< Deuteronomy 19 >

1 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá ti pa àwọn orílẹ̀-èdè tí yóò fi ilẹ̀ wọn fún ọ run, àti nígbà tí ìwọ bá ti lé wọn jáde tí o sì dó sí àwọn ilẹ̀ àti ilé wọn gbogbo.
După ce DOMNUL Dumnezeul tău va stârpi naţiunile, a căror ţară ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău, şi le vei alunga şi vei locui în cetăţile lor şi în casele lor,
2 Ìwọ yóò ya ìlú mẹ́ta sọ́tọ̀ fún ara à rẹ láàrín ilẹ̀ rẹ tí Olúwa Ọlọ́run fún ọ láti ni.
Să îţi separi trei cetăţi în mijlocul ţării tale, pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău, ca să o stăpâneşti.
3 Ṣe àwọn ọ̀nà sí wọn àti kí o pín ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún sí ọ̀nà mẹ́ta nítorí kí apànìyàn lè sá níbẹ̀.
Să îţi pregăteşti o cale şi să împarţi în trei părţi hotarele ţării tale, pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău ca să o moşteneşti, ca orice ucigaş să fugă acolo.
4 Èyí ni òfin nípa apànìyàn, tí ó sì sá síbẹ̀ láti pa ẹ̀mí rẹ̀ mọ́. Ẹni tí ó pa aládùúgbò láìmọ̀ọ́mọ̀ṣeé láìjẹ́ pé ó ti ní àrankàn pẹ̀lú u rẹ̀ láti ọjọ́ pípẹ́.
Şi acesta este cazul ucigaşului, care va fugi acolo, ca să trăiască. Cine ucide fără intenţie pe aproapele său, pe care nu l-a urât în trecut;
5 Bí àpẹẹrẹ, ọkùnrin kan lè lọ sínú igbó pẹ̀lú aládùúgbò rẹ̀ láti gé igi, bí ó sì ti gbé àáké e rẹ̀ láti gé igi náà lulẹ̀, bí àáké náà bá yọ tí ó sì bà aládùúgbò rẹ̀, tí òun sì kú. Ọkùnrin yìí lè sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú yìí láti gba ẹ̀mí rẹ̀ là.
Ca atunci când un om merge cu vecinul său în pădure să taie lemne şi mâna sa dă o lovitură cu securea să taie lemnul şi fierul iese din coadă şi cade pe vecinul său încât el moare; el să fugă într-una din acele cetăţi şi să trăiască;
6 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, agbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ lè máa lépa rẹ̀ nínú ìbínú, kí ó sì lé e bá nítorí pé ọ̀nà jì, kí ó sì pa á bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò yẹ sí ikú, nígbà tí ó ṣe é sí aládùúgbò rẹ̀ láìjẹ́ pé ó ti ní àrankàn pẹ̀lú u rẹ̀ láti ọjọ́ pípẹ́.
Ca nu cumva răzbunătorul sângelui să urmărească pe ucigaş, pe când inima lui este aprinsă şi să îl ajungă, deoarece calea este lungă şi să îl ucidă; deşi nu era demn de moarte, pentru că nu l-a urât în trecut.
7 Ìdí nìyìí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ya ìlú mẹ́ta sọ́tọ̀ fún ara rẹ.
De aceea îţi poruncesc, spunând: Să îţi separi trei cetăţi.
8 Tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá sì fẹ́ agbègbè rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba ńlá a yín, tí ó sì fún ọ ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ti ṣe ìlérí fún wọn,
Şi dacă DOMNUL Dumnezeul tău îţi lărgeşte hotarul, precum a jurat părinţilor tăi şi îţi dă toată ţara, pe care a promis că o va da părinţilor tăi,
9 nítorí tí ìwọ fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ tẹ̀lé gbogbo òfin yìí tí mo pàṣẹ fún ọ lónìí yìí, kí o fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì rìn ní ọ̀nà an rẹ̀ ní gbogbo ìgbà náà, kí o ya ìlú mẹ́ta sọ́tọ̀.
Dacă vei păzi ca să faci toate aceste porunci, pe care ţi le poruncesc astăzi, să iubeşti pe DOMNUL Dumnezeul tău şi să umbli pe căile lui în toate zilele, atunci să îţi mai adaugi încă trei cetăţi, pe lângă acestea trei,
10 Ṣe èyí kí a má ṣe ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ni ilẹ̀ rẹ, èyí tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, kí ìwọ kí ó má bá a jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ títa.
