< Deuteronomy 17 >

1 Ẹ má ṣe fi màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù, tàbí àbàwọ́n rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí ìríra ni èyí yóò jẹ́ fún un.
Du skal ikke ofre Herren din Gud Okse eller Lam, som har en Lyde, eller nogen slem Ting; thi det er Herren din Gud en Vederstyggelighed.
2 Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan tó ń gbé láàrín yín ní èyíkéyìí ìlú wọ̀n-ọn-nì, tí Olúwa fún un yín bá ń ṣe ibi ní ojú Olúwa Ọlọ́run yín, ní ríré májẹ̀mú rẹ̀ kọjá,
Naar der findes midt iblandt dig, i en af dine Byer, som Herren din Gud giver dig, Mand eller Kvinde, som gør det, som er ondt for Herren din Guds Øjne, ved at overtræde hans Pagt,
3 èyí tí ó lòdì sí òfin mi, ó ń sin ọlọ́run mìíràn, ó ń foríbalẹ̀ fún wọn: àní sí oòrùn, òṣùpá àti àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run,
og denne gaar hen og tjener andre Guder og tilbeder dem, enten Sol eller Maane eller noget af hele Himmelens Hær, som jeg ikke har budet,
4 tí èyí sì dé etí ìgbọ́ ọ yín, kí ẹ wádìí ọ̀rọ̀ náà dájúdájú. Bí ó bá jẹ́ òtítọ́ tí ó sì hàn gbangba pé ó ti ṣe ohun ìríra yìí, ní Israẹli.
og det bliver givet dig til Kende, og du hører det: Da skal du ransage det vel; og se, er det Sandhed, er det Ord vist, er denne Vederstyggelighed sket i Israel:
5 Ẹ mú ọkùnrin tàbí obìnrin tí ó ti ṣe ibi yìí wá sí ẹnu-ọ̀nà ibodè ìlú u yín, kí ẹ sọ ọ́ ní òkúta pa.
Da skal du føre den Mand eller den Kvinde, som gjorde denne onde Handel, ud til dine Porte, Manden eller Kvinden, og du skal stene dem med Sten, og de skulle dø.
6 Lénu ẹlẹ́rìí méjì tàbí mẹ́ta ni a ó pa ọkùnrin náà tí ó yẹ láti kú, ṣùgbọ́n ẹ má ṣe pànìyàn nípasẹ̀ ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo.
Efter to Vidners eller tre Vidners Mund skal den lide Døden, som er skyldig at dø; han skal ikke lide Døden efter eet Vidnes Mund.
7 Àwọn ẹlẹ́rìí ni kí ó kọ́kọ́ gbọ́wọ́ lé e láti pa á. Lẹ́yìn èyí ni kí gbogbo ènìyàn dáwọ́jọ láti pa á. Nípa báyìí, ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní àárín yín.
Vidnernes Haand skal først være paa ham til at slaa ham ihjel og til sidst alt Folkets Haand; saa skal du borttage den onde af din Midte.
8 Bí ẹjọ́ bá wá sí ilé ẹjọ́ èyí tí ó nira jù láti dá, yálà ìtàjẹ̀ sílẹ̀ ni, ọ̀ràn dídá tàbí ìkanni-lábùkù, ẹ mú wọn lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn.
Naar en Sag for Retten er for vanskelig for dig, imellem Blod og Blod, imellem Sag og Sag og imellem Slag og Slag, i hvad Retstrætte der kan være inden dine Porte: Da skal du gøre dig rede og gaa op til det Sted, som Herren din Gud skal udvælge.
9 Ẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn àlùfáà tí í ṣe Lefi, àní sí ọ̀dọ̀ adájọ́ tí ó wà fún ìgbẹ́jọ́ ní ìgbà náà. Ẹ béèrè lọ́wọ́ wọn, wọn yóò sì ṣe ìdájọ́.
Og du skal komme til Præsterne, Leviterne og til den Dommer, som mon være i de samme Dage; og du skal forespørge dig, saa skulle de give dig Rettens Ord til Kende.
10 Kí ìwọ kí ó sì ṣe bí ọ̀rọ̀ ìdájọ́, ti àwọn ará ibi tí Olúwa yóò yàn náà yóò fihàn ọ, kí ìwọ kí ó sì máa kíyèsí àti máa ṣe gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí wọn kọ́ ọ.
Og du skal gøre efter det Ords Lydelse, som de give dig til Kende fra det Sted, som Herren skal udvælge, og du skal tage Vare paa, at du gør efter alt det, som de lære dig.
11 Ẹ ṣe bí òfin tí wọ́n kọ́ ọ yín, àti ìpinnu tí wọ́n fún un yín. Ẹ má ṣe yípadà sọ́tùn tàbí sósì, kúrò nínú ohun tí wọ́n sọ fún un yín.
