< Deuteronomy 2 >

1 Nígbà náà ni a yípadà, tí a sì mú ọ̀nà wa pọ̀n lọ sí aginjù, a gba ọ̀nà Òkun Pupa, bí Olúwa ti darí mi. Ìgbà pípẹ́ ni a fi ń rìn kiri yíká agbègbè àwọn ìlú olókè Seiri.
Не-ам ынторс ши ам плекат ын пустиу, пе друмул каре дуче ла Маря Рошие, кум ымь порунчисе Домнул, ши ам околит мултэ време мунтеле Сеир.
2 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé,
Домнул мь-а зис:
3 “Ẹ ti rìn yí agbègbè ilẹ̀ olókè yìí pẹ́ tó, nísinsin yìí, ẹ yípadà sí ìhà àríwá.
‘Вэ ажунӂе де кынд околиць мунтеле ачеста. Ынтоарчеци-вэ спре мязэноапте.
4 Fún àwọn ènìyàn náà ní àwọn òfin wọ̀nyí: ‘Ẹ ti fẹ́ la ilẹ̀ àwọn arákùnrin yín kọjá, àwọn ọmọ Esau; àwọn ará Edomu tí ń gbé ní Seiri. Ẹ̀rù yín yóò bà wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi.
Дэ урмэтоаря порункэ попорулуй: «Акум авець сэ тречець прин хотареле фрацилор воштри, копиий луй Есау, каре локуеск ын Сеир. Ей се вор теме де вой, дар сэ вэ пэзиць бине.
5 Ẹ má ṣe wá wọn níjà torí pé èmi kò ní fún un yín ní èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn. Bí ó ti wù kí ó kéré mọ èmi kò ní fún un yín. Mo ti fi ilẹ̀ òkè Seiri fún Esau gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.
Сэ ну вэ ынкэераць ку ей, кэч ну вэ вой да ын цара лор нич мэкар о палмэ де лок: мунтеле Сеир л-ам дат ын стэпынире луй Есау.
6 Ẹ san owó oúnjẹ tí ẹ bá jẹ fún wọn àti omi tí ẹ bá mu.’”
Сэ кумпэраць де ла ей, ку прец де арӂинт, храна пе каре о вець мынка ши сэ кумпэраць де ла ей, ку прец де арӂинт, кяр ши апа пе каре о вець бя.
7 Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín. Ó ti mójútó ìrìnàjò yín nínú aginjù ńlá yìí. Olúwa Ọlọ́run yín wà pẹ̀lú u yín ní ogójì ọdún wọ̀nyí, dé bi pé ẹ̀yin kò ṣaláìní ohunkóhun.
Кэч Домнул Думнезеул тэу те-а бинекувынтат ын тот лукрул мынилор тале ши ць-а куноскут кэлэтория ын ачест маре пустиу. Ятэ, де патрузечь де ань де кынд Домнул Думнезеул тэу есте ку тине ши н-ай дус липсэ де нимик.»’
8 Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Esau tí ń gbé ní Seiri. A yà kúrò ní ọ̀nà Arabah èyí tí ó wá láti Elati àti Esioni-Geberi, a sì rìn gba ọ̀nà aginjù Moabu.
Ам трекут пе департе де фраций ноштри, копиий луй Есау, каре локуеск ын Сеир, ши пе департе де друмул каре дуче ын кымпие, департе де Елат ши де Ецион-Гебер; апой не-ам ынторс ши ам апукат спре пустиул Моабулуй.
9 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Moabu bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Ari fún àwọn ọmọ Lọti bí i ìní.”
Домнул мь-а зис: ‘Ну фаче рэзбой ку Моаб ши ну те апука ла луптэ ку ел, кэч ну-ць вой да нимик сэ стэпынешть ын цара луй. Арул л-ам дат ын стэпынире копиилор луй Лот.
10 (Àwọn Emimu ti gbé ibẹ̀ rí, àwọn ènìyàn tó síngbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Anaki.
