< Deuteronomy 17 >
1 Ẹ má ṣe fi màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù, tàbí àbàwọ́n rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ìríra ni èyí yóò jẹ́ fún un.
“Lingenzi umhlatshelo kuThixo uNkulunkulu wenu ngenkabi loba imvu elesici lesolekayo, ngoba lokho kuyisinengiso kuye.
2 Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan tó ń gbé láàrín yín ní èyíkéyìí ìlú wọ̀n-ọn-nì, tí Olúwa fún un yín bá ń ṣe ibi ní ojú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ríré májẹ̀mú rẹ̀ kọjá,
Nxa kulendoda loba owesifazane ohlala phakathi kwenu kwelinye lamadolobho eliwaphiwa nguThixo uNkulunkulu wenu limfumana esona emehlweni kaThixo uNkulunkulu wenu esephula isivumelwano,
3 èyí tí ó lòdì sí òfin mi, ó ń sin ọlọ́run mìíràn, ó ń foríbalẹ̀ fún wọn: àní sí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run,
njalo ngokwephula imilayo yami esezikhonzela abanye onkulunkulu, ebakhothamela loba ekhonza ilanga loba inyanga loba izinkanyezi zezulu,
4 tí èyí sì dé etí ìgbọ́ ọ yín, kí ẹ wádìí ọ̀rọ̀ náà dájúdájú. Bí ó bá jẹ́ òtítọ́ tí ó sì hàn gbangba pé ó ti ṣe ohun ìríra yìí, ní Israẹli.
kube kanti lokhu sekubikiwe kini, kutsho ukuthi kuzamele likuchwayisise ngokupheleleyo. Nxa kuliqiniso njalo sekubonakele ukuthi kuliqiniso lokhu okuyisinengiso okwenzakele ko-Israyeli,
5 Ẹ mú ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ti ṣe ibi yìí wá sí ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú u yín, kí ẹ sọ ọ́ ní òkúta pa.
thathani leyondoda loba owesifazane lowo owenze lesi senzo esibi limuse esangweni ledolobho lenu limkhande ngamatshe aze afe.
6 Lénu ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta ni a ó pa ọkùnrin náà tí ó yẹ láti kú, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe pànìyàn nípasẹ̀ ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo.
Ngobufakazi bababili loba abathathu indoda izabulawa, kodwa kakho ozabulawa ngobufakazi bomuntu oyedwa kuphela.
7 Àwọn ẹlẹ́rìí ni kí ó kọ́kọ́ gbọ́wọ́ lé e láti pa á. Lẹ́yìn èyí ni kí gbogbo ènìyàn dáwọ́jọ láti pa á. Nípa báyìí, ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní àárín yín.
Akuthi ofakazi labo kube yibo abaqalisayo ukumkhanda, besekulandela bonke abanye abantu. Kumele lisuse ububi phakathi kwenu.”
8 Bí ẹjọ́ bá wá sí ilé ẹjọ́ èyí tí ó nira jù láti dá, yálà ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni, ọ̀ràn dídá tàbí ìkanni-lábùkù, ẹ mú wọn lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn.
“Nxa amacala eza phambi kwemithethwandaba yenu enzima ukuwahlulela, loba awokuchitha igazi, ukwephula imithetho loba awokuhlaselwa, athatheni liye lawo endaweni uThixo uNkulunkulu wenu azayikhetha.
9 Ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àlùfáà tí í ṣe Lefi, àní sí ọ̀dọ̀ adájọ́ tí ó wà fún ìgbẹ́jọ́ ní ìgbà náà. Ẹ béèrè lọ́wọ́ wọn, wọn yóò sì ṣe ìdájọ́.
Hambani kubaphristi, abangabaLevi, kanye lakumahluleli osesikhundleni okwalesosikhathi. Buzani kibo bona bazalinika isigwebo esifaneleyo.
10 Kí ìwọ kí ó sì ṣe bí ọ̀rọ̀ ìdájọ́, ti àwọn ará ibi tí Olúwa yóò yàn náà yóò fihàn ọ, kí ìwọ kí ó sì máa kíyèsí àti máa ṣe gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí wọn kọ́ ọ.
Lina-ke kumele lenze njengokucebisa kwabo endaweni uThixo azayikhetha. Linanzelele ukuthi lenza lokho kanye abaliqondisa ukuba likwenze.
11 Ẹ ṣe bí òfin tí wọ́n kọ́ ọ yín, àti ìpinnu tí wọ́n fún un yín. Ẹ má ṣe yípadà sọ́tùn tàbí sósì, kúrò nínú ohun tí wọ́n sọ fún un yín.