Efter den Lovs Lydelse, som de lære dig, og efter den Ret, som de sige dig, skal du gøre; du skal ikke vige fra det Ord, som de tilkendegive dig, hverken til højre eller til venstre Side.
12 Ọkùnrin náà tí ó bá ṣe àìbọ̀wọ̀ fún adájọ́ tàbí àlùfáà tí ó ń ṣe iṣẹ́ ìránṣẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run yín, níbẹ̀ ni kí ẹ pa á. Nípa báyìí ẹ̀yin yóò sì fọ ohun búburú náà mọ́ kúrò ní Israẹli.
Men den Mand, som gør noget i Hovmodighed, at han ikke vil høre Præsten, som staar til at tjene der for Herren din Gud, eller Dommeren, den Mand skal dø, og du skal borttage den onde af Israel,
13 Gbogbo ènìyàn ni yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, wọn kò sì ní ṣe àìgbọ́ràn mọ́.
for at alt Folket maa høre det og frygte og ikke mere handle hovmodigen.
14 Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, tí ẹ sì ti gba ilẹ̀ náà, tí ẹ sì ń gbé inú rẹ̀, tí ẹ sì wá sọ pé, “Ẹ jẹ́ kí a yan ọba tí yóò jẹ lé wa lórí bí i ti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.”
Naar du kommer i det Land, som Herren din Gud giver dig, og ejer det og bor deri, og du siger: Jeg vil sætte en Konge over mig ligesom alle Folkene, som ere trindt omkring mig,
15 Ẹ rí i dájú pé ọba tí Olúwa Ọlọ́run yín yàn fún un yín ní ẹ yàn. Ó gbọdọ̀ jẹ́ láàrín àwọn arákùnrin yín. Ẹ má ṣe fi àjèjì jẹ ọba lórí i yín: àní ẹni tí kì í ṣe arákùnrin ní Israẹli.
da skal du sætte den til Konge over dig, som Herren din Gud skal udvælge; du skal sætte en af dine Brødres Midte til Konge over dig, du maa ikke sætte over dig en fremmed Mand, som ikke er din Broder.
16 Síwájú sí i, ọba náà kò gbọdọ̀ kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin jọ fún ara rẹ̀, tàbí kí ó rán àwọn ènìyàn náà padà sí Ejibiti láti wá àwọn ẹṣin sí i, nítorí pé Olúwa ti sọ fún un yín pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ tún padà lọ ní ọ̀nà náà mọ́.”
Kun skal han ikke holde mange Heste og ikke komme Folket til at drage tilbage til Ægypten for at hente mange Heste; thi Herren har sagt eder: I skulle ikke herefter ydermere drage tilbage ad denne Vej.
17 Kò gbọdọ̀ kó aya jọ, kí ọkàn rẹ̀ má bá a yapa kúrò. Kò gbọdọ̀ kó fàdákà àti wúrà jọ fún ara rẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀.
Han skal ikke heller tage sig mange Hustruer, at hans Hjerte ikke skal afvige; han skal ikke heller samle sig saare meget Sølv og Guld.
18 Nígbà tí ó bá jókòó lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ̀, kí ó ṣe àdàkọ àwọn òfin wọ̀nyí sí inú ìwé fún ara rẹ̀, láti inú ti àlùfáà tí wọ́n jẹ́ ọmọ Lefi.
Og det skal ske, naar han sidder paa sit Riges Trone, da skal han lade sig skrive en Afskrift af denne Lov i en Bog efter den, som er hos Præsterne, Leviterne.
19 Èyí yóò sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun ó sì máa kà nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀, kí ó lè máa kọ́ àti bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, láti máa tẹ̀lé gbogbo ọ̀rọ̀ inú òfin yìí àti àwọn ìlànà rẹ̀ tọkàntọkàn.
Og den skal være hos ham, og han skal læse i den alle sit Livs Dage, paa det han kan lære at frygte Herren sin Gud, at holde alle denne Lovs Ord og disse Skikke og gøre efter dem,
20 Kí ó má ba à lérò pé òun sàn ju àwọn arákùnrin rẹ̀ yòókù lọ, kí ó sì ti ipa bẹ́ẹ̀ yípadà kúrò nínú òfin wọ̀nyí sí ọ̀tún tàbí sí òsì. Bẹ́ẹ̀ ni òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò jẹ ọba pẹ́ títí ní Israẹli.
for at hans Hjerte ikke skal ophøje sig over hans Brødre, ej heller vige fra Budet til højre eller venstre Side, for at han maa forlænge sine Dage i sit Kongerige, han og hans Børn i Israel.

< Deuteronomy 17 >