< Deuteronomy 2 >

1 Nígbà náà ni a yípadà, tí a sì mú ọ̀nà wa pọ̀n lọ sí aginjù, a gba ọ̀nà Òkun Pupa, bí Olúwa ti darí mi. Ìgbà pípẹ́ ni a fi ń rìn kiri yíká agbègbè àwọn ìlú olókè Seiri.
Te phoeiah, BOEIPA loh kai taengah a thui vanbangla n'hooi uh tih carhaek li long kah khosoek la n'caeh uh phoeiah Seir tlang n'hil uh khaw khohnin loh sen coeng.
2 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé,
Te dongah BOEIPA loh kai m'voek tih,
3 “Ẹ ti rìn yí agbègbè ilẹ̀ olókè yìí pẹ́ tó, nísinsin yìí, ẹ yípadà sí ìhà àríwá.
'Hekah tlang khaw puet na hil uh coeng. Te dongah tlangpuei ben la mael uh laeh.
4 Fún àwọn ènìyàn náà ní àwọn òfin wọ̀nyí: ‘Ẹ ti fẹ́ la ilẹ̀ àwọn arákùnrin yín kọjá, àwọn ọmọ Esau; àwọn ará Edomu tí ń gbé ní Seiri. Ẹ̀rù yín yóò bà wọ́n, ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi.
Na pilnam te khaw uen lamtah namamih loh thui pah. Seir ah aka om na manuca Esau koca rhoek kah khorhi aka paan nangmih te n'rhih uh ni. Te dongah boeih ngaithuen uh.
5 Ẹ má ṣe wá wọn níjà torí pé èmi kò ní fún un yín ní èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn. Bí ó ti wù kí ó kéré mọ èmi kò ní fún un yín. Mo ti fi ilẹ̀ òkè Seiri fún Esau gẹ́gẹ́ bí ìní rẹ̀.
Amih kah khohmuen te nangmih taengah kam paek pawt oeh dongah amih te huek boeh. Na kho khopha kah a laeh pataeng khaw Seir tlang te tah Esau kah rho lamni ka paek coeng.
6 Ẹ san owó oúnjẹ tí ẹ bá jẹ fún wọn àti omi tí ẹ bá mu.’”
Buh khaw amih taengah tah tangka neh lai uh lamtah ca uh. Tui pataeng khaw amih taengah tah tangka neh lai uh lamtah o uh.
7 Olúwa Ọlọ́run yín ti bùkún un yín nínú gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín. Ó ti mójútó ìrìnàjò yín nínú aginjù ńlá yìí. Olúwa Ọlọ́run yín wà pẹ̀lú u yín ní ogójì ọdún wọ̀nyí, dé bi pé ẹ̀yin kò ṣaláìní ohunkóhun.
Hekah khosoek khoham ah na van uh te BOEIPA na Pathen loh a ming tih na kut dongkah bitat boeih dongah BOEIPA na Pathen loh na yoe a then sak. Tahae due kum sawmli khuiah nangmih te hno loh m'vaitah moenih,’ a ti.
8 Bẹ́ẹ̀ ni a kọjá ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin wa, àwọn ọmọ Esau tí ń gbé ní Seiri. A yà kúrò ní ọ̀nà Arabah èyí tí ó wá láti Elati àti Esioni-Geberi, a sì rìn gba ọ̀nà aginjù Moabu.
Te dongah Seir ah kho aka sa mah manuca Esau koca rhoek te m'poeng uh tih kolken longpuei Elath neh Eziongeber lamkah n'hooi uh tih Moab khosoek longpuei la n'khum uh.
9 Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ẹ má ṣe dẹ́rùba àwọn ará Moabu bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe bá wọn jagun torí pé n kò ní fi èyíkéyìí nínú ilẹ̀ wọn fún un yín. Mo ti fi Ari fún àwọn ọmọ Lọti bí i ìní.”
Tedae BOEIPA loh kai taengah, 'Ar he tah Lot koca rhoek taengah rho la ka paek coeng dongah anih kah khohmuen rho te nangmih kam pae mahpawh. Te dongah Moab te dum boel lamtah amih te caem nen khaw huek boeh.
