< Deuteronomy 17 >

1 Ẹ má ṣe fi màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù, tàbí àbàwọ́n rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ìríra ni èyí yóò jẹ́ fún un.
Nie złożysz PANU, swemu Bogu, ofiary z cielca lub owcy, które mają skazę lub jakąkolwiek wadę, gdyż to budzi odrazę w PANU, twym Bogu.
2 Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan tó ń gbé láàrín yín ní èyíkéyìí ìlú wọ̀n-ọn-nì, tí Olúwa fún un yín bá ń ṣe ibi ní ojú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ríré májẹ̀mú rẹ̀ kọjá,
Jeśli znajdzie się pośród was w jakimkolwiek z twoich miast, które daje ci PAN, twój Bóg, mężczyzna czy kobieta, którzy dopuszczą się zła w oczach PANA, twego Boga, przekraczając jego przymierze;
3 èyí tí ó lòdì sí òfin mi, ó ń sin ọlọ́run mìíràn, ó ń foríbalẹ̀ fún wọn: àní sí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run,
I idąc, będą służyć innym bogom i oddawać pokłon im lub słońcu, księżycowi albo całemu zastępowi niebios, czego nie nakazałem;
4 tí èyí sì dé etí ìgbọ́ ọ yín, kí ẹ wádìí ọ̀rọ̀ náà dájúdájú. Bí ó bá jẹ́ òtítọ́ tí ó sì hàn gbangba pé ó ti ṣe ohun ìríra yìí, ní Israẹli.
I zostanie ci o tym doniesione, a ty wysłuchasz tego, zbadasz [to] dokładnie i okaże się [to] prawdą i rzeczą pewną, że popełniono taką obrzydliwość w Izraelu;
5 Ẹ mú ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ti ṣe ibi yìí wá sí ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú u yín, kí ẹ sọ ọ́ ní òkúta pa.
Wtedy wyprowadzisz do swoich bram tego mężczyznę lub tę kobietę, którzy dopuścili się tego zła, i tego mężczyznę lub tę kobietę ukamienujesz, aż umrą.
6 Lénu ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta ni a ó pa ọkùnrin náà tí ó yẹ láti kú, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe pànìyàn nípasẹ̀ ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo.
Na podstawie zeznania dwóch lub trzech świadków ma być zabity skazany na śmierć; nie wolno skazać go na śmierć na podstawie zeznania jednego świadka.
7 Àwọn ẹlẹ́rìí ni kí ó kọ́kọ́ gbọ́wọ́ lé e láti pa á. Lẹ́yìn èyí ni kí gbogbo ènìyàn dáwọ́jọ láti pa á. Nípa báyìí, ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní àárín yín.
Ręka świadków będzie na nim, aby go zabić, a potem ręce całego ludu. Tak usuniesz zło spośród siebie.
8 Bí ẹjọ́ bá wá sí ilé ẹjọ́ èyí tí ó nira jù láti dá, yálà ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni, ọ̀ràn dídá tàbí ìkanni-lábùkù, ẹ mú wọn lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn.
Jeśli sprawa sądowa dotycząca przelania krwi, roszczeń, zranień oraz sporów w twoich bramach będzie dla ciebie za trudna, wtedy wstaniesz i pójdziesz do miejsca, które PAN, twój Bóg, wybierze.
9 Ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àlùfáà tí í ṣe Lefi, àní sí ọ̀dọ̀ adájọ́ tí ó wà fún ìgbẹ́jọ́ ní ìgbà náà. Ẹ béèrè lọ́wọ́ wọn, wọn yóò sì ṣe ìdájọ́.
I przyjdziesz do kapłanów Lewitów, i do sędziego, który w tym czasie będzie [urzędował], i poradzisz się ich, a oni oznajmią ci orzeczenie.
10 Kí ìwọ kí ó sì ṣe bí ọ̀rọ̀ ìdájọ́, ti àwọn ará ibi tí Olúwa yóò yàn náà yóò fihàn ọ, kí ìwọ kí ó sì máa kíyèsí àti máa ṣe gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí wọn kọ́ ọ.
I postąpisz zgodnie z orzeczeniem, które ci przekażą na tym miejscu, które PAN wybrał, i pilnie wykonasz wszystko tak, jak cię pouczą.
11 Ẹ ṣe bí òfin tí wọ́n kọ́ ọ yín, àti ìpinnu tí wọ́n fún un yín. Ẹ má ṣe yípadà sọ́tùn tàbí sósì, kúrò nínú ohun tí wọ́n sọ fún un yín.
