< Deuteronomy 18 >

1 Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi, àní gbogbo ẹ̀yà Lefi, wọn kì yóò ní ìpín tàbí ogún láàrín Israẹli, wọn yóò máa jẹ nínú ọrẹ ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa, nítorí òun ni ogún un tiwọn.
Lawiy kahinlar we shuningdek barliq Lawiylar qebilisining Israilda héchqandaq nésiwisi yaki mirasi bolmaydu; ular Perwerdigargha atap otta sunulidighan qurbanliqlardin we [Perwerdigarning] mirasidin yéyishke bolidu,
2 Wọn kì yóò ní ìní láàrín àwọn arákùnrin wọn; Olúwa ni yóò jẹ́ ìní i tiwọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.
Biraq ularning qérindashliri arisida héchqandaq mirasi bolmaydu; Perwerdigar éytqandek, U Özi ularning mirasidur.
3 Gbogbo èyí ni yóò jẹ́ ìpín àwọn àlùfáà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó fi akọ màlúù tàbí àgùntàn rú ẹbọ; wọn yóò fi èjìká àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ méjèèjì àti gbogbo inú fún àlùfáà.
Kahinlarning qurbanliq qilidighan xelqtin alidighan ülüshi mundaq: — (meyli kala yaki qoy bolsun) qol, éngek göshi we üchey-qérini kahinlargha bérilidu.
4 Àkọ́so irúgbìn ọkà rẹ, ti wáìnì àti ti òróró rẹ, àti àkọ́rẹ́ irun àgùntàn rẹ ni ìwọ yóò fi fún wọn.
Silerning ashliqinglardin, yéngi sharabinglardin we zeytun méyinglardin deslepki pishqan hosulni we qoyliringlardin deslepki qirqilghan yungni uninggha bérisiler;
5 Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n àti àwọn ọmọ wọn láti inú gbogbo ẹ̀yà láti dúró àti láti ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa títí láé.
chünki Perwerdigar Xudaying uni we uning ewladlirini Öz namida xizmitide daim turushqa barliq qebililiringlar ichidin talliwalghan.
6 Tí ọmọ Lefi kan bá sì wá láti ibikíbi nínú àwọn ìlú u yín ní Israẹli, níbi tí ó ń gbé ṣe àtìpó, tí ó sì wá gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
Eger Lawiy bolghan bir adem pütkül Israildiki herqandaq sheher-yézidin, yeni özi makanlashqan jaydin chiqip, Perwerdigar tallaydighan jaygha kelse
7 Nígbà náà ni ó lè máa ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi arákùnrin rẹ̀ ti ń dúró ṣe iṣẹ́ ìsìn níwájú Olúwa níbẹ̀.
we shu yerde Perwerdigar aldida turghuchi barliq qérindashlirigha oxshash Perwerdigar Xudasining namida xizmette turghan bolsa,
8 Wọn yóò ní ìpín kan láti jẹ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti gba owó nípa títa ogún baba rẹ̀.
undaqta (meyli u atisidin qalghan mirasini sétiwetken yaki sétiwetmigen bolsun) uning yeydighan ülüshi qérindashliriningkidek bolushi kérek.
9 Nígbà tí o bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ, ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ láti tẹ̀lé àwọn ọ̀nà ìríra àwọn orílẹ̀-èdè náà tí ó wà níbẹ̀.
Sen Perwerdigar Xudaying sanga béridighan zémin’gha kirgen chaghda, sen shu yerdiki ellerning yirginchlik adetlirini ögenmesliking kérek.
10 Má ṣe jẹ́ kí a rí ẹnikẹ́ni láàrín yín tí ó fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin la iná já (fi ọmọ rẹ rú ẹbọ) kí ẹnikẹ́ni má ṣe lọ fọ àfọ̀ṣẹ, tàbí ṣẹ́ oṣó, tàbí túmọ̀ àwọn àmì nǹkan tí ń bọ̀, tàbí àjẹ́,
Aranglarda öz oghli yaki qizini ottin ötküzidighan, palchiliq, remchilik, epsaniylik, jadugerlik
11 tàbí afògèdè, tàbí jẹ́ a bá iwin gbìmọ̀ tàbí oṣó tàbí abókùúsọ̀rọ̀.
yaki demidichilik qilghuchi yaki jinkesh, séhirger yaki ölgenlerdin yol sorighuchi héchqandaq kishi bolmisun;
12 Ẹnikẹ́ni tó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí jẹ́ ìríra sí Olúwa, àti nítorí àwọn ìwà ìríra wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde kúrò níwájú rẹ.
chünki bundaq ishlarni qilidighan herqandaq kishi Perwerdigargha nepretlik bolidu; bu yirginchlik ishlar tüpeylidin Perwerdigar Xudaying shu ellerni aldinglardin heydep chiqiridu.