10 (Àwọn Emimu ti gbé ibẹ̀ rí, àwọn ènìyàn tó síngbọnlẹ̀ tó sì pọ̀, wọ́n ga bí àwọn Anaki.
Hlamat lamkah anih khuiah aka om Emim pilnam khaw Anakim bangla tlung khaw tlung, ping khaw ping tih bahoeng sang.
11 Gẹ́gẹ́ bí Anaki àwọn ènìyàn náà pè wọ́n ní ará Refaimu ṣùgbọ́n àwọn ará Moabu pè wọ́n ní Emimu.
Rapha te khaw Anakim bangla a poek uh dongah amih te Moab loh Emim la a khue uh.
12 Àwọn ará Hori gbé ní Seiri, kí àwọn ọmọ Esau tó lé wọn kúrò níwájú wọn. Wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn, wọ́n tẹ̀dó sí ààyè wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Israẹli tí ṣe ní ilẹ̀ tí Olúwa yóò fún wọn ní ìní wọn.)
Seir ah khaw a hmai ah Khori rhoek kho a sak uh coeng. Tedae Esau ca rhoek loh amih te a huul uh. Amih te a mikhmuh lamloh mitmoeng uh. A rho khohmuen ah Israel saii bangla amih yueng la kho a sak uh. Te te BOEIPA loh amih taengah a paek.
13 Olúwa sì wí pé, “Ẹ dìde, kí ẹ sì la àfonífojì Seredi kọjá.” Bẹ́ẹ̀ ni a la àfonífojì náà kọjá.
Tahae ah thoo uh lamtah Zered soklong te kan uh,’ a ti dongah Zered soklong te n'kan uh.
14 Ó gbà wá ní ọdún méjìdínlógójì kí ó tó di wí pé a la àfonífojì Seredi kọjá láti ìgbà tí a ti kúrò ní Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà gbogbo ìran àwọn tí ó jẹ́ jagunjagun láàrín àwọn ènìyàn náà ti ṣègbé kúrò láàrín àwọn ènìyàn náà ní àsìkò yìí bí Olúwa ti búra fún wọn.
Kadeshbarnea lamkah n'cet uh tih Zered soklong m'poeng uh duela a tue loh sawmthum neh kum rhet di coeng. BOEIPA loh a caeng vanbangla rhaehhmuen lamkah thawnpuei caemtloek hlang rhoek khaw boeih khum uh coeng.
15 Ọwọ́ Olúwa sì wà lòdì sí wọn nítòótọ́, láti run wọn kúrò nínú ibùdó, títí gbogbo wọn fi run tan.
Amih a mitmoeng uh duela rhaehhmuen khui lamkah amih aka khawkkhek la BOEIPA kut khaw amih taengah om.
16 Lẹ́yìn tí ẹni tí ó gbẹ̀yìn pátápátá nínú àwọn jagunjagun àwọn ènìyàn wọ̀nyí ti kú,
Pilnam khui lamkah caemtloek hlang boeih khaw duek tih aka boeih bangla om coeng.
17 Olúwa sọ fún mi pé,
Te dongah BOEIPA loh kai m'voek tih,
18 “Lónìí ni ẹ̀yin yóò la agbègbè Moabu kọjá ní Ari.
'Moab khorhi kah Ar te tihnin ah vawl poeng laeh.
19 Bí ẹ bá dé ọ̀dọ̀ àwọn ará Ammoni, ẹ má ṣe halẹ̀ mọ́ wọn, ẹ kò sì gbọdọ̀ bá wọn jagun, torí pé èmi kì yóò fi àwọn ilẹ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ará Ammoni fún un yín ní ìní. Mo ti fi fún àwọn ọmọ Lọti ní ìní.”
Ammon koca rhoek taengla na pawk vaengah amih te dum boeh. Caemtloek nen khaw amih te huek boeh. Ammon koca rhoek kah khohmuen te nang taengah rho la kam paek moenih Lot koca rhoek ham ni rho la ka paek.