Ca să nu fie vărsat sânge nevinovat în ţara ta, pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău de moştenire, şi astfel sânge să fie peste tine.
11 Ṣùgbọ́n tí ọkùnrin kan bá kórìíra arákùnrin rẹ̀, tí ó sì lúgọ dè é, tí ó mú u tí o lù ú pa, tí ọkùnrin náà sì sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí,
Dar dacă vreun om urăşte pe aproapele său şi îl pândeşte şi se ridică împotriva lui şi îl loveşte de moarte încât el moare, şi fuge într-una din aceste cetăţi,
12 àwọn àgbàgbà ìlú rẹ yóò sì ránṣẹ́ pè é ìwọ, yóò sì mú un padà láti ìlú náà, wọn yóò sì fi í lé àwọn agbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ lọ́wọ́ kí ó lè kú.
Atunci bătrânii cetăţii sale să trimită şi să îl aducă de acolo şi să îl predea în mâna răzbunătorului sângelui, ca să moară.
13 Má ṣe ṣàánú fún un. O ní láti fọ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kúrò ni Israẹli, kí ó bá à lè dára fún ọ.
Ochiul tău să nu aibă milă de el, iar tu să îndepărtezi sângele nevinovat din Israel, ca să îţi fie bine.
14 Má ṣe pa òkúta ààlà aládùúgbò rẹ dà tí aṣíwájú rẹ fi lélẹ̀ nínú ogún tí ó gbà nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ni ní ìní.
Să nu muţi pietrele de hotar ale aproapelui tău, pe care le-au pus cei din vechime în moştenirea ta, pe care o vei moşteni în ţara, pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău, ca să o stăpâneşti.
15 Ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo kò tó láti dájọ́ ọkùnrin kan tí o fi ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yóò wù kí ó lè ṣẹ̀ lẹ́bi. A ó fi ìdí ọ̀rọ̀ múlẹ̀ láti orí ẹ̀rí ẹni méjì tàbí mẹ́ta.
Un singur martor să nu se ridice împotriva unui om pentru vreo nelegiuire, sau pentru vreun păcat, în orice păcat prin care păcătuieşte; prin gura a doi martori sau prin gura a trei martori, să fie întemeiat un lucru.
16 Tí alárankàn ẹlẹ́rìí èké bá dúró láti fi ẹ̀sùn ẹ̀ṣẹ̀ kan ọkùnrin kan,
Dacă se ridică un martor fals împotriva cuiva să mărturisească împotriva lui vreun lucru nedrept,
17 àwọn méjèèjì tí àríyànjiyàn wà láàrín wọn gbọdọ̀ dúró níwájú Olúwa níwájú àwọn àlùfáà àti àwọn adájọ́ tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní ìgbà náà.
Atunci cei doi bărbaţi, între care este cearta, să stea în picioare înaintea DOMNULUI, înaintea preoţilor şi a judecătorilor care vor fi în acele zile.
18 Àwọn adájọ́ gbọdọ̀ ṣe ìwádìí fínní fínní bí ẹ̀rí bá sì jẹ́ irọ́, tí ó fi ẹ̀rí èké sun arákùnrin rẹ̀,
Şi judecătorii să cerceteze cu de-amănuntul; şi, iată, dacă martorul este martor fals şi a mărturisit fals împotriva fratelui său,
19 nígbà náà ni kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ṣe fẹ́ ṣe sí arákùnrin rẹ̀. O ní láti wẹ búburú kúrò láàrín rẹ.
Atunci să îi faceţi precum s-a gândit el să facă fratelui său, astfel să îndepărtezi răul din mijlocul tău.
20 Àwọn ènìyàn tókù yóò gbọ́ nípa èyí, wọn yóò sì bẹ̀rù, kí irú nǹkan búburú bẹ́ẹ̀ máa tún sẹ̀ mọ́ láàrín yín.
Şi cei care rămân, să audă şi să se teamă şi să nu mai facă un asemenea rău printre voi.
21 Má ṣe fi àánú hàn, ẹ̀mí fún ẹ̀mí, ojú fún ojú, eyín fún eyín, apá fún apá, ẹsẹ̀ fún ẹsẹ̀.
Şi ochiul tău să nu aibă milă, ci viaţă pentru viaţă, ochi pentru ochi, dinte pentru dinte, mână pentru mână, picior pentru picior.

< Deuteronomy 19 >