< Deuteronomy 16 >
1 Ẹ kíyèsi oṣù Abibu, kí ẹ sì máa ṣe àjọ̀dún ìrékọjá ti Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí pé ní oṣù Abibu yìí ni ó mú un yín jáde ní Ejibiti lóru.
Ţine luna Abib şi ţine paştele DOMNULUI Dumnezeul tău, pentru că în luna Abib te-a scos DOMNUL Dumnezeul tău din Egipt, noaptea.
2 Ẹ fi ẹran kan rú ẹbọ bí ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín láti inú ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo màlúù yín ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀.
Să sacrifici de aceea paştele DOMNULUI Dumnezeul tău, din cireadă şi din turmă, în locul pe care îl va alege DOMNUL Dumnezeul tău, ca să îşi pună numele său acolo.
3 Ẹ má ṣe jẹ ẹ́ pẹ̀lú u àkàrà tí a fi ìwúkàrà ṣe, ṣùgbọ́n ọjọ́ méje ni kí ẹ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà, àkàrà ìpọ́njú, nítorí pé pẹ̀lú ìkánjú ni ẹ kúrò ní Ejibiti: kí ẹ bá à lè rántí ìgbà tí ẹ kúrò ní Ejibiti ní gbogbo ọjọ́ ayé yín.
Să nu mănânci pâine dospită cu acesta; şapte zile să îl mănânci cu azime, pâinea chinuirii, pentru că ai ieşit în grabă din ţara Egiptului, ca să îţi aminteşti de ziua când ai ieşit din ţara Egiptului în toate zilele vieţii tale.
4 Kí a má sì ṣe rí àkàrà wíwú ní ọ̀dọ̀ rẹ nínú ilẹ̀ rẹ ní ijọ́ méje. Kí ìwọ má ṣe jẹ́ kí nǹkan kan ṣẹ́kù nínú ẹran tí ìwọ ó fi rú ẹbọ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní di àárọ̀ ọjọ́ kejì.
Şi şapte zile să nu se vadă pâine dospită la tine, în toate hotarele tale; nici din carnea pe care o sacrifici seara, în cea dintâi zi, să nu îţi rămână toată noaptea până dimineaţa.
5 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe ìrékọjá náà ní ìlúkílùú kankan, tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín
Nu poţi sacrifica paştele în oricare din porţile tale, pe care ţi le dă DOMNUL Dumnezeul tău,
6 bí kò ṣe ibi tí yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀, níbẹ̀ ni ki ẹ ti ṣe ìrúbọ ìrékọjá náà ní ìrọ̀lẹ́ nígbà tí oòrùn bá ń wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìrántí ìgbà tí ẹ kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Ci la locul pe care îl va alege DOMNUL Dumnezeul tău să îşi pună numele său în el, acolo să sacrifici paştele, seara, la apusul soarelui, pe timpul când ai ieşit din Egipt.
7 Ẹ sun ún kí ẹ sì jẹ ẹ́ ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn. Ní àárọ̀, kí ẹ padà sí àgọ́ ọ yín.
Şi să frigi şi să mănânci în locul pe care îl va alege DOMNUL Dumnezeul tău şi dimineaţa să te întorci şi să te duci la corturile tale.
8 Ọjọ́ mẹ́fà ní kí ẹ fi jẹ àkàrà aláìwú, ní ọjọ́ keje, ẹ pe àjọ kan fún Olúwa Ọlọ́run yín, kí ẹ má sì ṣe iṣẹ́ kankan.
Şase zile să mănânci azime, iar în ziua a şaptea să fie o adunare solemnă pentru DOMNUL Dumnezeul tău; să nu faci nicio lucrare în ea.
9 Ka ọ̀sẹ̀ méje láti ìgbà tí ẹ bá ti bẹ̀rẹ̀ sí fi dòjé ṣe ìkórè ọkà.
Să îţi numeri şapte săptămâni; să începi să numeri cele şapte săptămâni de când începi să pui secera în grâne.
10 Nígbà náà ni kí ẹ ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nípa pípèsè ọrẹ àtinúwá, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
Şi să ţii sărbătoarea săptămânilor pentru DOMNUL Dumnezeul tău, cu o taxă a unei ofrande de bunăvoie din mâna ta, pe care să o dai DOMNULUI precum te va fi binecuvântat DOMNUL Dumnezeul tău.
11 Kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí yóò yàn ní ibùgbé fún orúkọ rẹ̀: ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin, àwọn ẹrú yín ọkùnrin àti àwọn ẹrú yín obìnrin, àwọn Lefi tí ó wà ní ìlú yín, àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé àárín yín.