20 (A ka ilẹ̀ yìí sí ilẹ̀ àwọn Refaimu, tí wọ́n ti gbé níbẹ̀ rí, ṣùgbọ́n àwọn ará Ammoni ń pè wọ́n ní ará Samsummimu.
Te te a khui ah lamhma la Rapha rhoek a om uh van coeng dongah Rapha khohmuen la a poek. Tedae Ammoni rhoek longtah amih te Zamzomi la a khue uh.
21 Wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tó lágbára, wọ́n sì pọ̀, wọ́n sì ga gogoro bí àwọn ará Anaki. Olúwa run wọn kúrò níwájú àwọn ará Ammoni, tí wọ́n lé wọn jáde tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.
Amih te Anakim bangla pilnam loh len khaw len, yet khaw yet tih sang khaw sang dae amamih mikhmuh ah BOEIPA loh amih te a mitmoeng sak tih a haek dongah amih yueng la Ammon rhoek loh kho a sakuh.
22 Bákan náà ni Olúwa ṣe fún àwọn ọmọ Esau, tí wọ́n ń gbé ní Seiri, nígbà tí ó pa àwọn ará Hori run níwájú wọn. Wọ́n lé wọn jáde wọ́n sì ń gbé ní ilẹ̀ wọn títí di òní.
Seir kah aka om te Esau koca rhoek ham a saii pah tih Khori rhoek a mit sak bangla amih khaw a mikhmuh ah a haek uh dongah tihnin due amih yueng la Esau koca rhoek loh kho a sakuh.
23 Nípa ti àwọn ará Affimu, tí wọ́n ń gbé ní àwọn ìlú kéékèèké dé Gasa, àwọn ará Kaftorimu, tí wọ́n jáde láti Krete wá ni ó pa wọ́n run, wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn.)
Gaza vongup khui duela aka om Avvii khaw Kaptor lamkah aka lo Kapthorim rhoek loh a mit sak tih amih yueng la tloep om bal.
24 “Ẹ gbáradì, kí ẹ sì kọjá odò Arnoni. Kíyèsi, Mo ti fi Sihoni ará Amori, ọba Heṣboni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́. Ẹ bá ilẹ̀ náà jagun kí ẹ sì gbà á.
Thoo uh laeh. Cet uh lamtah Arnon soklong ke kat uh. Na kut dongah kam paek Amori kah Heshbon manghai Sihon te so lamtah a khohmuen te pahoi huul. Te phoeiah anih te caemtloek neh huek.
25 Èmi bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ìbẹ̀rù àti ìfòyà yín sára gbogbo orílẹ̀-èdè lábẹ́ ọ̀run láti òní lọ. Wọn yóò gbọ́ ìròyìn in yín, wọn yóò sì wárìrì, wọn yóò sì wà nínú ìdààmú ọkàn torí i tiyín.”
Tihnin ah he ka tong vetih nang ham birhihnah ka khueh ni. Vaan hmui boeih kah pilnam rhoek loh a mikhmuh ah nang kah hinyahnah olthang a yaak uh vaengah tlai uh vetih na mikhmuh ah kilkul uh ni.
26 Mo rán àwọn ìránṣẹ́ láti aginjù Kedemoti lọ́ sọ́dọ̀ Sihoni ọba Heṣboni pẹ̀lú ọ̀rọ̀ àlàáfíà wí pé,
Te phoeiah Kedemoth khosoek lamkah puencawn rhoek te Heshbon manghai Sihon taengla rhoepnah olka neh ka tueih tih,
27 “Jẹ́ kí a la ilẹ̀ ẹ yín kọjá. Àwa yóò gba ti òpópónà nìkan. A kò ní yà sọ́tùn tàbí sósì.
'Na khohmuen long ah ka lan mai eh. Longpuei pakhat te ka vai vetih banvoei bantang la ka phael mahpawh.
28 Ẹ ta oúnjẹ tí a ó jẹ àti omi tí a ó mu fún wa ní iye owó wọn. Kìkì kí ẹ sá à jẹ́ kí a rìn kọjá:
Buh khaw kai taengah tangka neh yoi lamtah ka ca eh. Tui khaw kai taengah tangka la han yoi lamtah ka o eh. Ka kho nen mah dawk ka lan mai eh.
