< Deuteronomy 16 >

1 Ẹ kíyèsi oṣù Abibu, kí ẹ sì máa ṣe àjọ̀dún ìrékọjá ti Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí pé ní oṣù Abibu yìí ni ó mú un yín jáde ní Ejibiti lóru.
Przestrzegaj miesiąca Abib i obchodź Paschę dla PANA, swego Boga, ponieważ w miesiącu Abib PAN, twój Bóg, wyprowadził cię w nocy z Egiptu.
2 Ẹ fi ẹran kan rú ẹbọ bí ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín láti inú ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo màlúù yín ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀.
Złożysz PANU, swemu Bogu, ofiarę paschalną z owiec i wołów w miejscu, które PAN wybierze na mieszkanie dla swego imienia.
3 Ẹ má ṣe jẹ ẹ́ pẹ̀lú u àkàrà tí a fi ìwúkàrà ṣe, ṣùgbọ́n ọjọ́ méje ni kí ẹ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà, àkàrà ìpọ́njú, nítorí pé pẹ̀lú ìkánjú ni ẹ kúrò ní Ejibiti: kí ẹ bá à lè rántí ìgbà tí ẹ kúrò ní Ejibiti ní gbogbo ọjọ́ ayé yín.
Nie będziesz jadł wraz z nią chleba kwaszonego; przez siedem dni będziesz jadł z nią przaśniki, chleb utrapienia – gdyż w pośpiechu wyszedłeś z ziemi Egiptu – abyś pamiętał dzień swego wyjścia z ziemi Egiptu po wszystkie dni swego życia.
4 Kí a má sì ṣe rí àkàrà wíwú ní ọ̀dọ̀ rẹ nínú ilẹ̀ rẹ ní ijọ́ méje. Kí ìwọ má ṣe jẹ́ kí nǹkan kan ṣẹ́kù nínú ẹran tí ìwọ ó fi rú ẹbọ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní di àárọ̀ ọjọ́ kejì.
Nie zobaczy się u ciebie kwasu we wszystkich twoich granicach przez siedem dni. Z mięsa, które złożyłeś pierwszego dnia wieczorem, nie zostawisz nic przez noc do rana.
5 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe ìrékọjá náà ní ìlúkílùú kankan, tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín
Nie będziesz mógł składać [ofiary] paschalnej w żadnej twojej miejscowości, którą daje ci PAN, twój Bóg;
6 bí kò ṣe ibi tí yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀, níbẹ̀ ni ki ẹ ti ṣe ìrúbọ ìrékọjá náà ní ìrọ̀lẹ́ nígbà tí oòrùn bá ń wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìrántí ìgbà tí ẹ kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Lecz w miejscu, które PAN, twój Bóg, wybierze na mieszkanie dla swego imienia, tam będziesz składał [ofiarę] paschalną wieczorem o zachodzie słońca, w porze swego wyjścia z Egiptu.
7 Ẹ sun ún kí ẹ sì jẹ ẹ́ ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn. Ní àárọ̀, kí ẹ padà sí àgọ́ ọ yín.
Upieczesz ją i spożyjesz w miejscu, które PAN, twój Bóg, wybierze. Potem rano zawrócisz i pójdziesz do swoich namiotów.
8 Ọjọ́ mẹ́fà ní kí ẹ fi jẹ àkàrà aláìwú, ní ọjọ́ keje, ẹ pe àjọ kan fún Olúwa Ọlọ́run yín, kí ẹ má sì ṣe iṣẹ́ kankan.
Przez sześć dni będziesz jadł przaśniki, a siódmego dnia [będzie] uroczyste święto dla PANA, twego Boga. Nie będziesz [wtedy] wykonywał żadnej pracy.
9 Ka ọ̀sẹ̀ méje láti ìgbà tí ẹ bá ti bẹ̀rẹ̀ sí fi dòjé ṣe ìkórè ọkà.
Odliczysz sobie siedem tygodni. Zaczniesz liczyć te siedem tygodni od zapuszczenia sierpa w zboże.
10 Nígbà náà ni kí ẹ ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nípa pípèsè ọrẹ àtinúwá, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
Potem będziesz obchodził Święto Tygodni dla PANA, swego Boga, z dobrowolną ofiarą twojej ręki, którą dasz stosownie do tego, jak cię błogosławił PAN, twój Bóg.
11 Kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí yóò yàn ní ibùgbé fún orúkọ rẹ̀: ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin, àwọn ẹrú yín ọkùnrin àti àwọn ẹrú yín obìnrin, àwọn Lefi tí ó wà ní ìlú yín, àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé àárín yín.
