Ẹ ti rìn yí agbègbè ilẹ̀ olókè yìí pẹ́ tó, nísinsin yìí, ẹ yípadà sí ìhà àríwá.
Доста сте обилазили ту гору, обрните се на север.
4 Fún àwọn ènìyàn náà ní àwọn òfin wọ̀nyí: ‘Ẹ ti fẹ́ la ilẹ̀ àwọn arákùnrin yín kọjá, àwọn ọmọ Esau; àwọn ará Edomu tí ń gbé ní Seiri. Ẹ̀rù yín yóò bà wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi.
И заповеди народу и реци: Сада ћете прећи преко међе браће своје, синова Исавових, који живе у Сиру; и они ће вас се бојати, али се и ви добро чувајте.
5 Ẹ má ṣe wá wọn níjà torí pé èmi kò ní fún un yín ní èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn. Bí ó ti wù kí ó kéré mọ èmi kò ní fún un yín. Mo ti fi ilẹ̀ òkè Seiri fún Esau gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.
Немојте заметати боја са њима, јер вам нећу дати земље њихове ни стопе, јер сам дао Исаву гору Сир у наследство.
6 Ẹ san owó oúnjẹ tí ẹ bá jẹ fún wọn àti omi tí ẹ bá mu.’”
Јела купујте од њих за новце, и једите; и воду купујте од њих за новце, и пијте.
7 Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín. Ó ti mójútó ìrìnàjò yín nínú aginjù ńlá yìí. Olúwa Ọlọ́run yín wà pẹ̀lú u yín ní ogójì ọdún wọ̀nyí, dé bi pé ẹ̀yin kò ṣaláìní ohunkóhun.
Јер те је Господ Бог твој благословио у сваком послу руку твојих; и зна пут твој по овој великој пустињи, и ево четрдесет година беше с тобом Господ Бог твој, и ништа ти није недостајало.
8 Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Esau tí ń gbé ní Seiri. A yà kúrò ní ọ̀nà Arabah èyí tí ó wá láti Elati àti Esioni-Geberi, a sì rìn gba ọ̀nà aginjù Moabu.
И прођосмо браћу своју, синове Исавове, који живе у Сиру, пољем од Елата и од Гесион-Гавера; и оданде савивши ударисмо преко пустиње моавске.
9 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Moabu bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Ari fún àwọn ọmọ Lọti bí i ìní.”
И Господ ми рече: Немој пакостити Моавцима ни заметати боја са њима, јер ти нећу дати земље њихове у наследство; јер дадох синовима Лотовим у наследство Ар.
10 (Àwọn Emimu ti gbé ibẹ̀ rí, àwọn ènìyàn tó síngbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Anaki.
(Пре живљаху онде Емеји, народ велик и јак и висок као Енакими;
11 Gẹ́gẹ́ bí Anaki àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Refaimu ṣùgbọ́n àwọn ará Moabu pè wọ́n ní Emimu.
О њима се мислило да су дивови као и Енакими; али их Моавци зваху Емеји.
12 Àwọn ará Hori gbé ní Seiri, kí àwọn ọmọ Esau tó lé wọn kúrò níwájú wọn. Wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, wọ́n tẹ̀dó sí ààyè wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.)
И Хореји живљаху пре у Сиру, али их синови Исавови истераше и истребише испред себе и населише се на њихово место, као што учини Израиљ у земљи свог наследства које му даде Господ.)
13 Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Seredi kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.
А сада устаните и пређите преко потока Зареда. И пређосмо преко потока Зареда.
14 Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Seredi kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrín àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrín àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.
А времена за које идосмо од Кадис-Варније па докле пређосмо преко потока Зареда, беше тридесет и осам година, докле не изумре у логору сав онај нараштај, људи за војску, као што им се беше заклео Господ.
15 Ọwọ́ Olúwa sì wà lòdì sí wọn nítòótọ́, láti run wọn kúrò nínú ibùdó, títí gbogbo wọn fi run tan.
Јер и рука Господња беше против њих потирући их из логора докле не помреше.
16 Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátápátá nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,
И кад сви ти људи за војску помреше у народу,
17 Olúwa sọ fún mi pé,
Рече ми Господ говорећи:
18 “Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbègbè Moabu kọjá ní Ari.
