< Deuteronomy 2 >
1 Nígbà náà ni a yípadà, tí a sì mú ọ̀nà wa pọ̀n lọ sí aginjù, a gba ọ̀nà Òkun Pupa, bí Olúwa ti darí mi. Ìgbà pípẹ́ ni a fi ń rìn kiri yíká agbègbè àwọn ìlú olókè Seiri.
Thuutha ũcio tũkĩhũndũka, tũkiumagara tũrorete na werũ-inĩ, tũgĩthiĩ na njĩra ĩrĩa yerekeire Iria Itune, o ta ũrĩa Jehova anjĩĩrĩte. Tũkĩũrũũra bũrũri ũcio ũrĩ irĩma wa Seiru ihinda iraaya.
2 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé,
Nake Jehova agĩcooka akĩnjĩĩra atĩrĩ,
3 “Ẹ ti rìn yí agbègbè ilẹ̀ olókè yìí pẹ́ tó, nísinsin yìí, ẹ yípadà sí ìhà àríwá.
“Nĩmũrũũrĩte bũrũri ũyũ ũrĩ irĩma ihinda rĩa kũigana; rĩu garũrũkai mũrorete mwena wa gathigathini.
4 Fún àwọn ènìyàn náà ní àwọn òfin wọ̀nyí: ‘Ẹ ti fẹ́ la ilẹ̀ àwọn arákùnrin yín kọjá, àwọn ọmọ Esau; àwọn ará Edomu tí ń gbé ní Seiri. Ẹ̀rù yín yóò bà wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi.
Atha andũ, ũmeere atĩrĩ: ‘Mũrĩ hakuhĩ gũtuĩkanĩria bũrũri wa ariũ a ithe wanyu, njiaro cia Esaũ, arĩa matũũraga Seiru. Nĩmekũmwĩtigĩra, no inyuĩ mwĩmenyererei mũno.
5 Ẹ má ṣe wá wọn níjà torí pé èmi kò ní fún un yín ní èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn. Bí ó ti wù kí ó kéré mọ èmi kò ní fún un yín. Mo ti fi ilẹ̀ òkè Seiri fún Esau gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.
Mũtikamoogite nĩguo mũrũe, nĩgũkorwo ndikũmũhe bũrũri wao o na hanini, o na handũ mũngĩkinyithia kũgũrũ. Nĩheete Esaũ bũrũri ũcio ũrĩ irĩma wa Seiru ũtuĩke wake mwene.
6 Ẹ san owó oúnjẹ tí ẹ bá jẹ fún wọn àti omi tí ẹ bá mu.’”
Irio iria mũrĩrĩĩaga na maaĩ marĩa mũrĩnyuuaga mũrĩmarĩhaga na betha.’”
7 Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín. Ó ti mójútó ìrìnàjò yín nínú aginjù ńlá yìí. Olúwa Ọlọ́run yín wà pẹ̀lú u yín ní ogójì ọdún wọ̀nyí, dé bi pé ẹ̀yin kò ṣaláìní ohunkóhun.
Jehova Ngai wanyu nĩamũrathimĩte wĩra-inĩ wothe wa moko manyu. Nĩamũmenyereire rũgendo-inĩ rwanyu werũ-inĩ ũyũ mũnene. Mĩaka ĩyo mĩrongo ĩna ĩthirĩte, Jehova Ngai wanyu akoretwo hamwe na inyuĩ, na mũtirĩ mwaga kĩndũ o na kĩ.
8 Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Esau tí ń gbé ní Seiri. A yà kúrò ní ọ̀nà Arabah èyí tí ó wá láti Elati àti Esioni-Geberi, a sì rìn gba ọ̀nà aginjù Moabu.
Nĩ ũndũ ũcio tũgĩkĩhĩtũkĩra kũu kwa ariũ a ithe witũ, njiaro cia Esaũ, acio maatũire kũu Seiru. Nĩtwatigire barabara ya gũthiĩ Araba ĩrĩa yumĩte Elathu na Ezioni-Geberi, tũkĩnyiita barabara ya werũ ya gũthiĩ Moabi.
9 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Moabu bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Ari fún àwọn ọmọ Lọti bí i ìní.”
Ningĩ Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Ndũgathĩĩnie andũ a Moabi kana ũmogite nĩguo mũrũe, nĩgũkorwo ndikũmũhe bũrũri wao o na hanini. Nĩndĩkĩtie kũheana Ari kũrĩ njiaro cia Loti gũtuĩke igai rĩao.”
10 (Àwọn Emimu ti gbé ibẹ̀ rí, àwọn ènìyàn tó síngbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Anaki.
