< Deuteronomy 17 >
1 Ẹ má ṣe fi màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù, tàbí àbàwọ́n rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ìríra ni èyí yóò jẹ́ fún un.
Du skall icke offra åt Herren, din Gud, något djur av fäkreaturen eller av småboskapen, som har något lyte eller något annat fel, ty sådant är en styggelse för Herren, din Gud.
2 Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan tó ń gbé láàrín yín ní èyíkéyìí ìlú wọ̀n-ọn-nì, tí Olúwa fún un yín bá ń ṣe ibi ní ojú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ríré májẹ̀mú rẹ̀ kọjá,
Om bland dig, inom någon av de städer som Herren, din Gud, vill giva dig, någon man eller kvinna befinnes göra vad ont är i Herrens, din Guds, ögon, i det att han överträder hans förbund,
3 èyí tí ó lòdì sí òfin mi, ó ń sin ọlọ́run mìíràn, ó ń foríbalẹ̀ fún wọn: àní sí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run,
och går åstad och tjänar andra gudar och tillbeder dem, eller ock solen eller månen eller himmelens hela härskara, mot mitt bud,
4 tí èyí sì dé etí ìgbọ́ ọ yín, kí ẹ wádìí ọ̀rọ̀ náà dájúdájú. Bí ó bá jẹ́ òtítọ́ tí ó sì hàn gbangba pé ó ti ṣe ohun ìríra yìí, ní Israẹli.
och detta bliver berättat för dig, så att du får höra därom, då skall du noga undersöka saken; om det då befinnes vara sant och visst att en sådan styggelse har blivit förövad i Israel,
5 Ẹ mú ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ti ṣe ibi yìí wá sí ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú u yín, kí ẹ sọ ọ́ ní òkúta pa.
så skall du föra den man eller den kvinna som har gjort denna onda gärning ut till din stadsport det må nu vara en man eller en kvinna-och stena den skyldige till döds.
6 Lénu ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta ni a ó pa ọkùnrin náà tí ó yẹ láti kú, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe pànìyàn nípasẹ̀ ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo.
Efter två eller tre vittnens utsago skall han dödas; ingen skall dömas till döden efter allenast ett vittnes utsago.
7 Àwọn ẹlẹ́rìí ni kí ó kọ́kọ́ gbọ́wọ́ lé e láti pa á. Lẹ́yìn èyí ni kí gbogbo ènìyàn dáwọ́jọ láti pa á. Nípa báyìí, ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní àárín yín.
Först skall vittnenas hand lyftas mot honom för att döda honom, och sedan hela folkets hand: du skall skaffa bort ifrån dig vad ont är.
8 Bí ẹjọ́ bá wá sí ilé ẹjọ́ èyí tí ó nira jù láti dá, yálà ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni, ọ̀ràn dídá tàbí ìkanni-lábùkù, ẹ mú wọn lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn.
Om det i något fall bliver dig för svårt att själv döma i en blodssak eller i en rättsfråga eller i ett misshandlingsmål eller överhuvud i någon sak varom man tvistar i dina portar, så skall du-stå upp och begiva dig till den plats som HERREN, din Gud, utväljer,
9 Ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àlùfáà tí í ṣe Lefi, àní sí ọ̀dọ̀ adájọ́ tí ó wà fún ìgbẹ́jọ́ ní ìgbà náà. Ẹ béèrè lọ́wọ́ wọn, wọn yóò sì ṣe ìdájọ́.
och gå till de levitiska prästerna, och till den som på den tiden är domare; dem skall du fråga, och de skola förkunna för dig vad som är rätt.
10 Kí ìwọ kí ó sì ṣe bí ọ̀rọ̀ ìdájọ́, ti àwọn ará ibi tí Olúwa yóò yàn náà yóò fihàn ọ, kí ìwọ kí ó sì máa kíyèsí àti máa ṣe gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí wọn kọ́ ọ.
Och i enlighet med vad de förkunna för dig där, på den plats som Herren utväljer. skall du göra; du skall i alla stycken hålla och göra vad de lära dig.
11 Ẹ ṣe bí òfin tí wọ́n kọ́ ọ yín, àti ìpinnu tí wọ́n fún un yín. Ẹ má ṣe yípadà sọ́tùn tàbí sósì, kúrò nínú ohun tí wọ́n sọ fún un yín.
