< Deuteronomy 18 >
1 Àwọn àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi, àní gbogbo ẹ̀yà Lefi, wọn kì yóò ní ìpín tàbí ogún láàrín Israẹli, wọn yóò máa jẹ nínú ọrẹ ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa, nítorí òun ni ogún un tiwọn.
Priesteriem, Levitiem, visai Levja ciltij lai nav nedz daļas nedz mantības līdz ar Israēli; lai tie ēd no Tā Kunga uguns upuriem un no Viņa mantas daļas.
2 Wọn kì yóò ní ìní láàrín àwọn arákùnrin wọn; Olúwa ni yóò jẹ́ ìní i tiwọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.
Un mantības lai tiem nav savu brāļu vidū, Tas Kungs ir viņu mantība, itin kā Viņš uz tiem runājis.
3 Gbogbo èyí ni yóò jẹ́ ìpín àwọn àlùfáà láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn tí ó fi akọ màlúù tàbí àgùntàn rú ẹbọ; wọn yóò fi èjìká àti ẹ̀rẹ̀kẹ́ méjèèjì àti gbogbo inú fún àlùfáà.
Šī nu lai ir tā priesteru tiesa no tiem ļaudīm, no tiem, kas kādu upuri upurē, lai tas ir vērsis vai avs; priesterim lai dod pleci, abus žokļus un kuņģi.
4 Àkọ́so irúgbìn ọkà rẹ, ti wáìnì àti ti òróró rẹ, àti àkọ́rẹ́ irun àgùntàn rẹ ni ìwọ yóò fi fún wọn.
Savas labības, sava vīna un savas eļļas pirmajus, un pirmajus no savu avju cirpšanas tev būs viņam dot.
5 Nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti yàn wọ́n àti àwọn ọmọ wọn láti inú gbogbo ẹ̀yà láti dúró àti láti ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa títí láé.
Jo Tas Kungs, tavs Dievs, viņu ir izredzējis no visām tavām ciltīm, lai tas stāv un kalpo Tā Kunga vārdam, viņš un viņa dēli visu mūžu.
6 Tí ọmọ Lefi kan bá sì wá láti ibikíbi nínú àwọn ìlú u yín ní Israẹli, níbi tí ó ń gbé ṣe àtìpó, tí ó sì wá gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀ sí ibi tí Olúwa yóò yàn.
Un ja kāds Levits nāk no kādiem Israēla vārtiem, kur viņš piemīt, un nāk, tā kā viņa dvēselei tīk, uz to vietu, ko Tas Kungs izredzēs,
7 Nígbà náà ni ó lè máa ṣe ìránṣẹ́ ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ Lefi arákùnrin rẹ̀ ti ń dúró ṣe iṣẹ́ ìsìn níwájú Olúwa níbẹ̀.
Un kalpo Tā Kunga, sava Dieva, vārdā, kā visi viņa brāļi, tie Leviti, kas tur Tā Kunga priekšā stāv,
8 Wọn yóò ní ìpín kan láti jẹ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti gba owó nípa títa ogún baba rẹ̀.
Tad lai tie ēd līdzīgu daļu, pāri par viņu ienākumu no tēvu puses.
9 Nígbà tí o bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi fún ọ, ìwọ kò gbọdọ̀ kọ́ láti tẹ̀lé àwọn ọ̀nà ìríra àwọn orílẹ̀-èdè náà tí ó wà níbẹ̀.
Kad tu nāc tai zemē, ko Tas Kungs, tavs Dievs, tev dos, tad tev nebūs mācīties darīt pēc šo pagānu negantībām.
10 Má ṣe jẹ́ kí a rí ẹnikẹ́ni láàrín yín tí ó fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin la iná já (fi ọmọ rẹ rú ẹbọ) kí ẹnikẹ́ni má ṣe lọ fọ àfọ̀ṣẹ, tàbí ṣẹ́ oṣó, tàbí túmọ̀ àwọn àmì nǹkan tí ń bọ̀, tàbí àjẹ́,
Lai tavā starpā netop atrasts, kas savam dēlam vai savai meitai liek iet caur uguni, neviens zīlnieks, ne burvis, ne pūšļotājs, ne riebējs,
11 tàbí afògèdè, tàbí jẹ́ a bá iwin gbìmọ̀ tàbí oṣó tàbí abókùúsọ̀rọ̀.
Ne vārdotājs, ne pareģis, ne pesteļu cienītājs, nedz miroņu vaicātājs.
