< Deuteronomy 18 >

1 Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi, àní gbogbo ẹ̀yà Lefi, wọn kì yóò ní ìpín tàbí ogún láàrín Israẹli, wọn yóò máa jẹ nínú ọrẹ ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa, nítorí òun ni ogún un tiwọn.
Preoţii, leviţii şi tot tribul lui Levi nu vor avea nici parte, nici moştenire în Israel, ei să mănânce ofrandele prin foc ale DOMNULUI care sunt şi moştenirea lui.
2 Wọn kì yóò ní ìní láàrín àwọn arákùnrin wọn; Olúwa ni yóò jẹ́ ìní i tiwọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.
De aceea nu vor avea moştenire între fraţii lor, DOMNUL este moştenirea lor, precum le-a spus.
3 Gbogbo èyí ni yóò jẹ́ ìpín àwọn àlùfáà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó fi akọ màlúù tàbí àgùntàn rú ẹbọ; wọn yóò fi èjìká àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ méjèèjì àti gbogbo inú fún àlùfáà.
Şi acesta să fie dreptul preoţilor de la popor, de la cei care oferă un sacrificiu, fie bou fie oaie; să dea preotului spata şi amândouă fălcile şi pântecele.
4 Àkọ́so irúgbìn ọkà rẹ, ti wáìnì àti ti òróró rẹ, àti àkọ́rẹ́ irun àgùntàn rẹ ni ìwọ yóò fi fún wọn.
Primele roade de asemenea din grânele tale, din vinul tău şi din untdelemnul tău şi primele din tunsul oilor tale, să le dai lui.
5 Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n àti àwọn ọmọ wọn láti inú gbogbo ẹ̀yà láti dúró àti láti ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa títí láé.
Pentru că pe el l-a ales DOMNUL Dumnezeul tău dintre toate triburile tale să stea în picioare să servească în numele DOMNULUI, el şi fiii săi pentru totdeauna.
6 Tí ọmọ Lefi kan bá sì wá láti ibikíbi nínú àwọn ìlú u yín ní Israẹli, níbi tí ó ń gbé ṣe àtìpó, tí ó sì wá gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
Şi dacă vine un levit din oricare din porţile tale din tot Israelul, unde a locuit temporar şi vine cu toată dorinţa minţii lui în locul pe care îl va alege DOMNUL,
7 Nígbà náà ni ó lè máa ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi arákùnrin rẹ̀ ti ń dúró ṣe iṣẹ́ ìsìn níwájú Olúwa níbẹ̀.
Atunci să servească în numele DOMNULUI Dumnezeul său, precum fac toţi fraţii săi leviţi, care stau în picioare acolo înaintea DOMNULUI.
8 Wọn yóò ní ìpín kan láti jẹ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti gba owó nípa títa ogún baba rẹ̀.
Ei să aibă porţii de mâncat deopotrivă, pe lângă ceea ce vine din vânzarea averii sale părinteşti.
9 Nígbà tí o bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ, ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ láti tẹ̀lé àwọn ọ̀nà ìríra àwọn orílẹ̀-èdè náà tí ó wà níbẹ̀.
După ce vei fi intrat în ţara pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău, să nu te înveţi să faci după urâciunile acelor naţiuni.
10 Má ṣe jẹ́ kí a rí ẹnikẹ́ni láàrín yín tí ó fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin la iná já (fi ọmọ rẹ rú ẹbọ) kí ẹnikẹ́ni má ṣe lọ fọ àfọ̀ṣẹ, tàbí ṣẹ́ oṣó, tàbí túmọ̀ àwọn àmì nǹkan tí ń bọ̀, tàbí àjẹ́,
Să nu se găsească printre voi cineva care să facă pe fiul său sau pe fiica sa, să treacă prin foc, sau care foloseşte ghicire, sau prezicător al viitorului sau fermecător sau vrăjitoare,
11 tàbí afògèdè, tàbí jẹ́ a bá iwin gbìmọ̀ tàbí oṣó tàbí abókùúsọ̀rọ̀.
Sau descântător, sau unul care consultă demonii, sau vrăjitor, sau unul care cheamă morţii.
