< Deuteronomy 18 >

1 Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi, àní gbogbo ẹ̀yà Lefi, wọn kì yóò ní ìpín tàbí ogún láàrín Israẹli, wọn yóò máa jẹ nínú ọrẹ ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa, nítorí òun ni ogún un tiwọn.
Преоций, левиций ши тоатэ семинция луй Леви сэ ну айбэ нич парте де мошие, нич моштенире ын Исраел; сэ се хрэняскэ дин жертфеле мистуите де фок ын чинстя Домнулуй ши дин даруриле адусе Домнулуй.
2 Wọn kì yóò ní ìní láàrín àwọn arákùnrin wọn; Olúwa ni yóò jẹ́ ìní i tiwọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.
Сэ ну айбэ моштенире ын мижлокул фрацилор лор: Домнул ва фи моштениря лор, кум ле-а спус.
3 Gbogbo èyí ni yóò jẹ́ ìpín àwọn àlùfáà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó fi akọ màlúù tàbí àgùntàn rú ẹbọ; wọn yóò fi èjìká àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ méjèèjì àti gbogbo inú fún àlùfáà.
Ятэ каре ва фи дрептул преоцилор де ла попор: чей че вор адуче о жертфэ, фие боу, фие мел, сэ дя преотулуй спата, фэлчиле ши пынтечеле.
4 Àkọ́so irúgbìn ọkà rẹ, ti wáìnì àti ti òróró rẹ, àti àkọ́rẹ́ irun àgùntàn rẹ ni ìwọ yóò fi fún wọn.
Сэ-й дай челе динтый роаде дин грыул тэу, дин мустул тэу ши дин унтделемнул тэу ши пырга дин лына оилор тале,
5 Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n àti àwọn ọmọ wọn láti inú gbogbo ẹ̀yà láti dúró àti láti ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa títí láé.
кэч пе ел л-а алес Домнул Думнезеул тэу динтре тоате семинцииле, ка сэ факэ служба ын Нумеле Домнулуй, ел ши фиий луй, ын тоате зилеле.
6 Tí ọmọ Lefi kan bá sì wá láti ibikíbi nínú àwọn ìlú u yín ní Israẹli, níbi tí ó ń gbé ṣe àtìpó, tí ó sì wá gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
Кынд ва плека ун левит дин уна дин четэциле тале, дин локул унде локуеште ел ын Исраел, ка сэ се дукэ, дупэ деплина доринцэ а суфлетулуй сэу, ын локул пе каре-л ва алеӂе Домнул
7 Nígbà náà ni ó lè máa ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi arákùnrin rẹ̀ ti ń dúró ṣe iṣẹ́ ìsìn níwájú Olúwa níbẹ̀.
ши ва фаче службэ ын Нумеле Домнулуй Думнезеулуй тэу, ка тоць фраций луй левиць каре стау ынаинтя Домнулуй,
8 Wọn yóò ní ìpín kan láti jẹ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti gba owó nípa títa ogún baba rẹ̀.
ва прими ка хранэ о парте ла фел ку а лор ши, пе лынгэ еа, се ва букура ши де венитуриле ешите дин вынзаря аверий луй пэринтешть.
9 Nígbà tí o bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ, ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ láti tẹ̀lé àwọn ọ̀nà ìríra àwọn orílẹ̀-èdè náà tí ó wà níbẹ̀.
Дупэ че вей интра ын цара пе каре ць-о дэ Домнул Думнезеул тэу, сэ ну те ынвець сэ фачь дупэ урычуниле нямурилор ачелора.
10 Má ṣe jẹ́ kí a rí ẹnikẹ́ni láàrín yín tí ó fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin la iná já (fi ọmọ rẹ rú ẹbọ) kí ẹnikẹ́ni má ṣe lọ fọ àfọ̀ṣẹ, tàbí ṣẹ́ oṣó, tàbí túmọ̀ àwọn àmì nǹkan tí ń bọ̀, tàbí àjẹ́,
Сэ ну фие ла тине нимень каре сэ-шь трякэ пе фиул сау пе фийка луй прин фок, нимень каре сэ айбэ мештешугул де гичитор, де чититор ын стеле, де веститор ал вииторулуй, де врэжитор,
11 tàbí afògèdè, tàbí jẹ́ a bá iwin gbìmọ̀ tàbí oṣó tàbí abókùúsọ̀rọ̀.
де дескынтэтор, нимень каре сэ ынтребе пе чей че кямэ духуриле сау дау ку гиокул, нимень каре сэ ынтребе пе морць.