13 O ní láti jẹ́ aláìlẹ́gàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Sen Perwerdigar Xudaying aldida eyibsiz mukemmel bolushung kérek;
14 Àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ yóò gba ilẹ̀ tí wọ́n ń gbé, wọ́n fetí sí tí àwọn tí ó ń ṣe oṣó tàbí ṣe àfọ̀ṣẹ. Ṣùgbọ́n, ní ti ìwọ, Olúwa Ọlọ́run rẹ kò fi ààyè gbà ọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀.
chünki sen zémindin heydeydighan bu eller remchiler we palchilargha qulaq salidu; biraq Perwerdigar Xudaying séni undaq qilishqa yol qoymaydu.
15 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé wòlíì kan dìde gẹ́gẹ́ bí èmi láàrín àwọn arákùnrin rẹ. Tìrẹ ni kí o gbọ́.
Perwerdigar Xudaying siler üchün aranglardin, qérindashliringlar arisidin manga oxshaydighan bir peyghember turghuzidu; siler uninggha qulaq sélinglar.
16 Nítorí èyí ni ohun tí ìwọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Horebu ní ọjọ́ àjọ, nígbà tí ìwọ wí pé, “Kí àwa má ṣe gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run wa tàbí rí iná ńlá yìí mọ́. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ àwa yóò kú.”
Bu siler Horeb téghida yighilghan künde Perwerdigar Xudayinglardin: «Perwerdigar Xudayimning awazini yene anglimayli, bu dehshetlik otni körmeyli, bolmisa ölüp kétimiz» dep telep qilghininglargha pütünley mas kélidu.
17 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ohun tí wọ́n sọ dára.
Shu chaghda Perwerdigar manga: «Ularning manga dégen sözi yaxshi boldi.
18 Èmi yóò gbé wòlíì kan dìde fún wọn láàrín àwọn arákùnrin wọn bí ìwọ, Èmi yóò fi ọ̀rọ̀ mi sí i ní ẹnu, yóò sì sọ fún wọn gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un.
Men ulargha qérindashliri arisidin sanga oxshaydighan bir peyghemberni turghuzimen, Men Öz sözlirimni uning aghzigha salimen we u Men uninggha barliq tapilighinimni ulargha sözleydu.
19 Ẹnikẹ́ni tí kò bá sì tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi tí wòlíì náà yóò sọ ní orúkọ mi, èmi fúnra à mi yóò sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.
We shundaq boliduki, u Méning namimda deydighan sözlirimge qulaq salmaydighan herqandaq kishi bolsa, Men uningdin hésab alimen.
20 Ṣùgbọ́n bí wòlíì kan bá kùgbù sọ ọ̀rọ̀ kan tí èmi kò paláṣẹ fún un láti sọ ní orúkọ mi tàbí wòlíì tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ ọlọ́run mìíràn, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ ní láti kú.”
Emma Méning namimda bashbashtaqliq qilip Men uninggha tapilimighan birer sözni sözlise yaki bashqa ilahlarning namida söz qilidighan peyghember bolsa, shu peyghember öltürülsun.
21 Ṣùgbọ́n ìwọ lè wí ní ọkàn rẹ pé, “Báwo ni àwa yóò ṣe mọ ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ?”
Eger sen könglüngde: «Perwerdigar qilmighan sözni qandaq perq étimiz» déseng,
22 Nígbà tí ohun tí wòlíì bá sọ ní orúkọ Olúwa kò bá wá sí ìmúṣẹ tàbí jẹ́ òtítọ́, ìyẹn ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ tí sọ láìwádìí. Kí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.
bir peyghember Perwerdigarning namida söz qilghan bolsa we u bésharet qilghan ish toghra chiqmisa yaki emelge ashurulmisa, undaqta bu söz Perwerdigardin chiqmighan; shu peyghember bashbashtaqliq bilen sözligen dep, uningdin qorqma.

< Deuteronomy 18 >