(Май ынаинте, аич локуяу емимий: ун попор маре, мулт ла нумэр ши де статурэ ыналтэ, ка анакимий.
11 Gẹ́gẹ́ bí Anaki àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Refaimu ṣùgbọ́n àwọn ará Moabu pè wọ́n ní Emimu.
Ей тречяу дрепт рефаимиць, ка ши анакимий, дар моабиций ый нумяу емимь.
12 Àwọn ará Hori gbé ní Seiri, kí àwọn ọmọ Esau tó lé wọn kúrò níwájú wọn. Wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, wọ́n tẹ̀dó sí ààyè wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.)
Сеир ера локуит алтэдатэ де хориць; копиий луй Есау й-ау изгонит, й-ау нимичит динаинтя лор ши с-ау ашезат ын локул лор, кум а фэкут Исраел ын цара пе каре о стэпынеште ши пе каре й-а дат-о Домнул.)
13 Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Seredi kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.
Акум скулаци-вэ ши тречець пырыул Зеред.’ Ам трекут пырыул Зеред.
14 Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Seredi kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrín àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrín àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.
Время кыт ау цинут кэлэторииле ноастре де ла Кадес-Барня пынэ ла тречеря пырыулуй Зеред а фост де трейзечь ши опт де ань, пынэ а перит дин мижлокул таберей тот нямул оаменилор де рэзбой, кум ле журасе Домнул.
15 Ọwọ́ Olúwa sì wà lòdì sí wọn nítòótọ́, láti run wọn kúrò nínú ibùdó, títí gbogbo wọn fi run tan.
Мына Домнулуй а фост ымпотрива лор, ка сэ-й нимичяскэ дин мижлокул таберей, пынэ че ау перит.
16 Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátápátá nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,
Дупэ че ау перит тоць бэрбаций де рэзбой, муринд ын мижлокул попорулуй,
17 Olúwa sọ fún mi pé,
Домнул мь-а ворбит ши а зис:
18 “Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbègbè Moabu kọjá ní Ari.
‘Сэ тречь азь хотарул Моабулуй, ла четатя Ар,
19 Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ammoni, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ammoni fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọti ní ìní.”
ши сэ те апропий де копиий луй Амон. Сэ ну фачь рэзбой ку ей ши сэ ну те ей ла луптэ ку ей, кэч ну-ць вой да нимик де стэпынит ын цара копиилор луй Амон: ам дат-о ын стэпынире копиилор луй Лот.’
20 (A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Refaimu, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ammoni ń pè wọ́n ní ará Samsummimu.
Цара ачаста тречя, де асеменя, ка о царэ а луй Рефаим; май ынаинте, локуяу ын еа рефаимиций, ши амониций ый нумяу замзумимь:
21 Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gogoro bí àwọn ará Anaki. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ammoni, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.
ун попор маре, мулт ла нумэр ши де статурэ ыналтэ, ка анакимий. Домнул й-а нимичит динаинтя амоницилор, каре й-ау изгонит ши с-ау ашезат ын локул лор.
22 Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Esau, tí wọ́n ń gbé ní Seiri, nígbà tí ó pa àwọn ará Hori run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.
(Аша а фэкут Домнул ши пентру копиий луй Есау, каре локуеск ын Сеир, кынд а нимичит пе хориць динаинтя лор; ей й-ау изгонит ши с-ау ашезат ын локул лор, пынэ ын зиуа де азь.
23 Nípa ti àwọn ará Affimu, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèké dé Gasa, àwọn ará Kaftorimu, tí wọ́n jáde láti Krete wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)
Де асеменя, авиций, каре локуяу ын сате пынэ ла Газа, ау фост нимичиць де кафториць, ешиць дин Кафтор, каре с-ау ашезат ын локул лор.)
24 “Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Arnoni. Kíyèsi, Mo ti fi Sihoni ará Amori, ọba Heṣboni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.