(Aemi nĩo maatũũraga kuo tene, andũ maarĩ hinya na aingĩ mũno, na makaraiha ta ariũ a Anaki.
11 Gẹ́gẹ́ bí Anaki àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Refaimu ṣùgbọ́n àwọn ará Moabu pè wọ́n ní Emimu.
O nao andũ acio maatuĩtwo Arefai, o ta Anaki, no andũ a Moabi maameetaga Aemi.
12 Àwọn ará Hori gbé ní Seiri, kí àwọn ọmọ Esau tó lé wọn kúrò níwájú wọn. Wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, wọ́n tẹ̀dó sí ààyè wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.)
Aahori tene maatũũraga Seiru, no njiaro cia Esaũ ikĩmarutũrũra, makiuma kuo. Njiaro cia Esaũ ikĩniina Aahori, ikĩmeeheria mbere yao, na magĩtũũra kuo ithenya rĩao, o ta ũrĩa andũ a Isiraeli meekire bũrũri-inĩ ũrĩa Jehova aamaheire megwatĩre ũtuĩke wao.)
13 Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Seredi kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.
Nake Jehova akiuga atĩrĩ, “Rĩu ũkĩrai mũringe Kĩanda gĩa Zeredi.” Nĩ ũndũ ũcio tũgĩkĩringa karũũĩ kau.
14 Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Seredi kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrín àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrín àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.
Mĩaka mĩrongo ĩtatũ na ĩnana nĩyathirire kuuma hĩndĩ ĩrĩa tuoimire Kadeshi-Barinea nginya rĩrĩa twaringire Kĩanda kĩu gĩa Zeredi. Ihinda-inĩ rĩu rũciaro ruothe rwa andũ arĩa maathiiaga ita rũgĩkorwo rũthirĩte kũu kambĩ-inĩ, o ta ũrĩa Jehova aamerĩte na mwĩhĩtwa.
15 Ọwọ́ Olúwa sì wà lòdì sí wọn nítòótọ́, láti run wọn kúrò nínú ibùdó, títí gbogbo wọn fi run tan.
Guoko kwa Jehova nĩ kwamokĩrĩire nginya hĩndĩ ĩrĩa aamaniinire biũ, magĩthira kũu kambĩ-inĩ.
16 Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátápátá nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,
Na rĩrĩ, rĩrĩa mũndũ wa mũthia gatagatĩ-inĩ ka andũ acio arĩa maathiiaga ita aakuire-rĩ,
18 “Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbègbè Moabu kọjá ní Ari.
“Ũmũthĩ nĩmũkũhĩtũkĩra Ari, bũrũri-inĩ wa Moabi.
19 Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ammoni, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ammoni fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọti ní ìní.”
Mwakinya kũrĩ Aamoni, mũtikamathĩĩnie kana mũmoogite nĩguo mũrũe, nĩgũkorwo ndikũmũhe bũrũri o na ũmwe wa Aamoni. Nĩndĩũheanĩte kũrĩ njiaro cia Loti ũtuĩke igai rĩao.”
20 (A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Refaimu, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ammoni ń pè wọ́n ní ará Samsummimu.
(O naguo ũcio watuĩtwo ta bũrũri wa Arefai, arĩa matũũrĩte kuo, no Aamoni maametaga Azamuzumi.
21 Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gogoro bí àwọn ará Anaki. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ammoni, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.
Maarĩ andũ marĩ hinya na aingĩ na makaraiha ta Aanaki. Jehova nĩamaniinire makĩeherera Aamoni, nao makĩmaingata magĩtũũra kuo ithenya rĩao.
22 Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Esau, tí wọ́n ń gbé ní Seiri, nígbà tí ó pa àwọn ará Hori run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.
Ũguo noguo Jehova eekĩire njiaro cia Esaũ arĩa maatũũrĩte Seiru, hĩndĩ ĩrĩa aaniinire Aahori mehere mbere yao. Nĩmamarutũrũrire, na nĩo matũũraga kuo ithenya rĩao nginya ũmũthĩ.
23 Nípa ti àwọn ará Affimu, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèké dé Gasa, àwọn ará Kaftorimu, tí wọ́n jáde láti Krete wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)
Nao Aavi arĩa maatũũraga tũtũũra-inĩ gũthiĩ o nginya Gaza, nĩmaniinirwo nĩ Akafitori arĩa moimĩte Kafitori, nao magĩtũũra kuo ithenya rĩao.)
24 “Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Arnoni. Kíyèsi, Mo ti fi Sihoni ará Amori, ọba Heṣboni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.
