< Deuteronomy 19 >

1 Nígbà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá ti pa àwọn orílẹ̀-èdè tí yóò fi ilẹ̀ wọn fún ọ run, àti nígbà tí ìwọ bá ti lé wọn jáde tí o sì dó sí àwọn ilẹ̀ àti ilé wọn gbogbo.
Gdy wytraci Pan, Bóg twój, narody, których ziemię Pan, Bóg twój, dawa tobie, a posiędziesz ją, i mieszkać będziesz w miastach ich, i w domach ich:
2 Ìwọ yóò ya ìlú mẹ́ta sọ́tọ̀ fún ara à rẹ láàrín ilẹ̀ rẹ tí Olúwa Ọlọ́run fún ọ láti ni.
Trzy miasta odłączysz sobie w pośród ziemi twojej, którą Pan, Bóg twój dawa tobie w osiadłość;
3 Ṣe àwọn ọ̀nà sí wọn àti kí o pín ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún sí ọ̀nà mẹ́ta nítorí kí apànìyàn lè sá níbẹ̀.
Wyprostujesz sobie drogę, i rozdzielisz na trzy części granice ziemi twojej, którąć w dziedzictwo poda Pan, Bóg twój, żeby tam uciekał każdy mężobójca.
4 Èyí ni òfin nípa apànìyàn, tí ó sì sá síbẹ̀ láti pa ẹ̀mí rẹ̀ mọ́. Ẹni tí ó pa aládùúgbò láìmọ̀ọ́mọ̀ṣeé láìjẹ́ pé ó ti ní àrankàn pẹ̀lú u rẹ̀ láti ọjọ́ pípẹ́.
A toć będzie prawo mężobójcy, który tam uciecze, aby żyw został, gdyby zabił bliźniego swego z nieobaczenia, a nie miałby go przedtem w nienawiści;
5 Bí àpẹẹrẹ, ọkùnrin kan lè lọ sínú igbó pẹ̀lú aládùúgbò rẹ̀ láti gé igi, bí ó sì ti gbé àáké e rẹ̀ láti gé igi náà lulẹ̀, bí àáké náà bá yọ tí ó sì bà aládùúgbò rẹ̀, tí òun sì kú. Ọkùnrin yìí lè sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú yìí láti gba ẹ̀mí rẹ̀ là.
Jako gdyby kto szedł z bliźnim swym do lasu drwa rąbać, a zaniósłby się ręką swą z siekierą, aby uciął drzewo, a spadłaby siekiera z toporzyska, i trafiłaby bliźniego jego, żeby umarł, ten uciecze do jednego z tych miast, aby żyw został;
6 Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, agbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ lè máa lépa rẹ̀ nínú ìbínú, kí ó sì lé e bá nítorí pé ọ̀nà jì, kí ó sì pa á bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò yẹ sí ikú, nígbà tí ó ṣe é sí aládùúgbò rẹ̀ láìjẹ́ pé ó ti ní àrankàn pẹ̀lú u rẹ̀ láti ọjọ́ pípẹ́.
By snać nie gonił powinny zabitego mężobójcę onego, gdyby się rozpaliło serce jego, a dogoniwszy go na dalekiej drodze, nie zabił go, choćby nie był winien śmierci, ponieważ go nie miał w nienawiści przedtem.
7 Ìdí nìyìí tí mo fi pa á láṣẹ fún ọ láti ya ìlú mẹ́ta sọ́tọ̀ fún ara rẹ.
Przetoż ja przykazuję tobie, mówiąc: Trzy miasta odłączysz sobie;
8 Tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá sì fẹ́ agbègbè rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìbúra fún àwọn baba ńlá a yín, tí ó sì fún ọ ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ti ṣe ìlérí fún wọn,
A gdy rozszerzy Pan, Bóg twój, granice twoje, jako przysiągł ojcom twoim, i dać wszystkę ziemię, którą zaślubił dać ojcom twoim:
9 nítorí tí ìwọ fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ tẹ̀lé gbogbo òfin yìí tí mo pàṣẹ fún ọ lónìí yìí, kí o fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì rìn ní ọ̀nà an rẹ̀ ní gbogbo ìgbà náà, kí o ya ìlú mẹ́ta sọ́tọ̀.
Jeźliże będziesz strzegł wszystkich tych przykazań, i czynił je, które ja dziś rozkazuję tobie, żebyś miłował Pana, Boga twego, i chdził drogami jego po wszystkie dni, tedy przydasz sobie jeszcze trzy miasta do onych trzech miast.
