< Deuteronomy 16 >

1 Ẹ kíyèsi oṣù Abibu, kí ẹ sì máa ṣe àjọ̀dún ìrékọjá ti Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí pé ní oṣù Abibu yìí ni ó mú un yín jáde ní Ejibiti lóru.
Przestrzegaj miesiąca Abib, abyś weń obchodził święto przejścia Panu, Bogu twemu, ponieważ miesiąca Abiba wywiódł cię Pan, Bóg twój, z Egiptu w nocy.
2 Ẹ fi ẹran kan rú ẹbọ bí ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín láti inú ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo màlúù yín ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀.
A będziesz ofiarował ofiarę świętą przejścia Panu, Bogu twemu, z owiec i z wołów, na miejscu, które obierze Pan, aby tam mieszkało imię jego.
3 Ẹ má ṣe jẹ ẹ́ pẹ̀lú u àkàrà tí a fi ìwúkàrà ṣe, ṣùgbọ́n ọjọ́ méje ni kí ẹ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà, àkàrà ìpọ́njú, nítorí pé pẹ̀lú ìkánjú ni ẹ kúrò ní Ejibiti: kí ẹ bá à lè rántí ìgbà tí ẹ kúrò ní Ejibiti ní gbogbo ọjọ́ ayé yín.
Nie będziesz z nimi jadł kwaszonego; przez siedem dni jeść będziesz z nimi przaśniki, chleb utrapienia, (boś z kwapieniem wyszedł z ziemi Egipskiej), abyś pamiętał dzień wyjścia twego z ziemi Egipskiej po wszystkie dni żywota twego.
4 Kí a má sì ṣe rí àkàrà wíwú ní ọ̀dọ̀ rẹ nínú ilẹ̀ rẹ ní ijọ́ méje. Kí ìwọ má ṣe jẹ́ kí nǹkan kan ṣẹ́kù nínú ẹran tí ìwọ ó fi rú ẹbọ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní di àárọ̀ ọjọ́ kejì.
A nie pokaże się u ciebie kwas we wszystkich granicach twoich przez siedem dni, i nie zostanie nic przez noc z mięsa, które byś ofiarował w wieczór pierwszego dnia, aż do poranku.
5 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe ìrékọjá náà ní ìlúkílùú kankan, tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín
Nie będziesz mógł ofiarować ofiary święta przejścia w któremkolwiek mieście twojem, z onych, które Pan, Bóg twój, dawa tobie.
6 bí kò ṣe ibi tí yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀, níbẹ̀ ni ki ẹ ti ṣe ìrúbọ ìrékọjá náà ní ìrọ̀lẹ́ nígbà tí oòrùn bá ń wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìrántí ìgbà tí ẹ kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Ale na miejscu, które obierze Pan, Bóg twój, aby tam mieszkało imię jego, ofiarować będziesz ofiarę świętą przejścia w wieczór przy zajściu słońca, w ten czas, któregoś wyszedł z Egiptu.
7 Ẹ sun ún kí ẹ sì jẹ ẹ́ ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn. Ní àárọ̀, kí ẹ padà sí àgọ́ ọ yín.
To upieczesz i jeść będziesz na miejscu, które obierze Pan, Bóg twój; potem wrócisz się rano, i pójdziesz do namiotów swoich.
8 Ọjọ́ mẹ́fà ní kí ẹ fi jẹ àkàrà aláìwú, ní ọjọ́ keje, ẹ pe àjọ kan fún Olúwa Ọlọ́run yín, kí ẹ má sì ṣe iṣẹ́ kankan.
Przez sześć dni będziesz jadł przaśniki, ale w dzień siódmy święto uroczyste będzie Pana, Boga twego; nie będziesz czynił weń żadnej roboty.
9 Ka ọ̀sẹ̀ méje láti ìgbà tí ẹ bá ti bẹ̀rẹ̀ sí fi dòjé ṣe ìkórè ọkà.
Siedem też tygodni odliczysz sobie; gdy zapuścisz sierp w zboże twoje, poczniesz liczyć siedem tygodni.
10 Nígbà náà ni kí ẹ ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nípa pípèsè ọrẹ àtinúwá, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
A potem będziesz obchodził święto tygodni Panu, Bogu twemu; z dostatku ręki twej dobrowolnie dasz według tego, jako cię ubłogosławił Pan, Bóg twój.
11 Kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí yóò yàn ní ibùgbé fún orúkọ rẹ̀: ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin, àwọn ẹrú yín ọkùnrin àti àwọn ẹrú yín obìnrin, àwọn Lefi tí ó wà ní ìlú yín, àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé àárín yín.