“Umagarai mũringe Kĩanda kĩa Arinoni. Na atĩrĩ, nĩneanĩte Sihoni ũrĩa, Mũamori mũthamaki wa Heshiboni, na bũrũri wake moko-inĩ manyu. Ambĩrĩriai kũrũa nake, mwĩgwatĩre bũrũri ũcio.
25 Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdààmú ọkàn torí i tiyín.”
Mũthenya ũyũ wa ũmũthĩ nĩngwambĩrĩria gũtũma andũ a ndũrĩrĩ ciothe iria itũire gũkũ thĩ inyiitwo nĩ guoya na kĩmako nĩ ũndũ wanyu. Ciaigua ũhoro wanyu nĩikũinaina na inyiitwo nĩ kĩgirĩko kĩnene nĩ ũndũ wanyu.”
26 Mo rán àwọn ìránṣẹ́ láti aginjù Kedemoti lọ́ sọ́dọ̀ Sihoni ọba Heṣboni pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,
Tũrĩ werũ-inĩ wa Kedemothu nĩndatũmire andũ kũrĩ Sihoni mũthamaki wa Heshiboni ngĩmũũria tũgĩe na thayũ, na ngĩmwĩra atĩrĩ,
27 “Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A kò ní yà sọ́tùn tàbí sósì.
“Twĩtĩkĩrie tũtuĩkanĩrie bũrũri waku. Tũkũrũmĩrĩra barabara ĩrĩa nene tũtikwahũka na mwena wa ũrĩo kana wa ũmotho.
28 Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sá à jẹ́ kí a rìn kọjá:
Twenderiei irio cia kũrĩa na maaĩ ma kũnyua, tũrĩhe na betha. No rĩrĩ, ũtwĩtĩkĩrie tũtuĩkanĩrie kũu na magũrũ,
29 gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Esau tí ó ń gbé ní Seiri àti àwọn ará Moabu tí ó ń gbé ní Ari, ti gbà wá láààyè títí a fi la Jordani já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”
o ta ũrĩa njiaro cia Esaũ iria itũũraga Seiru, na andũ a Moabi arĩa matũũraga Ari maatwĩkire, nginya tũringe Rũũĩ rwa Jorodani tũkinye bũrũri ũrĩa Jehova Ngai witũ araatũhe.”
30 Ṣùgbọ́n Sihoni ọba Heṣboni kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.
No Sihoni mũthamaki wa Heshiboni nĩaregire tũtuĩkanĩrie kuo. Nĩgũkorwo Jehova Ngai wanyu nĩatũmire roho wake ũngʼathie, na akĩũmia ngoro yake, nĩgeetha amũneane moko-inĩ manyu, o ta ũrĩa ekĩte rĩu.
31 Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsi i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Sihoni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”
Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Nĩndambĩrĩria kũneana Sihoni na bũrũri wake kũrĩ inyuĩ. Ambĩrĩriai kũmahũũra mũmatoorie, nĩgeetha mwĩgwatĩre bũrũri ũcio wake.”
32 Nígbà tí Sihoni àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jahasi,
Hĩndĩ ĩrĩa Sihoni oimagarire na mbũtũ yake yothe nĩguo acemanie na ithuĩ mbaara-inĩ kũu Jahazu,
33 Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.
Jehova Ngai witũ nĩamũneanire moko-inĩ maitũ na ithuĩ tũkĩmũhũũra, tũkĩmũũraga hamwe na ariũ ake na mbũtũ yake yothe.
34 Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátápátá tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.
Hĩndĩ ĩyo tũkĩnyiita matũũra make mothe tũkĩmaananga biũ, o na tũkĩniina arũme, na andũ-a-nja, o na ciana. Tũtiatigirie mũndũ o na ũmwe.
35 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.
No mahiũ na indo iria twaatahire kuuma matũũra macio twanyiitire nĩtweyoeire tũgĩthiĩ nacio.
36 Láti Aroeri, létí odò Arnoni àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gileadi, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.
Kuuma Aroeri mũthia-inĩ wa kĩanda kĩa Arinoni, na kuuma itũũra rĩrĩa rĩarĩ kĩanda-inĩ kĩu, nginya o Gileadi, gũtirĩ itũũra o na rĩmwe rĩatũkĩririe hinya. Jehova Ngai witũ nĩaneanire matũũra mothe kũrĩ ithuĩ.
37 Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jabbok, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.
No kũringana na watho wa Jehova Ngai witũ, mũtiigana gũkuhĩrĩria bũrũri o na ũrĩkũ wa Aamoni, kana mũgĩkuhĩrĩria bũrũri ũrĩa wariganĩtie na Rũũĩ rwa Jaboku, o na kana bũrũri ũrĩa ũthiũrũrũkĩirie matũũra marĩa marĩ irĩma-inĩ.