< Deuteronomy 17 >

1 Ẹ má ṣe fi màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù, tàbí àbàwọ́n rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ìríra ni èyí yóò jẹ́ fún un.
Nie będziesz ofiarował Panu, Bogu twemu, wołu, ani bydlęcia, na którem by była skaza, albo jakakolwiek wada, gdyż to jest obrzydliwością Panu, Bogu twemu.
2 Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan tó ń gbé láàrín yín ní èyíkéyìí ìlú wọ̀n-ọn-nì, tí Olúwa fún un yín bá ń ṣe ibi ní ojú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ríré májẹ̀mú rẹ̀ kọjá,
Jeźliby się znalazł między wami w któremkolwiek mieście twem, które Pan, Bóg twój, dawa tobie, mąż albo niewiasta, któryby się czego złego dopuścił przed oczyma Pana, Boga twego, przestępując przymierze jego,
3 èyí tí ó lòdì sí òfin mi, ó ń sin ọlọ́run mìíràn, ó ń foríbalẹ̀ fún wọn: àní sí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run,
A poszedłszy, służyłby obcym bogom, i kłaniałby się im, albo słońcu, albo miesiącowi, albo wszystkim zastępom niebieskim, czegom nie przykazał;
4 tí èyí sì dé etí ìgbọ́ ọ yín, kí ẹ wádìí ọ̀rọ̀ náà dájúdájú. Bí ó bá jẹ́ òtítọ́ tí ó sì hàn gbangba pé ó ti ṣe ohun ìríra yìí, ní Israẹli.
I oznajmionoć by to, a usłyszawszy, wywiadowałbyś się pilno, a oto, byłaby prawda, i rzecz pewna, że się stała ta obrzydliwość w Izraelu:
5 Ẹ mú ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ti ṣe ibi yìí wá sí ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú u yín, kí ẹ sọ ọ́ ní òkúta pa.
Tedy wywiedziesz onego męża, albo onę niewiastę, którzy uczynili tę złą rzecz, do bram twoich, męża onego, albo niewiastę, i ukamionujesz je, a pomrą.
6 Lénu ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta ni a ó pa ọkùnrin náà tí ó yẹ láti kú, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe pànìyàn nípasẹ̀ ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo.
W uściech dwóch świadków, albo trzech świadków zabity będzie, kto umrzeć ma; niech nie umiera na słowo świadka jednego.
7 Àwọn ẹlẹ́rìí ni kí ó kọ́kọ́ gbọ́wọ́ lé e láti pa á. Lẹ́yìn èyí ni kí gbogbo ènìyàn dáwọ́jọ láti pa á. Nípa báyìí, ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní àárín yín.
Ręka świadków będzie na nim najpierwsza, na zabicie jego, a ręka wszystkiego ludu potem; a tak odejmiesz złe z pośrodku siebie.
8 Bí ẹjọ́ bá wá sí ilé ẹjọ́ èyí tí ó nira jù láti dá, yálà ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni, ọ̀ràn dídá tàbí ìkanni-lábùkù, ẹ mú wọn lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn.
Byłoliby też co trudnego przy sądzie, między krwią a krwią, między sprawą a sprawą, i między raną a raną, i około poswarków w bramach twoich, tedy wstaniesz, a pójdziesz na miejsce, które obierze Pan, Bóg twój.
9 Ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àlùfáà tí í ṣe Lefi, àní sí ọ̀dọ̀ adájọ́ tí ó wà fún ìgbẹ́jọ́ ní ìgbà náà. Ẹ béèrè lọ́wọ́ wọn, wọn yóò sì ṣe ìdájọ́.
I przyjdziesz do kapłanów Lewitów, i do sędziego, który będzie na on czas, i będziesz ich pytał, a oznajmiąć, jako to osądzić masz.
10 Kí ìwọ kí ó sì ṣe bí ọ̀rọ̀ ìdájọ́, ti àwọn ará ibi tí Olúwa yóò yàn náà yóò fihàn ọ, kí ìwọ kí ó sì máa kíyèsí àti máa ṣe gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí wọn kọ́ ọ.
I uczynisz według tego, jakoć powiedzą z miejsca tego, które obrał Pan, i postąpisz sobie według wszystkiego, jako cię nauczą.
11 Ẹ ṣe bí òfin tí wọ́n kọ́ ọ yín, àti ìpinnu tí wọ́n fún un yín. Ẹ má ṣe yípadà sọ́tùn tàbí sósì, kúrò nínú ohun tí wọ́n sọ fún un yín.