Yenzani ngokomthetho njengalokho abalifundisa ngakho lezinqumo abalipha zona. Lingaphambuki kulokho abalitshela khona, liye kwesokudla loba kwesenxele.
12 Ọkùnrin náà tí ó bá ṣe àìbọ̀wọ̀ fún adájọ́ tàbí àlùfáà tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, níbẹ̀ ni kí ẹ pa á. Nípa báyìí ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní Israẹli.
Indoda etshengisela ukudelela iseyisa umahluleli loba umphristi owenza umsebenzi wokukhonza khonapho uThixo uNkulunkulu wenu kumele ibulawe. Kumele lisuse bonke ububi phakathi kuka-Israyeli.
13 Gbogbo ènìyàn ni yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, wọn kò sì ní ṣe àìgbọ́ràn mọ́.
Bonke abantu bazakuzwa besabe, bangabe besadelela futhi.”
14 Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, tí ẹ sì ti gba ilẹ̀ náà, tí ẹ sì ń gbé inú rẹ̀, tí ẹ sì wá sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a yan ọba tí yóò jẹ lé wa lórí bí i ti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.”
“Ekungeneni kwenu elizweni uThixo uNkulunkulu wenu alinika lona selilithethe laba ngelenu njalo selihlezi kulo, njalo selisithi, ‘Asibekeni inkosi isibuse ukuze sifanane lezinye izizwe esakhelene lazo,’
15 Ẹ rí i dájú pé ọba tí Olúwa Ọlọ́run yín yàn fún un yín ní ẹ yàn. Ó gbọdọ̀ jẹ́ láàrín àwọn arákùnrin yín. Ẹ má ṣe fi àjèjì jẹ ọba lórí i yín: àní ẹni tí kì í ṣe arákùnrin ní Israẹli.
wobani leqiniso lokuthi libeka inkosi ekhethwe nguThixo uNkulunkulu wenu. Kumele abe ngomunye wabafowenu. Lingafaki umuntu wezizweni ukuba alibuse, ongasiye wakini ko-Israyeli.
16 Síwájú sí i, ọba náà kò gbọdọ̀ kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin jọ fún ara rẹ̀, tàbí kí ó rán àwọn ènìyàn náà padà sí Ejibiti láti wá àwọn ẹṣin sí i, nítorí pé Olúwa ti sọ fún un yín pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ tún padà lọ ní ọ̀nà náà mọ́.”
Inkosi njalo akumelanga izifuyele amabhiza amanengi loba ithume abantu babuyele eGibhithe ukuyazuza amanye khona ngoba uThixo ulitshelile wathi, ‘Lingaphindi liyihambe njalo leyondlela.’
17 Kò gbọdọ̀ kó aya jọ, kí ọkàn rẹ̀ má bá a yapa kúrò. Kò gbọdọ̀ kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara rẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Kayingathathi abafazi abanengi funa inhliziyo yayo idukiswe. Kayingazinothisi ngesiliva langegolide elinengi kakhulu.
18 Nígbà tí ó bá jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀, kí ó ṣe àdàkọ àwọn òfin wọ̀nyí sí inú ìwé fún ara rẹ̀, láti inú ti àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi.
Nxa isithatha isihlalo sobukhosi bombuso wayo kayithathe umqulu izilobele kulo umthetho lo iwuthatha encwadini yabaphristi abangabaLevi.
19 Èyí yóò sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun ó sì máa kà nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, kí ó lè máa kọ́ àti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, láti máa tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí àti àwọn ìlànà rẹ̀ tọkàntọkàn.
Umqulu lowo kawuhlale ukuyo, ihlale iwubala zonke insuku zokuphila kwayo ukuze ifunde ukwesaba uThixo uNkulunkulu wayo, ilandele ngokunanzelela wonke amazwi omthetho lo lalezi izimiso,
20 Kí ó má ba à lérò pé òun sàn ju àwọn arákùnrin rẹ̀ yòókù lọ, kí ó sì ti ipa bẹ́ẹ̀ yípadà kúrò nínú òfin wọ̀nyí sí ọ̀tún tàbí sí òsì. Bẹ́ẹ̀ ni òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jẹ ọba pẹ́ títí ní Israẹli.
njalo ukuze ingazenzi ongcono kulabanye abakibo, ingaphambuki emthethweni iye ngakwesokunene loba ngakwesokhohlo. Ngakho yona kanye lezizukulwane zayo bazabusa isikhathi eside embusweni wayo ko-Israyeli.”