‘Скулаци-вэ, плекаць ши тречець пырыул Арнон. Ятэ, ыць дау ын мынь пе Сихон, ымпэратул Хесбонулуй, Аморитул, ши цара луй. Ынчепе кучериря, фэ рэзбой ку ел!
25 Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdààmú ọkàn torí i tiyín.”
Де азь ынколо, вой бэга гроаза ши фрика де тине ын тоате попоареле де суб чер; ши, ла аузул файмей тале, вор тремура ши се вор ынгрози де тине.’
26 Mo rán àwọn ìránṣẹ́ láti aginjù Kedemoti lọ́ sọ́dọ̀ Sihoni ọba Heṣboni pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,
Дин пустиул Кедемот, ам тримис соль ла Сихон, ымпэратул Хесбонулуй, ку ворбе де паче. Ам тримис сэ-й спунэ:
27 “Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A kò ní yà sọ́tùn tàbí sósì.
‘Ласэ-мэ сэ трек прин цара та; вой цине друмул маре, фэрэ сэ мэ абат нич ла дряпта, нич ла стынга.
28 Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sá à jẹ́ kí a rìn kọjá:
Сэ-мь винзь пе прец де арӂинт храна пе каре о вой мынка ши сэ-мь дай ку прец де арӂинт апа пе каре о вой бя; ну вой фаче алтчева декыт сэ трек ку пичорул,
29 gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Esau tí ó ń gbé ní Seiri àti àwọn ará Moabu tí ó ń gbé ní Ari, ti gbà wá láààyè títí a fi la Jordani já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”
лукру пе каре ми л-ау ынгэдуит копиий луй Есау каре локуеск ын Сеир ши моабиций каре локуеск ын Ар – ынгэдуе-мь ши ту лукрул ачеста, пынэ вой трече Йорданул, ка сэ интру ын цара пе каре не-о дэ Домнул Думнезеул ностру.’
30 Ṣùgbọ́n Sihoni ọba Heṣboni kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.
Дар Сихон, ымпэратул Хесбонулуй, н-а врут сэ не ласе сэ тречем пе ла ел, кэч Домнул Думнезеул тэу й-а фэкут духул неындуплекат ши й-а ымпетрит инима, ка сэ-л дя ын мыниле тале, кум везь азь.
31 Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsi i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Sihoni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”
Домнул мь-а зис: ‘Везь, акум ынчеп сэ-ць дау пе Сихон ши цара луй; ынчепе ши ту дар сэ-й ей ын стэпынире цара ка с-о моштенешть.’
32 Nígbà tí Sihoni àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jahasi,
Сихон не-а ешит ынаинте ку тот попорул луй, ка сэ лупте ымпотрива ноастрэ, ла Иахац.
33 Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.
Домнул Думнезеул ностру ни л-а дат ын мынь ши л-ам бэтут, пе ел ши пе фиий луй ши пе тот попорул луй.
34 Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátápátá tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.
Й-ам луат атунч тоате четэциле ши ле-ам нимичит ку десэвыршире: бэрбаць, фемей ши прунчь й-ам нимичит ку десэвыршире ши н-ам лэсат сэ скапе ничунул мэкар.
35 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.
Нумай вителе ле-ам рэпит пентру ной, прекум ши прада дин четэциле пе каре ле луасерэм.
36 Láti Aroeri, létí odò Arnoni àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gileadi, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.
Де ла Ароер, каре есте пе малуриле пырыулуй Арнон, ши де ла четатя каре есте ын вале пынэ ла Галаад, н-а фост ничо четате пря таре пентру ной: Домнул Думнезеул ностру ни ле-а дат пе тоате ын мынэ.
37 Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jabbok, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.
Дар де цара копиилор луй Амон ну те-ай апропият, де тоате малуриле пырыулуй Иабок, де четэциле де ла мунте ши де тоате локуриле пе каре те-а оприт Домнул Думнезеул тэу сэ ле ловешть.

< Deuteronomy 2 >