< Deuteronomy 2 >

1 Nígbà náà ni a yípadà, tí a sì mú ọ̀nà wa pọ̀n lọ sí aginjù, a gba ọ̀nà Òkun Pupa, bí Olúwa ti darí mi. Ìgbà pípẹ́ ni a fi ń rìn kiri yíká agbègbè àwọn ìlú olókè Seiri.
And we yeden forth fro thennus, and camen in to the wildirnesse that ledith to the Reed See, as the Lord seide to me; and we cumpassiden the hil of Seir in long tyme.
2 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé,
And the Lord seide to me, It sufficith to you to cumpasse this hil;
3 “Ẹ ti rìn yí agbègbè ilẹ̀ olókè yìí pẹ́ tó, nísinsin yìí, ẹ yípadà sí ìhà àríwá.
go ye ayens the north.
4 Fún àwọn ènìyàn náà ní àwọn òfin wọ̀nyí: ‘Ẹ ti fẹ́ la ilẹ̀ àwọn arákùnrin yín kọjá, àwọn ọmọ Esau; àwọn ará Edomu tí ń gbé ní Seiri. Ẹ̀rù yín yóò bà wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi.
And comaunde thou to the puple, and seie, Ye schulen passe bi the termes of youre britheren, the sones of Esau, that dwellen in Seir, and thei schulen drede you.
5 Ẹ má ṣe wá wọn níjà torí pé èmi kò ní fún un yín ní èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn. Bí ó ti wù kí ó kéré mọ èmi kò ní fún un yín. Mo ti fi ilẹ̀ òkè Seiri fún Esau gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.
Therfor se ye diligentli, that ye be not moued ayens hem; for Y schal not yyue to you of the land `of hem as myche as the steppe of o foot may trede, for Y yaf the hil of Seir in to the possessioun of Esau.
6 Ẹ san owó oúnjẹ tí ẹ bá jẹ fún wọn àti omi tí ẹ bá mu.’”
Ye schulden bie of hem metis for money, and ye schulen ete; ye schulden drawe, and drynke watir bouyt.
7 Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín. Ó ti mójútó ìrìnàjò yín nínú aginjù ńlá yìí. Olúwa Ọlọ́run yín wà pẹ̀lú u yín ní ogójì ọdún wọ̀nyí, dé bi pé ẹ̀yin kò ṣaláìní ohunkóhun.
Thi Lord God blesside thee in al the werk of thin hondis; he knewe thi weye, hou thou passidist this moste wildirnesse, bi fourti yeer; and thi Lord God dwellide with thee, and no thing failide to thee.
8 Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Esau tí ń gbé ní Seiri. A yà kúrò ní ọ̀nà Arabah èyí tí ó wá láti Elati àti Esioni-Geberi, a sì rìn gba ọ̀nà aginjù Moabu.
And whanne we hadden passid bi oure britheren, the sones of Esau, that dwelliden in Seir, bi the weie of the feeld of Elath, and of Asiongaber, we camen to the weie that ledith in to deseert of Moab.
9 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Moabu bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Ari fún àwọn ọmọ Lọti bí i ìní.”
And the Lord seide to me, Fiyte thou not ayens Moabitis, nether bigyn thou batel ayens hem, for Y schal not yyue to thee ony thing of the lond `of hem, for Y yaf Ar in to possessioun to `the sones of Loth.
10 (Àwọn Emimu ti gbé ibẹ̀ rí, àwọn ènìyàn tó síngbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Anaki.
Emyn, `that is, griseful men, weren first dwelleris therof, a greet puple, and strong, and so hiy, that thei weren bileued as giantis,
11 Gẹ́gẹ́ bí Anaki àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Refaimu ṣùgbọ́n àwọn ará Moabu pè wọ́n ní Emimu.
of the generacioun of Enachym, and thei weren lijk the sones of Enachym; forsothe Moabitis clepen hem Emyn.
12 Àwọn ará Hori gbé ní Seiri, kí àwọn ọmọ Esau tó lé wọn kúrò níwájú wọn. Wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, wọ́n tẹ̀dó sí ààyè wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.)
Forsothe Horreis dwelliden bifore in Seir, and whanne thei weren put out, and weren doon awey, `the sones of Esau dwelliden there, as Israel dide in the lond of his possessioun, which the Lord yaf to hym.
13 Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Seredi kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.
Therfor we riseden, that we schulden passe the stronde of Zared, and camen to it.
14 Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Seredi kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrín àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrín àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.
Sotheli the tyme in whiche we yeden fro Cades Barne `til to the passynge of the stronde of Zared, was of eiyte and thretti yeer, til al the generacioun of `men fiyteris was wastid fro `the castels, as the Lord hadde swore; whos hond was ayens hem,
15 Ọwọ́ Olúwa sì wà lòdì sí wọn nítòótọ́, láti run wọn kúrò nínú ibùdó, títí gbogbo wọn fi run tan.
that thei schulden perische fro the myddis of `the castels.