12 Ẹnikẹ́ni tó bá ṣe nǹkan wọ̀nyí jẹ́ ìríra sí Olúwa, àti nítorí àwọn ìwà ìríra wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò fi lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde kúrò níwájú rẹ.
Jo visi, kas to dara, Tam Kungam ir negantība, un šīs negantības dēļ Tas Kungs, tavs Dievs, tos izdzen tavā priekšā.
13 O ní láti jẹ́ aláìlẹ́gàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ.
Bezvainīgam tev būs būt Tā Kunga, sava Dieva, priekšā.
14 Àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ yóò gba ilẹ̀ tí wọ́n ń gbé, wọ́n fetí sí tí àwọn tí ó ń ṣe oṣó tàbí ṣe àfọ̀ṣẹ. Ṣùgbọ́n, ní ti ìwọ, Olúwa Ọlọ́run rẹ kò fi ààyè gbà ọ́ láti ṣe bẹ́ẹ̀.
Jo šās tautas, ko tu izdzīsi, cienī burvjus un zīlniekus, bet tev tā neklājās; tev Tas Kungs, tavs Dievs, tā nav devis.
15 Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé wòlíì kan dìde gẹ́gẹ́ bí èmi láàrín àwọn arákùnrin rẹ. Tìrẹ ni kí o gbọ́.
Pravieti, kāds es esmu, Tas Kungs, tavs Dievs, tev cels no tava vidus, no taviem brāļiem, - tam jums būs klausīt.
16 Nítorí èyí ni ohun tí ìwọ béèrè lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Horebu ní ọjọ́ àjọ, nígbà tí ìwọ wí pé, “Kí àwa má ṣe gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run wa tàbí rí iná ńlá yìí mọ́. Bí bẹ́ẹ̀ kọ́ àwa yóò kú.”
Pēc visa tā, ko tu esi lūdzies no Tā Kunga, sava Dieva, Horebā, sapulces dienā, sacīdams: es vairs negribu dzirdēt Tā Kunga, sava Dieva, balsi, un negribu vairs redzēt šo lielo uguni, ka nemirstu.
17 Olúwa sì wí fún mi pé, “Ohun tí wọ́n sọ dára.
Tad Tas Kungs uz mani sacīja: tas ir labi, ko tie runājuši.
18 Èmi yóò gbé wòlíì kan dìde fún wọn láàrín àwọn arákùnrin wọn bí ìwọ, Èmi yóò fi ọ̀rọ̀ mi sí i ní ẹnu, yóò sì sọ fún wọn gbogbo ohun tí mo ti paláṣẹ fún un.
Es tiem celšu pravieti, kāds tu esi, no viņu brāļu vidus, un Es likšu Savu vārdu viņa mutē, un viņš runās uz tiem visu, ko Es tam pavēlēšu.
19 Ẹnikẹ́ni tí kò bá sì tẹ́tí sí ọ̀rọ̀ mi tí wòlíì náà yóò sọ ní orúkọ mi, èmi fúnra à mi yóò sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀.
Un ja kāds neklausīs Maniem vārdiem, ko viņš runās Manā Vārdā, no tā Es to prasīšu.
20 Ṣùgbọ́n bí wòlíì kan bá kùgbù sọ ọ̀rọ̀ kan tí èmi kò paláṣẹ fún un láti sọ ní orúkọ mi tàbí wòlíì tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ ọlọ́run mìíràn, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ ní láti kú.”
Bet tas pravietis, kas iedrošinājās runāt Manā Vārdā, ko Es tam neesmu pavēlējis runāt, vai ja tas citu dievu vārdā runās, šim pravietim būs mirt.
21 Ṣùgbọ́n ìwọ lè wí ní ọkàn rẹ pé, “Báwo ni àwa yóò ṣe mọ ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ?”
Ja tu tad savā sirdī sacīsi: kā lai pazīstam to vārdu, ko Tas Kungs nav runājis? -
22 Nígbà tí ohun tí wòlíì bá sọ ní orúkọ Olúwa kò bá wá sí ìmúṣẹ tàbí jẹ́ òtítọ́, ìyẹn ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa kò sọ, irú wòlíì bẹ́ẹ̀ tí sọ láìwádìí. Kí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀.
Kad tas pravietis Tā Kunga Vārdā runās, un tas vārds nenotiek un nenāk, - tad šis ir tas vārds, ko Tas Kungs nav runājis, tas pravietis to ir aplam runājis, tāpēc nebīsties no viņa.