Postąpisz zgodnie z pouczeniem prawa, którego ci udzielą, i zgodnie z rozstrzygnięciem, które ci przekażą. Nie odstąpisz od orzeczenia, które ci oznajmią ani na prawo, ani na lewo.
12 Ọkùnrin náà tí ó bá ṣe àìbọ̀wọ̀ fún adájọ́ tàbí àlùfáà tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, níbẹ̀ ni kí ẹ pa á. Nípa báyìí ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní Israẹli.
A człowiek, który postąpi zuchwale i nie posłucha kapłana pełniącego tam służbę przed PANEM, twoim Bogiem, lub sędziego, poniesie śmierć. Tak usuniesz to zło z Izraela.
13 Gbogbo ènìyàn ni yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, wọn kò sì ní ṣe àìgbọ́ràn mọ́.
A cały lud usłyszy [o tym] i będzie się bał, i nie postąpi już zuchwale.
14 Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, tí ẹ sì ti gba ilẹ̀ náà, tí ẹ sì ń gbé inú rẹ̀, tí ẹ sì wá sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a yan ọba tí yóò jẹ lé wa lórí bí i ti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.”
Gdy wejdziesz do ziemi, którą daje ci PAN, twój Bóg, gdy posiądziesz ją i zamieszkasz w niej, i powiesz sobie: Ustanowię nad sobą króla tak jak wszystkie okoliczne narody;
15 Ẹ rí i dájú pé ọba tí Olúwa Ọlọ́run yín yàn fún un yín ní ẹ yàn. Ó gbọdọ̀ jẹ́ láàrín àwọn arákùnrin yín. Ẹ má ṣe fi àjèjì jẹ ọba lórí i yín: àní ẹni tí kì í ṣe arákùnrin ní Israẹli.
Tego tylko ustanowisz królem nad sobą, którego PAN, twój Bóg, wybierze. Spośród swoich braci ustanowisz nad sobą króla; nie możesz ustanowić nad sobą cudzoziemca, który nie jest twoim bratem.
16 Síwájú sí i, ọba náà kò gbọdọ̀ kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin jọ fún ara rẹ̀, tàbí kí ó rán àwọn ènìyàn náà padà sí Ejibiti láti wá àwọn ẹṣin sí i, nítorí pé Olúwa ti sọ fún un yín pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ tún padà lọ ní ọ̀nà náà mọ́.”
Tylko niech nie pomnaża sobie koni ani nie prowadzi ludu do Egiptu, aby nabyć wiele koni, ponieważ PAN wam powiedział: Nie wracajcie tą drogą nigdy więcej.
17 Kò gbọdọ̀ kó aya jọ, kí ọkàn rẹ̀ má bá a yapa kúrò. Kò gbọdọ̀ kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara rẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Nie będzie też pomnażał sobie żon, aby jego serce się nie odwróciło; niech nie nabywa zbyt wiele srebra i złota.
18 Nígbà tí ó bá jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀, kí ó ṣe àdàkọ àwọn òfin wọ̀nyí sí inú ìwé fún ara rẹ̀, láti inú ti àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi.
A gdy już zasiądzie na swym królewskim tronie, napisze sobie w księdze odpis tego prawa od kapłanów Lewitów.
19 Èyí yóò sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun ó sì máa kà nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, kí ó lè máa kọ́ àti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, láti máa tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí àti àwọn ìlànà rẹ̀ tọkàntọkàn.
I będzie go miał przy sobie, i będzie go czytał po wszystkie dni swego życia, aby się nauczył bać PANA, swego Boga, by przestrzegał wszystkich słów tego prawa oraz tych ustaw i [aby] je wykonywał;
20 Kí ó má ba à lérò pé òun sàn ju àwọn arákùnrin rẹ̀ yòókù lọ, kí ó sì ti ipa bẹ́ẹ̀ yípadà kúrò nínú òfin wọ̀nyí sí ọ̀tún tàbí sí òsì. Bẹ́ẹ̀ ni òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jẹ ọba pẹ́ títí ní Israẹli.
Aby jego serce nie wynosiło się ponad jego braci i żeby nie odstąpił od tego przykazania ani na prawo, ani na lewo, aby żył długo w swoim królestwie, on i jego synowie, pośród Izraela.

< Deuteronomy 17 >