16 Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátápátá nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,
Forsothe after that alle the fiyteris felden doun,
17 Olúwa sọ fún mi pé,
the Lord spak to me, and seide,
18 “Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbègbè Moabu kọjá ní Ari.
Thou schalt passe to dai the termes of Moab,
19 Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ammoni, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ammoni fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọti ní ìní.”
the cytee, Ar bi name, and thou schalt neiy in the nyy coost of the sones of Amon; be thou war that thou fiyte not ayens hem, nether be moued to batel; for Y schal not yyue to thee of the lond of the sones of Amon, for Y yaf it to the `sones of Loth in to possessioun.
20 (A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Refaimu, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ammoni ń pè wọ́n ní ará Samsummimu.
It is arettid the lond of giauntis, and giauntis enhabitiden therynne sumtyme, whiche giauntis Amonytis clepen Zonym;
21 Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gogoro bí àwọn ará Anaki. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ammoni, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.
a myche puple and greet, and of noble lengthe, as Enachym, whiche the Lord dide awey fro the face of hem,
22 Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Esau, tí wọ́n ń gbé ní Seiri, nígbà tí ó pa àwọn ará Hori run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.
and made hem to dwelle for `tho giauntis, as he dide to the sones of Esau, that dwellen in Seire, `and dide awai Horreis, and yaf to hem the lond `of Horreis, which `the sones of Esau welden `til in to present tyme.
23 Nípa ti àwọn ará Affimu, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèké dé Gasa, àwọn ará Kaftorimu, tí wọ́n jáde láti Krete wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)
Also men of Capadocie puttiden out Eueys, that dwelliden in Asseryn, `til to Gaza; which yeden out fro Capadocie, and diden awey Eueis, and dwelliden for hem.
24 “Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Arnoni. Kíyèsi, Mo ti fi Sihoni ará Amori, ọba Heṣboni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.
Rise ye, and `passe ye the stronde of Arnon; lo! Y haue bitake in `thin hond Seon, king of Esebon, of Amorreis; and his lond bigynne thou `to welde, and smyte thou batel ayens him.
25 Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdààmú ọkàn torí i tiyín.”
To dai Y schal bigynne to sende thi drede and strengthe in to puplis that dwellen vndir al heuene, that whanne thi name is herd, thei drede, and tremble bi the maner of wymmen trauelynge of child, and `be holdun with sorewe.
26 Mo rán àwọn ìránṣẹ́ láti aginjù Kedemoti lọ́ sọ́dọ̀ Sihoni ọba Heṣboni pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,
Therfor Y sente messangeris fro the wildirnesse of Cademoch to Seon, kyng of Esebon; and Y seide with pesible wordis,
27 “Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A kò ní yà sọ́tùn tàbí sósì.
We schulen passe thorou thi lond, we schulen go in the comyn weie; we schulen not bowe nether to the riyt side, nether to the left side.
28 Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sá à jẹ́ kí a rìn kọjá:
Sille thow metis `to vs for prijs, that we ete; yif thow watir for money, and so we schulen drynke. Oneli it is that thou graunte passage to vs,
29 gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Esau tí ó ń gbé ní Seiri àti àwọn ará Moabu tí ó ń gbé ní Ari, ti gbà wá láààyè títí a fi la Jordani já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”
as the sones of Esau diden, that dwellen in Seir, and as Moabitis diden, that dwellen in Ar, til we comen to Jordan, and passen to the lond which oure Lord God schal yyue to vs.
30 Ṣùgbọ́n Sihoni ọba Heṣboni kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.
And Seon, kyng of Esebon, nolde yyue passage `to vs; for thi Lord God made hard his spirit, and made sad in yuel `the herte of hym, that he schulde be bitakun in to thin hondis, as thou seest now.
31 Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsi i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Sihoni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”
And the Lord seide to me, Lo, Y bigan to bitake to thee Seon, and his lond; bigynne thou to welde it.
32 Nígbà tí Sihoni àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jahasi,
And Seon yede out ayens vs with al his puple to batel in Jasa.
33 Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.
And oure Lord God bitook hym to vs, and we han smyte hym with hise sones, and al his puple.
34 Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátápátá tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.
And we token in that tyme alle the citees, whanne the dwelleris of tho citees, men, and wymmen, and children weren slayn; we leften not in hem ony thing,
35 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.
outakun beestis that camen in to the part of men takynge prey, and outakun spuylis of the cytees whiche we tokun.
36 Láti Aroeri, létí odò Arnoni àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gileadi, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.
Fro Aroer, which is on the brenke of the stronde of Arnon, fro the toun which is set in the valey, `til to Galaad, no town was ether citee, that ascapide oure hondis.
37 Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jabbok, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.
Oure Lord God bitook alle to vs; outakun the lond of the sones of Amon, to which lond we neiyiden not, and outakun alle thingis that liggen to the stronde of Jeboth, and outakun the citees of the munteyns, and alle places fro whiche oure Lord God forbeed vs.

< Deuteronomy 2 >