10 Ṣe èyí kí a má ṣe ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ni ilẹ̀ rẹ, èyí tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fún ọ gẹ́gẹ́ bí ogún, kí ìwọ kí ó má bá a jẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ títa.
Aby nie była wylewana krew niewinna w pośrodku ziemi twojej, którą Pan, Bóg twój, dawa tobie w dziedzictwo, aby nie została na tobie krew.
11 Ṣùgbọ́n tí ọkùnrin kan bá kórìíra arákùnrin rẹ̀, tí ó sì lúgọ dè é, tí ó mú u tí o lù ú pa, tí ọkùnrin náà sì sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí,
Ale jeźliby kto mając w nienawiści bliźniego swego, a zasadziwszy się nań, powstałby przeciw jemu, i uderzyłby go śmiertelnie, ażby umarł, a uciekł do jednego z tych miast:
12 àwọn àgbàgbà ìlú rẹ yóò sì ránṣẹ́ pè é ìwọ, yóò sì mú un padà láti ìlú náà, wọn yóò sì fi í lé àwọn agbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ lọ́wọ́ kí ó lè kú.
Tedy poślą starsi miasta onego, i porwą go stamtąd, i wydadzą go w ręce powinnemu zabitego, i umrze.
13 Má ṣe ṣàánú fún un. O ní láti fọ ẹ̀bi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kúrò ni Israẹli, kí ó bá à lè dára fún ọ.
Nie sfolguje mu oko twoje; ale odejmiesz krew niewinną z Izraela, abyć się dobrze działo.
14 Má ṣe pa òkúta ààlà aládùúgbò rẹ dà tí aṣíwájú rẹ fi lélẹ̀ nínú ogún tí ó gbà nínú ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ fi fún ọ láti ni ní ìní.
Nie będziesz przenosił granicy bliźniego twego, którą założyli przodkowie w dziedzictwie twojem, które osiędziesz w ziemi, którą Pan, Bóg twój dawa tobie w osiadłość.
15 Ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo kò tó láti dájọ́ ọkùnrin kan tí o fi ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ yóò wù kí ó lè ṣẹ̀ lẹ́bi. A ó fi ìdí ọ̀rọ̀ múlẹ̀ láti orí ẹ̀rí ẹni méjì tàbí mẹ́ta.
Nie powstanie świadek jeden przeciwko człowiekowi w jakiejkolwiek nieprawości, albo w jakimkolwiek grzechu ze wszystkich grzechów, któremi by kto zgrzeszył; w uściech dwóch świadków, albo w uściech trzech świadków stanie każde słowo.
16 Tí alárankàn ẹlẹ́rìí èké bá dúró láti fi ẹ̀sùn ẹ̀ṣẹ̀ kan ọkùnrin kan,
Jeźliby powstał świadek kłamliwy przeciw komu, świadcząc przeciw niemu, że odstąpił od Boga:
17 àwọn méjèèjì tí àríyànjiyàn wà láàrín wọn gbọdọ̀ dúró níwájú Olúwa níwájú àwọn àlùfáà àti àwọn adájọ́ tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní ìgbà náà.
Tedy staną oni dwaj mężowie, którzy mają spór, przed Panem, przed kapłany, i przed sędziami, którzy będą na ten czas.
18 Àwọn adájọ́ gbọdọ̀ ṣe ìwádìí fínní fínní bí ẹ̀rí bá sì jẹ́ irọ́, tí ó fi ẹ̀rí èké sun arákùnrin rẹ̀,
I będą się pilnie wywiadowali sędziowie; a obacząli, że świadek on jest świadkiem fałszywym, kłamstwo powiadając na brata swego,
19 nígbà náà ni kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ṣe fẹ́ ṣe sí arákùnrin rẹ̀. O ní láti wẹ búburú kúrò láàrín rẹ.
Uczynicie mu, jako on myślił uczynić bratu swemu; i odejmiesz złe z pośrodku siebie;
20 Àwọn ènìyàn tókù yóò gbọ́ nípa èyí, wọn yóò sì bẹ̀rù, kí irú nǹkan búburú bẹ́ẹ̀ máa tún sẹ̀ mọ́ láàrín yín.
Aby drudzy usłyszawszy to, ulękli się, i nie dopuszczali się więcej takowej złości czynić w pośród ciebie.
21 Má ṣe fi àánú hàn, ẹ̀mí fún ẹ̀mí, ojú fún ojú, eyín fún eyín, apá fún apá, ẹsẹ̀ fún ẹsẹ̀.
A nie sfolguje oko twoje; gardło za gardło, oko za oko, ząb za ząb, ręka za rękę, noga za nogę będzie.

< Deuteronomy 19 >