< Deuteronomy 16 >

1 Ẹ kíyèsi oṣù Abibu, kí ẹ sì máa ṣe àjọ̀dún ìrékọjá ti Olúwa Ọlọ́run yín, nítorí pé ní oṣù Abibu yìí ni ó mú un yín jáde ní Ejibiti lóru.
Ügyelj az Abib hónapra, és készíts az Úrnak, a te Istenednek páskhát; mert az Abib hónapban hozott ki téged az Úr, a te Istened Égyiptomból éjjel.
2 Ẹ fi ẹran kan rú ẹbọ bí ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín láti inú ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo màlúù yín ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀.
Páskha gyanánt pedig ölj az Úrnak, a te Istenednek juhot és ökröt azon a helyen, a melyet kiválaszt az Úr, a te Istened, hogy oda helyezze az ő nevét.
3 Ẹ má ṣe jẹ ẹ́ pẹ̀lú u àkàrà tí a fi ìwúkàrà ṣe, ṣùgbọ́n ọjọ́ méje ni kí ẹ fi jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà, àkàrà ìpọ́njú, nítorí pé pẹ̀lú ìkánjú ni ẹ kúrò ní Ejibiti: kí ẹ bá à lè rántí ìgbà tí ẹ kúrò ní Ejibiti ní gbogbo ọjọ́ ayé yín.
Ne egyél azzal semmi kovászost, hanem hét napon át egyél azzal kovásztalan lepényeket, nyomorúságnak kenyerét, (mert sietséggel jöttél ki Égyiptom földéről) hogy megemlékezzél arról a napról életednek minden idejében, a melyen kijöttél Égyiptom földéről.
4 Kí a má sì ṣe rí àkàrà wíwú ní ọ̀dọ̀ rẹ nínú ilẹ̀ rẹ ní ijọ́ méje. Kí ìwọ má ṣe jẹ́ kí nǹkan kan ṣẹ́kù nínú ẹran tí ìwọ ó fi rú ẹbọ ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní di àárọ̀ ọjọ́ kejì.
És ne lásson senki kovászt hét napon át sehol a te határodban; és a húsból, a melyet az első napon estve megáldozol, semmi ne maradjon reggelig.
5 Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe ìrékọjá náà ní ìlúkílùú kankan, tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín
Nem ölheted le a páskhát akármelyikben a te városaid közül, a melyeket az Úr, a te Istened ád néked;
6 bí kò ṣe ibi tí yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibùgbé fún orúkọ rẹ̀, níbẹ̀ ni ki ẹ ti ṣe ìrúbọ ìrékọjá náà ní ìrọ̀lẹ́ nígbà tí oòrùn bá ń wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìrántí ìgbà tí ẹ kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.
Hanem azon a helyen, a melyet kiválaszt az Úr, a te Istened, hogy az ő nevét oda helyezze: ott öld le a páskhát estve, napnyugtakor, abban az időben, a mikor kijöttél Égyiptomból.
7 Ẹ sun ún kí ẹ sì jẹ ẹ́ ní ibi tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò yàn. Ní àárọ̀, kí ẹ padà sí àgọ́ ọ yín.
Azon a helyen süsd és edd is meg, a melyet kiválaszt az Úr, a te Istened; reggel pedig fordulj vissza és menj haza a te hajlékodba.
8 Ọjọ́ mẹ́fà ní kí ẹ fi jẹ àkàrà aláìwú, ní ọjọ́ keje, ẹ pe àjọ kan fún Olúwa Ọlọ́run yín, kí ẹ má sì ṣe iṣẹ́ kankan.
Hat napon át egyél kovásztalant; hetednapon pedig az Úrnak, a te Istenednek berekesztő ünnepe lévén, ne munkálkodjál azon.
9 Ka ọ̀sẹ̀ méje láti ìgbà tí ẹ bá ti bẹ̀rẹ̀ sí fi dòjé ṣe ìkórè ọkà.
Számlálj azután magadnak hét hetet; attól fogva kezdjed számlálni a hét hetet, hogy sarlódat a vetésbe bocsátod.
10 Nígbà náà ni kí ẹ ṣe àjọ ọ̀sẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, nípa pípèsè ọrẹ àtinúwá, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín.
És tarts hetek ünnepét az Úrnak, a te Istenednek, a te kezednek szabad akarat szerint való adományával, a melyet ahhoz képest adj, a mint megáldott téged az Úr, a te Istened.
11 Kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí yóò yàn ní ibùgbé fún orúkọ rẹ̀: ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin, àwọn ẹrú yín ọkùnrin àti àwọn ẹrú yín obìnrin, àwọn Lefi tí ó wà ní ìlú yín, àti àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba, àti àwọn opó tí ń gbé àárín yín.