A będziesz się weselił przed Panem, Bogiem twoim, ty i syn twój, i córka twoja, i sługa twój, i służebnica twoja, i Lewita, który jest w bramach twoich, i przychodzień, i sierota, i wdowa, którzy będą w pośrodku ciebie, na miejscu, które obierze Pan, Bóg twój, aby tam mieszkało imię jego.
12 Ẹ rántí pé, ẹ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, nítorí náà ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà wọ̀nyí dáradára.
A będziesz wspominał, żeś był niewolnikiem w Egipcie; przetoż strzedz i czynić będziesz te ustawy.
13 Ẹ ṣe ayẹyẹ àgọ́ ìpàdé fún ọjọ́ méje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá ti kórè oko yín tí ẹ ti pakà tí ẹ sì ti fún ọtí tán.
Przytem święto kuczek obchodzić będziesz przez siedem dni, gdy zbierzesz pożytki z bojewiska twego, i z prasy twojej.
14 Ẹ máa yọ̀ ní àkókò àjọ̀dún un yín, ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin, àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín, àti àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó tí ń gbé ní àwọn ìlú u yín.
I będziesz się weselił w święto uroczyste twoje, ty, i syn twój, i córka twoja, i sługa twój, i służebnica twoja, i Lewita, i przychodzień, i sierota, i wdowa, którzy będą w bramach twoich.
15 Ọjọ́ méje ni kí ẹ̀yin kí ó fi ṣe ayẹyẹ fún Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín ní gbogbo ìkórè e yín, àti ní gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín, ayọ̀ ọ yín yóò sì kún.
Przez siedem dni będziesz obchodził święto uroczyste Panu, Bogu twemu, na miejscu, które obierze Pan, gdyć błogosławić będzie Pan, Bóg twój, we wszystkich urodzajach twoich, i we wszelkiej pracy rąk twoich; a tak będziesz wesół.
16 Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún ni kí gbogbo àwọn ọkùnrin rẹ kí ó farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ní ibi tí yóò yàn. Níbi àjọ àkàrà àìwú, níbi àjọ ọ̀sẹ̀, àti àjọ àgọ́ ìpàdé. Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú Olúwa ní ọwọ́ òfo.
Trzy kroć do roku ukaże się każdy mężczyzna twój przed Panem, Bogiem twoim, na miejscu, które obierze, w święto przaśników, i w święto tygodni, i w święto kuczek, a nie ukaże się nikt przed Panem próżny.
17 Kí olúkúlùkù ó mú ọrẹ wá bí agbára rẹ̀ ti tó, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ó fi fún un ọ̀.
Każdy ukaże się z darem ręki swojej według błogosławieństwa Pana, Boga twego, które on da tobie.
18 Ẹ yan àwọn adájọ́ àti àwọn olóyè fún ẹ̀yà a yín kọ̀ọ̀kan, ní gbogbo ìlú tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, wọ́n sì gbọdọ̀ máa fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.
Sędzie i urzędniki postanowisz sobie we wszystkich bramach twoich, które Pan, Bóg twój, da tobie w każdem pokoleniu twojem, aby sądzili lud sądem sprawiedliwym.
19 Ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú ènìyàn. Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
Nie będziesz podwracał sądu, ani będziesz miał względu na osobę, i daru brać nie będziesz; albowiem dar zaślepia oczy mądrych, a podwraca słowa sprawiedliwych.
20 Ẹ tẹ̀lé ìdájọ́ òtítọ́ àní ìdájọ́ òtítọ́ nìkan, kí ẹ bá à lè gbé kí ẹ sì gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín.
Sprawiedliwości, sprawiedliwości naśladować będziesz, abyś żył, i posiadł ziemię, którą Pan, Bóg twój, dawa tobie.
21 Ẹ má ṣe ri ère òrìṣà Aṣerah sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ tí ẹ ti mọ fún Olúwa Ọlọ́run yín.
Nie sadź sobie gaju z żadnego drzewa przy ołtarzu Pana, Boga twego, który sobie zbudujesz.
22 Ẹ kò gbọdọ̀ gbé òkúta òrìṣà gbígbẹ́ kan kalẹ̀ fún ara yín, nítorí èyí ni Olúwa Ọlọ́run yín kórìíra.
Ani sobie wystawiaj słupa, gdyż to ma w nienawiści Pan, Bóg twój.

< Deuteronomy 16 >