Şi să te bucuri înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău, tu şi fiul tău şi fiica ta şi servitorul tău şi servitoarea ta, şi levitul care este înăuntrul porţilor tale şi străinul şi cel fără tată şi văduva, care sunt printre voi; în locul pe care l-a ales DOMNUL Dumnezeul tău să îşi pună numele său acolo.
12 Ẹ rántí pé, ẹ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, nítorí náà ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà wọ̀nyí dáradára.
Şi să îţi aminteşti că ai fost rob în Egipt şi să ţii şi să împlineşti aceste statute.
13 Ẹ ṣe ayẹyẹ àgọ́ ìpàdé fún ọjọ́ méje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá ti kórè oko yín tí ẹ ti pakà tí ẹ sì ti fún ọtí tán.
Să ţii sărbătoarea corturilor şapte zile, după ce vei fi adunat grânele tale şi vinul tău,
14 Ẹ máa yọ̀ ní àkókò àjọ̀dún un yín, ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin, àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín, àti àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó tí ń gbé ní àwọn ìlú u yín.
Şi să te bucuri la sărbătoarea ta, tu şi fiul tău şi fiica ta şi servitorul tău şi servitoarea ta şi levitul şi străinul şi cel fără tată şi văduva, care sunt înăuntrul porţilor tale.
15 Ọjọ́ méje ni kí ẹ̀yin kí ó fi ṣe ayẹyẹ fún Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín ní gbogbo ìkórè e yín, àti ní gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín, ayọ̀ ọ yín yóò sì kún.
Şapte zile să ţii o sărbătoare solemnă pentru DOMNUL Dumnezeul tău în locul pe care îl va alege DOMNUL, pentru că DOMNUL Dumnezeul tău te va binecuvânta în tot venitul tău şi în toate lucrările mâinilor tale, ca să te bucuri într-adevăr.
16 Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún ni kí gbogbo àwọn ọkùnrin rẹ kí ó farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ní ibi tí yóò yàn. Níbi àjọ àkàrà àìwú, níbi àjọ ọ̀sẹ̀, àti àjọ àgọ́ ìpàdé. Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú Olúwa ní ọwọ́ òfo.
De trei ori pe an, toată partea ta bărbătească să se înfăţişeze înaintea DOMNULUI Dumnezeul tău în locul pe care îl va alege; la sărbătoarea azimelor şi la sărbătoarea săptămânilor şi la sărbătoarea corturilor şi să nu se înfăţişeze înaintea DOMNULUI cu mâna goală;
17 Kí olúkúlùkù ó mú ọrẹ wá bí agbára rẹ̀ ti tó, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ó fi fún un ọ̀.
Fiecare om să dea precum este în stare, conform binecuvântării pe care ţi-a dat-o DOMNUL Dumnezeul tău.
18 Ẹ yan àwọn adájọ́ àti àwọn olóyè fún ẹ̀yà a yín kọ̀ọ̀kan, ní gbogbo ìlú tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, wọ́n sì gbọdọ̀ máa fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.
Să îţi pui judecători şi administratori în toate porţile tale, pe care ţi le dă DOMNUL Dumnezeul tău în triburile tale, şi ei să judece poporul cu judecată dreaptă.
19 Ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú ènìyàn. Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
Să nu strâmbi judecata, să nu părtineşti după înfăţişare, nu lua niciun dar, pentru că darul orbeşte ochii înţelepţilor şi perverteşte cuvintele celor drepţi.
20 Ẹ tẹ̀lé ìdájọ́ òtítọ́ àní ìdájọ́ òtítọ́ nìkan, kí ẹ bá à lè gbé kí ẹ sì gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín.
Să urmăreşti ceea ce este în întregime drept, ca să trăieşti şi să stăpâneşti ţara pe care ţi-o dă DOMNUL Dumnezeul tău.
21 Ẹ má ṣe ri ère òrìṣà Aṣerah sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ tí ẹ ti mọ fún Olúwa Ọlọ́run yín.
Să nu îţi sădeşti vreun crâng de pomi lângă altarul DOMNULUI Dumnezeul tău, pe care ţi-l vei face.
22 Ẹ kò gbọdọ̀ gbé òkúta òrìṣà gbígbẹ́ kan kalẹ̀ fún ara yín, nítorí èyí ni Olúwa Ọlọ́run yín kórìíra.
Nici să nu îţi ridici vreun chip de piatră, pe care îl urăşte DOMNUL Dumnezeul tău.