És örvendezz az Úrnak, a te Istenednek színe előtt, te és a te fiad, és leányod, szolgád, szolgálóleányod, és a lévita, a ki a te kapuidon belől van, és a jövevény, az árva és az özvegy, a kik te közötted vannak, azon a helyen, a melyet kiválasztott az Úr, a te Istened, hogy oda helyezze az ő nevét.
12 Ẹ rántí pé, ẹ ti jẹ́ ẹrú ní Ejibiti rí, nítorí náà ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà wọ̀nyí dáradára.
És emlékezzél meg róla, hogy te is szolga voltál Égyiptomban; és tartsd meg, és teljesítsd e rendeléseket.
13 Ẹ ṣe ayẹyẹ àgọ́ ìpàdé fún ọjọ́ méje lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá ti kórè oko yín tí ẹ ti pakà tí ẹ sì ti fún ọtí tán.
A sátorok ünnepét hét napig tartsd, mikor begyűjtöd a termést a te szérűdről és sajtódról.
14 Ẹ máa yọ̀ ní àkókò àjọ̀dún un yín, ẹ̀yin, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin, àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín, àti àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó tí ń gbé ní àwọn ìlú u yín.
És örvendezz a te ünnepeden, te és a te fiad, a te leányod, szolgád és szolgálóleányod, a lévita, a jövevény, az árva és az özvegy, a kik belől vannak a te kapuidon.
15 Ọjọ́ méje ni kí ẹ̀yin kí ó fi ṣe ayẹyẹ fún Olúwa Ọlọ́run yín ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín ní gbogbo ìkórè e yín, àti ní gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín, ayọ̀ ọ yín yóò sì kún.
Hét napig ünnepelj az Úrnak, a te Istenednek azon a helyen, a melyet kiválaszt az Úr; mert megáld téged az Úr, a te Istened minden termésedben, és kezeidnek minden munkájában; azért örvendezz igen!
16 Ní ẹ̀ẹ̀mẹ́ta lọ́dún ni kí gbogbo àwọn ọkùnrin rẹ kí ó farahàn níwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ní ibi tí yóò yàn. Níbi àjọ àkàrà àìwú, níbi àjọ ọ̀sẹ̀, àti àjọ àgọ́ ìpàdé. Ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ wá sí iwájú Olúwa ní ọwọ́ òfo.
Minden esztendőben háromszor jelenjen meg közüled minden férfiú az Úrnak, a te Istenednek színe előtt azon a helyen, a melyet kiválaszt; a kovásztalan kenyerek ünnepén, a hetek ünnepén, és a sátorok ünnepén. De üres kézzel senki se jelenjen meg az Úr előtt!
17 Kí olúkúlùkù ó mú ọrẹ wá bí agbára rẹ̀ ti tó, gẹ́gẹ́ bí ìbùkún Olúwa Ọlọ́run rẹ tí ó fi fún un ọ̀.
Kiki az ő képessége szerint adjon, az Úrnak, a te Istenednek áldása szerint, a melyet ád néked.
18 Ẹ yan àwọn adájọ́ àti àwọn olóyè fún ẹ̀yà a yín kọ̀ọ̀kan, ní gbogbo ìlú tí Olúwa Ọlọ́run yín yóò fún un yín, wọ́n sì gbọdọ̀ máa fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.
Bírákat és felügyelőket állíts minden kapudba, a melyeket az Úr, a te Istened ád néked, a te törzseid szerint, hogy ítéljék a népet igaz ítélettel.
19 Ìwọ kò gbọdọ̀ yí ìdájọ́ po, ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúsàájú ènìyàn. Ìwọ kò gbọdọ̀ gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ nítorí pé àbẹ̀tẹ́lẹ̀ ń fọ́ ojú ọlọ́gbọ́n, ó sì ń ba ọ̀rọ̀ olódodo jẹ́.
El ne fordítsd az itéletet; személyt se válogass; ajándékot se végy; mert az ajándék megvakítja a bölcsek szemeit, és elfordítja az igazak beszédét.
20 Ẹ tẹ̀lé ìdájọ́ òtítọ́ àní ìdájọ́ òtítọ́ nìkan, kí ẹ bá à lè gbé kí ẹ sì gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín ń fún un yín.
Igazságot, igazságot kövess, hogy élhess, és örökségül bírhasd azt a földet, a melyet az Úr, a te Istened ád néked.
21 Ẹ má ṣe ri ère òrìṣà Aṣerah sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ tí ẹ ti mọ fún Olúwa Ọlọ́run yín.
Ne plántálj magadnak berket semmiféle fából, az Úrnak, a te Istenednek oltára mellé, a melyet készítesz magadnak.
22 Ẹ kò gbọdọ̀ gbé òkúta òrìṣà gbígbẹ́ kan kalẹ̀ fún ara yín, nítorí èyí ni Olúwa Ọlọ́run yín kórìíra.
Oszlopot se emelj magadnak, a mit gyűlöl az Úr, a te Istened.

< Deuteronomy 16 >