12 Ẹnikẹ́ni tó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí jẹ́ ìríra sí Olúwa, àti nítorí àwọn ìwà ìríra wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde kúrò níwájú rẹ.
Кэч орьчине фаче ачесте лукрурь есте о урычуне ынаинтя Домнулуй ши дин причина ачестор лукрурь ва изгони Домнул Думнезеул тэу пе ачесте нямурь динаинтя та.
13 O ní láti jẹ́ aláìlẹ́gàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Ту сэ те ций ын тотул тотулуй тот нумай де Домнул Думнезеул тэу.
14 Àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ yóò gba ilẹ̀ tí wọ́n ń gbé, wọ́n fetí sí tí àwọn tí ó ń ṣe oṣó tàbí ṣe àfọ̀ṣẹ. Ṣùgbọ́n, ní ti ìwọ, Olúwa Ọlọ́run rẹ kò fi ààyè gbà ọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀.
Кэч нямуриле ачеля пе каре ле вей изгони аскултэ де чей че читеск ын стеле ши де гичиторь, дар цие, Домнул Думнезеул тэу ну-ць ынгэдуе лукрул ачеста.
15 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé wòlíì kan dìde gẹ́gẹ́ bí èmi láàrín àwọn arákùnrin rẹ. Tìrẹ ni kí o gbọ́.
Домнул Думнезеул тэу ыць ва ридика дин мижлокул тэу, динтре фраций тэй, ун пророк ка мине: сэ аскултаць де ел!
16 Nítorí èyí ni ohun tí ìwọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Horebu ní ọjọ́ àjọ, nígbà tí ìwọ wí pé, “Kí àwa má ṣe gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run wa tàbí rí iná ńlá yìí mọ́. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ àwa yóò kú.”
Астфел, ел ва рэспунде ла череря пе каре ай фэкут-о Домнулуй Думнезеулуй тэу ла Хореб, ын зиуа адунэрий попорулуй, кынд зичяй: ‘Сэ ну май ауд гласул Домнулуй Думнезеулуй меу ши сэ ну май вэд ачест фок маре, ка сэ ну мор.’
17 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ohun tí wọ́n sọ dára.
Атунч, Домнул мь-а зис: ‘Че ау зис ей есте бине.
18 Èmi yóò gbé wòlíì kan dìde fún wọn láàrín àwọn arákùnrin wọn bí ìwọ, Èmi yóò fi ọ̀rọ̀ mi sí i ní ẹnu, yóò sì sọ fún wọn gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un.
Ле вой ридика дин мижлокул фрацилор лор ун пророк ка тине, вой пуне кувинтеле Меле ын гура луй ши ел ле ва спуне тот че-й вой порунчи Еу.
19 Ẹnikẹ́ni tí kò bá sì tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi tí wòlíì náà yóò sọ ní orúkọ mi, èmi fúnra à mi yóò sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.
Ши дакэ чинева ну ва аскулта де кувинтеле Меле, пе каре ле ва спуне ел ын Нумеле Меу, Еу ый вой чере сокотялэ.
20 Ṣùgbọ́n bí wòlíì kan bá kùgbù sọ ọ̀rọ̀ kan tí èmi kò paláṣẹ fún un láti sọ ní orúkọ mi tàbí wòlíì tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ ọlọ́run mìíràn, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ ní láti kú.”
Дар пророкул каре ва авя ындрэзняла сэ спунэ ын Нумеле Меу ун кувынт пе каре ну-й вой порунчи сэ-л спунэ сау каре ва ворби ын нумеле алтор думнезей, пророкул ачела сэ фие педепсит ку моартя.’
21 Ṣùgbọ́n ìwọ lè wí ní ọkàn rẹ pé, “Báwo ni àwa yóò ṣe mọ ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ?”
Поате кэ вей зиче ын инима та: ‘Кум вом куноаште кувынтул пе каре ну-л ва спуне Домнул?’
22 Nígbà tí ohun tí wòlíì bá sọ ní orúkọ Olúwa kò bá wá sí ìmúṣẹ tàbí jẹ́ òtítọ́, ìyẹn ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ tí sọ láìwádìí. Kí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.
Кынд чея че ва спуне пророкул ачела ын Нумеле Домнулуй ну ва авя лок ши ну се ва ынтымпла, ва фи ун кувынт пе каре ну л-а спус Домнул. Пророкул ачела л-а спус дин ындрэзнялэ: сэ н-ай тямэ де ел.

< Deuteronomy 18 >