29 gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Esau tí ó ń gbé ní Seiri àti àwọn ará Moabu tí ó ń gbé ní Ari, ti gbà wá láààyè títí a fi la Jordani já dé ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò fún wa.”
BOEIPA ka Pathen loh kaimih taengah m'paek khohmuen la Jordan lamkah ka lan uh vaengah Seir ah aka om Esau koca rhoek neh Ar ah aka om Moab rhoek loh kai ham a saii uh bangla sai van mai,’ ka ti nah.
30 Ṣùgbọ́n Sihoni ọba Heṣboni kò gbà fún wa láti kọjá. Torí pé Olúwa Ọlọ́run yín ti mú ọkàn rẹ̀ yigbì, àyà rẹ̀ sì kún fún agídí kí ó ba à le fi lé e yín lọ́wọ́, bí ó ti ṣe báyìí.
Te vaengah mamih lan sak ham te Heshbon manghai Sihon loh a kohuem pawh. Tedae tihnin kah bangla BOEIPA na Pathen loh nang kut dongah paek a ngaih dongah ni Sihon kah mueihla te a mangkhak sak tih a thinko khaw a ning sak.
31 Olúwa sì bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kíyèsi i, mo ti bẹ̀rẹ̀ sí ní fi Sihoni àti ilẹ̀ rẹ̀ lé e yín lọ́wọ́. Báyìí, ẹ máa ṣẹ́gun rẹ̀, kí ẹ sì gba ilẹ̀ rẹ̀.”
Tedae BOEIPA loh kai taengah, 'So lah, Sihon neh anih khohmuen te na mikhmuh ah tloeng hamla ka tawn coeng. A khohmuen te pang pah ham tawn pah lamtah huul pah,’ a ti.
32 Nígbà tí Sihoni àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde wá láti bá wa jagun ní Jahasi,
Te vaengah Sihon neh amah pilnam pum loh caemtloek neh mamih doe ham Jahaz ah ha pawk.
33 Olúwa Ọlọ́run wa fi lé wa lọ́wọ́ bẹ́ẹ̀ ni a ṣẹ́gun rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo ológun rẹ̀.
Tedae anih te mamih kah BOEIPA Pathen loh mamih mikhmuh la han thak dongah amah neh anih koca rhoek kah a ca khaw, a pilnam pum khaw n'tloek uh.
34 Nígbà náà, gbogbo ìlú wọn ni a kó tí a sì pa wọ́n run pátápátá tọkùnrin, tobìnrin àti gbogbo ọmọ wọn. A kò sì dá ẹnikẹ́ni sí.
Te vaengah a khopuei boeih te m'buem pa uh tih khopuei takuem te n'thup uh. Huta tongpa neh camoe rhaengnaeng khaw m'paih uh pawh.
35 Ṣùgbọ́n a kó gbogbo ohun ọ̀sìn àti ìkógun àwọn ìlú tí a ṣẹ́gun fún ara wa.
Tedae rhamsa te mamih ham m'poelyoe uh tih khopuei rhoek te kutbuem la m'buem uh.
36 Láti Aroeri, létí odò Arnoni àti láti àwọn ìlú tí ó wà lẹ́bàá odò náà títí ó fi dé Gileadi, kò sí ìlú tí ó lágbára jù fún wa, Olúwa Ọlọ́run wa fi gbogbo wọn fún wa.
Arnon soklong tuikung kah Aroer lamkah soklong khopuei Gilead pataeng khaw mamih ham aka phoeng khorha la om pawh. Tedae mamih kah BOEIPA Pathen loh mamih mikhmuh ah boeih a tloeng.
37 Ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa Ọlọ́run wa, ẹ kò súnmọ́ ọ̀kan nínú ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò dé ilẹ̀ tí ó lọ sí Jabbok, tàbí ilẹ̀ tí ó yí àwọn ìlú òkè e nì ká.
Tedae Ammon koca rhoek kah khohmuen tah mamih BOEIPA Pathen kah a uen vanbangla Jabbok soklong paem boeih neh tlang kah khopuei boeih khaw ben uh boeh.

< Deuteronomy 2 >