12 Ẹnikẹ́ni tó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí jẹ́ ìríra sí Olúwa, àti nítorí àwọn ìwà ìríra wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde kúrò níwájú rẹ.
Pentru că toţi cei care fac aceste lucruri sunt o urâciune înaintea DOMNULUI şi pentru aceste urâciuni îi alungă DOMNUL Dumnezeul tău dinaintea ta.
13 O ní láti jẹ́ aláìlẹ́gàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Tu să fii desăvârşit cu DOMNUL Dumnezeul tău.
14 Àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ yóò gba ilẹ̀ tí wọ́n ń gbé, wọ́n fetí sí tí àwọn tí ó ń ṣe oṣó tàbí ṣe àfọ̀ṣẹ. Ṣùgbọ́n, ní ti ìwọ, Olúwa Ọlọ́run rẹ kò fi ààyè gbà ọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀.
Pentru că aceste naţiuni, pe care le vei stăpâni, au dat ascultare la prezicători ai viitorului şi la ghicitori, dar cât despre tine, DOMNUL Dumnezeul tău nu ţi-a permis să faci astfel.
15 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé wòlíì kan dìde gẹ́gẹ́ bí èmi láàrín àwọn arákùnrin rẹ. Tìrẹ ni kí o gbọ́.
DOMNUL Dumnezeul tău îţi va ridica un Profet din mijlocul tău, dintre fraţii tăi, asemenea mie, lui să îi daţi ascultare;
16 Nítorí èyí ni ohun tí ìwọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Horebu ní ọjọ́ àjọ, nígbà tí ìwọ wí pé, “Kí àwa má ṣe gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run wa tàbí rí iná ńlá yìí mọ́. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ àwa yóò kú.”
Conform cu tot ce ai dorit de la DOMNUL Dumnezeul tău în Horeb, în ziua adunării, spunând: Să nu mai aud vocea DOMNULUI Dumnezeul meu, nici să nu mai văd focul acesta mare, ca să nu mor.
17 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ohun tí wọ́n sọ dára.
Şi DOMNUL mi-a spus: Bine au vorbit ce au vorbit.
18 Èmi yóò gbé wòlíì kan dìde fún wọn láàrín àwọn arákùnrin wọn bí ìwọ, Èmi yóò fi ọ̀rọ̀ mi sí i ní ẹnu, yóò sì sọ fún wọn gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un.
Le voi ridica un Profet dintre fraţii lor, asemenea ţie şi voi pune cuvintele mele în gura lui; şi el le va vorbi tot ce îi voi porunci.
19 Ẹnikẹ́ni tí kò bá sì tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi tí wòlíì náà yóò sọ ní orúkọ mi, èmi fúnra à mi yóò sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.
Şi se va întâmpla, că oricui nu va da ascultare cuvintelor mele, pe care le va spune el în numele meu, îi voi cere socoteală.
20 Ṣùgbọ́n bí wòlíì kan bá kùgbù sọ ọ̀rọ̀ kan tí èmi kò paláṣẹ fún un láti sọ ní orúkọ mi tàbí wòlíì tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ ọlọ́run mìíràn, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ ní láti kú.”
Dar profetul care s-ar îngâmfa să vorbească în numele meu un cuvânt, pe care nu l-am poruncit să îl vorbească sau care va vorbi în numele altor dumnezei, acel profet să moară.
21 Ṣùgbọ́n ìwọ lè wí ní ọkàn rẹ pé, “Báwo ni àwa yóò ṣe mọ ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ?”
Şi dacă spui în inima ta: Cum vom cunoaşte cuvântul pe care nu l-a spus DOMNUL?
22 Nígbà tí ohun tí wòlíì bá sọ ní orúkọ Olúwa kò bá wá sí ìmúṣẹ tàbí jẹ́ òtítọ́, ìyẹn ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ tí sọ láìwádìí. Kí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.
Când un profet vorbeşte în numele DOMNULUI şi lucrul nu se împlineşte, nici nu se întâmplă, acela este cuvântul pe care nu l-a vorbit DOMNUL; ci profetul l-a vorbit cu îngâmfare, să nu te temi de el.

< Deuteronomy 18 >