A w miejscu, które PAN, twój Bóg, wybierze na mieszkanie dla swego imienia, będziesz się radował przed PANEM, swoim Bogiem, ty, twój syn i twoja córka, twój sługa i twoja służąca, Lewita, który jest w twoich bramach, przybysz, sierota i wdowa, którzy będą wśród was.
12 Ẹ rántí pé, ẹ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, nítorí náà ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà wọ̀nyí dáradára.
I będziesz pamiętał, że byłeś niewolnikiem w Egipcie. Dlatego pilnuj wypełnienia tych nakazów.
13 Ẹ ṣe ayẹyẹ àgọ́ ìpàdé fún ọjọ́ méje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá ti kórè oko yín tí ẹ ti pakà tí ẹ sì ti fún ọtí tán.
Będziesz obchodził Święto Namiotów przez siedem dni, gdy zbierzesz [plony] ze swojego klepiska i tłoczni.
14 Ẹ máa yọ̀ ní àkókò àjọ̀dún un yín, ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin, àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín, àti àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó tí ń gbé ní àwọn ìlú u yín.
I będziesz się radował podczas tego święta, ty, twój syn i twoja córka, twój sługa i twoja służąca, Lewita, który jest w twoich bramach, przybysz, sierota i wdowa, którzy [będą] w [obrębie] twoich bram.
15 Ọjọ́ méje ni kí ẹ̀yin kí ó fi ṣe ayẹyẹ fún Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín ní gbogbo ìkórè e yín, àti ní gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín, ayọ̀ ọ yín yóò sì kún.
Przez siedem dni będziesz obchodził uroczyste święto dla PANA, swego Boga, w miejscu, które PAN wybierze, gdyż PAN, twój Bóg, będzie cię błogosławił we wszystkich twoich zbiorach i w każdej pracy twoich rąk; i będziesz pełny radości.
16 Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún ni kí gbogbo àwọn ọkùnrin rẹ kí ó farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ní ibi tí yóò yàn. Níbi àjọ àkàrà àìwú, níbi àjọ ọ̀sẹ̀, àti àjọ àgọ́ ìpàdé. Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú Olúwa ní ọwọ́ òfo.
Trzy razy w roku wszyscy twoi mężczyźni pokażą się przed PANEM, twoim Bogiem, w miejscu, które on wybierze: na Święto Przaśników, na Święto Tygodni i na Święto Namiotów. A nikt nie pokaże się przed PANEM z pustymi rękami.
17 Kí olúkúlùkù ó mú ọrẹ wá bí agbára rẹ̀ ti tó, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ó fi fún un ọ̀.
Każdy [przyjdzie] z darem ze swojej ręki według błogosławieństwa PANA, twojego Boga, które on ci daje.
18 Ẹ yan àwọn adájọ́ àti àwọn olóyè fún ẹ̀yà a yín kọ̀ọ̀kan, ní gbogbo ìlú tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, wọ́n sì gbọdọ̀ máa fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.
Ustanowisz sobie sędziów i urzędników we wszystkich swoich miastach, które PAN, twój Bóg, daje ci dla wszystkich waszych pokoleń, aby sądzili lud sprawiedliwym sądem.
19 Ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú ènìyàn. Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
Nie będziesz naginał sądu, nie będziesz miał względu na osobę i nie będziesz brał daru, gdyż dar zaślepia oczy mądrych i wypacza słowa sprawiedliwych.
20 Ẹ tẹ̀lé ìdájọ́ òtítọ́ àní ìdájọ́ òtítọ́ nìkan, kí ẹ bá à lè gbé kí ẹ sì gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín.
Podążaj całkowicie za sprawiedliwością, abyś żył i posiadł ziemię, którą daje ci PAN, twój Bóg.
21 Ẹ má ṣe ri ère òrìṣà Aṣerah sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ tí ẹ ti mọ fún Olúwa Ọlọ́run yín.
Nie posadzisz sobie gaju z żadnego drzewa dokoła ołtarza PANA, swego Boga, jaki sobie zbudujesz.
22 Ẹ kò gbọdọ̀ gbé òkúta òrìṣà gbígbẹ́ kan kalẹ̀ fún ara yín, nítorí èyí ni Olúwa Ọlọ́run yín kórìíra.
Nie postawisz sobie posągu, [gdyż] PAN, twój Bóg, nienawidzi tego.

< Deuteronomy 16 >