Według słów zakonu, którego cię nauczą, i według sądu, któryć powiedzą, sprawować się będziesz; nie ustąpisz od słowa, któreć powiedzą, ani na prawo ani na lewo.
12 Ọkùnrin náà tí ó bá ṣe àìbọ̀wọ̀ fún adájọ́ tàbí àlùfáà tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, níbẹ̀ ni kí ẹ pa á. Nípa báyìí ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní Israẹli.
A jeźliby kto uczynił to z hardości, żeby nie chciał usłuchać kapłana tam postanowionego ku służbie przed Panem, Bogiem twoim, albo sędziego, niech umrze on mąż; i odejmiesz to złe z Izraela,
13 Gbogbo ènìyàn ni yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, wọn kò sì ní ṣe àìgbọ́ràn mọ́.
Aby wszystek lud usłyszawszy bał się, a więcej hardzie sobie nie poczynał.
14 Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, tí ẹ sì ti gba ilẹ̀ náà, tí ẹ sì ń gbé inú rẹ̀, tí ẹ sì wá sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a yan ọba tí yóò jẹ lé wa lórí bí i ti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.”
Gdy wnijdziesz do ziemi, którą Pan, Bóg twój, dawa tobie, a opanujesz ją, i będziesz mieszkał w niej, i rzeczesz: Postanowię nad sobą króla, jako i wszystkie narody okoliczne:
15 Ẹ rí i dájú pé ọba tí Olúwa Ọlọ́run yín yàn fún un yín ní ẹ yàn. Ó gbọdọ̀ jẹ́ láàrín àwọn arákùnrin yín. Ẹ má ṣe fi àjèjì jẹ ọba lórí i yín: àní ẹni tí kì í ṣe arákùnrin ní Israẹli.
Tego tylko postanowisz nad sobą króla, którego obierze Pan, Bóg twój; z pośrodku braci twej postanowisz nad sobą króla; nie będziesz mógł przełożyć nad sobą cudzoziemca, któryby nie był bratem twoim.
16 Síwájú sí i, ọba náà kò gbọdọ̀ kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin jọ fún ara rẹ̀, tàbí kí ó rán àwọn ènìyàn náà padà sí Ejibiti láti wá àwọn ẹṣin sí i, nítorí pé Olúwa ti sọ fún un yín pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ tún padà lọ ní ọ̀nà náà mọ́.”
Tylko niech nie chowa wiele koni, ani nawraca ludu do Egiptu, aby wiele koni nabył, ponieważ wam Pan rzekł: Nie wracajcie się zaś tą drogą więcej.
17 Kò gbọdọ̀ kó aya jọ, kí ọkàn rẹ̀ má bá a yapa kúrò. Kò gbọdọ̀ kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara rẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Nie będzie też miał wiele żon, aby się nie odwróciło serce jego; srebra też i złota niech nazbyt wiele nie nabywa.
18 Nígbà tí ó bá jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀, kí ó ṣe àdàkọ àwọn òfin wọ̀nyí sí inú ìwé fún ara rẹ̀, láti inú ti àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi.
A gdy usiędzie na stolicy królestwa swego, przepisze sobie ten powtórzony zakon w księgi od kapłanów Lewitów.
19 Èyí yóò sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun ó sì máa kà nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, kí ó lè máa kọ́ àti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, láti máa tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí àti àwọn ìlànà rẹ̀ tọkàntọkàn.
A będzie go miał przy sobie a będzie go czytał po wszystkie dni żywota swego, aby się uczył bać Pana, Boga swego, i przestrzegał wszystkich słów zakonu tego, i ustaw tych, a czynił je;
20 Kí ó má ba à lérò pé òun sàn ju àwọn arákùnrin rẹ̀ yòókù lọ, kí ó sì ti ipa bẹ́ẹ̀ yípadà kúrò nínú òfin wọ̀nyí sí ọ̀tún tàbí sí òsì. Bẹ́ẹ̀ ni òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jẹ ọba pẹ́ títí ní Israẹli.
Aby się nie wynosiło serce jego nad bracią jego, i żeby się nie unosiło od tego przykazania na prawo, ani na lewo, aby długo żył na królestwie swojem, on i synowie jego w pośrodku Izraela.

< Deuteronomy 17 >