Ти ћеш данас прећи преко међе моавске код Ара;
19 Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ammoni, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ammoni fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọti ní ìní.”
И доћи ћеш близу синова Амонових; немој им пакостити ни заметати боја са њима, јер ти нећу дати земље амонске у наследство, јер је дадох синовима Лотовим у наследство.
20 (A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Refaimu, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ammoni ń pè wọ́n ní ará Samsummimu.
(И за њу се мислило да је земља дивовска; у њој пре живљаху дивови, које Амонци зваху Замзуми.
21 Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gogoro bí àwọn ará Anaki. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ammoni, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.
Беху народ велик и јак и висок као Енакими; али их истреби Господ испред њих, те они преузеше земљу њихову и населише се на њихово место;
22 Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Esau, tí wọ́n ń gbé ní Seiri, nígbà tí ó pa àwọn ará Hori run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.
Као што учини синовима Исавовим, који живљаху у Сиру, јер истреби Хореје испред њих, и преузеше земљу њихову и осташе на њиховом месту до данас.
23 Nípa ti àwọn ará Affimu, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèké dé Gasa, àwọn ará Kaftorimu, tí wọ́n jáde láti Krete wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)
И Авеје, који живљаху у Асироту па до Газе, истребише Кафтореји, који изађоше од Кафтора, и населише се на њихово место.)
24 “Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Arnoni. Kíyèsi, Mo ti fi Sihoni ará Amori, ọba Heṣboni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.
Устаните, идите и пређите преко потока Арнона; гле, дао сам ти у руке Сиона Аморејина, цара есевонског и земљу његову; почни узимати наследство и завојшти на њ.
25 Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdààmú ọkàn torí i tiyín.”
Данас почињем задавати страх и трепет од тебе народима под целим небом; који год чују за те, дрхтаће и препадаће се од тебе.
26 Mo rán àwọn ìránṣẹ́ láti aginjù Kedemoti lọ́ sọ́dọ̀ Sihoni ọba Heṣboni pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,
И послах посленике из пустиње Кедамота к Сиону, цару есевонском с мирним речима говорећи:
27 “Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A kò ní yà sọ́tùn tàbí sósì.
Да пређем преко твоје земље; управо ћу путем ићи, нећу свртати ни надесно ни налево.
28 Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sá à jẹ́ kí a rìn kọjá:
Храну да ми дајеш за новце да једем, и воду за новце да ми дајеш да пијем, само да прођем пешице,
29 gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Esau tí ó ń gbé ní Seiri àti àwọn ará Moabu tí ó ń gbé ní Ari, ti gbà wá láààyè títí a fi la Jordani já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”
Као што ми учинише синови Исавови који живе у Сиру, и Моавци, који живе у Ару, докле не пређем преко Јордана у земљу коју нам даје Господ Бог наш.
30 Ṣùgbọ́n Sihoni ọba Heṣboni kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.
Али не хте Сион, цар есевонски пустити да прођемо кроз његову земљу, јер Господ Бог твој учини те отврдну дух његов и срце његово поста упорно, да би га предао у твоје руке, као што се види данас.
31 Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsi i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Sihoni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”
И рече ми Господ: Гледај, почех предавати теби Сиона и земљу његову; почни узимати земљу његову да је наследиш.
32 Nígbà tí Sihoni àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jahasi,
И изиђе пред нас Сион и сав народ његов на бој у Јасу.
33 Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.
И даде нам га Господ Бог наш, и убисмо га са синовима његовим и свим народом његовим.
34 Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátápátá tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.
И узесмо тада све градове његове, и побисмо људе по свим тим градовима, и жене и децу, не остависмо живог ниједног.
35 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.
Само стоку запленисмо за се и плен што беше по градовима које узесмо.
36 Láti Aroeri, létí odò Arnoni àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gileadi, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.
Од Ароира који је на потоку Арнону, и од града који је у долини, па до Галада не беше града који би нам одолео: све то даде нам Господ Бог наш.
37 Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jabbok, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.
Само к земљи синова Амонових ниси приступио нити ка коме крају на потоку Јавоку, ни ка градовима у гори нити коме месту што је забранио Господ Бог наш.

< Deuteronomy 2 >