Efter den lag som de lära dig, och efter den dom som de avkunna för dig skall du göra. Från det som de förkunna för dig skall du icke vika av, vare sig till höger eller till vänster.
12 Ọkùnrin náà tí ó bá ṣe àìbọ̀wọ̀ fún adájọ́ tàbí àlùfáà tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, níbẹ̀ ni kí ẹ pa á. Nípa báyìí ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní Israẹli.
Men om någon gör sig skyldig till den förmätenheten att icke vilja lyssna till prästen, som står och gör tjänst där inför Herren, din Gud, eller till domaren, så skall den mannen dö: du skall skaffa bort ifrån Israel vad ont är.
13 Gbogbo ènìyàn ni yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, wọn kò sì ní ṣe àìgbọ́ràn mọ́.
Och allt folket skall höra det och frukta, och de skola icke mer göra sig skyldiga till sådan förmätenhet.
14 Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, tí ẹ sì ti gba ilẹ̀ náà, tí ẹ sì ń gbé inú rẹ̀, tí ẹ sì wá sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a yan ọba tí yóò jẹ lé wa lórí bí i ti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.”
När du kommer in i det land som Herren, din Gud, vill giva dig, och du tager det i besittning och bor där om du då säger: »Jag vill sätta en konung över mig, såsom alla folk omkring mig hava»,
15 Ẹ rí i dájú pé ọba tí Olúwa Ọlọ́run yín yàn fún un yín ní ẹ yàn. Ó gbọdọ̀ jẹ́ láàrín àwọn arákùnrin yín. Ẹ má ṣe fi àjèjì jẹ ọba lórí i yín: àní ẹni tí kì í ṣe arákùnrin ní Israẹli.
så skall du till konung över dig sätta den som Herren, din Gud, utväljer. En av dina bröder skall du sätta till konung över dig; du får icke sätta till konung över dig en utländsk man, som icke är din broder.
16 Síwájú sí i, ọba náà kò gbọdọ̀ kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin jọ fún ara rẹ̀, tàbí kí ó rán àwọn ènìyàn náà padà sí Ejibiti láti wá àwọn ẹṣin sí i, nítorí pé Olúwa ti sọ fún un yín pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ tún padà lọ ní ọ̀nà náà mọ́.”
Men han må icke skaffa sig hästar i mängd, och icke sända sitt folk tillbaka till Egypten för att skaffa de många hästarna, ty Herren har ju sagt till eder: »I skolen icke mer återvända denna väg.»
17 Kò gbọdọ̀ kó aya jọ, kí ọkàn rẹ̀ má bá a yapa kúrò. Kò gbọdọ̀ kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara rẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Icke heller skall han skaffa sig hustrur i mängd, på det att hans hjärta icke må bliva avfälligt; och icke heller skall han skaffa sig alltför mycket silver och guld.
18 Nígbà tí ó bá jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀, kí ó ṣe àdàkọ àwọn òfin wọ̀nyí sí inú ìwé fún ara rẹ̀, láti inú ti àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi.
Och när han har blivit uppsatt på sin konungatron, skall han hämta denna lag från de levitiska prästerna och taga en avskrift därav åt sig i en bok.
19 Èyí yóò sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun ó sì máa kà nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, kí ó lè máa kọ́ àti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, láti máa tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí àti àwọn ìlànà rẹ̀ tọkàntọkàn.
Och den skall han hava hos sig och läsa i den i alla sina livsdagar, för att han må lära att frukta Herren, sin Gud, så att han håller alla denna lags ord och dessa stadgar och gör efter dem.
20 Kí ó má ba à lérò pé òun sàn ju àwọn arákùnrin rẹ̀ yòókù lọ, kí ó sì ti ipa bẹ́ẹ̀ yípadà kúrò nínú òfin wọ̀nyí sí ọ̀tún tàbí sí òsì. Bẹ́ẹ̀ ni òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jẹ ọba pẹ́ títí ní Israẹli.
Så skall han göra, för att hans hjärta icke må förhäva sig över hans bröder, och för att han icke må vika av ifrån buden, vare sig till höger eller till vänster; på det att han och hans söner må länge regera; sitt rike, bland Israels folk.